< Psalms 118 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
Bekennet Jehovah, denn Er ist gut, denn Seine Barmherzigkeit ist ewig.
2 Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
Israel spreche nun, daß Seine Barmherzigkeit ist ewig.
3 Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
Es spreche nun Aharons Haus: Seine Barmherzigkeit ist ewig.
4 Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
Es sprechen nun die, so Jehovah fürchten: Seine Barmherzigkeit ist ewig.
5 Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
Aus der Bedrängnis rief ich zum Jah; es antwortete mir in der Weite Jah.
6 Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
Jehovah ist für mich. Ich fürchte mich nicht. Was kann der Mensch mir tun?
7 Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
Jehovah ist unter denen, so mir beistehen, und ich werde sehen auf die, so mich hassen.
8 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
Besser ist es, daß man sich auf Jehovah verläßt, denn daß man vertraut auf den Menschen.
9 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
Besser ist es, daß man sich auf Jehovah verläßt, denn daß man vertraut auf Fürsten.
10 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
Die Völkerschaften alle haben mich umgeben; in Jehovahs Namen haue ich sie nieder.
11 Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
Sie haben mich umgeben, ja, rings umgeben, doch in Jehovahs Namen haue ich sie nieder.
12 Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
Wie Bienen umgaben sie mich, sie sind verloschen, wie ein Feuer von Dornen; in Jehovahs Namen haue ich sie nieder.
13 Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
Du stießest mich an, damit ich fiele; doch Jehovah stand mir bei.
14 Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
Meine Stärke und mein Psalm ist Jah, und Er wird mir zum Heil.
15 Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
Des Lobpreisens Stimme und des Heils ist in den Zelten der Gerechten; Jehovahs Rechte tut Tapferes.
16 Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
Jehovahs Rechte ist erhöht, Jehovahs Rechte tut Tapferes.
17 Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
Nicht sterben werde ich, sondern leben und Jahs Taten erzählen.
18 Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
Jah züchtigt mich, aber dem Tode gibt Er mich nicht hin.
19 Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
Öffnet die Tore der Gerechtigkeit mir, ich gehe darinnen ein, ich bekenne Jah.
20 Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
Dies ist Jehovahs Tor, laßt die Gerechten darinnen einziehen.
21 Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
Ich will Dich bekennen, daß Du mir antwortest, und mir zum Heile bist geworden.
22 Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
Der Stein, den die Bauleute verschmäht, ist zum Haupt der Ecke geworden.
23 Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
Das ist geschehen von Jehovah, es ist wunderbar in unseren Augen.
24 Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
Dies ist der Tag, den Jehovah gemacht. Laßt uns an ihm frohlocken und fröhlich sein.
25 Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
O, rette uns doch, Jehovah, o lasse es, Jehovah, doch gelingen.
26 Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
Gesegnet sei, der da kommt in Jehovahs Namen! Wir segnen euch aus dem Hause Jehovahs.
27 Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
Gott ist Jehovah, und Er erleuchtet uns. Bindet mit Seilen das Festopfer an die Hörner des Altars.
28 Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
Du bist mein Gott; und Dich bekenne ich, mein Gott, ich will Dich erhöhen.
29 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
Bekennet Jehovah, denn Er ist gut; denn ewig ist Seine Barmherzigkeit.

< Psalms 118 >