< Proverbs 22 >

1 Yíyan orúkọ rere sàn ju púpọ̀ ọrọ̀ lọ, àti ojúrere dára ju fàdákà àti wúrà lọ.
Vzácnější jest jméno dobré než bohatství veliké, a přízeň lepší než stříbro a zlato.
2 Ọlọ́rọ̀ àti tálákà péjọpọ̀: Olúwa ni ẹlẹ́dàá gbogbo wọn.
Bohatý a chudý potkávají se, učinitel obou jest Hospodin.
3 Ọlọ́gbọ́n ènìyàn ti rí ibi tẹ́lẹ̀, ó ṣé ara rẹ̀ mọ́: ṣùgbọ́n àwọn òpè tẹ̀síwájú, a sì jẹ wọ́n ní yà.
Opatrný vida zlé, vyhne se, ale hloupí předce jdouce, těžkosti docházejí.
4 Èrè ìrẹ̀lẹ̀ àti ìbẹ̀rù Olúwa ni ọrọ̀ ọlá, àti ìyè.
Pokory a bázně Hospodinovy odplata jest bohatství a sláva i život.
5 Ègún àti ìdẹ̀kùn ń bẹ ní ọ̀nà aláyídáyidà: ẹni tí ó bá pa ọkàn rẹ̀ mọ́ yóò jìnnà sí wọn.
Trní a osídla jsou na cestě převráceného; kdož ostříhá duše své, vzdálí se od nich.
6 Tọ́ ọmọdé ní ọ̀nà tí yóò tọ̀: nígbà tí ó bá dàgbà, kì yóò kúrò nínú rẹ̀.
Vyučuj mladého podlé způsobu cesty jeho; nebo když se i zstará, neuchýlí se od ní.
7 Ọlọ́rọ̀ ṣe olórí olùpọ́njú, ajigbèsè sì ṣe ìránṣẹ́ fún ẹni tí a jẹ ní gbèsè.
Bohatý nad chudými panuje, a vypůjčující bývá služebníkem toho, jenž půjčuje.
8 Ẹni tí ó bá fúnrúgbìn ẹ̀ṣẹ̀, yóò ká asán: ọ̀pá ìbínú rẹ̀ yóò kùnà.
Kdo rozsívá nepravost, žíti bude trápení; prut zajisté prchlivosti jeho přestane.
9 Ẹni tí ó ní ojú àánú ni a ó bùkún fún; nítorí tí ó fi nínú oúnjẹ rẹ̀ fún olùpọ́njú.
Oko dobrotivé, onoť požehnáno bude; nebo udílí z chleba svého chudému.
10 Lé ẹlẹ́gàn sí ìta, ìjà yóò sì jáde; nítòótọ́ ìjà àti ẹ̀gàn yóò dẹ́kun.
Vyvrz posměvače, a odejdeť svada, anobrž přestane svár a lehkost.
11 Ẹni tí ó fẹ́ ìwà funfun ti àyà, tí ó sì ń sọ̀rọ̀ iyì jáde, ọba yóò ṣe ọ̀rẹ́ rẹ̀.
Kdo miluje čistotu srdce, a v čích rtech jest příjemnost, takového král přítelem bývá.
12 Ojú Olúwa pa ìmọ̀ mọ́, ó sì yí ọ̀rọ̀ olùrékọjá pò.
Oči Hospodinovy ostříhají umění, ale snažnosti ošemetného převrací.
13 Ọ̀lẹ wí pé, “Kìnnìún ń bẹ lóde! Yóò pa mí ní ìgboro!”
Říká lenoch: Lev jest vně, naprostřed ulic byl bych zabit.
14 Ẹnu àwọn àjèjì obìnrin, ihò jíjìn ni; ẹni tí a ń bínú sí láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá ni yóò ṣubú sínú rẹ̀.
Jáma hluboká ústa postranních; ten, na kohož se hněvá Hospodin, vpadne tam.
15 Àyà ọmọdé ni ìwà wèrè dì sí; ṣùgbọ́n pàṣán ìtọ́ni ni yóò lé e jìnnà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀.
Bláznovství přivázáno jest k srdci mladého, ale metla kázně vzdálí je od něho.
16 Ẹni tó ń ni tálákà lára láti ní ọrọ̀, tí ó sì ń ta ọlọ́rọ̀ lọ́rẹ, yóò di aláìní bí ó ti wù kó rí. Gbọ́ ọ̀rọ̀ ọlọ́gbọ́n ènìyàn.
Kdo utiská nuzného, aby rozmnožil své, a dává bohatému, jistotně bude v nouzi.
17 Dẹtí rẹ sílẹ̀, kí o gbọ́ ọ̀rọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n, kí o sì fi àyà rẹ sí ẹ̀kọ́ mi.
Nakloň ucha svého, a slyš slova moudrých, a mysl svou přilož k učení mému.
18 Nítorí ohun dídùn ni bí ìwọ bá pa wọ́n mọ́ ní inú rẹ; nígbà tí a sì pèsè wọn tán ní ètè rẹ.
Nebo to bude utěšenou věcí, jestliže je složíš v srdci svém, budou-li spolu nastrojena ve rtech tvých.
19 Kí ìgbẹ́kẹ̀lé rẹ lè wà ní ti Olúwa, èmi fihàn ọ́ lónìí, àní fún ọ.
Aby bylo v Hospodinu doufání tvé, oznamujiť to dnes. I ty také ostříhej toho.
20 Èmi kò ha ti kọ̀wé ohun dáradára sí ọ ní ti ìmọ̀ràn àti ní ti ẹ̀kọ́,
Zdaližť jsem nenapsal znamenitých věcí z strany rad a umění,
21 kí ó lè mú ọ mọ ìdájú ọ̀rọ̀ òtítọ́; kí ìwọ le máa fi ìdáhùn òtítọ́ fún àwọn tí ó rán ọ?
Aťbych v známost uvedl jistotu řečí pravých, tak abys vynášeti mohl slova pravdy těm, kteříž by k tobě poslali?
22 Má ṣe ja tálákà ní olè, nítorí tí ó jẹ́ tálákà: bẹ́ẹ̀ ni kí o má sì ṣe ni olùpọ́njú lára ní ibodè,
Nelup nuzného, proto že nuzný jest, aniž potírej chudého v bráně.
23 nítorí Olúwa yóò gbèjà wọn, yóò sì gba ọkàn àwọn tí ń gba tiwọn náà.
Nebo Hospodin povede při jejich, a vydře duši těm, kteříž vydírají jim.
24 Má ṣe bá oníbìínú ènìyàn ṣe ọ̀rẹ́; má sì ṣe bá ọkùnrin onínú-fùfù rìn.
Nebývej přítelem hněvivého, a s mužem prchlivým neobcuj,
25 Kí ìwọ má ba à kọ́ ìwà rẹ̀, ìwọ a sì gba ìkẹ́kùn fún ara rẹ.
Abys se nenaučil stezkám jeho, a nevložil osídla na duši svou.
26 Má ṣe wà nínú àwọn tí ń ṣe ìgbọ̀nwọ́, tàbí nínú àwọn tí ó dúró fún gbèsè.
Nebývej mezi rukojměmi, mezi slibujícími za dluhy.
27 Bí ìwọ kò bá ní nǹkan tí ìwọ ó fi san, nítorí kín ni yóò ṣe gba ẹni rẹ kúrò lábẹ́ rẹ?
Nemáš-li, čím bys zaplatil, proč má kdo bráti lůže tvé pod tebou?
28 Má ṣe yẹ ààlà ilẹ̀ ìgbàanì, tí àwọn baba rẹ ti pa.
Nepřenášej mezníku starodávního, kterýž učinili otcové tvoji.
29 Ìwọ ha rí ènìyàn tí ó ń fi àìṣe ìmẹ́lẹ́ ṣe iṣẹ́ rẹ̀? Òun yóò dúró níwájú àwọn ọba; òun kì yóò dúró níwájú àwọn ènìyàn lásán.
Vídáš-li, že muž snažný v díle svém před králi stává? Nestává před nepatrnými.

< Proverbs 22 >