< Nehemiah 12 >

1 Àwọn wọ̀nyí ni àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tí ó bá Serubbabeli ọmọ Ṣealitieli àti Jeṣua padà: Seraiah, Jeremiah, Esra,
[Many] priests and [other] descendants of Levi returned (from Babylonia/to Jerusalem) with Zerubbabel and Jeshua. They included Seraiah, Jeremiah, Ezra,
2 Amariah, Malluki, Hattusi,
Amariah, Malluch, Hattush,
3 Ṣekaniah, Rehumu, Meremoti,
Shecaniah, Rehum, Meremoth,
4 Iddo, Ginetoni, Abijah,
Iddo, Ginnethon, Abijah,
5 Mijamini, Moadiah, Bilgah,
Mijamin, Moadiah, Bilgah,
6 Ṣemaiah, Joiaribu, Jedaiah,
Shemaiah, Joiarib, Jedaiah,
7 Sallu, Amoki, Hilkiah, àti Jedaiah. Wọ̀nyí ni olórí àwọn àlùfáà àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn ní ìgbà ayé e Jeṣua.
Sallu, Amok, Hilkiah, and Jedaiah. All those men were leaders of the priests during the time that Jeshua [was the Supreme Priest].
8 Àwọn ọmọ Lefi ni Jeṣua, Binnui, Kadmieli, Ṣerebiah, Juda àti Mattaniah ẹni tí òun pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, ni wọn ṣe àkóso orin ìdúpẹ́.
[Some of the other] descendants of Levi who returned were Jeshua, Binnui, Kadmiel, Sherebiah, Judah, and Mattaniah. They were in charge of singing songs to thank [God].
9 Bakbukiah àti Unni, àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn dúró sí òdìkejì wọn nínú ìsìn.
Bakbukiah, Unni, and other descendants of Levi formed a choir that stood opposite the other group [and sang in reply to them].
10 Jeṣua ni baba Joiakimu, Joiakimu ni baba Eliaṣibu, Eliaṣibu ni baba Joiada,
Jeshua [who was the Supreme Priest] was the father of Joiakim, who was the father of Eliashib, who was the father of Joiada,
11 Joiada ni baba Jonatani, Jonatani sì ni baba Jaddua.
who was the father of Jonathan, who was the father of Jaddua.
12 Ní ìgbé ayé Joiakimu, wọ̀nyí ni àwọn olórí àwọn ìdílé àwọn àlùfáà: ti ìdílé Seraiah, Meraiah; ti ìdílé Jeremiah, Hananiah;
When Joiakim was the Supreme Priest, these were the leaders of the clans of priests: Meraiah, from [the clan of] Seraiah; Hananiah, from [the clan of] Jeremiah;
13 ti ìdílé Esra, Meṣullamu; ti ìdílé Amariah, Jehohanani;
Meshullam, from [the clan of] Ezra; Jehohanan, from [the clan of] Amariah;
14 ti ìdílé Malluki, Jonatani; ti ìdílé Ṣekaniah, Josẹfu;
Jonathan, from [the clan of] Malluch; Joseph, from [the clan of] Shecaniah;
15 ti ìdílé Harimu, Adna; ti ìdílé Meraioti Helikai;
Adna, from [the clan of] Harim; Helkai, from [the clan of] Meremoth/Maraioth;
16 ti ìdílé Iddo, Sekariah; ti ìdílé Ginetoni, Meṣullamu;
Zechariah, from [the clan of] Iddo; Meshullam, from [the clan of] Ginnethon;
17 ti ìdílé Abijah, Sikri; ti ìdílé Miniamini àti ti ìdílé Moadiah, Piltai;
Zicri, from [the clan of] Abijah. There was also a leader from [the clan of] Miniamin; Piltai, from [the clan of] Moadiah;
18 ti ìdílé Bilgah, Ṣammua; ti ìdílé Ṣemaiah, Jehonatani;
Shammua, from [the clan of] Bilgah; Jehonathan, from [the clan of] Shemaiah;
19 ti ìdílé Joiaribu, Mattenai; ti ìdílé Jedaiah, Ussi;
Mattenai, from [the clan of] Joiarib; Uzzi, from [the clan of] Jedaiah;
20 ti ìdílé Sallu, Kallai; ti ìdílé Amoki, Eberi;
Kallai, from [the clan of] Sallu/Sallai; Eber, from [the clan of] Amok;
21 ti ìdílé Hilkiah, Haṣabiah; ti ìdílé Jedaiah, Netaneli.
Hashabiah, from [the clan of] Hilkiah; and Nethanel, from [the clan of] Jedaiah.
22 Àwọn olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi ní ìgbà ayé Eliaṣibu, Joiada, Johanani àti Jaddua, àti pẹ̀lú ti àwọn àlùfáà ni a kọ sílẹ̀ ní ìgbà ìjọba Dariusi ará Persia.
During the years that Eliashib, Joiada, Johanan, and Jaddua [were Supreme Priests], they (wrote/kept a list of) the names of the clans who were descendants of Levi. When Darius was the king of Persia, they stopped writing that list.
23 Àwọn olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Lefi títí di àkókò Johanani ọmọ Eliaṣibu ni a kọ sílẹ̀ nínú ìwé ìtàn.
They wrote the names of the leaders of the clans who were descendants of Levi in the Book of Events [in Israel], but they stopped writing those names when Eliashib’s grandson Johanan [was the Supreme Priest].
24 Àti àwọn olórí àwọn ọmọ Lefi ni Haṣabiah, Ṣerebiah, Jeṣua ọmọ Kadmieli, àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn, tí wọ́n dúró ní ìdojúkojú wọn láti fi ìyìn àti láti dúpẹ́, apá kan ń dá èkejì lóhùn, gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run.
These are the leaders of the clans [who are] descendants of Levi: Hashabiah, Sherebiah, Jeshua, Binnui, Kadmiel and others who were divided into two groups. The two groups faced each other, one group replying to the other, during the time that they praised and thanked God. They did that just as King David, the man who served God well, had instructed.
25 Mattaniah, Bakbukiah, Obadiah, Meṣullamu, Talmoni àti Akkubu ni aṣọ́nà tí wọ́n ń sọ yàrá ìkó nǹkan pamọ́ sí ní ẹnu-ọ̀nà.
These singers included Mattaniah, Bakbukiah, and Obadiah. The men who guarded the storerooms close to the gates [of the temple] were Meshullam, Talmon, and Akkub.
26 Wọ́n ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní ìgbà ayé e Joiakimu ọmọ Jeṣua, ọmọ Josadaki, àti ní ọjọ́ ọ Nehemiah baálẹ̀ àti ní ọjọ́ Esra àlùfáà àti akọ̀wé.
They did that work during the time that Joiakim, who was the son of Jeshua and the grandson of Jehozadak, [was the Supreme Priest, ] and I was the governor, and Ezra was the priest who knew the Jewish laws very well.
27 Nígbà ìyàsímímọ́ odi Jerusalẹmu a mú àwọn ọmọ Lefi jáde wá láti ibi tí wọ́n ń gbé, wọ́n sì mú wọn wá sí Jerusalẹmu láti fi ayọ̀ ṣe ayẹyẹ ìyàsímímọ́ pẹ̀lú orin ìdúpẹ́ àti pẹ̀lú ohun èlò orin kimbali, haapu àti ohun èlò orin olókùn.
When we dedicated the wall around Jerusalem, we summoned the descendants of Levi [who help the priests] from the nearby places where they [were living]. We asked them to [join with us to] celebrate when we dedicated the wall. We wanted them to sing songs to thank [Yahweh] and make music by playing cymbals and harps and other stringed instruments.
28 A kó àwọn akọrin náà jọ papọ̀ láti àwọn ìletò tí ó yí Jerusalẹmu náà ká—láti àwọn abúlé Netofa,
We summoned the descendants of Levi who habitually sang together. They came to Jerusalem from nearby areas [where they had settled], and from places around Netophah [town southeast of Jerusalem],
29 láti Beti-Gilgali, àti láti àwọn agbègbè Geba àti Asmafeti, nítorí àwọn akọrin ti kọ́ àwọn ìletò fúnra wọn ní agbègbè Jerusalẹmu.
and from three places [northeast of Jerusalem]—Beth Gilgal [city] and the areas around Geba and Azmaveth. Those singers had built villages to live in near Jerusalem.
30 Nígbà tí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n ya àwọn ènìyàn sí mímọ́, àti ẹnu ibodè àti odi pẹ̀lú.
[When they came to Jerusalem], the priests and [other] descendants of Levi [who help the priests] performed rituals to cause themselves to be acceptable to God, and then they performed similar rituals to purify the [other] people, the gates, and the wall.
31 Mo sì tún yan àwọn olórí Juda láti gun orí odi náà. Mo sì tún yan àwọn ẹgbẹ́ akọrin ńlá méjì láti dúpẹ́. Àwọn kan yóò gòkè odi lọ sí apá ọ̀tún sí ọ̀nà ibodè Ààtàn.
Then I gathered together the leaders of Judah on top of the wall, and I appointed them to lead two large groups to march around the city [on top of the wall], thanking God. [As they faced the city, ] one group walked to the right toward the Dung Gate.
32 Hoṣaiah àti ìdajì àwọn olórí Juda tẹ̀lé wọn,
Behind their leaders marched Hoshaiah and half of the leaders of Judah.
33 àwọn wọ̀nyí náà sì lọ pẹ̀lú wọn, Asariah, Esra, Meṣullamu,
Behind them marched a group of priests who were blowing trumpets. They were Azariah, Ezra, Meshullam, Judah, Benjamin, Shemaiah, and Jeremiah. Next came Zechariah, the son of Jonathan, the son of Shemaiah, the son of Mattaniah, the son of Micaiah, the son of Zaccur, a descendant of Asaph.
34 Juda, Benjamini, Ṣemaiah, Jeremiah,
35 pẹ̀lú àwọn àlùfáà díẹ̀ pẹ̀lú ìpè, pẹ̀lú u Sekariah ọmọ Jonatani, ọmọ Ṣemaiah, ọmọ Mattaniah, ọmọ Mikaiah, ọmọ Sakkuri, ọmọ Asafu,
36 àti àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, Ṣemaiah, Asareeli, Milalai, Gilalai, Maai, Netaneli, Juda àti Hanani—pẹ̀lú ohun èlò orin bí àṣẹ Dafidi ènìyàn Ọlọ́run. Esra akọ̀wé ni ó ṣáájú wọn bí wọ́n ti ń tò lọ lọ́wọ̀ọ̀wọ́.
Behind them marched other members of Zechariah’s clan: Shemaiah, Azarel, Milalai, Gilalai, Maai, Nethanel, Judah, and Hanani. They all were playing the same kinds of musical instruments that King David had played [many years previously]. Ezra, the man who knew the Jewish laws very well, marched in front of this group.
37 Ní ẹnu ibodè orísun wọ́n ti ń lọ tààrà sí ọ̀nà ní orí àtẹ̀gùn ìlú Dafidi ní orí òkè tí ó kángun sí odi, wọ́n sì gba ẹ̀gbẹ́ ilé Dafidi kọjá títí dé ẹnu ibodè omi ní ìhà ìlà-oòrùn.
When they reached the Fountain Gate, they went up the steps to David’s City, past his palace, and then to the wall at the Water Gate, on the east side [of the city].
38 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin kejì gba ọ̀nà òdìkejì lọ. Mo tẹ̀lé wọn ní orí odi, pẹ̀lú ìdajì àwọn ènìyàn, kọjá ilé ìṣọ́ ìléru lọ sí odi fífẹ̀,
The other group of those who were thanking [Yahweh] marched to the left on top of the wall. I followed them with half of the people. [We marched] past the Tower of the Ovens to the Broad Wall.
39 kọjá ẹnu ibodè Efraimu ibodè Jeṣana, ẹnu ibodè ẹja, ilé ìṣọ́ Hananeli àti ilé ìṣọ́ ọgọ́rùn-ún, títí dé ẹnu ibodè àgùntàn. Wọ́n sì dúró ní ibodè ìṣọ́.
[From there we marched] past Ephraim Gate, Jeshanah Gate, the Fish Gate, the Tower of Hananel, the Tower of the Hundred Soldiers, to the Sheep Gate. We finished marching near the gate into the temple.
40 Àwọn ẹgbẹ́ akọrin méjèèjì tí wọ́n dúpẹ́ wà ní ààyè nínú ilé Ọlọ́run, èmi náà sì dúró ní ààyè mi pẹ̀lú ìdajì àwọn ìjòyè,
Both the groups reached the temple while they were thanking God. They stood in their places there. The leaders who were with me [also stood with me in our places].
41 àti àwọn àlùfáà Eliakimu, Maaseiah, Miniamini, Mikaiah, Elioenai, Sekariah àti Hananiah pẹ̀lú àwọn ìpè wọn.
My group included these priests who were [all blowing] trumpets: Eliakim, Maaseiah, Miniamin, Micaiah, Elioenai, Zechariah, Hananiah,
42 Àti pẹ̀lú Maaseiah, Ṣemaiah, Eleasari àti Ussi, àti Jehohanani, àti Malkiah, àti Elamu, àti Eseri. Àwọn akọrin kọrin sókè ní abẹ́ alábojútó Jesrahiah.
[another] Maaseiah, Shemaiah, Eleazar, Uzzi, Jehohanan, Malchijah, Elam, and Ezer. The singers, whose leader was Jezrahiah, sang loudly.
43 Ní ọjọ́ náà wọ́n rú ẹbọ ńlá, wọ́n ṣe àjọyọ̀ nítorí Ọlọ́run ti fún wọn ní ayọ̀ ńlá. Àwọn obìnrin àti àwọn ọmọdé sì yọ̀ pẹ̀lú. A lè gbọ́ ariwo ayọ̀ tí ó jáde láti Jerusalẹmu ní jìnnà réré.
[After we went outside the temple, ] we offered many sacrifices. We men all rejoiced because God had caused us to be very happy. The women and the children also rejoiced. People far away could hear the noise that we made there in Jerusalem.
44 Ní àkókò náà, a yan àwọn ènìyàn láti jẹ́ alábojútó yàrá ìṣúra fún àwọn ọrẹ àkọ́so èso àti àwọn ìdámẹ́wàá. Láti inú àwọn oko tí ó wà ní àyíká ìlú ni wọ́n ti ní láti mú wá sínú yàrá ìṣúra, ìpín tí òfin sọ fún àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, nítorí inú àwọn ará a Juda yọ́ sí àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi tó ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́.
On that day, men were appointed {they appointed men} to be in charge of the storerooms where they kept the money that people contributed [for the temple]. They also kept there [the other things that the people contributed—] the tithes and the first part of the grain and fruit that was harvested each year. Those men collected those things from the fields/farms near the cities, and [took them to Jerusalem and] gave them to the priests and the [other] descendants of Levi, as [Moses had said in his] laws that they should do. All the Israeli people were happy about the work that the priests and the descendants of Levi did,
45 Wọ́n ń ṣiṣẹ́ Ọlọ́run wọn àti iṣẹ́ ìyàsímímọ́, bẹ́ẹ̀ náà ni fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà, wọ́n ń ṣe gẹ́gẹ́ bí Dafidi àti Solomoni ọmọ rẹ̀ ti pàṣẹ fún wọn.
because they performed the rituals to purify things, and the other rituals that God had commanded. The musicians in the temple also did their work as King David and his son Solomon had declared that they should do.
46 Ní ọjọ́ pípẹ́ sẹ́yìn ní ìgbà Dafidi àti Asafu, ni àwọn atọ́nisọ́nà ti wà fún àwọn akọrin àti fún orin ìyìn àti orin ọpẹ́ sí Ọlọ́run.
Ever since the time that David had been the king and Asaph had been his chief musician, the musicians had led the people while they sang songs to praise and thank God.
47 Nítorí náà ní ìgbà ayé Serubbabeli àti Nehemiah, gbogbo Israẹli ni ó ń dá ìpín lójoojúmọ́ fún àwọn akọrin àti àwọn aṣọ́nà. Wọ́n sì tún yan ìpín mìíràn sọ́tọ̀ fún àwọn ọmọ Lefi tókù, àwọn ọmọ Lefi náà tún ya ìpín ti àwọn ọmọ Aaroni sọ́tọ̀ fún wọn.
During the years that Zerubbabel and I governed the Israeli people, they all contributed the food that the singers and temple gatekeepers needed each day. They gave (a tithe/10%) of their crops to the descendants of Levi [who helped the priests], and those descendants of Levi gave (a tithe/10%) of that to [the priests, who were] descendants of Aaron [the first Supreme Priest].

< Nehemiah 12 >