< Psalms 119 >

1 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀, ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.
Beati quelli che sono integri nelle loro vie, che camminano secondo la legge dell’Eterno.
2 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
Beati quelli che osservano le sue testimonianze, che lo cercano con tutto il cuore,
3 Wọn kò ṣe ohun tí kò dára; wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
ed anche non operano iniquità, ma camminano nelle sue vie.
4 Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀ kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
Tu hai ordinato i tuoi precetti perché siano osservati con cura.
5 Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
Oh siano le mie vie dirette all’osservanza dei tuoi statuti!
6 Nígbà náà, ojú kò ní tì mí nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
Allora non sarò svergognato quando considererò tutti i tuoi comandamenti.
7 Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
Io ti celebrerò con dirittura di cuore, quando avrò imparato i tuoi giusti decreti.
8 Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
Io osserverò i tuoi statuti, non abbandonarmi del tutto.
9 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Come renderà il giovane la sua via pura? Col badare ad essa secondo la tua parola.
10 Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Io ti ho cercato con tutto il mio cuore; non lasciarmi deviare dai tuoi comandamenti.
11 Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
Io ho riposto la tua parola nel mio cuore per non peccare contro di te.
12 Ìyìn ni fún Olúwa; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Tu sei benedetto, o Eterno; insegnami i tuoi statuti.
13 Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
Ho raccontato con le mie labbra tutti i giudizi della tua bocca.
14 Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ, bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
Io gioisco nella via delle tue testimonianze, come se possedessi tutte le ricchezze.
15 Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
Io mediterò sui tuoi precetti e considerò i tuoi sentieri.
16 Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ; èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
Io mi diletterò nei tuoi statuti, non dimenticherò la tua parola.
17 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè; èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Fa’ del bene al tuo servitore perché io viva ed osservi la tua parola.
18 La ojú mi kí èmi lè ríran rí ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
Apri gli occhi miei ond’io contempli le maraviglie della tua legge.
19 Àlejò ní èmi jẹ́ láyé, má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
Io sono un forestiero sulla terra; non mi nascondere i tuoi comandamenti.
20 Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
L’anima mia si strugge dalla brama che ha dei tuoi giudizi in ogni tempo.
21 Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Tu sgridi i superbi, i maledetti, che deviano dai tuoi comandamenti.
22 Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi, nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
Togli di sopra a me il vituperio e lo sprezzo, perché io ho osservato le tue testimonianze.
23 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
Anche quando i principi siedono e parlano contro di me, il tuo servitore medita i tuoi statuti.
24 Òfin rẹ ni dídùn inú mi; àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
Sì, le tue testimonianze sono il mio diletto e i miei consiglieri.
25 Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀; ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
L’anima mia è attaccata alla polvere; vivificami secondo la tua parola.
26 Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Io ti ho narrato le mie vie, e tu m’hai risposto; insegnami i tuoi statuti.
27 Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ: nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Fammi intendere la via dei tuoi precetti, ed io mediterò le tue maraviglie.
28 Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́; fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
L’anima mia, dal dolore, si strugge in lacrime; rialzami secondo la tua parola.
29 Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
Tieni lontana da me la via della menzogna, e, nella tua grazia, fammi intender la tua legge.
30 Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́ èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
Io ho scelto la via della fedeltà, mi son posto i tuoi giudizi dinanzi agli occhi.
31 Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
Io mi tengo attaccato alle tue testimonianze; o Eterno, non lasciare che io sia confuso.
32 Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ, nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
Io correrò per la via dei tuoi comandamenti, quando m’avrai allargato il cuore.
33 Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ; nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
Insegnami, o Eterno, la via dei tuoi statuti ed io la seguirò fino alla fine.
34 Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́ èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
Dammi intelletto e osserverò la tua legge; la praticherò con tutto il cuore.
35 Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí, nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
Conducimi per il sentiero dei tuoi comandamenti, poiché io mi diletto in esso.
36 Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
Inclina il mio cuore alle tue testimonianze e non alla cupidigia.
37 Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán: pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Distogli gli occhi miei dal contemplare la vanità, e vivificami nelle tue vie.
38 Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí òfin rẹ dára.
Mantieni al tuo servitore la tua parola, che inculca il tuo timore.
39 Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
Rimuovi da me il vituperio ch’io temo, perché i tuoi giudizi son buoni.
40 Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ! Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
Ecco, io bramo i tuoi precetti, vivificami nella tua giustizia.
41 Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa, ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Vengano su me le tue benignità, o Eterno, e la tua salvezza, secondo la tua parola.
42 Nígbà náà ni èmi yóò dá ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn, nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
E avrò di che rispondere a chi mi fa vituperio, perché confido nella tua parola.
43 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
Non mi toglier del tutto dalla bocca la parola della verità, perché spero nei tuoi giudizi.
44 Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo láé àti láéláé.
Ed io osserverò la tua legge del continuo, in sempiterno.
45 Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira, nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
E camminerò con libertà, perché ho cercato i tuoi precetti.
46 Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba ojú kì yóò sì tì mí,
Parlerò delle tue testimonianze davanti ai re e non sarò svergognato.
47 nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
E mi diletterò nei tuoi comandamenti, i quali io amo.
48 Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn, èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
Alzerò le mie mani verso i tuoi comandamenti che amo, e mediterò i tuoi statuti.
49 Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
Ricordati della parola detta al tuo servitore; su di essa m’hai fatto sperare.
50 Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí: ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
Questo è il mio conforto nella mia afflizione; che la tua parola mi vivifica.
51 Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró, ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
I superbi mi cuopron di scherno, ma io non devìo dalla tua legge.
52 Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa, èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
Io mi ricordo de’ tuoi giudizi antichi, o Eterno, e mi consolo.
53 Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú, tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
Un’ira ardente mi prende a motivo degli empi, che abbandonano la tua legge.
54 Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi níbikíbi tí èmi ń gbé.
I tuoi statuti sono i miei cantici, nella casa del mio pellegrinaggio.
55 Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
Io mi ricordo la notte del tuo nome, o Eterno, e osservo la tua legge.
56 nítorí tí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
Questo bene mi è toccato, di osservare i tuoi precetti.
57 Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa: èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
L’Eterno è la mia parte; ho promesso d’osservare le tue parole.
58 Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Io ho cercato il tuo favore con tutto il cuore: abbi pietà di me, secondo la tua parola.
59 Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
Io ho riflettuto alle mie vie e ho rivolto i miei passi verso le tue testimonianze.
60 Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
Mi sono affrettato, e non ho indugiato ad osservare i tuoi comandamenti.
61 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
I lacci degli empi m’hanno avviluppato, ma io non ho dimenticato la tua legge.
62 Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ nítorí òfin òdodo rẹ.
A mezzanotte io mi levo per celebrarti a motivo dei tuoi giusti giudizi.
63 Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
Io sono il compagno di tutti quelli che ti temono e di quelli che osservano i tuoi precetti.
64 Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa, kọ́ mi ní òfin rẹ.
O Eterno, la terra è piena della tua benignità; insegnami i tuoi statuti.
65 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
Tu hai fatto del bene al tuo servitore, o Eterno, secondo la tua parola.
66 Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere, nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
Dammi buon senno e intelligenza, perché ho creduto nei tuoi comandamenti.
67 Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà, ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Prima che io fossi afflitto, andavo errando; ma ora osservo la tua parola.
68 Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Tu sei buono e fai del bene; insegnami i tuoi statuti.
69 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí, èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
I superbi hanno ordito menzogne contro a me, ma io osservo i tuoi precetti con tutto il cuore.
70 Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú, ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
Il loro cuore è denso come grasso, ma io mi diletto nella tua legge.
71 Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
E’ stato un bene per me l’essere afflitto, ond’io imparassi i tuoi statuti.
72 Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
La legge della tua bocca mi val meglio di migliaia di monete d’oro e d’argento.
73 Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí; fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
Le tue mani m’hanno fatto e formato; dammi intelletto e imparerò i tuoi comandamenti.
74 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Quelli che ti temono mi vedranno e si rallegreranno, perché ho sperato nella tua parola.
75 Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni, àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
Io so, o Eterno, che i tuoi giudizi son giusti, e che nella tua fedeltà m’hai afflitto.
76 Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi, gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
Deh, sia la tua benignità il mio conforto, secondo la tua parola detta al tuo servitore.
77 Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè, nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
Vengan su me le tue compassioni, ond’io viva; perché la tua legge è il mio diletto.
78 Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga nítorí wọn pa mí lára láìnídìí ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Sian contusi i superbi, perché, mentendo, pervertono la mia causa; ma io medito i tuoi precetti.
79 Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi, àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
Rivolgansi a me quelli che ti temono e quelli che conoscono le tue testimonianze.
80 Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ, kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
Sia il mio cuore integro nei tuoi statuti ond’io non sia confuso.
81 Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ, ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
L’anima mia vien meno bramando la tua salvezza; io spero nella tua parola.
82 Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ; èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
Gli occhi miei vengon meno bramando la tua parola, mentre dico: Quando mi consolerai?
83 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín, èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
Poiché io son divenuto come un otre al fumo; ma non dimentico i tuoi statuti.
84 Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
Quanti sono i giorni del tuo servitore? Quando farai giustizia di quelli che mi perseguitano?
85 Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi, tí ó lòdì sí òfin rẹ.
I superbi mi hanno scavato delle fosse; essi, che non agiscono secondo la tua legge.
86 Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé; ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
Tutti i tuoi comandamenti sono fedeltà; costoro mi perseguitano a torto; soccorrimi!
87 Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé, ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
Mi hanno fatto quasi sparire dalla terra; ma io non ho abbandonato i tuoi precetti.
88 Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ, èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
Vivificami secondo la tua benignità, ed io osserverò la testimonianza della tua bocca.
89 Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni; ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
In perpetuo, o Eterno, la tua parola è stabile nei cieli.
90 Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran; ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
La tua fedeltà dura d’età in età; tu hai fondato la terra ed essa sussiste.
91 Òfin rẹ dúró di òní nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
Tutto sussiste anche oggi secondo i tuoi ordini, perché ogni cosa è al tuo servigio.
92 Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi, èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
Se la tua legge non fosse stata il mio diletto, sarei già perito nella mia afflizione.
93 Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé, nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
Io non dimenticherò mai i tuoi precetti, perché per essi tu mi hai vivificato.
94 Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
Io son tuo, salvami, perché ho cercato i tuoi precetti.
95 Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run, ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
Gli empi m’hanno aspettato per farmi perire, ma io considero le tue testimonianze.
96 Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin; ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
Io ho veduto che ogni cosa perfetta ha un limite, ma il tuo comandamento ha una estensione infinita.
97 Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó! Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
Oh, quanto amo la tua legge! è la mia meditazione di tutto il giorno.
98 Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
I tuoi comandamenti mi rendon più savio dei miei nemici; perché sono sempre meco.
99 Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ, nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
Io ho più intelletto di tutti i miei maestri, perché le tue testimonianze son la mia meditazione.
100 Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ, nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
Io ho più intelligenza de’ vecchi, perché ho osservato i tuoi precetti.
101 Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
Io ho trattenuto i miei piedi da ogni sentiero malvagio, per osservare la tua parola.
102 Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
Io non mi sono distolto dai tuoi giudizi, perché tu m’hai ammaestrato.
103 Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó, ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
Oh come son dolci le tue parole al mio palato! Son più dolci del miele alla mia bocca.
104 Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ; nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
Mediante i tuoi precetti io divento intelligente; perciò odio ogni sentiero di falsità.
105 Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
La tua parola è una lampada al mio piè ed una luce sul mio sentiero.
106 Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
Io ho giurato, e lo manterrò, d’osservare i tuoi giusti giudizi.
107 A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
Io sono sommamente afflitto; o Eterno, vivificami secondo la tua parola.
108 Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi, kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
Deh, o Eterno, gradisci le offerte volontarie della mia bocca, e insegnami i tuoi giudizi.
109 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
La vita mia è del continuo in pericolo ma io non dimentico la tua legge.
110 Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Gli empi mi hanno teso dei lacci, ma io non mi sono sviato dai tuoi precetti.
111 Òfin rẹ ni ogún mi láéláé; àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
Le tue testimonianze son la mia eredità in perpetuo, perché son la letizia del mio cuore.
112 Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́ láé dé òpin.
Io ho inclinato il mio cuore a praticare i tuoi statuti, in perpetuo, sino alla fine.
113 Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
Io odio gli uomini dal cuor doppio, ma amo la tua legge.
114 Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Tu sei il mio rifugio ed il mio scudo; io spero nella tua parola.
115 Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú, kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
Dipartitevi da me, o malvagi, ed io osserverò i comandamenti del mio Dio.
116 Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, kí èmi kí ó lè yè Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
Sostienmi secondo la tua parola, ond’io viva, e non rendermi confuso nella mia speranza.
117 Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu; nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
Sii il mio sostegno, e sarò salvo, e terrò del continuo i tuoi statuti dinanzi agli occhi.
118 Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
Tu disprezzi tutti quelli che deviano dai tuoi statuti, perché la loro frode è falsità.
119 Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́; nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
Tu togli via come schiuma tutti gli empi dalla terra; perciò amo le tue testimonianze.
120 Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀: èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
La mia carne rabbrividisce per lo spavento di te, e io temo i tuoi giudizi.
121 Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́: má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
Io ho fatto ciò che è diritto e giusto; non abbandonarmi ai miei oppressori.
122 Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú: má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
Da’ sicurtà per il bene del tuo servitore, e non lasciare che i superbi m’opprimano.
123 Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ, fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
Gli occhi miei vengon meno, bramando la tua salvezza e la parola della tua giustizia.
124 Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Opera verso il tuo servitore secondo la tua benignità, e insegnami i tuoi statuti.
125 Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye kí èmi lè ní òye òfin rẹ
Io sono tuo servitore; dammi intelletto, perché possa conoscere le tue testimonianze.
126 Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa; nítorí òfin rẹ ti fọ́.
E’ tempo che l’Eterno operi; essi hanno annullato la tua legge.
127 Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
Perciò io amo i tuoi comandamenti più dell’oro, più dell’oro finissimo.
128 nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀, èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
Perciò ritengo diritti tutti i tuoi precetti, e odio ogni sentiero di menzogna.
129 Òfin rẹ̀ ìyanu ni: nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
Le tue testimonianze sono maravigliose; perciò l’anima mia le osserva.
130 Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá; ó fi òye fún àwọn òpè.
La dichiarazione delle tue parole illumina; dà intelletto ai semplici.
131 Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ, nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
Io ho aperto la bocca e ho sospirato perché ho bramato i tuoi comandamenti.
132 Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi, bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
Volgiti a me ed abbi pietà di me, com’è giusto che tu faccia a chi ama il tuo nome.
133 Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ, má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
Rafferma i miei passi nella tua parola, e non lasciare che alcuna iniquità mi domini.
134 Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn, kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
Liberami dall’oppressione degli uomini, ed io osserverò i tuoi precetti.
135 Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Fa’ risplendere il tuo volto sul tuo servitore, e insegnami i tuoi statuti.
136 Omijé sàn jáde ní ojú mi, nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
Rivi di lacrime mi scendon giù dagli occhi, perché la tua legge non è osservata.
137 Olódodo ni ìwọ Olúwa ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
Tu sei giusto, o Eterno, e diritti sono i tuoi giudizi.
138 Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo: wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
Tu hai prescritto le tue testimonianze con giustizia e con grande fedeltà.
139 Ìtara mi ti pa mí run, nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
Il mio zelo mi consuma perché i miei nemici han dimenticato le tue parole.
140 Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
La tua parola è pura d’ogni scoria; perciò il tuo servitore l’ama.
141 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
Io son piccolo e sprezzato, ma non dimentico i tuoi precetti.
142 Òdodo rẹ wà títí láé òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
La tua giustizia è una giustizia eterna, e la tua legge è verità.
143 Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi, ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
Distretta e tribolazione m’hanno còlto, ma i tuoi comandamenti sono il mio diletto.
144 Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé; fún mi ní òye kí èmi lè yè.
Le tue testimonianze sono giuste in eterno; dammi intelletto ed io vivrò.
145 Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: dá mi lóhùn Olúwa, èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
Io grido con tutto il cuore; rispondimi, o Eterno! Io osserverò i tuoi statuti.
146 Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
Io t’invoco; salvami, e osserverò le tue testimonianze.
147 Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Io prevengo l’alba e grido; io spero nella tua parola.
148 Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru, nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Gli occhi miei prevengono lo vigilie della notte, per meditare la tua parola.
149 Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ: pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Ascolta la mia voce secondo la tua benignità; o Eterno, vivificami secondo la tua giustizia.
150 Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí, ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
Si accostano a me quelli che van dietro alla scelleratezza; essi son lontani dalla tua legge.
151 Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa, àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
Tu sei vicino, o Eterno, e tutti i tuoi comandamenti son verità.
152 Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
Da lungo tempo so dalle tue testimonianze che tu le hai stabilite in eterno.
153 Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí, nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
Considera la mia afflizione, e liberami; perché non ho dimenticato la tua legge.
154 Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Difendi tu la mia causa e riscattami; vivificami secondo la tua parola.
155 Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
La salvezza è lungi dagli empi, perché non cercano i tuoi statuti.
156 Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Le tue compassioni son grandi, o Eterno; vivificami secondo i tuoi giudizi.
157 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi, ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
I miei persecutori e i miei avversari son molti, ma io non devìo dalle tue testimonianze.
158 Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́ nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
Io ho veduto gli sleali e ne ho provato orrore; perché non osservano la tua parola.
159 Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ; pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
Vedi come amo i tuoi precetti! O Eterno, vivificami secondo la tua benignità.
160 Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ; gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
La somma della tua parola è verità; e tutti i giudizi della tua giustizia durano in eterno.
161 Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí, ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
I principi m’hanno perseguitato senza ragione, ma il mio cuore ha timore delle tue parole.
162 Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
Io mi rallegro della tua parola, come uno che trova grandi spoglie.
163 Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
Io odio e abomino la menzogna, ma amo la tua legge.
164 Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.
Io ti lodo sette volte al giorno per i giudizi della tua giustizia.
165 Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ, kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
Gran pace hanno quelli che amano la tua legge, e non c’è nulla che possa farli cadere.
166 Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa, èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
Io ho sperato nella tua salvezza, o Eterno, e ho messo in pratica i tuoi comandamenti.
167 Èmi gba òfin rẹ gbọ́, nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
L’anima mia ha osservato le tue testimonianze, ed io le amo grandemente.
168 Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ, nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
Io ho osservato i tuoi precetti e le tue testimonianze, perché tutte le mie vie ti stanno dinanzi.
169 Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa; fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Giunga il mio grido dinanzi a te, o Eterno; dammi intelletto secondo la tua parola.
170 Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Giunga la mia supplicazione in tua presenza; liberami secondo la tua parola.
171 Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde, nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Le mie labbra esprimeranno la tua lode, perché tu m’insegni i tuoi statuti.
172 Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ, nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
La mia lingua celebrerà la tua parola, perché tutti i tuoi comandamenti sono giustizia.
173 Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
La tua mano mi aiuti, perché ho scelto i tuoi precetti.
174 Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa, àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
Io bramo la tua salvezza, o Eterno, e la tua legge è il mio diletto.
175 Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́, kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
L’anima mia viva, ed essa ti loderà; e mi soccorrano i tuoi giudizi.
176 Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù. Wá ìránṣẹ́ rẹ, nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.
Io vo errando come pecora smarrita; cerca il tuo servitore, perché io non dimentico i tuoi comandamenti.

< Psalms 119 >