< Proverbs 7 >

1 Ọmọ mi, pa ọ̀rọ̀ mi mọ́, sì fi àwọn òfin mi pamọ́ sínú ọkàn rẹ.
Mon fils, retiens mes paroles, et garde avec toi mes préceptes.
2 Pa òfin mi mọ́, ìwọ yóò sì yè tọ́jú ẹ̀kọ́ mi bí ẹyinlójú rẹ.
Observe mes préceptes, et tu vivras, garde mon enseignement comme la prunelle de tes yeux.
3 Kọ wọ́n sí ọwọ́ òsì rẹ, má ṣe fi jẹun kọ wọ́n sí inú wàláà àyà rẹ.
Lie-les sur tes doigts, écris-les sur la table de ton cœur.
4 Wí fún ọgbọ́n pé, “Ìwọ ni arábìnrin mi,” sì pe òye ní ìbátan rẹ.
Dis à la sagesse: Tu es ma sœur! et appelle l'intelligence ton amie,
5 Wọn yóò pa ó mọ́ kúrò lọ́wọ́ obìnrin alágbèrè, kúrò lọ́wọ́ àjèjì obìnrin àti ọ̀rọ̀ ìtànjẹ rẹ̀.
pour qu'elle te préserve de la femme d'autrui, de l'étrangère qui fait entendre de douces paroles.
6 Ní ojú fèrèsé ilé è mi mo wo ìta láti ojú fèrèsé.
Etant à la fenêtre de ma maison, je regardais à travers le treillis.
7 Mo rí i láàrín àwọn aláìmọ̀kan mo sì kíyèsi láàrín àwọn ọ̀dọ́kùnrin, ọ̀dọ́ kan tí ó ṣe aláìgbọ́n.
J'aperçus parmi les insensés, je remarquai parmi les jeunes gens un garçon dépourvu de sens.
8 Ó ń lọ ní pópónà ní tòsí i ilé alágbèrè obìnrin náà, ó ń rìn lọ sí ọ̀nà ilé e rẹ̀.
Il passait dans la rue, près du logis d'une étrangère, et il s'avançait vers sa demeure.
9 Ní ìrọ̀lẹ́ bí oòrùn ṣe ń wọ̀, bí òkùnkùn ṣe ń bo ni lára.
C'était au crépuscule, à la chute du jour, au milieu de la nuit et de l'obscurité.
10 Bẹ́ẹ̀ ni obìnrin kan jáde wá láti pàdé rẹ̀, ó múra bí panṣágà pẹ̀lú ètè búburú.
Et voilà qu'une femme l'aborde, ayant la mise d'une courtisane et la dissimulation dans le cœur.
11 (Ó jẹ́ aláriwo àti alágídí, ìdí rẹ̀ kì í jókòó nílé;
Elle est impétueuse et indomptable; ses pieds ne peuvent se reposer dans sa maison;
12 bí ó ti ń já níhìn-ín ní ó ń já lọ́hùn ún gbogbo orígun ni ó ti ń ba ní ibùba.)
tantôt dans la rue, tantôt sur les places, et près de tous les angles, elle se tient aux aguets.
13 Ó dìímú, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu pẹ̀lú ojú díndín ó wí pé,
Elle saisit le jeune homme et l'embrasse, et avec un visage effronté lui dit:
14 “Mo ní ọrẹ àlàáfíà ní ilé; lónìí ni mo san ẹ̀jẹ́ mi.
« Je devais offrir des victimes pacifiques, aujourd'hui j'ai accompli mes vœux.
15 Nítorí náà ni n o ṣe jáde wá pàdé è rẹ; mo wá ọ káàkiri mo sì ti rí ọ!
C'est pourquoi je suis sortie à ta rencontre, pour te chercher, et je t'ai trouvé.
16 Mo ti tẹ́ ibùsùn mi pẹ̀lú aṣọ aláràbarà láti ilẹ̀ Ejibiti.
J'ai garni mon lit de couvertures, de tapis de fil d'Egypte.
17 Mo ti fi nǹkan olóòórùn dídùn sí ibùsùn mi bí i òjìá, aloe àti kinamoni.
J'ai parfumé ma couche de myrrhe, d'aloès et de cinnamome.
18 Wá, jẹ́ kí a lo ìfẹ́ papọ̀ ní kíkún títí di àárọ̀; jẹ́ kí a gbádùn ara wa pẹ̀lú ìfẹ́!
Viens, enivrons-nous d'amour jusqu'au matin, livrons-nous aux délices de la volupté.
19 Ọkọ ọ̀ mi ò sí nílé; ó ti lọ sí ìrìnàjò jíjìn.
Car mon mari n'est pas à la maison, il est parti pour un lointain voyage;
20 Ó mú owó púpọ̀ lọ́wọ́ kò sì ní darí dé kí ó tó di ọ̀sán.”
il a pris avec lui le sac de l'argent, il ne reviendra à la maison qu'à la pleine lune. »
21 Pẹ̀lú ọ̀rọ̀ dídùn ó sì í lọ́nà; ó tàn án jẹ pẹ̀lú ẹnu dídùn.
Elle le séduit à force de paroles, elle l'entraîne par les paroles de ses lèvres;
22 Òun sì tọ̀ ọ́ lọ lẹsẹ̀ kan náà, bí i màlúù tí ń lọ sí ibi pípa, tàbí bí àgbọ̀nrín tí ń lọ sí ibi okùn ìso.
il se met aussitôt à la suivre, comme le bœuf qui va à la boucherie, comme l'insensé qui court au châtiment des entraves,
23 Títí tí ọ̀kọ̀ fi gún un ní ẹ̀dọ̀, bí ẹyẹ ṣe ń fẹ́ wọ inú okùn, láìmọ̀ pé yóò gba ẹ̀mí òun.
jusqu'à ce qu'une flèche lui perce le foie, comme l'oiseau qui se précipite dans le filet, sans savoir qu'il y va pour lui de sa vie.
24 Nítorí náà báyìí ẹ̀yin ọmọ mi, tẹ́tí sí mi fọkàn sí nǹkan tí mo sọ.
Et maintenant, mes fils, écoutez-moi, et soyez attentifs aux paroles de ma bouche.
25 Má ṣe jẹ́ kí ọkàn rẹ kí ó yà sí ọ̀nà rẹ̀, tàbí kí ó rìn lọ sí ipa ọ̀nà rẹ̀.
Que ton cœur ne se détourne pas vers ses voies, ne t'égare pas dans ses sentiers.
26 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn tí ó ti fà lulẹ̀. Ogunlọ́gọ̀ àwọn alágbára ni ó ti pa.
Car elle a fait de nombreux blessés, et nombreuses ont été ses victimes.
27 Ilé e rẹ̀ ni ọ̀nà tààrà sí isà òkú, tí ó lọ tààrà sí àgbàlá ikú. (Sheol h7585)
Sa maison est le chemin du schéol, qui descend au séjour de la mort. (Sheol h7585)

< Proverbs 7 >