< Ruth 2 >

1 Naomi ní ìbátan kan láti ìdílé Elimeleki ọkọ rẹ̀, aláàánú ọlọ́rọ̀, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Boasi.
و نعومی خویش شوهری داشت که مردی دولتمند، بوعز نام از خاندان الیملک بود.۱
2 Rutu ará Moabu sì wí fún Naomi pé, “Jẹ́ kí èmi kí ó lọ sí inú oko láti ṣá ọkà tí àwọn olùkórè fi sílẹ̀ ní ọ̀dọ̀ ẹnikẹ́ni tí èmi yóò bá ojúrere rẹ̀ pàdé.” Naomi sì sọ fún un pé, “Máa lọ, ọmọbìnrin mi.”
و روت موآبیه به نعومی گفت: «مرا اجازت ده که به کشتزارها بروم و در عقب هر کسی‌که در نظرش التفات یابم خوشه چینی نمایم. او وی را گفت: «برو‌ای دخترم.»۲
3 Rutu sì jáde lọ láti ṣá ọkà tí àwọn olùkórè fi sílẹ̀ lẹ́yìn wọn. Ó wá jẹ́ wí pé inú oko Boasi tí ó ti ìdílé Elimeleki wá ni ó lọ láìmọ̀-ọ́n-mọ̀.
پس روانه شده، به کشتزاردرآمد و در عقب دروندگان خوشه چینی می‌نمود، و اتفاق او به قطعه زمین بوعز که ازخاندان الیملک بود، افتاد.۳
4 Nígbà náà ni Boasi dé láti Bẹtilẹhẹmu tí ó sì kí àwọn olùkórè wí pé, “Kí Olúwa wà pẹ̀lú yín.” Wọ́n sì dá a lóhùn pé, “Kí Olúwa bùkún fún ọ.”
و اینک بوعز ازبیت لحم آمده، به دروندگان گفت: «خداوند باشما باد.» ایشان وی را گفتند: «خداوند تو رابرکت دهد.»۴
5 Boasi sì béèrè lọ́wọ́ olórí àwọn olùkórè wí pé, “Ti ta ni ọ̀dọ́mọbìnrin yẹn?”
و بوعز به نوکر خود که بر دروندگان گماشته بود، گفت: «این دختر از آن کیست؟»۵
6 Ìránṣẹ́ tí ó jẹ́ olórí àwọn olùkórè náà sì fèsì pé, “Ọ̀dọ́mọbìnrin ará Moabu tí ó tẹ̀lé Naomi wá láti ilẹ̀ Moabu ni.
نوکر که بردروندگان گماشته شده بود، در جواب گفت: «این است دختر موآبیه که با نعومی از بلاد موآب برگشته است،۶
7 Ó sọ wí pé, ‘Kí ń jọ̀wọ́ jẹ́ kí òun máa ṣá ọkà lẹ́yìn àwọn olùkórè.’ Ó sì ti ń ṣe iṣẹ́ kárakára láti òwúrọ̀ títí di ìsinsin yìí nínú oko àyàfi ìgbà tí ó lọ láti sinmi fún ìgbà díẹ̀ lábẹ́ ibojì.”
و به من گفت: تمنا اینکه خوشه چینی نمایم و در عقب دروندگان در میان بافه‌ها جمع کنم، پس آمده، از صبح تا به حال مانده است، سوای آنکه اندکی در خانه توقف کرده است.»۷
8 Nígbà náà ni Boasi sọ fún Rutu pé, “Gbọ́ ọmọbìnrin mi, má ṣe lọ sí oko mìíràn láti ṣá ọkà, má sì ṣe kúrò ní ibi. Dúró níbí pẹ̀lú àwọn ìránṣẹ́bìnrin mi.
و بوعز به روت گفت: «ای دخترم مگرنمی شنوی، به هیچ کشت زار دیگر برای خوشه چینی مرو و از اینجا هم مگذر بلکه باکنیزان من در اینجا باش.۸
9 Wo ibi tí wọ́n ti ń kórè kí o sì máa tẹ̀lé àwọn obìnrin. Mo ti pàṣẹ fún àwọn ọkùnrin kí wọ́n má ṣe fi ọwọ́ kàn ọ́. Nígbàkígbà tí òǹgbẹ bá sì ń gbẹ ọ́, lọ kí ó sì mu omi nínú àmù èyí tí àwọn ọkùnrin ti pọn omi sí nínú.”
و چشمانت به زمینی که می‌دروند نگران باشد و در عقب ایشان برو، آیاجوانان را حکم نکردم که تو را لمس نکنند، و اگرتشنه باشی، نزد ظروف ایشان برو و از آنچه جوانان می‌کشند، بنوش.»۹
10 Rutu wólẹ̀, ó sì wí fún Boasi pé, “Èéṣe tí èmi fi bá ojúrere rẹ pàdé tó báyìí, tí o sì kíyèsi mi, èmi àjèjì àti àlejò?”
پس به روی درافتاده، او را تا به زمین تعظیم کرد و به او گفت: «برای چه در نظر تو التفات یافتم که به من توجه نمودی و حال آنکه غریب هستم.»۱۰
11 Boasi sì fèsì wí pé, “Èmi ti gbọ́ gbogbo bí o ti ń ṣe sí ìyá ọkọ ọ̀ rẹ láti ìgbà tí ọkọ rẹ ti kú àti bí o ti ṣe fi baba àti ìyá rẹ àti ilẹ̀ rẹ sílẹ̀, tí o sì wá láti gbé láàrín àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ̀ tẹ́lẹ̀ rí.
بوعز در جواب او گفت: «از هر‌آنچه بعد ازمردن شوهرت به مادر شوهر خود کردی اطلاع تمام به من رسیده است، و چگونه پدر و مادر وزمین ولادت خود را ترک کرده، نزد قومی که پیشتر ندانسته بودی، آمدی.۱۱
12 Kí Olúwa kí ó san ẹ̀san ohun tí ìwọ ṣe fún ọ. Kí o sì gba èrè kíkún láti ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, abẹ́ ìyẹ́ ẹni tí ìwọ sá wá fún ààbò.”
خداوند عمل تورا جزا دهد و از جانب یهوه، خدای اسرائیل، که در زیر بالهایش پناه بردی، اجر کامل به تو برسد.»۱۲
13 Rutu sì fèsì wí pé, “Kí èmi kí ó máa rí ojúrere láti ọ̀dọ̀ rẹ síwájú sí i olúwa mi. Ìwọ ti tù mí nínú nípa sísọ ọ̀rọ̀ rere sí ìránṣẹ́bìnrin rẹ, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi kò tó ọ̀kan nínú àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ.”
گفت: «ای آقایم، در نظر تو التفات بیابم زیرا که مرا تسلی دادی و به کنیز خود سخنان دل آویزگفتی، اگر‌چه من مثل یکی از کنیزان تو نیستم.»۱۳
14 Nígbà tí àkókò oúnjẹ sì tó, Boasi sọ fún Rutu pé, “Wá gba ìwọ̀n àkàrà yìí kí o sì fi run wáìnì kíkan.” Òun sì jókòó pẹ̀lú àwọn olùkórè, Boasi sì fún un ní ọkà yíyan. Òun sì jẹ́, ó yó, ó sì tún ṣẹ́kù.
بوعز وی را گفت: «در وقت چاشت اینجابیا و از نان بخور و لقمه خود را در شیره فرو بر.» پس نزد دروندگان نشست و غله برشته به او دادندو خورد و سیر شده، باقی‌مانده را واگذاشت.۱۴
15 Nígbà tí ó sì dìde láti máa ṣá ọkà, Boasi pàṣẹ fún àwọn òṣìṣẹ́ rẹ̀ wí pé, “Bí ó tilẹ̀ ń ṣà láàrín oko ọkà pàápàá, ẹ má ṣe dí i lọ́wọ́.
وچون برای خوشه چینی برخاست بوعز جوانان خود را امر کرده، گفت: «بگذارید که در میان بافه‌ها هم خوشه چینی نماید و او را زجرمنمایید.۱۵
16 Bí kò ṣe pé kí ẹ mú lára àwọn ìtí sílẹ̀ fún láti ṣá, kí ẹ má sì ṣe ba a wí.”
و نیز از دسته‌ها کشیده، برایش بگذارید تا برچیند و او را عتاب مکنید.»۱۶
17 Rutu sì ń ṣá ọkà títí ó fi di ìrọ̀lẹ́, nígbà tí ó sì pa ọkà barle tí ó rí ṣà, tí ó sì fẹ́ ẹ tán, èyí tí ó rí sì tó ìwọ̀n garawa kan (lita méjìlélógún).
پس تا شام در آن کشتزار خوشه چینی نموده، آنچه را که برچیده بود، کوبید و به قدر یک ایفه جو بود.۱۷
18 Ó sì gbé e, ó sì lọ sí ìlú, ìyá ọkọ rẹ sì rí ọkà tí ó rí ṣà bi o tí pọ̀ tó, Rutu sì mú oúnjẹ tí ó jẹ kù lẹ́yìn tí ó ti yó tan fún ìyá ọkọ rẹ̀.
پس آن را برداشته، به شهردرآمد، و مادر شوهرش آنچه را که برچیده بود، دید، و آنچه بعد از سیرشدنش باقی‌مانده بود، بیرون آورده، به وی داد.۱۸
19 Ìyá ọkọ rẹ̀ sì bi í léèrè wí pé, “Níbo ni ìwọ ti ṣá ọkà lónìí? Àti wí pé oko ta ni ìwọ gbé ṣiṣẹ́? Alábùkún fún ni ọkùnrin náà tí ó bojú wò ọ.” Rutu sì sọ ọ̀dọ̀ ẹni tí ó ti ṣiṣẹ́ fún ìyá ọkọ rẹ̀ pé, “Ní oko ọkùnrin kan tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Boasi ni mo ti ṣiṣẹ́ lónìí.”
و مادر شوهرش وی را گفت: «امروز کجا خوشه چینی نمودی و کجاکار کردی؟ مبارک باد آنکه بر تو توجه نموده است.» پس مادر شوهر خود را از کسی‌که نزد وی کار کرده بود، خبر داده، گفت: «نام آن شخص که امروز نزد او کار کردم، بوعز است.»۱۹
20 Naomi sì wí fún un pé, “Kí Olúwa, kí ó bùkún fún ọkùnrin náà. Ọlọ́run kò dáwọ́ oore àti àánú ṣíṣe sí àwọn alààyè àti òkú dúró.” Naomi sì sọ síwájú sí i wí pé, “Ìbátan tí ó súnmọ́ wa pẹ́kípẹ́kí ni ọkùnrin náà ń ṣe, ó sì jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn tí ó ní ẹ̀tọ́ láti ra ohun ìní ìdílé padà.”
و نعومی به عروس خود گفت: «او از جانب خداوند مبارک باد زیرا که احسان را بر زندگان ومردگان ترک ننموده است.» و نعومی وی را گفت: «این شخص، خویش ما و از ولی های ماست.»۲۰
21 Rutu, ará Moabu sì wí pé, “Ju gbogbo rẹ̀ lọ, ó sọ fún mi pé, ‘Kí ń máa ṣá ọkà pẹ̀lú àwọn òṣìṣẹ́ òun, títí wọn yóò fi parí ìkórè.’”
و روت موآبیه گفت که «او نیز مرا گفت باجوانان من باش تا همه درو مرا تمام کنند.»۲۱
22 Naomi sì sọ fún Rutu, ìyàwó ọmọ rẹ̀ pé, “Ìbá dára bí ó bá le bá àwọn ìránṣẹ́bìnrin rẹ̀ ṣiṣẹ́. Nítorí pé wọ́n le è dà ọ́ láàmú bí o bá lọ sí oko ẹlòmíràn.”
نعومی به عروس خود روت گفت که «ای دخترم خوب است که با کنیزان او بیرون روی وتو را در کشتزار دیگر نیابند.»۲۲
23 Rutu sì bá àwọn ìránṣẹ́bìnrin Boasi ṣiṣẹ́ títí tí wọ́n fi parí ìkórè ọkà barle àti ti jéró. Ó sì ń gbé pẹ̀lú ìyá ọkọ rẹ̀.
پس با کنیزان بوعز برای خوشه چینی می‌ماند تا درو جو و دروگندم تمام شد، و با مادرشوهرش سکونت داشت.۲۳

< Ruth 2 >