< Psalms 92 >

1 Saamu. Orin. Fún Ọjọ́ Ìsinmi. Ohun rere ni láti máa fi ọpẹ́ fún Olúwa àti láti máa kọrin sí orúkọ rẹ̀, Ọ̀gá-ògo,
Salmo: Canción para el día del Sábado. BUENO es alabar á Jehová, y cantar salmos á tu nombre, oh Altísimo;
2 láti kéde ìfẹ́ rẹ̀ ní òwúrọ̀ àti òtítọ́ rẹ̀ ní alẹ́,
Anunciar por la mañana tu misericordia, y tu verdad en las noches,
3 lára ohùn èlò orin olókùn mẹ́wàá àti lára ohun èlò orin haapu.
En el decacordio y en el salterio, en tono suave con el arpa.
4 Nítorí ìwọ ni ó mú inú mi dùn nípa iṣẹ́ rẹ Olúwa; èmi kọrin ayọ̀ sí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ.
Por cuanto me has alegrado, oh Jehová, con tus obras; en las obras de tus manos me gozo.
5 Báwo ni iṣẹ́ rẹ tí tóbi tó, Olúwa? Èrò inú rẹ ìjìnlẹ̀ ni!
¡Cuán grandes son tus obras, oh Jehová! Muy profundos son tus pensamientos.
6 Òpè ènìyàn kò mọ̀ ọ́n, aṣiwèrè kò sì mọ̀ ọ́n,
El hombre necio no sabe, y el insensato no entiende esto:
7 nígbà tí àwọn ènìyàn búburú bá rú jáde bí i koríko àti gbogbo àwọn olùṣe búburú gbèrú, wọn yóò run láéláé.
Que brotan los impíos como la hierba, y florecen todos los que obran iniquidad, para ser destruídos para siempre.
8 Ṣùgbọ́n ìwọ Olúwa ni a ó gbéga títí láé.
Mas tú, Jehová, para siempre eres Altísimo.
9 Nítorí nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ, Olúwa, nítòótọ́ àwọn ọ̀tá rẹ yóò ṣègbé; gbogbo àwọn olùṣe búburú ni a ó fọ́nká.
Porque he aquí tus enemigos, oh Jehová, porque he aquí, perecerán tus enemigos; serán disipados todos los que obran maldad.
10 Ìwọ ti gbé ìwo mi ga bí i ti màlúù igbó; òróró dídára ni a dà sí mi ní orí.
Empero tú ensalzarás mi cuerno como [el de] unicornio: seré ungido con aceite fresco.
11 Ojú mi ti rí ìṣubú àwọn ọ̀tá mi; ìparun sí àwọn ènìyàn búburú tí ó dìde sí mi.
Y mirarán mis ojos sobre mis enemigos: oirán mis oídos de los que se levantaron contra mí, de los malignos.
12 Olódodo yóò gbèrú bí i igi ọ̀pẹ, wọn yóò dàgbà bí i igi kedari Lebanoni,
El justo florecerá como la palma: crecerá como cedro en el Líbano.
13 tí a gbìn sí ilé Olúwa, Wọn yóò rúwé nínú àgbàlá Ọlọ́run wa.
Plantados en la casa de Jehová, en los atrios de nuestro Dios florecerán.
14 Wọn yóò máa so èso ní ìgbà ogbó, wọn yóò dúró ní àkọ̀tun, wọn yóò sì tutù nini,
Aun en la vejez fructificarán; estarán vigorosos y verdes;
15 láti fihàn pé, “Ẹni ìdúró ṣinṣin ni Olúwa; òun ni àpáta mi, kò sì ṣí aburú kankan nínú rẹ̀.”
Para anunciar que Jehová mi fortaleza es recto, y que en él no hay injusticia.

< Psalms 92 >