< 2 Ukorintiyawa 2 >

1 Namere in wa kpila kibinai ning likot nan ba kuru ndak kitimine tutung nanya piu sa nanya tinana nayi ba.
Nítorí náà mo tí pinnu nínú ara mí pé, èmi kì yóò tún fi ìbànújẹ́ tọ̀ yin wá.
2 Andi wa nan za minu ukul, gyari ma tiiyi nhsau kibinai ame ule na inlanzaghe ukulere?
Nítorí pé bí èmi bá mú inú yín bàjẹ́, ǹjẹ́ ta ni ẹni ti ìbá mú inú mí dùn ní àkókò tí inú mi bá bàjẹ́ bí kò ṣe ẹni tí mo ti ba nínú jẹ́?
3 In wa yertin nafo na inasu bara inwa dak kitii mine na among mine ba lanzu ukule ba na a nunghere ma tiyi ayiaboo. Idinin likara kibinai kiti mine vat bara na mmang nighe mi rummere nan yinu vat.
Èmi sì kọ̀wé bí mo tí kọ sí yín pé, nígbà tí mo bá sì de, kí èmi má ṣe ni ìbànújẹ́ lọ́dọ̀ àwọn ti ìbá mú mi ní ayọ̀, nítorí tí mo ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú gbogbo yín, wí pé ẹ̀yin yóò jẹ́ alábápín ayọ̀ mi.
4 Bara indin yertu minu nanya nijase idia nin nayi asirn, nin mizin midiy, na idinin iti minu inpiu ni dawo b. Bara nanin iyinin incancam nsu ule na dimu kiti mine.
Nítorí pé nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàhálà àti ìrora ọkàn mí ni mo ti fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ omijé kọ̀wé sí yín; kì í ṣe nítorí kí a lè bà yín nínú jẹ́, ṣùgbọ́n kí ẹ̀yin bá a lè mọ bí ìfẹ́ tí mo ní sí yín ṣe jinlẹ̀ tó.
5 Wase umong lanzai ukul, na alanza miyari cas b, bara nani inkon kubi na adinin su atiminu gbagbairyari vat b.
Bí ẹnikẹ́ni bá fa ohun ìbànújẹ́ kì í ṣe èmi ni ó bà nínú jẹ́, bí kò ṣe ẹ̀yin fúnra yín, níwọ̀n ìyówù kí ó jẹ́; n kò fẹ́ sọ ọ́ lọ́nà líle jù.
6 Ule uburne le unite na ibureghe mbatina.
Ìyà náà tí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ti fi jẹ́ irú ènìyàn bẹ́ẹ̀ tó fún un.
7 Nene uworu ule uwahale shawan nin nin, umong na ataa i nunkughe kibina, bara ingetek kibinai wa teghe ayiairne gbarda.
Kàkà bẹ́ẹ̀, ẹ̀yin ìbá kúkú dáríjì í, kí ẹ sí tù ú nínú ní gbogbo ọ̀nà, kí ìbànújẹ́ má bà á bo irú ènìyàn bẹ́ẹ̀ mọ́lẹ̀.
8 Nani idin timinu likara kibinai i dursughe usu na anit ba yenju.
Nítorí náà mo bẹ̀ yín, ẹ fi ìdánilójú ìfẹ́ yín hàn sí irú ẹni náà.
9 Ulena unnare wati inyertin minu bara inan dumun minu nin yinu sa idinin kudurtin [biyaya]nanya nimong vat.
Ìdí tí mo ṣe kọ̀wé ni kí èmi ba à lè rí ẹ̀rí dìímú nípa ìgbọ́ràn yín nínú ohun gbogbo.
10 Andi ishawa nin kulapin nanit va, men ma ma shawu mung ma, ilemon na inshawa mun, inshawa mun m, imini shawamu bara anighere nbun Krisri.
Ṣùgbọ́n bí ẹ̀yin bá dáríjì ẹnikẹ́ni, èmi pẹ̀lú dáríjì í. Ohun tí èmi pẹ̀lú bá fi jì, nítorí tiyín ní mo fi jì níwájú Kristi.
11 ilele kiden ghere bara shitan wa su narin tikanc, bara na titani imong ele na idi kibinai ba.
Kí Satani má ba à rẹ́ wa jẹ. Nítorí àwa kò ṣe aláìmọ́ àrékérekè rẹ̀.
12 Bara na Ucife wa punin kibulun kubi kona inwa dak nanya Troas unwaazinlirin Kriste kikane.
Ṣùgbọ́n nígbà ti mo dé Troasi láti wàásù ìyìnrere Kristi, tí mo sì rí i wí pé Olúwa ti ṣí ìlẹ̀kùn fún mi,
13 Nin nani wan, na inse uno kibinai b, bara na iwa yene gwananin Titus kikane ba, intina kpila udu Umakadoniya.
síbẹ̀ èmi kò ní àlàáfíà lọ́kàn mi, nítorí tí èmi kò rí Titu arákùnrin mi níbẹ̀. Nítorí ìdí èyí ni mo ṣe dágbére fún wọn, mo si rékọjá lọ sí Makedonia.
14 Bara nani uzazunu Kutelle ri ulena adi nanya Kristi na adin cinu nin narik udu linbun, nanya bite uliru umang din nudu anit lanza kauley.
Ṣùgbọ́n ọpẹ́ ni fún Ọlọ́run, ẹni tí ń yọ ayọ̀ ìṣẹ́gun lórí wá nígbà gbogbo nínú Kristi, tí a sì ń fi òórùn dídùn ìmọ̀ rẹ̀ hàn nípa wa níbi gbogbo.
15 Bara tidi Kutelle mamas nin Kristi, vat nanya na le na ina tucu nani nin nalena Yesu na tucu nanin ba ima tii anan kul.
Nítorí òórùn dídùn Kristi ni àwa jẹ́ fún Ọlọ́run, nínú àwọn tí a ń gbàlà àti nínú àwọn tí ó ń ṣègbé.
16 Udu nalena idin kuzu ima imon immang ghari unuzu kul udu ukul. Udu nale na inatuc, unuzu inlai udu lai, ghari dinin su nilemong ghe?
Fún àwọn kan, àwa jẹ́ òórùn sí ikú, àti fún àwọn mìíràn òórùn ìyè sí ìyè. Ta ni ó ha si tọ́ fún nǹkan wọ̀nyí?
17 Bara na aari di nafo anit gbardan na idin lesu uliru Kutelle isesu ikurfun ba. Nanya nan, nin lau kibina, na ina tuu unuzu Kutell, nanya mmuro Kutell, ti din nlirun Kristi.
Nítorí àwa kò dàbí àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀, tí ń fi ọ̀rọ̀ Ọlọ́run ṣòwò jẹun; ṣùgbọ́n nínú òtítọ́ inú àwa ń sọ̀rọ̀ níwájú Ọlọ́run nínú Kristi gẹ́gẹ́ bí àwọn tí a rán láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá.

< 2 Ukorintiyawa 2 >