< Psalms 42 >

1 Fún adarí orin. Maskili ti àwọn ọmọ Kora. Bí àgbọ̀nrín ti ń mí hẹlẹ sí ipa odò omi, bẹ́ẹ̀ ni ọkàn mi ń mí hẹlẹ sí ọ Ọlọ́run.
Przewodnikowi chóru. Psalm pouczający dla synów Korego. Jak jeleń pragnie wód strumieni, tak moja dusza pragnie ciebie, Boże.
2 Òùngbẹ Ọlọ́run ń gbẹ ọkàn mi, fún Ọlọ́run alààyè. Nígbà wo ni èmi ó lọ bá Ọlọ́run?
Moja dusza jest spragniona Boga, Boga żywego. Kiedy przyjdę i ukażę się przed obliczem Boga?
3 Oúnjẹ mi ni omijé mi ní ọ̀sán àti ní òru, nígbà tí àwọn ènìyàn ń wí fún mi ní gbogbo ọjọ́ pé, “Ọlọ́run rẹ dà?”
Łzy stały się dla mnie chlebem we dnie i w nocy, gdy mówią do mnie co dzień: Gdzie jest twój Bóg?
4 Nígbà tí mo bá rántí nǹkan yìí, èmi tú ọkàn mi jáde nínú mi: èmi ti bá ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn lọ, èmi bá wọn lọ sí ilé Ọlọ́run pẹ̀lú ohùn ayọ̀ àti ìyìn, pẹ̀lú ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń pa ọjọ́ mímọ́ mọ́.
Wylewam swą duszę, gdy wspominam, jak krocząc w tłumie, szedłem z nimi do domu Bożego wśród głosów radości i chwały, pośród świętującego tłumu.
5 Èéṣe tí o fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi? Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi? Ìwọ ṣe ìrètí ní ti Ọlọ́run, nítorí èmi yóò sá à máa yìn ín, Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.
Dlaczego się smucisz, moja duszo, i czemu się we mnie trwożysz? Zaufaj Bogu, bo jeszcze będę go wysławiał [za] jego zbawcze oblicze.
6 Ọlọ́run mi, ọkàn mi ń rẹ̀wẹ̀sì nínú mi: nítorí náà, èmi ó rántí rẹ láti ilẹ̀ Jordani wá, láti Hermoni láti òkè Mibsari.
Mój Boże, smuci się we mnie moja dusza, dlatego wspominam cię z ziemi Jordanu i Hermonu, z góry Misar.
7 Ibú omi ń pe ibú omi nípa híhó omi ṣíṣàn rẹ̀ gbogbo rírú omi àti bíbì omi rẹ̀ bò mí mọ́lẹ̀.
Przepaść przyzywa przepaść szumem twoich upustów; wszystkie twoje fale i nawałnice przewalają się nade mną.
8 Ní ọ̀sán ní Olúwa ran ìfẹ́ rẹ̀, àti ni àṣálẹ́ ni orin rẹ̀ wà pẹ̀lú mi àdúrà sí Ọlọ́run ayé mi.
Lecz we dnie PAN udzieli mi swego miłosierdzia, a w nocy [będzie] we mnie jego pieśń [i] moja modlitwa do Boga mego życia.
9 Èmi wí fún Ọlọ́run àpáta mi, “Èéṣe tí ìwọ fi gbàgbé mi? Èéṣe tí èmi o fi máa rìn nínú ìbànújẹ́, nítorí ìnilára ọ̀tá?”
Powiem Bogu, mojej skale: Czemu o mnie zapomniałeś? Czemu chodzę smutny z powodu ucisku wroga?
10 Bí ẹni pé idà egungun mi ni ẹ̀gàn tí àwọn ọ̀tá mi ń gàn mí, bí wọn ti ń béèrè ní gbogbo ọjọ́. “Níbo ni Ọlọ́run rẹ wà?”
Jak rana w moich kościach, tak mnie urągają moi wrogowie, gdy mówią do mnie każdego dnia: Gdzie jest twój Bóg?
11 Èéṣe tí ìwọ fi ń rẹ̀wẹ̀sì, ìwọ ọkàn mi? Èéṣe tí ara rẹ kò fi lélẹ̀ nínú mi? Fi ìrètí rẹ sínú Ọlọ́run, nítorí èmi yóò sì máa yìn ín, Òun ni Olùgbàlà mi àti Ọlọ́run mi.
Czemu się smucisz, moja duszo, i czemu się we mnie trwożysz? Zaufaj Bogu, bo jeszcze będę go wysławiał, [gdyż on jest] zbawieniem mego oblicza i moim Bogiem.

< Psalms 42 >