< Roma 7 >

1 Sana iyiru ba linuana [in din liru nin na nit ale na yiru uduka] bara uduka din dortu nin nit nan nya na yirin in lai me?
Ẹ̀yin kò ha mọ̀, ara: nítorí èmí bá àwọn tí ó mọ òfin sọ̀rọ̀ pé, òfin ní ipá lórí ènìyàn níwọ̀n ìgbà tí ó bá wà láààyè nìkan?
2 Ame uwani ni luma a terin nin lesse nan nya nisilin niluma ywase ulesse nnku, abuntu nannya ni silin ni luma.
Fún àpẹẹrẹ, nípa òfin ní a de obìnrin mọ́ ọkọ rẹ̀ níwọ̀n ìgbà tí ọkọ náà wà láààyè, ṣùgbọ́n bí ọkọ rẹ̀ bá kú, a tú u sílẹ̀ kúrò nínú òfin ìgbéyàwó náà.
3 Bara nan, nan nya kubi ko na ulsse di nin lai asa anuzu asu iluma nin mong ima yichi ghe ukilak. Asa ulesse nku anuzu ni silin nilumea na du ikilaki asa su ilumama nin mong uni.
Nígbà náà, bí ó bá fẹ́ ọkùnrin mìíràn nígbà tí ọkọ rẹ̀ wà láààyè, panṣágà ní a ó pè é. Ṣùgbọ́n bí ọkọ rẹ̀ bá kú, ó bọ́ lọ́wọ́ òfin náà, kí yóò sì jẹ́ panṣágà bí ó bá ní ọkọ mìíràn.
4 Bara nanere nwa na nin i wa ti munu anan kul bar uduka nan nyan Kirst, bara ina dofuzonu ligowe nin nin nat, bara ame, naiwafiya ghe nan nya nan ku, bara bara nan macha nono fiu Kutelle.
Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ará mi, ẹ̀yin pẹ̀lú ti di òkú sí òfin nípa ara Kristi, kí ẹ̀yin kí ó lè ní ẹlòmíràn, àní ẹni náà tí a jí dìde kúrò nínú òkú, kí àwa kí ó lè so èso fún Ọlọ́run.
5 Kube na ti wadi nakidowo wanuzu kamang nan nya niti niti nidowo bite. In nuzum duka bara tinan nut tuno nono kul.
Nítorí ìgbà tí a wa nípa ti ara, ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ nípa ti òfin, ma ń ṣiṣẹ́ nínú wa, tí a sì ń so èso tí ó yẹ fún ikú.
6 Nene ina nutun nari nan nyan duk a tinani naku nan nyan in chn bite na ti wa kif, bara ti nan su kata kapese nan nya in fip Kutelle, na nan nya in chin ukuse ba.
Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, nípa kíkú ohun tó so wá pọ̀ tẹ́lẹ̀ rí, a ti tú wa sílẹ̀ kúrò nínú òfin, kí a lè sin ín ní ìlànà tuntun ti Ẹ̀mí, kì í ṣe ní ìlànà àtijọ́ tí ìwé òfin gùnlé.
7 Ani iyari tima belle nene? Ani uduk kulapiari litime? Na uwa so nanin b. Vat nin nan, na inwa na yinin kulapi ba, sasana uduka b. Na inwa yiru iyiru iyari kunaniyizi sasa na uduke na bellin b, “Naubasu kunaniyizi ba,”
Ǹjẹ́ àwa o ha ti wí, nígbà náà? Òfin ha ń ṣe ẹ̀ṣẹ̀ bí? Kí a má rí i! Ṣùgbọ́n èmi kì bá tí mọ ohun tí ẹ̀ṣẹ̀ jẹ́, bí kò ṣe nípa òfin. Èmi kì bá tí mọ ojúkòkòrò, bí kò ṣe bí òfin ti wí pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ ṣe ojúkòkòrò.”
8 Tutun kulapi nayiru kubi nan nya in duka unare na dak nin vat intok kulapi nan nya nin. Tutun andi na Uduka di ba kulapin nkul
Ṣùgbọ́n ẹ̀ṣẹ̀ sì ti ipa òfin rí ààyè ṣiṣẹ́ onírúurú ìfẹ́kúfẹ̀ẹ́ nínú mi. Nítorí láìsí òfin, ẹ̀ṣẹ̀ jẹ́ ikú.
9 so uurum in wa yita nin bai sa Uduka ne uduka dak kulapi koni na kuru kurun fita iminaku
Èmi sì ti wà láààyè láìsí òfin nígbà kan rí; ṣùgbọ́n nígbà tí òfin dé, ẹ̀ṣẹ̀ sọjí èmi sì kú.
10 Uduka na una din wori ubani ulai unin na da nin kul.
Mo ṣàkíyèsí pé òfin tí ó yẹ kí ó mú ìyè wá ni ó padà mú ikú wá.
11 Kulapi na yiru kubi nan nyan Uduka kurusuzu, nkoni na molii kitenen uduke.
Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ti ipa òfin rí ààyè láti tàn mí jẹ, ó sì ti ipa òfin ṣe ikú pa mi.
12 Nani ushara di lau a uduka lau imon ichine nin chau. So urum in wa yita nin lai sa uduka, nene na uduka na da, kulapi koni na kuru ku fita immini nak,
Bẹ́ẹ̀ ni mímọ́ ni òfin, mímọ́ sì ni àṣẹ, àti òdodo, àti dídára.
13 Nni nene imon ichine isoyi ukulla? Na nani b. Nani kulapi, bara in durso kulapi ari sai nan nyan ni mon igegeme. uni na dai nin kul bara nan nya induka kulapi na na nnzu kamang.
Ǹjẹ́ ohun tí ó dára ha di ikú fún mi bí? Kí a má rí i! Ṣùgbọ́n kí ẹ̀ṣẹ̀, kí ó lè farahàn bí ẹ̀ṣẹ̀, ó ń ti ipa ohun tí ó dára ṣiṣẹ́ ikú nínú mi, kí ẹ̀ṣẹ̀ lè ti ipa òfin di búburú rékọjá.
14 Bara tiyiru o Usharawe di nin fip kutelle, vat nanin in di na kidow. Ina lewi udu lichi nan nya, kulapi.
Nítorí àwa mọ̀ pé ohun ẹ̀mí ni òfin, ṣùgbọ́n ẹni ti ara ni èmi, tí a ti tà sábẹ́ ẹ̀ṣẹ̀.
15 Bara iwon ile na idin suzuna in yirub. Imon ile na indi nin sun su. Na in nare indun sue ba imon ile nain nari inare indin sue.
Èmi pàápàá, kò mọ̀ ohun tí èmi ń ṣe. Nítorí pé, ohun tí mo fẹ́ ṣe gan an n kò ṣe é, ṣùgbọ́n ohun tí mo kórìíra ni mo ń ṣe.
16 Bara nani andi in din su iwon ile na in dimin suwe b. Men yinni nin woru ushara chau.
Ṣùgbọ́n bí mo bá ṣe ohun tí èmi kò fẹ́, mo gbà pé òfin dára.
17 Bara nani na mere din suzu ininb, kulape na kudi in nan nya nigher.
Ṣùgbọ́n bí ọ̀rọ̀ ṣe rí yìí kì í ṣe èmi ni ó ṣe é bí kò ṣe ẹ̀ṣẹ̀ tí ń gbé inú mi.
18 Bara nanin men nan nya kidowo nigh, na imon ichine duku b, bara usuu ni mon ichine di nmi vat nani na in wasa su ba.
Èmi mọ̀ dájú pé kò sí ohun tí ó dára kan tí ń gbé inú mi, àní, nínú ara ẹ̀ṣẹ̀ mi. Èmi fẹ́ ṣe èyí tí ó dára, ṣùgbọ́n kò sé é ṣe.
19 Bara imon ichine ile na in dinin su in s, indin su b, nani imon inanzang ile na in di nin suwa ba inere in din su.
Nítorí ohun tí èmi ṣe kì í ṣe ohun rere tí èmi fẹ́ láti ṣe; rárá, ṣùgbọ́n búburú tí èmi kò fẹ́, èyí nì ni èmi ń ṣe.
20 Nene asan insuimon ile na indi nin su b, to nanere nane din in sue b, vat nane kulere na kudi nan nya nighe.
Nísinsin yìí, bí mo bá ń ṣe nǹkan tí n kò fẹ́ láti ṣe, kì í ṣe èmí fúnra mi ni ó ṣe é, bí kò ṣe ẹ̀ṣẹ̀ tí ń bẹ nínú ni ó ṣe é.
21 In se nan nya ime likara lichine in di nin sun in su imon ichin, vat nanin imon inanzanghari di in me.
Nítorí náà, èmi kíyèsi pé òfin ní ń ṣiṣẹ́ nínú mi, nígbà tí èmi bá fẹ́ ṣe rere, búburú wà níbẹ̀ pẹ̀lú mi.
22 In di nin liburi libo nin shara Kutelle bara uni ule na adi nan nya ni.
Nínú ìjìnlẹ̀ ọkàn mi mo ní inú dídùn sí òfin Ọlọ́run;
23 Mmini yene umon uka'idari ugan di niti niti kidowo nighe udi likum nin ukai'da upeseh nan nya kibinai nighe aminin yirai kuchin bara ukai'da kulapi ule udi niti niti nidowo nighe.
mo rí òfin mìíràn tó ń ṣiṣẹ́ nínú ẹ̀yà ara mi, èyí tí ń gbógun ti òfin tó tinú ọkàn mi wá, èyí tí ó sọ mi di ẹrú òfin ẹ̀ṣẹ̀ tí ó ń ṣiṣẹ́ nínú ẹ̀yà ara mi.
24 Ki kimong nameng! Ghari ba tuchu menku nan nya kidawo nkul?
Èmi ẹni òsì! Ta ni yóò ha gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ara kíkú yìí?
25 Liburi libo kiti Kutelle bara Kirsti Yisa Chikila bit. Bara nani meng litini ghe in lon li kot mmaa dortu Ushara Kutell, in lon li kot tutung indortu uka'ida kulapi nin kidowo.
Ọpẹ́ ni fún Ọlọ́run nípasẹ̀ Jesu Kristi Olúwa wa! Ǹjẹ́ nítorí náà, èmi fúnra mi jẹ́ ẹrú sí òfin Ọlọ́run, ṣùgbọ́n nínú ara ẹ̀ṣẹ̀ mo jẹ́ ẹrú fún òfin ẹ̀ṣẹ̀.

< Roma 7 >