< Psalms 119 >

1 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀, ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.
Heureux ceux dont la voie est innocente, qui marchent selon la loi de l'Éternel!
2 Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
Heureux ceux qui observent ses ordonnances, le cherchent de tout leur cœur,
3 Wọn kò ṣe ohun tí kò dára; wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
ne commettent point le mal, et marchent dans ses voies!
4 Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀ kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
Tu as prescrit tes commandements, pour qu'on les garde avec soin!
5 Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
O! si mes voies étaient dirigées vers l'observation de tes commandements!
6 Nígbà náà, ojú kò ní tì mí nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
Alors je ne serais pas confus, en considérant tous tes préceptes.
7 Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
Je te louerai d'un cœur sincère, en apprenant tes justes lois.
8 Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
Je veux garder tes commandements: ne me laisse pas trop dans l'abandonnement! Beth.
9 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Comment un jeune homme rendra-t-il sa voie pure? C'est en la surveillant d'après ta parole.
10 Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Je te cherche de tout mon cœur: fais que je ne m'écarte pas de tes commandements!
11 Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
Je serre ta parole dans mon cœur, afin de ne point pécher contre toi.
12 Ìyìn ni fún Olúwa; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Sois béni, ô Éternel! enseigne-moi tes décrets!
13 Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
De mes lèvres j'énumère toutes les lois sorties de ta bouche.
14 Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ, bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
La voie que tracent tes préceptes, me donne autant de joie que tous les trésors.
15 Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
Je veux méditer tes commandements, et avoir les yeux sur tes sentiers.
16 Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ; èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
Je fais mes délices de tes décrets, et je n'oublie point ta parole. Guimel.
17 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè; èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Fais du bien à ton serviteur, pour que je vive, et que j'observe ta parole!
18 La ojú mi kí èmi lè ríran rí ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
Dessille mes yeux, pour que je découvre les merveilles cachées dans ta loi!
19 Àlejò ní èmi jẹ́ láyé, má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
Je suis un étranger sur la terre: ne me cèle pas tes commandements!
20 Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
Mon âme se consume à désirer tes lois en tout temps.
21 Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
Tu gourmandes les superbes, hommes maudits, qui s'écartent de tes commandements.
22 Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi, nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
Décharge-moi de l'opprobre et du mépris, car j'observe tes ordonnances!
23 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
Des princes mêmes se sont concertés contre moi: ton serviteur médite tes statuts;
24 Òfin rẹ ni dídùn inú mi; àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
tes ordres sont aussi mes délices et mes conseillers. Daleth.
25 Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀; ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Mon âme gît dans la poudre: rends-moi la vie selon ta promesse!
26 Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Je te raconte mes voies, et tu m'exauces: enseigne-moi tes ordonnances!
27 Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ: nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
Fais-moi découvrir la voie tracée par tes lois, et je veux approfondir tes merveilles!
28 Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́; fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Mon âme pleure de chagrin: relève-moi selon ta promesse!
29 Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
Tiens à distance de moi le chemin du mensonge, et accorde-moi la faveur de [connaître] ta loi!
30 Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́ èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
Je choisis le chemin de la vérité, et je me propose tes jugements.
31 Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
Je m'attache à tes ordonnances: Éternel, ne me rends pas confus!
32 Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ, nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
Je courrai dans la voie de tes commandements, car tu ouvres mon cœur. Hé.
33 Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ; nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
Éternel, indique-moi la voie de tes statuts, afin que je la tienne jusques au bout!
34 Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́ èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
Donne-moi l'intelligence, pour que je garde ta loi, et que je l'observe de tout mon cœur!
35 Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí, nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
Fais-moi suivre le sentier de tes préceptes, car j'en fais mes délices!
36 Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
Incline mon cœur vers tes préceptes, et non vers l'amour du gain!
37 Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán: pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Détourne mes yeux de regarder ce qui est vain, anime-moi sur tes sentiers!
38 Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí òfin rẹ dára.
Envers ton serviteur remplis ta promesse, qui fut faite à la crainte qu'on a de toi!
39 Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
Tiens loin de moi l'opprobre que je redoute, car tes jugements sont pleins de bonté!
40 Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ! Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
Voici, je porte mes désirs vers tes commandements, fais-moi vivre dans ta justice! Vav.
41 Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa, ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Et que tes grâces arrivent jusqu'à moi, Éternel, ton secours, selon ta promesse!
42 Nígbà náà ni èmi yóò dá ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn, nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
afin que je puisse répondre à celui qui m'outrage; car je me confie en ta promesse.
43 Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
N'ôte jamais de ma bouche le langage de la vérité! car je suis dans l'attente de tes jugements.
44 Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo láé àti láéláé.
Et j'observerai ta loi constamment, à jamais, perpétuellement;
45 Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira, nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
et je marcherai dans une voie spacieuse, car je cherche tes commandements.
46 Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba ojú kì yóò sì tì mí,
Et je parlerai de ta loi en présence des rois, et je n'aurai point de honte.
47 nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
Et je ferai mes délices de tes commandements, que j'aime,
48 Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn, èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
et je lèverai mes mains vers tes commandements que j'aime et je méditerai tes statuts. Zaïn.
49 Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
Souviens-toi de ta promesse à ton serviteur, puisque tu m'as donné l'espérance!
50 Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí: ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
Voici ma consolation dans ma misère, c'est que ta promesse me redonne la vie.
51 Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró, ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
Des superbes me tournent en grande dérision; de ta loi je ne dévie point.
52 Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa, èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
Je me rappelle tes jugements de jadis, Éternel, et je me console.
53 Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú, tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
Un bouillant transport me saisit à la vue des impies, qui abandonnent ta loi.
54 Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi níbikíbi tí èmi ń gbé.
Tes décrets me suggèrent des cantiques, dans le lieu de mon exil.
55 Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
La nuit je pense à ton nom, Éternel, et j'observe ta loi.
56 nítorí tí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
Voici ce qui m'est propre, c'est que je garde tes commandements. Cheth.
57 Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa: èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Mon partage, ô Éternel, je le dis, c'est de garder tes paroles.
58 Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Je cherche ta faveur de toute mon âme: sois-moi propice selon ta promesse!
59 Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
Je suis circonspect dans mes voies, et je retourne mes pas vers tes commandements.
60 Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
Je me hâte, et ne diffère point d'observer tes commandements.
61 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Les pièges des impies m'enveloppent; je n'oublie point ta loi.
62 Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ nítorí òfin òdodo rẹ.
Au milieu de la nuit, je me lève pour te louer des jugements de ta justice.
63 Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
Je me lie avec tous ceux qui te craignent, et observent tes commandements.
64 Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa, kọ́ mi ní òfin rẹ.
La terre, ô Éternel, est pleine de ta grâce: enseigne-moi tes ordonnances! Theth.
65 Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
Tu fais du bien à ton serviteur, Éternel, selon ta promesse.
66 Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere, nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
Enseigne-moi la bonne science et la connaissance! car je crois en tes commandements.
67 Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà, ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Avant mon humiliation, je m'égarais; mais maintenant je prends garde à ta parole.
68 Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Tu es bon et bienfaisant; enseigne-moi tes statuts!
69 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí, èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
Des superbes contre moi ourdissent l'astuce; moi, de tout mon cœur j'observe tes commandements.
70 Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú, ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
Leur cœur a l'insensibilité de la graisse, moi, je fais mes délices de ta loi.
71 Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
Il m'est utile d'avoir été humilié, pour devenir docile à tes préceptes.
72 Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
La loi qui sort de ta bouche a plus de prix pour moi que des milliers d'or et d'argent. Jod.
73 Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí; fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
Tes mains m'ont créé, m'ont formé; donne-moi l'intelligence, pour apprendre tes statuts!
74 Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Ceux qui te craignent, me verront et se réjouiront, car j'espère dans tes promesses.
75 Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni, àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
Je sais, Éternel, que tes jugements sont justes, et que tu m'as affligé en demeurant fidèle.
76 Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi, gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
O que ta grâce soit ma consolation, selon ta promesse à ton serviteur!
77 Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè, nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
Envoie-moi ta miséricorde, pour que j'aie la vie! car ta loi fait mes délices.
78 Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga nítorí wọn pa mí lára láìnídìí ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Que les superbes soient confondus, car ils m'accablent gratuitement! pour moi, je médite tes commandements.
79 Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi, àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
Qu'ils reviennent à moi ceux qui te craignent, et ceux qui connaissent tes commandements!
80 Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ, kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
Que mon cœur soit tout à tes ordonnances, afin que je ne sois pas confondu! Caph.
81 Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ, ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Mon âme languit après ton salut; je compte sur ta promesse.
82 Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ; èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
Mes yeux s'éteignent dans l'attente de ta promesse, je dis: Quand me consoleras-tu?
83 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín, èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
Car je suis comme une outre fumée; je n'oublie point tes commandements.
84 Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
Quel est le nombre des jours de ton serviteur? Quand feras-tu justice de mes persécuteurs?
85 Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi, tí ó lòdì sí òfin rẹ.
Des orgueilleux creusent des fosses devant moi; ils n'agissent point d'après ta loi.
86 Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé; ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
Tous tes commandements sont vrais: sans cause ils me persécutent; assiste-moi!
87 Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé, ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
Ils m'ont presque détruit, après m'avoir terrassé; mais je n'abandonne point tes commandements,
88 Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ, èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
Selon ta miséricorde rends-moi la vie, afin que j'observe les ordres de ta bouche! Lamed.
89 Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni; ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
Éternellement, Seigneur, ta parole subsiste dans les Cieux,
90 Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran; ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
d'âge en âge ta vérité demeure; tu as fondé la terre, et elle est stable;
91 Òfin rẹ dúró di òní nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
suivant tes lois tout subsiste aujourd'hui, car toutes choses te sont assujetties.
92 Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi, èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
Si ta loi n'eût fait mes délices, j'aurais péri dans ma misère.
93 Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé, nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
Jamais je n'oublierai tes commandements, car c'est par eux que tu me fais vivre.
94 Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
Je suis à toi: donne-moi ton secours! car je cherche tes commandements.
95 Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run, ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
Les impies m'attendent pour me faire périr; je suis attentif à tes ordres.
96 Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin; ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
A toute chose parfaite j'ai vu une fin; ta loi est infinieMem.
97 Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó! Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
Combien j'aime ta loi! elle est ma pensée de tous les jours.
98 Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
Tes préceptes me rendent plus sage que mes ennemis. car ils sont toujours avec moi.
99 Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ, nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
Je suis plus expert que tous mes maîtres, car tes ordonnances sont la pensée que j'ai;
100 Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ, nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
je suis plus entendu que les vieillards, car j'observe tes commandements.
101 Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
Je tiens mon pied loin de tout mauvais sentier, afin que j'observe ta parole.
102 Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
Je ne m'écarte point de ta loi, car c'est toi qui m'instruis.
103 Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó, ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
Que ta parole est douce à mon palais! elle l'est plus que le miel à ma bouche.
104 Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ; nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
Dans tes commandements je puise l'intelligence, aussi je hais tous les sentiers du mensonge. Nun.
105 Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
Ta parole est une lampe devant mes pieds, et une lumière sur mon sentier.
106 Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
J'ai fait le serment, et je le tiens, d'observer tes justes lois.
107 A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
Je suis extrêmement affligé: Éternel, rends-moi la vie selon ta promesse!
108 Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi, kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
Agrée, Éternel, le libre hommage de ma bouche, et enseigne-moi tes lois!
109 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
Ma vie est toujours en péril; mais je n'oublie point ta loi.
110 Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
Des impies me tendent des pièges, mais je ne m'écarte point de tes ordres.
111 Òfin rẹ ni ogún mi láéláé; àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
Je me suis pour toujours approprié tes préceptes car ils sont la joie de mon cœur.
112 Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́ láé dé òpin.
J'ai plié mon cœur à la pratique de tes lois, pour jamais, jusqu'à la fin. Samech.
113 Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
Je hais les hommes partagés, et j'aime ta loi.
114 Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Tu es mon abri et mon bouclier; j'attends ta promesse.
115 Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú, kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
Eloignez-vous de moi, méchants, afin que je garde les commandements de mon Dieu!
116 Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, kí èmi kí ó lè yè Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
Soutiens-moi selon ta promesse, afin que je vive, et ne me confonds point à cause de mon espoir!
117 Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu; nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
Sois mon appui, pour que je sois sauvé, et que j'aie toujours les yeux sur tes commandements!
118 Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
Tu méprises tous ceux qui s'écartent de tes lois; car leur fraude n'est qu'illusion.
119 Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́; nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
Tu enlèves comme des scories tous les impies de la terre; c'est pourquoi j'aime tes ordonnances.
120 Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀: èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
Tes terreurs font frissonner mon corps, et je redoute tes jugements. Aïn.
121 Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́: má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
J'ai pratiqué la loi, la justice: tu ne m'abandonneras pas à mes oppresseurs!
122 Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú: má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
Prends le parti de ton serviteur pour le sauver! que les superbes ne m'oppriment pas!
123 Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ, fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
Mes yeux languissent après ton secours et ta juste promesse.
124 Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Traite ton serviteur selon ta miséricorde, et enseigne-moi tes ordonnances!
125 Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye kí èmi lè ní òye òfin rẹ
Je suis ton serviteur: donne-moi l'intelligence, pour que j'aie la science de tes commandements.
126 Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa; nítorí òfin rẹ ti fọ́.
Il est pour l'Éternel temps d'agir; ils ont enfreint ta loi.
127 Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
Aussi j'aime tes commandements, plus que l'or, et que l'or pur;
128 nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀, èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
aussi je trouve justes tous tes commandements; et je hais tous les sentiers du mensonge. Pé.
129 Òfin rẹ̀ ìyanu ni: nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
Tes commandements sont admirables; c'est pourquoi mon âme les garde.
130 Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá; ó fi òye fún àwọn òpè.
La révélation de tes paroles éclaire, donne de l'intelligence aux simples.
131 Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ, nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
J'ouvre la bouche, je soupire; car je suis avide de tes commandements.
132 Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi, bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
Tourne tes regards sur moi, et prends pitié de moi, selon le droit de ceux qui aiment ton nom!
133 Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ, má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
Affermis mes pas dans ta parole, et ne laisse aucun mal prendre empire sur moi!
134 Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn, kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
Délivre-moi de l'oppression des hommes, afin que j'observe tes commandements!
135 Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
Fais luire ta face sur ton serviteur, et enseigne-moi tes ordonnances!
136 Omijé sàn jáde ní ojú mi, nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
Des torrents d'eau coulent de mes yeux, parce que l'on n'observe pas ta loi. Tsadé.
137 Olódodo ni ìwọ Olúwa ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
Tu es juste, Éternel, et tes jugements sont équitables;
138 Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo: wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
tu prescris la justice dans tes ordonnances, et une grande vérité.
139 Ìtara mi ti pa mí run, nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
Mon indignation me consume, de ce que mes ennemis oublient tes paroles.
140 Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
Ta parole est parfaitement pure, et ton serviteur l'aime.
141 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
Je suis chétif et méprisé; je n'oublie point tes préceptes.
142 Òdodo rẹ wà títí láé òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
Ta justice est un droit éternel, et ta loi, une vérité.
143 Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi, ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
La détresse et l'angoisse m'ont atteint; tes commandements sont mon délice.
144 Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé; fún mi ní òye kí èmi lè yè.
La justice de tes ordonnances est éternelle; donne-moi l'intelligence, afin que je vive! Quoph.
145 Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: dá mi lóhùn Olúwa, èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
Je t'invoque de tout mon cœur, exauce-moi, Éternel afin que j'observe tes ordonnances!
146 Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
Je t'invoque: aide-moi, afin que je garde tes commandements!
147 Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Je devance l'aurore et je crie; j'attends ta promesse.
148 Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru, nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
Avant les veilles j'ouvre déjà les yeux, pour méditer ta parole.
149 Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ: pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Entends ma voix selon ta miséricorde! Éternel, selon ta justice donne-moi la vie!
150 Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí, ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
Ils s'approchent ceux qui poursuivent le mal, ils se tiennent loin de ta loi;
151 Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa, àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
mais tu es proche, Éternel, et tous tes commandements sont vérité.
152 Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
Dès longtemps je sais par tes décrets que pour l'éternité tu les as arrêtés. Resch.
153 Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí, nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
Vois ma misère, et me délivre! car je n'oublie point ta loi.
154 Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Soutiens ma querelle, et me rachète! selon ta promesse donne-moi la vie!
155 Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
Le salut est loin des impies; car ils ne cherchent point tes ordonnances.
156 Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
Tes compassions sont grandes, Éternel; donne-moi la vie selon tes décrets!
157 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi, ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
Mes persécuteurs et mes oppresseurs sont nombreux; je n'ai point dévié de tes commandements.
158 Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́ nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
Je vois les infidèles, et j'en ai de l'horreur; ils n'observent point ta parole.
159 Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ; pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
Considère que j'aime tes commandements: Éternel, selon ta miséricorde donne-moi la vie!
160 Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ; gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
Le sommaire de ta parole, c'est vérité, et toutes tes justes lois sont éternelles. Schin.
161 Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí, ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
Des princes me persécutent sans cause; mais mon cœur ne craint que tes paroles.
162 Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
Je me réjouis de ta parole, comme celui qui trouve un grand butin.
163 Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
Je hais, je déteste le mensonge; j'aime ta loi.
164 Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.
Sept fois le jour je te célèbre, à cause de tes justes lois.
165 Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ, kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
Ils ont une grande paix ceux qui aiment la loi, pour eux il n'y a point de traverses.
166 Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa, èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
Je m'attends à ton secours, Éternel, et je pratique tes commandements.
167 Èmi gba òfin rẹ gbọ́, nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
Mon âme observe tes ordonnances, et j'ai pour elles un grand amour.
168 Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ, nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
J'exécute tes ordres et tes commandements, car toutes mes voies sont présentes à tes yeux. Thav.
169 Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa; fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
Que mes cris aient accès près de toi, Éternel! selon ta promesse donne-moi l'intelligence!
170 Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
Que ma prière arrive devant toi! selon ta promesse sauve-moi!
171 Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde, nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
Que mes lèvres épanchent la louange! car tu m'enseignes tous tes commandements!
172 Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ, nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
Que ma langue célèbre ta parole! car toutes tes lois sont justes.
173 Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
Que ta main me soit en aide! car j'ai fait choix de tes commandements.
174 Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa, àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
Je suis désireux de ton secours, Éternel, et ta loi fait mes délices.
175 Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́, kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
Que mon âme vive, et qu'elle te loue! et de tes jugements donne-moi le secours!
176 Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù. Wá ìránṣẹ́ rẹ, nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.
Je suis errant, comme une brebis perdue; cherche ton serviteur! car je n'oublie pas tes commandements.

< Psalms 119 >