< Psalms 99 >

1 Olúwa jẹ ọba; jẹ́ kí ayé kí ó wárìrì Ó jókòó lórí ìtẹ́ kérúbù jẹ́ kí ayé kí ó wárìrì.
PAN króluje, niech drżą narody; siedzi między cherubinami, niech zachwieje się ziemia.
2 Olúwa tóbi ní Sioni; Ó sì ga jù gbogbo orílẹ̀-èdè lọ.
Wielki jest PAN na Syjonie i wywyższony nad wszystkie narody.
3 Kí wọ́n sì yin orúkọ rẹ̀ tí ó tóbi tí ó ni ẹ̀rù, Mímọ́ ni Òun.
Niech wysławiają twoje wielkie i straszne imię, bo jest święte.
4 Ọba náà ní agbára, ó sì fẹ́ òdodo, ìwọ fi ìdí àìṣègbè múlẹ̀; ìwọ ṣe ohun tí ó tọ́ àti ohun tí ó yẹ nínú Jakọbu.
Moc króla miłuje sąd, ty ustanowiłeś słuszność, ty wykonujesz sąd i sprawiedliwość w Jakubie.
5 Gbígbéga ni Olúwa Ọlọ́run wa ẹ foríbalẹ̀ níbi ẹsẹ̀ rẹ̀; ó jẹ́ mímọ́.
Wywyższajcie PANA, naszego Boga, i oddajcie pokłon u podnóżka jego stóp, [bo] on jest święty.
6 Mose àti Aaroni wà nínú àwọn àlùfáà rẹ̀ Samuẹli wà nínú àwọn tí ó ń ké pe orúkọ rẹ̀ wọ́n ké pe Olúwa, ó sì dá wọn lóhùn.
Mojżesz i Aaron wśród jego kapłanów, a Samuel wśród tych, którzy wzywają jego imienia; wołali do PANA, a on ich wysłuchał.
7 Ó sọ̀rọ̀ sí wọn nínú ọ̀wọ́n àwọsánmọ̀, wọ́n pa ẹ̀rí rẹ̀ mọ́ àti ìlànà tí ó fún wọn.
W słupie obłoku mówił do nich, [a] oni strzegli jego świadectw i praw, [które] im dał.
8 Olúwa Ọlọ́run wa, ó dá wọn lóhùn; ó jẹ́ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì àwọn ọmọ Israẹli ìwọ tí ó ń fi ìyà àìṣedéédéé wọn jẹ wọ́n.
PANIE, nasz Boże, ty ich wysłuchiwałeś, byłeś dla nich Bogiem, który przebacza, choć karałeś ich za ich występki.
9 Gbígbéga ni Olúwa Ọlọ́run wa kí a sìn ín ní òkè mímọ́ rẹ̀ nítorí Olúwa Ọlọ́run wa jẹ́ mímọ́.
Wywyższajcie PANA, naszego Boga, i oddajcie pokłon na jego świętej górze, bo PAN, nasz Bóg, [jest] święty.

< Psalms 99 >