< Proverbs 2 >

1 Ọmọ mi, bí ìwọ bá gba ọ̀rọ̀ mi, tí ìwọ sì pa òfin mi mọ́ sí inú rẹ,
Figliuol mio, se ricevi le mie parole e serbi con cura i miei comandamenti,
2 tí ìwọ dẹtí rẹ sílẹ̀ sí ọgbọ́n tí ìwọ sì fi ọkàn rẹ sí òye,
prestando orecchio alla sapienza e inclinando il cuore all’intelligenza;
3 àní, bí ìwọ bá ké tọ ìmọ̀ lẹ́yìn, tí ìwọ sì gbé ohùn rẹ sókè fún òye
sì, se chiami il discernimento e rivolgi la tua voce all’intelligenza,
4 bí ìwọ bá ṣàfẹ́rí rẹ̀ bí i fàdákà tí ìwọ sì wa kiri bí ìṣúra tí a fi pamọ́.
se la cerchi come l’argento e ti dài a scavarla come un tesoro,
5 Nígbà náà ni ìwọ yóò bẹ̀rù Olúwa, ìwọ yóò sì rí ìmọ̀ Ọlọ́run.
Allora intenderai il timor dell’Eterno, e troverai la conoscenza di Dio.
6 Nítorí Olúwa ni ó ń fún ni ní ọgbọ́n, láti ẹnu rẹ̀ sì ni ìmọ̀ àti òye ti ń wá.
Poiché l’Eterno dà la sapienza; dalla sua bocca procedono la scienza e l’intelligenza.
7 Ó to ìgbàlà fún àwọn olódodo, Òun ni asà fún àwọn tí ń rìn déédé,
Egli tiene in serbo per gli uomini retti un aiuto potente, uno scudo per quelli che camminano integramente,
8 Ó pa ipa ọ̀nà ìdájọ́ mọ́ Ó sì ń pa ọ̀nà àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ mọ́.
affin di proteggere i sentieri della equità e di custodire la via dei suoi fedeli.
9 Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ òdodo àti ìdájọ́, àti àìṣègbè—gbogbo ipa ọ̀nà rere.
Allora intenderai la giustizia, l’equità, la rettitudine, tutte le vie del bene.
10 Nítorí ọgbọ́n yóò wọ inú ọkàn rẹ ìmọ̀ yóò sì jẹ́ ìtura fún ọkàn rẹ.
Perché la sapienza t’entrerà nel cuore, e la scienza sarà gradevole all’anima tua;
11 Ìmòye yóò pa ọ mọ́ òye yóò sì máa ṣọ́ ọ.
la riflessione veglierà su te, e l’intelligenza ti proteggerà;
12 Ọgbọ́n yóò gbà ọ́ là kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn búburú, lọ́dọ̀ àwọn ènìyàn tí ọrọ̀ ọ wọn jẹ́ àyídáyidà,
ti scamperà così dalla via malvagia, dalla gente che parla di cose perverse,
13 ẹni tí ó kúrò ní ọ̀nà ìdúró ṣinṣin láti rìn ní ọ̀nà tí ó ṣókùnkùn,
da quelli che lasciano i sentieri della rettitudine per camminare nella via delle tenebre,
14 ẹni tí ó yọ̀ nínú ṣíṣe búburú, tí ó ṣe inú dídùn sí àyídáyidà àwọn ènìyàn ibi,
che godono a fare il male e si compiacciono delle perversità del malvagio,
15 ọ̀nà ẹni tí ó wọ́ tí wọ́n sì jẹ́ alárékérekè ní ọ̀nà wọn.
che seguono sentieri storti e battono vie tortuose.
16 Yóò gba ìwọ pẹ̀lú là kúrò lọ́wọ́ àwọn àjèjì obìnrin, àní, lọ́wọ́ obìnrin àjèjì tí ń fi ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ̀ tannijẹ,
Ti scamperà dalla donna adultera, dalla infedele che usa parole melate,
17 ẹni tí ó ti kọ ọkọ àkọ́fẹ́ ìgbà èwe rẹ̀ sílẹ̀ tí ó sì gbàgbé májẹ̀mú tí ó ti dá níwájú Ọlọ́run rẹ̀.
che ha abbandonato il compagno della sua giovinezza e ha dimenticato il patto del suo Dio.
18 Nítorí ilé rẹ̀ jẹ́ ọ̀nà sí ikú ipa ọ̀nà rẹ̀ sọ́dọ̀ àwọn òkú.
Poiché la sua casa pende verso la morte, e i suoi sentieri menano ai defunti.
19 Kò sẹ́ni tó lọ sọ́dọ̀ rẹ̀ tí ó padà bẹ́ẹ̀ ni wọn kì í dé ọ̀nà ìyè.
Nessuno di quelli che vanno da lei ne ritorna, nessuno riprende i sentieri della vita.
20 Bẹ́ẹ̀ ni ìwọ yóò rìn ní ọ̀nà àwọn ènìyàn rere kí ìwọ kí ó sì pa ọ̀nà àwọn olódodo mọ́.
Così camminerai per la via dei buoni, e rimarrai nei sentieri dei giusti.
21 Nítorí ẹni dídúró ṣinṣin yóò gbé ní ilé náà àwọn aláìlẹ́gàn sì ni yóò máa wà nínú rẹ̀.
Ché gli uomini retti abiteranno la terra, e quelli che sono integri vi rimarranno;
22 Ṣùgbọ́n a ó ké ènìyàn búburú kúrò lórí ilẹ̀ náà a ó sì fa àwọn aláìṣòótọ́ tu kúrò lórí rẹ̀.
ma gli empi saranno sterminati di sulla terra e gli sleali ne saranno divelti.

< Proverbs 2 >