< Nehemiah 9 >

1 Ní ọjọ́ kẹrìnlélógún oṣù kan náà, àwọn ọmọ Israẹli péjọpọ̀, wọ́n gbààwẹ̀, wọ́n wọ aṣọ ọ̀fọ̀, wọ́n sì da eruku sórí ara wọn.
Aynı ayın yirmi dördüncü günü İsrailliler toplandı. Hepsi oruç tutmuş, çul kuşanmış, başına toprak serpmişti.
2 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì ya ara wọn sọ́tọ̀ kúrò nínú gbogbo àwọn àjèjì. Wọ́n dúró ní ààyè e wọn, wọ́n sì ń jẹ́wọ́ àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ẹ wọn àti iṣẹ́ búburú àwọn baba wọn.
İsrail soyundan gelenler bütün yabancılardan ayrılmıştı. Günahlarını ve atalarının yaptığı kötülükleri ayakta itiraf ettiler.
3 Wọ́n dúró sí ibi tí wọ́n wà, wọ́n sì fi ìdámẹ́rin ọjọ́ kà nínú ìwé òfin Olúwa Ọlọ́run wọn, wọ́n sì tún fi ìdámẹ́rin mìíràn ní ìjẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ àti ní sí sin Olúwa Ọlọ́run wọn.
Oldukları yerde durup günün dörtte biri boyunca Tanrıları RAB'bin Yasa Kitabı'nı okudular. Günün öbür dörtte birindeyse günahlarını itiraf ederek Tanrıları RAB'be tapındılar.
4 Nígbà náà ni Jeṣua, àti Bani, Kadmieli, Ṣebaniah, Bunni, Ṣerebiah, Bani àti Kenaani gòkè dúró lórí àwọn àtẹ̀gùn àwọn ọmọ Lefi, wọ́n sì fi ohùn rara kígbe sí Olúwa Ọlọ́run wọn.
Levililer'e yüksekçe bir yer ayrılmıştı. Yeşu, Bani, Kadmiel, Şevanya, Bunni, Şerevya, Bani ve Kenani orada oturuyordu. Ayağa kalkıp yüksek sesle Tanrıları RAB'be yakardılar.
5 Nígbà náà ni àwọn ọmọ Lefi: Jeṣua, Kadmieli, Bani, Haṣbneiah, Ṣerebiah, Hodiah, Ṣebaniah àti Petahiah—wí pé, “Ẹ dìde ẹ fi ìyìn fún Olúwa Ọlọ́run yín, tí ó wà láé àti láéláé.” “Ìbùkún ni fún orúkọ rẹ tí ó ní ògo, kí ó sì di gbígbéga ju gbogbo ìbùkún àti ìyìn lọ.
Levililer'den Yeşu, Kadmiel, Bani, Haşavneya, Şerevya, Hodiya, Şevanya ve Petahya halka, “Ayağa kalkın!” dediler, “Başlangıçtan sonsuza kadar var olan Tanrınız RAB'be övgüler olsun. ‘Ya Rab senin kutsal adın öyle yücedir ki, bizim yüceltmelerimiz, övgülerimiz yetersiz kalır.’”
6 Ìwọ nìkan ni Olúwa. Ìwọ ni ó dá ọ̀run, àní àwọn ọ̀run tí ó ga jù pẹ̀lú gbogbo ogun wọn, ayé àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀, òkun, àti ohun gbogbo tí ń bẹ nínú rẹ̀. Ìwọ sì pa gbogbo wọn mọ́ láàyè, ogun ọ̀run sì ń sìn ọ́.
Halk şöyle dua etti: “Tek RAB sensin. Gökleri, göklerin göklerini, bütün gök cisimlerini, yeryüzünü ve içindeki her şeyi, denizleri ve içlerindeki her şeyi sen yarattın. Hepsine sen can verdin. Bütün gök cisimleri sana tapınır.
7 “Ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run, tí ó yan Abramu tí ó sì mú u jáde láti Uri ti Kaldea, tí ó sì sọ orúkọ rẹ̀ ní Abrahamu.
“Ya RAB, Avram'ı seçen, onu Kildaniler'in Ur Kenti'nden çıkaran, ona İbrahim adını veren Tanrı sensin.
8 Ìwọ sì rí í pé ọkàn rẹ̀ jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ, ìwọ sì dá májẹ̀mú pẹ̀lú u rẹ̀ láti fi ilẹ̀ àwọn ará a Kenaani, Hiti, Amori, Peresi, Jebusi àti Girgaṣi fún irú àwọn ọmọ rẹ̀. Ìwọ ti pa ìpinnu rẹ̀ mọ́ nítorí tí ìwọ jẹ́ olódodo.
Onu kendine yürekten bağlı buldun ve onunla bir antlaşma yaptın. Kenanlı, Hitit, Amorlu, Perizli, Yevus ve Girgaş topraklarını onun soyuna vereceğim deyip sözünü tuttun. Çünkü sen doğrusun.
9 “Ìwọ rí ìpọ́njú àwọn baba ńlá wa ní Ejibiti; ìwọ gbọ́ igbe ẹkún wọn ní Òkun Pupa.
“Atalarımızın Mısır'da çektiklerini gördün, Kamış Denizi'nde yakarışlarını işittin.
10 Ìwọ rán iṣẹ́ àmì àti iṣẹ́ ìyanu sí Farao, sí gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀ àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ ẹ rẹ̀, nítorí ìwọ mọ ìwà ìgbéraga tí àwọn ará Ejibiti hù sí wọn. Ìwọ ra orúkọ fún ara à rẹ, èyí tí ó sì wà títí di òní yìí.
Firavuna, görevlilerine ve ülkesinin halkına karşı mucizeler, harikalar yarattın. Çünkü atalarımızı nasıl ezdiklerini biliyordun. Bugün olduğu gibi ün kazandın.
11 Ìwọ pín òkun níwájú wọn, nítorí kí wọn lè kọjá ní ìyàngbẹ ilẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ sọ àwọn tí ń lépa wọn sínú ibú, bí òkúta sínú omi ńlá.
Denizi yararak atalarımıza yol açtın. Denizin ortasından, kuru topraktan geçip gittiler. Onları kovalayanları ise bir taş gibi azgın derin sulara fırlattın.
12 Ní ọ̀sán ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn àwọsánmọ̀ àti ní òru ni ìwọ darí i wọn pẹ̀lú ọ̀wọn iná láti fún wọn ní ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀nà tí wọn yóò gbà.
Gündüzün bir bulut sütunuyla, geceleyin yollarına ışık tutmak için bir ateş sütunuyla atalarımıza yol gösterdin.
13 “Ìwọ sọ̀kalẹ̀ wá sí orí òkè Sinai; ìwọ bá wọn sọ̀rọ̀ láti ọ̀run. Ìwọ fún wọn ní ìlànà àti àwọn òfin tí ó jẹ́ òdodo tí ó sì tọ́ àti ìlànà tí ó dára.
“Sina Dağı'na indin, onlarla göklerden konuştun. Onlara doğru ilkeler, adil yasalar, iyi kurallar, buyruklar verdin.
14 Ìwọ mú ọjọ́ ìsinmi rẹ mímọ́ di mí mọ̀ fún wọn, o sì fún wọn ní àwọn ìlànà, àwọn àṣẹ àti àwọn òfin láti ọwọ́ Mose ìránṣẹ́ rẹ.
Kutsal Şabat Günü'nü bildirdin. Kulun Musa aracılığıyla buyruklar, kurallar, yasalar verdin.
15 Ìwọ fún wọn ní oúnjẹ láti ọ̀run wá nígbà tí ebi ń pa wọ́n àti nígbà òǹgbẹ, o fún wọn ní omi láti inú àpáta; o sì sọ fún wọn pé, kí wọ́n lọ láti lọ gba ilẹ̀ náà tí ìwọ ti jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fi fún wọn nípa ìgbọ́wọ́sókè.
Acıktıklarında gökten ekmek verdin, susadıklarında kayadan su çıkardın. Onlara vermeye ant içtiğin ülkeye girmelerini, orayı mülk edinmelerini buyurdun.
16 “Ṣùgbọ́n àwọn, baba ńlá wa, wọ́n ṣe ìgbéraga, wọ́n sì ṣe agídí, wọn kò sì tẹríba fún àwọn ìlànà rẹ.
“Ama atalarımız gurura kapıldı; dikbaşlılık edip buyruklarına uymadılar.
17 Wọ́n kọ̀ láti fetísílẹ̀, wọ́n sì kùnà láti rántí iṣẹ́ ìyanu tí ìwọ ṣe ní àárín wọn. Wọ́n ṣe agídí, nínú ìṣọ̀tẹ̀ wọn, wọ́n yan olórí láti padà sí oko ẹrú wọn. Ṣùgbọ́n ìwọ Ọlọ́run tí ó ń dáríjì, olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú, ó lọ́ra láti bínú, ó sì pọ̀ ní ìfẹ́. Nítorí náà ìwọ kò sì kọ̀ wọ́n sílẹ̀,
Söz dinlemek istemediler, aralarında yaptığın harikaları unuttular. Dikbaşlılık ettiler, eski kölelik yaşamlarına dönmek için kendilerine bir önder bularak başkaldırdılar. Ama sen bağışlayan, iyilik yapan, acıyan, tez öfkelenmeyen, sevgisi engin bir Tanrı'sın. Onları terk etmedin.
18 nítòótọ́ nígbà tí wọ́n ṣe ẹgbọrọ màlúù dídá, tí wọ́n sì wí pé, ‘Èyí ni Ọlọ́run rẹ tí ó mú ọ gòkè láti Ejibiti wá; tàbí nígbà tí wọ́n sọ ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì’.
Kendilerine buzağı biçiminde dökme bir put yaptılar, ‘Sizi Mısır'dan çıkaran Tanrınız budur!’ diyerek seni çok aşağıladılar.
19 “Nítorí àánú ńlá rẹ, ìwọ kò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ní aginjù. Ní ọ̀sán ọ̀wọn ìkùùkuu kò kúrò ní ọ̀dọ̀ wọn láti ṣe amọ̀nà an wọn, tàbí ọ̀wọ́n iná láti tàn sí wọn ní òru ní ọ̀nà tí wọn yóò rìn.
Yine de, yüce merhametinden ötürü onları çölde bırakmadın. Gündüzün yol göstermek için bulut sütununu, geceleyin yollarına ışık tutmak için ateş sütununu önlerinden eksik etmedin.
20 Ìwọ fi ẹ̀mí rere rẹ fún wọn láti kọ́ wọn. Ìwọ kò dá manna rẹ dúró ní ẹnu wọn, ó sì fún wọn ní omi fún òǹgbẹ.
Onları eğitmek için iyi Ruhun'u verdin. Ağızlarından manı eksiltmedin. Susadıklarında onlara su verdin.
21 Fún ogójì ọdún ni ìwọ fi bọ́ wọn ní aginjù; wọn kò ṣe aláìní ohunkóhun, aṣọ wọn kò gbó bẹ́ẹ̀ ni ẹsẹ̀ wọn kò wú.
Kırk yıl onları çölde besledin. Hiç eksikleri olmadı. Ne giysileri eskidi, ne de ayakları şişti.
22 “Ìwọ fi àwọn ìjọba àti àwọn orílẹ̀-èdè fún wọn, ó sì fi gbogbo ilẹ̀ náà fún wọ́n. Wọ́n sì gba ilẹ̀ ọba Sihoni ará a Heṣboni àti ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani.
“Onlara ülkeler, uluslar verdin, aralarında bölüştürdün. Heşbon Kralı Sihon'un, Başan Kralı Og'un ülkesini mülk edindiler.
23 Ìwọ ti mú àwọn ọmọ wọn pọ̀ bí ìràwọ̀ ojú ọ̀run, ó sì mú wọn wá sí ilẹ̀ tí o ti sọ fún àwọn baba wọn pé kí wọn wọ̀, kí wọn sì jogún un rẹ̀.
Onlara gökteki yıldızlar kadar çocuk verdin. Onları, mülk edinmek üzere atalarına söz verdiğin ülkeye getirdin.
24 Àwọn ọkùnrin wọn wọ inú rẹ̀, wọ́n sì gbà ilẹ̀ náà. Ìwọ sì tẹ orí àwọn ará a Kenaani, tí ń gbé inú ilẹ̀ náà ba níwájú wọn; ó fi àwọn ará a Kenaani lé wọn lọ́wọ́ pẹ̀lú àwọn ọba wọn àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kí wọn ṣe wọn bí ó ti wù wọ́n.
Çocukları Kenan ülkesini ele geçirip mülk edindiler. Ülke halkının onlara boyun eğmesini sağladın. Krallarını ve ülkedeki halkları istediklerini yapsınlar diye ellerine teslim ettin.
25 Wọ́n gba àwọn ìlú olódi àti ilẹ̀ ọlọ́ràá; wọ́n gba àwọn ilé tí ó kún fún onírúurú gbogbo nǹkan rere, àwọn kànga tí a ti gbẹ́, àwọn ọgbà àjàrà, àwọn ọgbà olifi àti àwọn igi eléso ní ọ̀pọ̀lọpọ̀. Wọ́n jẹ, wọ́n yó, wọ́n sì sanra dáradára; wọ́n sì yọ̀ nínú oore ńlá rẹ.
Surlu kentler, verimli topraklar ele geçirdiler. Güzel eşyalarla dolu evlere, kazılmış sarnıçlara, bağlara, zeytinliklere, çok sayıda meyve ağacına sahip oldular. Yediler, doydular, beslendiler ve onlara yaptığın büyük iyiliklere sevindiler.
26 “Ṣùgbọ́n wọ́n ṣe àìgbọ́ràn, wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí ọ; wọ́n gbàgbé òfin rẹ. Wọ́n pa àwọn wòlíì rẹ, tí o fi gbà wọn ni ìyànjú pé kí wọn yí padà sí ọ; wọ́n sì se ọ̀rọ̀-òdì tí ó burú jàì.
“Ama halkın söz dinlemedi, sana başkaldırdı. Yasana sırt çevirdiler, sana dönmeleri için kendilerini uyaran peygamberleri öldürdüler. Seni çok aşağıladılar.
27 Nítorí náà, ìwọ fi wọ́n lé àwọn ọ̀tá wọn lọ́wọ́, àwọn tí ó ni wọ́n lára. Ṣùgbọ́n nígbà tí a ni wọ́n lára wọ́n kígbe sí ọ. Ìwọ gbọ́ wọn láti ọ̀run wá àti nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àánú rẹ, ìwọ fún wọn ní olùgbàlà, tí ó gbà wọ́n lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá wọn.
Bu yüzden onları düşmanlarının eline teslim ettin. Düşmanları onları ezdi. Sıkıntıya düşünce sana feryat ettiler. Onları göklerden duydun, yüce merhametinden ötürü kurtarıcılar gönderdin. Bunlar halkı düşmanlarının elinden kurtardı.
28 “Ṣùgbọ́n bí wọ́n bá ti wà nínú ìsinmi, wọn a sì túnṣe búburú lójú rẹ. Nígbà náà ni ìwọ kọ̀ wọ́n sílẹ̀ ṣọ́wọ́ àwọn ọ̀tá kí wọ́n lè jẹ ọba lórí wọn. Nígbà tí wọ́n bá sì tún kígbe sí ọ, ìwọ a gbọ́ láti ọ̀run wá, àti nínú àánú rẹ ni ìwọ gbà láti ìgbà dé ìgbà.
“Ne var ki İsrail halkı rahata kavuşunca yine senin gözünde kötü olanı yaptı. Bu yüzden onları düşmanlarının eline terk ettin. Düşmanları onlara egemen oldu. Yine sana yönelip feryat ettiler. Onları göklerden duydun ve merhametinden ötürü defalarca kurtardın.
29 “Ìwọ kìlọ̀ fún wọn láti padà sínú òfin rẹ, ṣùgbọ́n wọ́n hu ìwà ìgbéraga, wọ́n sì ṣe àìgbọ́ràn si àṣẹ rẹ. Wọ́n ṣẹ̀ sí ìlànà rẹ, nípa èyí tí ènìyàn yóò yè tí wọ́n bá pa wọ́n mọ́. Nínú agídí ọkàn wọ́n kọ ẹ̀yìn sí ọ, wọ́n jẹ́ olórí kunkun wọn kò sì fẹ́ gbọ́.
“Onları Kutsal Yasan'a dönmeleri için uyardınsa da, gurura kapılarak buyruklarına karşı geldiler. Kurallarını çiğneyip günah işlediler. Oysa kim kurallarına bağlı kalırsa yaşam bulur. İnatla sana sırt çevirdiler, dinlemek istemediler.
30 Fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ni ìwọ fi ní sùúrù pẹ̀lú wọn. Nípa ẹ̀mí rẹ ni ìwọ kìlọ̀ fún wọn nípasẹ̀ àwọn wòlíì. Síbẹ̀ wọn kò fi etí sílẹ̀, nítorí náà ni ìwọ ṣe fi wọ́n lé àwọn aládùúgbò wọn lọ́wọ́.
Yıllarca onlara katlandın. Ruhun'la, peygamberlerin aracılığıyla onları uyardın. Ama kulak asmadılar. Bunun üzerine onları çeşitli ülke halklarının ellerine teslim ettin.
31 Ṣùgbọ́n nínú ọ̀pọ̀ àánú rẹ, ìwọ kò mú òpin bá wọn tàbí kọ̀ wọ́n sílẹ̀, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run olóore-ọ̀fẹ́ àti aláàánú.
Yüce merhametinden ötürü yok olmalarına izin vermedin. Onları terk etmedin. Çünkü sen iyilik yapan, acıyan bir Tanrı'sın.
32 “Ǹjẹ́ nítorí náà, Ọlọ́run wa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó lágbára, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ó pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, má ṣe jẹ́ gbogbo ìnira yìí dàbí ohun kékeré ní ojú rẹ—ìnira tí ó ti wá sórí wa, sórí àwọn ọba wa àti àwọn olórí wa, sórí àwọn àlùfáà wa àti àwọn wòlíì, sórí àwọn baba wa àti sórí gbogbo ènìyàn rẹ̀, láti àwọn ọjọ́ àwọn ọba Asiria wá títí di òní.
“Ey Tanrımız! Sen antlaşmana bağlı kalırsın. Güçlü, görkemli, yüce bir Tanrı'sın. Asur krallarının döneminden bugüne kadar krallarımız, önderlerimiz, kâhinlerimiz, peygamberlerimiz, atalarımız ve bütün halk acı çekti. Çektiklerimizi küçümseme.
33 Ìwọ jẹ́ olódodo nínú ohun gbogbo tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wa; ìwọ sì ti ṣe òtítọ́, nígbà tí a bá ṣe búburú.
Başımıza gelen bütün olaylarda sen hep adil davrandın, doğru olanı yaptın, bizse kötülük yaptık.
34 Àwọn ọba wa, àwọn olórí wa, àwọn àlùfáà wa, àti àwọn baba wa kò tẹ̀lé òfin rẹ; wọn kò fetísílẹ̀ sí àṣẹ rẹ tàbí àwọn ìkìlọ̀ tí ìwọ fún wọn.
Krallarımız, önderlerimiz, kâhinlerimiz, atalarımız yasana göre yaşamadılar. Verdiğin buyrukları, yaptığın uyarıları dinlemediler.
35 Àní nígbà tí wọ́n wà nínú ìjọba wọn, tí wọ́n ń gbádùn oore ńlá tí ìwọ fi fún wọn, ní ilẹ̀ tí ó tóbi tí ó sì lọ́ràá, wọn kò sìn ọ́ tàbí padà kúrò nínú àwọn ọ̀nà búburú wọn.
Ülkelerinde onlara sağladığın bolluk içinde, önlerine serdiğin geniş, verimli topraklarda sana kulluk etmediler, kötülüklerinden dönmediler.
36 “Ṣùgbọ́n wò ó, àwa jẹ́ ẹrú lónìí, àwa jẹ́ ẹrú ní ilẹ̀ tí ìwọ fún àwọn baba ńlá wa, nítorí kí wọn bá máa jẹ èso rẹ̀ àti ìre mìíràn tí ó mú jáde.
“Bak, bugün köleyiz. Meyvelerini, iyi ürünlerini yesinler diye atalarımıza verdiğin ülkede köle olduk.
37 Nítorí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ wa, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkórè rẹ lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ọba tí ó fi ṣe olórí wa. Wọ́n ń ṣe àkóso lórí wa àti lórí ẹran wa bí ó ti wù wọ́n, àwa sì wà nínú ìpọ́njú ńlá.
Günahlarımız yüzünden ürünlerimizin çoğunu başımıza getirdiğin krallara veriyoruz. Bizi de, hayvanlarımızı da istedikleri gibi kullanıyorlar. Büyük sıkıntı içindeyiz.”
38 “Nítorí gbogbo èyí, a ń ṣe àdéhùn tí ó fẹsẹ̀múlẹ̀, a sì kọ ọ́ sínú ìwé, àwọn olórí ọmọ Lefi àwọn àlùfáà sì fi èdìdì dì í.”
“Bütün bu olanlardan ötürü biz İsrail halkı olarak kesin bir yazılı antlaşma yapıyoruz. Önderlerimiz, Levililerimiz ve kâhinlerimiz de antlaşmayı mühürlüyor.”

< Nehemiah 9 >