< Psalms 9 >

1 Fún adarí orin. Ní ti ohun orin. “Ní ti ikú ọmọ.” Saamu ti Dafidi. Èmi ó yìn ọ́, Olúwa, pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi; èmi ó sọ ti ìyanu rẹ gbogbo.
Przewodnikowi chóru, na Halmutlabben. Pieśń Dawida. Będę [cię] wysławiał, PANIE, całym mym sercem; będę opowiadał o wszystkich twoich cudach.
2 Inú mi yóò dùn, èmi yóò sì yọ̀ nínú rẹ; èmi ó kọrin ìyìn sí orúkọ rẹ, Ìwọ Ọ̀gá-Ògo jùlọ.
Będę się cieszył i radował tobą, będę śpiewał twemu imieniu, o Najwyższy!
3 Àwọn ọ̀tá mi pẹ̀yìndà; wọ́n kọsẹ̀ wọn sì ṣègbé níwájú rẹ.
Gdy cofną się moi nieprzyjaciele, upadną i znikną sprzed twego oblicza.
4 Nítorí ìwọ ti di òtítọ́ àti ọ̀ràn mi mú; ìwọ ti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ, láti ṣe ìdájọ́ òdodo.
Ty bowiem przeprowadziłeś mój sąd i moją sprawę, zasiadłeś na tronie jako sędzia sprawiedliwy.
5 Ìwọ ti bá orílẹ̀-èdè wí, Ìwọ sì ti pa ẹni búburú run; Ìwọ ti yọ orúkọ wọn kúrò láé àti láéláé.
Skarciłeś pogan, wytraciłeś niegodziwych, wymazałeś ich imię na wieki wieków.
6 Ìparun àìlópin ti borí àwọn ọ̀tá, ìwọ ti fa àwọn ìlú wọn tu; àní ìrántí wọn sì ti ṣègbé.
O nieprzyjacielu, twoje spustoszenia skończyły się na zawsze, zburzyłeś miasta, ich pamięć przepadła razem z nimi.
7 Olúwa jẹ ọba títí láé; ó ti gbé ìtẹ́ rẹ̀ kalẹ̀ fún ìdájọ́.
Ale PAN trwa na wieki, ustawił swój tron, by sądzić.
8 Òun yóò sì ṣe ìdájọ́ ayé ní òdodo; yóò ṣe àkóso ènìyàn pẹ̀lú òdodo.
On będzie sądził świat sprawiedliwie, osądzi narody według słuszności.
9 Olúwa ni ààbò fún àwọn tí a ni lára, ibi ìsádi ní àkókò ìpọ́njú.
I będzie PAN ucieczką dla uciśnionego, schronieniem w czasie niedoli.
10 Àwọn tí ó mọ orúkọ rẹ yóò gbẹ́kẹ̀lé ọ, nítorí, Olúwa, kò kọ àwọn tó ń wá a sílẹ̀.
I będą ufać tobie ci, którzy znają twoje imię, bo nie opuszczasz, PANIE, tych, którzy cię szukają.
11 Kọ orin ìyìn sí Olúwa, tí o ń jẹ ọba ní Sioni; kéde láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ohun tí ó ṣe.
Śpiewajcie PANU, który mieszka na Syjonie, opowiadajcie wśród narodów o jego dziełach.
12 Nítorí ẹni tí ó ń gbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ rántí; òun kò kọ ẹkún àwọn tí a pọ́n lójú.
Bo on dopomina się krwi i pamięta o nich, a nie zapomina wołania strapionych.
13 Olúwa, wo bí àwọn ọ̀tá ṣe ń ṣe inúnibíni sí mi! Ṣàánú, kí o sì gbé mí sókè kúrò ní ẹnu-ọ̀nà ikú,
Zmiłuj się nade mną, PANIE, spójrz, jak mnie uciskają ci, którzy mnie nienawidzą, ty, który podnosisz mnie z bram śmierci;
14 kí èmi kí ó lè sọ ti ìyìn rẹ ni ẹnu-ọ̀nà àwọn ọmọbìnrin Sioni àti láti máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ.
Abym głosił wszelką twą chwałę w bramach córki Syjonu; będę się radował twoim zbawieniem.
15 Àwọn orílẹ̀-èdè ti jì sí kòtò tí wọn ti gbẹ́; ẹsẹ̀ wọn ni àwọ̀n tí wọ́n dẹ sílẹ̀ kọ́.
Poganie wpadli w dół, [który] wykopali; w sidłach, które zastawili, uwięzła ich noga.
16 A mọ Olúwa nípa òdodo rẹ̀; àwọn ènìyàn búburú ni a dẹ́kun mú nípa iṣẹ́ ọwọ́ wọn.
PAN dał się poznać, gdy odbył sąd, w dzieła swoich rąk uwikłał się niegodziwy. (Higgajon, Sela)
17 Àwọn ènìyàn búburú ni a ó dà sí isà òkú, àti gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó gbàgbé Ọlọ́run. (Sheol h7585)
Niegodziwi zstąpią do piekła, wszystkie narody, które zapominają Boga. (Sheol h7585)
18 Ṣùgbọ́n àwọn aláìní ni a kò ní gbàgbé láéláé, ìrètí àwọn ti ó tálákà ni a kì yóò gbàgbé láéláé.
Bo biedak nie będzie zapomniany na zawsze, nadzieja ubogich nie zginie na wieki.
19 Dìde, Olúwa, má ṣe jẹ́ kí ènìyàn borí; jẹ́ kí a ṣe ìdájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ni iwájú rẹ.
Powstań, PANIE, niech nie triumfuje człowiek, niech narody zostaną osądzone przed twoim obliczem.
20 Lù wọ́n pẹ̀lú ìpayà, Olúwa; jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè mọ̀ pé ènìyàn lásán ni wọ́n. (Sela)
PANIE, ześlij na nie strach, aby narody poznały, że są tylko ludźmi. (Sela)

< Psalms 9 >