< 2 Ukorintiyawa 6 >

1 nani katwa logow, idin foo minu nnacara na wa seruu ubolu Kutelle hen nani ba
Gẹ́gẹ́ bí alábáṣiṣẹ́pọ̀ nínú Ọlọ́run, ǹjẹ́, àwa ń rọ̀ yín kí ẹ má ṣe gba oore-ọ̀fẹ́ Ọlọ́run lásán.
2 Bara na abenle “Nanya kubi ku mang inwa lanza minu, ninwe liri intucu nwa bun minu “Yeneng nenere kubi kumanghe yeneng nenere lirin tucua.
Nítorí o wí pé, “Ní àkókò ìtẹ́wọ́gbà mi, èmi tí gbọ́ ohùn rẹ, àti ọjọ́ ìgbàlà, èmi sì ti ràn ọ́ lọ́wọ́.” Èmi wí fún ọ, nísinsin yìí ní àkókò ìtẹ́wọ́gbà, nísinsin yìí ni ọjọ́ ìgbàlà.
3 Na arik na ceu litalan tirzu nbun mun b, bara na tidinin su katwa bite se ulazi ba.
Àwa kò sì gbé ohun ìkọ̀sẹ̀ kankan si ọ̀nà ẹnikẹ́ni, ki iṣẹ́ ìránṣẹ́ wa má ṣe di ìsọ̀rọ̀-òdì sí.
4 Nin yenu nani, ti duro atibite nin nitwa bite vat au arike acin Kutelleari nanya nteru nibinai umin ijasi.
Ṣùgbọ́n dípò bẹ́ẹ̀, ni ọnà gbogbo, àwa ń fi ara wa hàn bí àwọn ìránṣẹ́ Ọlọ́run nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ sùúrù, nínú ìpọ́njú, nínú àìní, nínú wàhálà,
5 utecu, nannya kuti licin ufizu nayi nin katwa kagbagba, nin salin moroninkitik nin kukpon.
nípa nínà, nínú túbú, nínú ìrúkèrúdò, nínú iṣẹ́ àṣekára, nínú àìsàn, nínú ìgbààwẹ̀.
6 Nin lau uyiru, kbinai ki shau nin washalang nin fip me al, nin su nanya kibinai.
Nínú ìwà mímọ́, nínú ìmọ̀, nínú ìpamọ́ra, nínú ìṣeun, nínú Ẹ̀mí Mímọ́, nínú ìfẹ́ àìṣẹ̀tàn.
7 Nin ligbulang kidegen, nin likara Kutelle nin ticilak nibinai nilau ncra ulime nin cara ugule.
Nínú ọ̀rọ̀ òtítọ́, nínú agbára Ọlọ́run, nínú ìhámọ́ra òdodo ní apá ọ̀tún àti ní apá òsì.
8 Ti di katwa nin ngongon nin salin ngongo, nin tizugo nin lir. I wa yicu nari anan kinu arik nin kidegene bite.
Nípa ọlá àti ẹ̀gàn, nípa ìyìn búburú àti ìyìnrere: bí ẹlẹ́tàn, ṣùgbọ́n a jásí olóòtítọ́,
9 Tidin su katwa we nafon na iwa yiru nari ba a iyiro nari lau nafo tidin kul na tiyita nin lai nafo anan burn, bara nitwa bite na nafo anan caa ukul ba.
bí ẹni tí a kò mọ̀, ṣùgbọ́n a mọ̀ wá dájúdájú; bí ẹni tí ń kú lọ, ṣùgbọ́n a ṣì wà láààyè; bí ẹni tí a nà, ṣùgbọ́n a kò sì pa wá,
10 Tidi katwa nafo nin nibinai nisirne bara nani tidi nin nibinai nibo, nafo nan diru nimum tina yita mum. tina
bí ẹni tí ó kún fún ìbànújẹ́, ṣùgbọ́n àwa ń yọ̀ nígbà gbogbo; bí tálákà, ṣùgbọ́n àwa ń sọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ dí ọlọ́rọ̀; bí ẹni tí kò ní nǹkan, ṣùgbọ́n àwa ni ohun gbogbo.
11 Tina me belin minu kidegene bite va, anan Korintiy, nibinai bite pun pas.
Ẹ̀yin ará Kọrinti, a ti bá yín sọ òtítọ́ ọ̀rọ̀, a ṣí ọkàn wa páyà sí yín.
12 Nati wantin minu nibinai mine b, bara nani anughere wanting ukpilizu ni binai mine
Àwa kò fa ìfẹ́ wa sẹ́yìn fún yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin fa ìfẹ́ yín sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ wa.
13 Nene nanya kpilizu ubarabara indi liru nan ghenu nafo nono punun nibinai mine pash
Ní sísán padà, ní ọ̀nà tí ó dára, èmi ń sọ bí ẹni pé fún àwọn ọmọdé, ẹ̀yin náà ẹ ṣí ọkàn yín páyà pẹ̀lú.
14 Na iwa teru nibinai mine nin nanan salinyinu b, bara nanin iyanghari munu kibinai ki lau nin sali udoka? Sa iyanghari munu njana nin sirti?
Ẹ má ṣe fi àìdọ́gba dàpọ̀ pẹ̀lú àwọn aláìgbàgbọ́, nítorí ìdàpọ̀ kín ni òdodo ní pẹ̀lú àìṣòdodo? Ìdàpọ̀ kín ni ìmọ́lẹ̀ sì ní pẹ̀lú òkùnkùn?
15 Iyapin iyinari di Kristi ku nin nin Beliyar [kudodoa]? Sa uyapi uladari di unanyinu sauyenu ninnan salin yinuri.
Ìrẹ́pọ̀ kín ni Kristi ní pẹ̀lú Beliali? Tàbí ìpín wó ni ẹni tí ó gbàgbọ́ ní pẹ̀lú aláìgbàgbọ́?
16 Nin yapin uyenuari di kuti Kutelle nin Chill? Bara na arik ati alau Kutelle unan laiyar, nafo na ana belin “in ma so nanya mine in kuru cinu nanya mine inin yita Kutelle mine, anin wang yita aniti nin.
Ìrẹ́pọ̀ kín ni tẹmpili Ọlọ́run ní pẹ̀lú òrìṣà? Nítorí ẹ̀yin ní tẹmpili Ọlọ́run alààyè; gẹ́gẹ́ bí Ọlọ́run ti wí pé: “Èmi á gbé inú wọn, èmi o sì máa rìn láàrín wọn, èmi ó sì jẹ́ Ọlọ́run wọn, wọn yóò sì jẹ́ ènìyàn mi.”
17 nani Ucif nabelin”nuzun nanya mine iso kusari kurum.” Na iwa dudo imon inazan ile isali lau b, menbah ba timinu mahabi.''
Nítorí náà, “Ẹ jáde kúrò láàrín wọn, kí ẹ sì yá ara yín si ọ̀tọ̀, ni Olúwa wí. Ki ẹ má ṣe fi ọwọ́ kan ohun àìmọ́; Èmi ó sì gbà yín.”
18 Menghe ma so Ucif kiti fer. Anunghe nin soo ason nin ni na shono nin “Ubenlun Ucif udia.
Àti, “Èmi o sì jẹ́ Baba fún yín. Ẹ̀yin ó sì jẹ́ ọmọkùnrin mi àti ọmọbìnrin mi, ní Olúwa Olódùmarè wí.”

< 2 Ukorintiyawa 6 >