< Psalms 118 >

1 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó dára; àánú rẹ̀ dúró láéláé.
Célébrez l'Eternel, car il est bon; parce que sa bonté demeure à toujours.
2 Jẹ́ kí Israẹli wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
Qu'Israël dise maintenant, que sa bonté demeure à toujours.
3 Jẹ́ kí ilé Aaroni wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé”.
Que la maison d'Aaron dise maintenant, que sa bonté demeure à toujours.
4 Jẹ́ kí àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa wí pé: “Àánú rẹ̀ dúró láéláé.”
Que ceux qui craignent l'Eternel disent maintenant, que sa bonté demeure à toujours.
5 Nínú ìrora mi, mo sọkún sí Olúwa, ó sì dá mi lóhùn nípa pé ó tú mi sílẹ̀.
Me trouvant dans la détresse, j'ai invoqué l'Eternel, et l'Eternel m'a répondu, et m'a mis au large.
6 Olúwa ń bẹ fún èmi; èmi kì yóò bẹ̀rù. Kí ni ènìyàn lè ṣe sí mi?
L'Eternel est pour moi, je ne craindrai point. Que me ferait l'homme?
7 Olúwa ń bẹ fún mi; òun ni olùrànlọ́wọ́ mi. Nítorí náà ni èmi ó ṣe rí ìṣẹ́gun mi lórí àwọn tí ó kórìíra mi.
L'Eternel est pour moi entre ceux qui m'aident; c'est pourquoi je verrai en ceux qui me haïssent ce [que je désire].
8 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju àti gbẹ́kẹ̀lé ènìyàn lọ.
Mieux vaut se confier en l'Eternel, que de se confier en l'homme.
9 Ó dára láti máa gbẹ́kẹ̀lé Olúwa ju à ti gbẹ́kẹ̀lé àwọn ọmọ-aládé lọ.
Mieux vaut se confier en l'Eternel, que de se reposer sur les principaux [d'entre les peuples].
10 Gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yí mi káàkiri, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn kúrò.
Ils m'avaient environné; mais au Nom de l'Eternel je les mettrai en pièces.
11 Wọ́n yí mi káàkiri ní gbogbo ẹ̀gbẹ́, ṣùgbọ́n ní orúkọ Olúwa èmi gé wọn dànù.
Ils m'avaient environné, ils m'avaient, dis-je, environné; [mais] au Nom de l'Eternel je les ai mis en pièces.
12 Wọ́n gbá yìn ìn yí mi ká bí oyin, ṣùgbọ́n wọ́n kú kíákíá bí iná ẹ̀gún; ní orúkọ Olúwa èmi ké wọn dànù.
Ils m'avaient environné comme des abeilles; ils ont été éteints comme un feu d'épines, car au Nom de l'Eternel je les ai mis en pièces.
13 Ìwọ tì mí gidigidi kí n lè ṣubú, ṣùgbọ́n Olúwa ràn mí lọ́wọ́.
Tu m'avais rudement poussé, pour me faire tomber, mais l'Eternel m'a été en aide.
14 Olúwa ni agbára àti orin mi; ó sì di ìgbàlà mi.
L'Eternel est ma force, [et le sujet de mon] Cantique, et il a été mon libérateur.
15 Ohùn ayọ̀ àti ìgbàlà ń bẹ nínú àgọ́ àwọn olódodo: “Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!
Une voix de chant de triomphe et de délivrance retentit dans les tabernacles des justes; la droite de l'Eternel, [s'écrient ils], fait vertu.
16 Ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ní a gbéga; ọwọ́ ọ̀tún Olúwa ń ṣe ohun agbára!”
La droite de l'Eternel est haut élevée, la droite de l'Eternel fait vertu.
17 Èmi kì yóò kú, ṣùgbọ́n èmi yóò yè, èmi yóò pòkìkí ohun tí Olúwa ṣe.
Je ne mourrai point, mais je vivrai, et je raconterai les faits de l'Eternel.
18 Olúwa bá mi wí gidigidi, ṣùgbọ́n òun kò fi mí lé ikú lọ́wọ́.
L’Eternel m'a châtié sévèrement, mais il ne m'a point livré à la mort.
19 Ṣí ìlẹ̀kùn ẹnu-ọ̀nà òdodo fún mi: èmi yóò bá ibẹ̀ wọlé, èmi yóò sì fi ọpẹ́ fún Olúwa.
Ouvrez-moi les portes de justice; j'y entrerai, et je célébrerai l'Eternel.
20 Èyí ni ìlẹ̀kùn Olúwa ibẹ̀ ni àwọn olódodo yóò bá wọlé.
C'est ici la porte de l'Eternel; les justes y entreront.
21 Èmi yóò fi ọpẹ́ fún ọ, nítorí ó dá mi lóhùn; ìwọ sì di ìgbàlà mi.
Je te célébrerai de ce que tu m'as exaucé et de ce que tu as été mon libérateur.
22 Òkúta tí àwọn ọ̀mọ̀lé kọ̀sílẹ̀, ni ó di pàtàkì igun ilé;
La Pierre que les Architectes avaient rejetée, est devenue le principal du coin.
23 Olúwa ti ṣe èyí, ó ṣe ìyanu ní ojú wa.
Ceci a été fait par l'Eternel, [et] a été une chose merveilleuse devant nos yeux.
24 Èyí ni ọjọ́ tí Olúwa dá: ẹ jẹ́ kí ayọ̀ kí inú wa sì máa dùn nínú rẹ̀.
C'est ici la journée que l'Eternel a faite; égayons-nous? et nous réjouissons en elle.
25 Olúwa, gbà wá; Olúwa, fún wa ní àlàáfíà.
Eternel, je te prie, délivre maintenant. Eternel, je te prie, donne maintenant prospérité.
26 Ìbùkún ni ẹni tí ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa. Àwa ti fi ìbùkún fún ọ láti ilé Olúwa wá.
Béni soit celui qui vient au Nom de l'Eternel; nous vous bénissons de la maison de l'Eternel.
27 Olúwa ni Ọlọ́run, ó ti mú ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ tàn sí wa lára pẹ̀lú ẹ̀ka igi ní ọwọ́, ó dára pọ̀ mọ́ ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ń wọ́ nínú ayọ̀ ẹ fi okùn di ẹbọ náà mọ́ ìwo pẹpẹ.
L'Eternel est le [Dieu] Fort, et il nous a éclairés. Liez avec des cordes la bête du sacrifice, [et amenez-la], jusqu’aux cornes de l'autel.
28 Ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ; ìwọ ni Ọlọ́run mi, èmi yóò gbé ọ ga.
Tu es mon [Dieu] Fort, c'est pourquoi je te célébrerai. Tu es mon Dieu, je t'exalterai.
29 Ẹ fi ọpẹ́ fún Olúwa, nítorí tí ó ṣeun; nítorí tí àánú rẹ̀ dúró láéláé.
Célébrez l'Eternel; car il [est] bon, parce que sa miséricorde demeure à toujours.

< Psalms 118 >