< Psalms 44 >

1 Fún adarí orin. Ti àwọn ọmọ Kora. Maskili. À ti fi etí wa gbọ́, Ọlọ́run; àwọn baba wa tí sọ fún wa ohun tí ìwọ ṣe ní ọjọ́ wọn, ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn.
Přednímu zpěváku z synů Chóre, vyučující. Bože, ušima svýma slýchali jsme, a otcové naši vypravovali nám o skutcích, kteréž jsi činíval za dnů jejich, za dnů starodávních.
2 Ìwọ fi ọwọ́ rẹ lé orílẹ̀-èdè jáde, Ìwọ sì gbin àwọn baba wa; ìwọ run àwọn ènìyàn náà Ìwọ sì mú àwọn baba wa gbilẹ̀.
Tys sám rukou svou vyhnal pohany, a vštípil jsi je; potřel jsi lidi, a je jsi rozplodil.
3 Kì í ṣe nípa idà wọn ni wọ́n gba ilẹ̀ náà, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe apá wọn ní ó gbà wọ́n bí kò ṣe; ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ àti, apá rẹ; àti ìmọ́lẹ̀ ojú rẹ̀, nítorí ìwọ fẹ́ wọn.
Neboť jsou neopanovali země mečem svým, aniž jim rámě jejich spomohlo, ale pravice tvá a rámě tvé, a světlost oblíčeje tvého, proto že jsi je zamiloval.
4 Ìwọ ni ọba àti Ọlọ́run mi, ẹni tí ó pàṣẹ ìṣẹ́gun fún Jakọbu.
Ty jsi sám král můj, ó Bože, udílejž hojného spasení Jákobova.
5 Nípasẹ̀ rẹ ni àwa ó bi àwọn ọ̀tá wa ṣubú; nípasẹ̀ orúkọ rẹ ni àwa ó tẹ àwọn ọ̀tá tí ó dìde sí wa mọ́lẹ̀,
V toběť jsme protivníky naše potírali, a ve jménu tvém pošlapávali jsme povstávající proti nám.
6 èmi kì yóò gbẹ́kẹ̀lé ọrun mi, idà mi kì yóò mú ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wá,
Neboť jsem v lučišti svém naděje neskládal, aniž mne kdy obránil meč můj.
7 ṣùgbọ́n ìwọ fún wa ní ìṣẹ́gun lórí àwọn ọ̀tá wa, ìwọ sì ti dójúti àwọn tí ó kórìíra wa.
Ale ty jsi nás vysvobozoval od nepřátel našich, a kteříž nás nenávidí, ty jsi zahanboval.
8 Nínú Ọlọ́run àwa ń ṣògo ní gbogbo ọjọ́, àwa ó sì yin orúkọ rẹ títí láé. (Sela)
A protož chválíme tě Boha na každý den, a jméno tvé ustavičně oslavujeme. (Sélah)
9 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí, ìwọ ti kọ̀ wá, ìwọ sì ti dójútì wá, Ìwọ kò sì bá àwọn ọmọ-ogun wa jáde mọ́.
Ale nyní jsi nás zahnal i zahanbil, a nevycházíš s vojsky našimi.
10 Ìwọ ti bá wa jà, ìwọ sì ti ṣẹ́gun wa níwájú àwọn ọ̀tá wa, àwọn ọ̀tá wa ti gba ilẹ̀ wa, wọ́n sì fi ipá gba oko wa.
Obrátil jsi nás nazpět, a ti, kteříž nás nenávidí, rozchvátali mezi sebou jmění naše.
11 Ìwọ fi wá fún jíjẹ bí ẹran àgùntàn, Ìwọ sì ti tú wa ká sí àárín àwọn kèfèrí.
Oddal jsi nás, jako ovce k snědení, i mezi pohany rozptýlil jsi nás.
12 Ìwọ ta àwọn ènìyàn rẹ fún owó kékeré, Ìwọ kò sì jẹ èrè kankan lórí iye tí ìwọ tà wọ́n.
Prodal jsi lid svůj bez peněz, a nenadsadils mzdy jejich.
13 Ìwọ sọ wá di ẹni ẹ̀sín ní ọ̀dọ̀ àwọn aládùúgbò wa, ẹlẹ́yà àti ẹni àbùkù sí àwọn tí ó yí wa ká.
Vydal jsi nás k utrhání sousedům našim, ku posměchu a ku potupě těm, kteříž jsou vůkol nás.
14 Ìwọ ti sọ wá di ẹni ìfisọ̀rọ̀ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè; àwọn ènìyàn ń mi orí wọn sí wa.
Uvedl jsi nás v přísloví mezi národy, a mezi lidmi, aby nad námi hlavou zmítáno bylo.
15 Ìdójútì mi ń bẹ pẹ̀lú mi ní gbogbo ọjọ́, ìtìjú sì bojú mi mọ́lẹ̀,
Na každý den styděti se musím, a hanba tváři mé přikrývá mne,
16 nítorí ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn àti ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn ní ojú àwọn ọ̀tá àti olùgbẹ̀san.
A to z příčiny řeči utrhajícího a hanějícího, z příčiny nepřítele a vymstívajícího se.
17 Gbogbo àwọn nǹkan wọ̀nyí ń ṣẹlẹ̀ sí wa, síbẹ̀ àwa kò gbàgbé rẹ bẹ́ẹ̀ ni a kò ṣèké sí májẹ̀mú rẹ̀.
Všecko to přišlo na nás, a však jsme se nezapomenuli na tě, aniž jsme zrušili smlouvy tvé.
18 Ọkàn wa kò padà sẹ́yìn; bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wa kò yẹ̀ kúrò ní ọ̀nà rẹ̀.
Neobrátilo se nazpět srdce naše, aniž se uchýlil krok náš od stezky tvé,
19 Ṣùgbọ́n wọ́n kọlù wá, ìwọ sì sọ wá di ẹran ọdẹ fún àwọn ẹranko búburú, tí wọn sì fi òkùnkùn biribiri bò wá mọ́lẹ̀.
Ačkoli jsi nás byl potřel na místě draků, a přikryl jsi nás stínem smrti.
20 Bí àwa bá ti gbàgbé orúkọ Ọlọ́run wa tàbí tí a na ọwọ́ wa sí ọlọ́run àjèjì.
Kdybychom se byli zapomenuli na jméno Boha svého, a pozdvihli rukou svých k bohu cizímu,
21 Ǹjẹ́ Ọlọ́run kì yóò rí ìdí rẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó mọ ohun ìkọ̀kọ̀ inú ọkàn?
Zdaliž by toho Bůh byl nevyhledával? Nebo on zná skrytosti srdce.
22 Síbẹ̀, nítorí rẹ̀ àwa da àyà kọ ikú, ní ojoojúmọ́ a ń kà wá sí bí àgùntàn fún pípa.
Anobrž pro tebe mordováni býváme každého dne, jmíni jsme jako ovce k zabití oddané.
23 Jí, Olúwa! Èéṣe tí ìwọ ń sùn? Dìde fúnra rẹ̀! Má ṣe kọ̀ wá sílẹ̀ láéláé.
Procitiž, proč spíš, ó Pane? Probudiž se, a nezaháněj nás na věky.
24 Èéṣe tí ìwọ ń pa ojú rẹ mọ́ tí ìwọ sì gbàgbé ìpọ́njú àti ìnira wa?
I pročež tvář svou skrýváš, a zapomínáš se na trápení a ssoužení naše?
25 Nítorí a tẹrí ọkàn wa ba sínú eruku; ara wa sì dì mọ́ erùpẹ̀ ilẹ̀.
Nebotě se již sklonila až k prachu duše naše, přilnul k zemi život náš.
26 Dìde kí o sì ràn wá lọ́wọ́; rà wá padà nítorí ìfẹ́ rẹ tí ó dúró ṣinṣin.
Povstaniž k našemu spomožení, a vykup nás pro své milosrdenství.

< Psalms 44 >