< Micah 2 >

1 Ègbé ni fún àwọn tí ń gbèrò àìṣedéédéé tí wọ́n sì ń ṣiṣẹ́ ibi lórí ibùsùn wọn! Nígbà tí ojúmọ́ bá mọ́, wọn yóò gbé e jáde nítorí ó wà ní agbára wọn láti ṣe é.
Malheur à ceux qui méditent l’iniquité et préparent le mal sur leurs couches, pour l’accomplir dès la pointe du jour autant que cela est en leur pouvoir!
2 Wọ́n sì ń ṣe ojúkòkòrò oko, wọ́n sì fi agbára wọn gbà wọ́n, àti àwọn ilé, wọ́n sì gbà wọ́n. Wọ́n sì ni ènìyàn àti ilẹ̀ rẹ̀ lára àní ènìyàn àti ohun ìní rẹ̀.
Ils convoitent des champs et les volent, des maisons et s’en emparent. Ils usent de violence envers les hommes et leurs demeures, envers les propriétaires et leurs domaines.
3 Nítorí náà, Olúwa wí pé: “Èmi ń gbèrò ibi sí àwọn ìdílé wọ̀nyí, nínú èyí tí wọn kì yóò le è gba ara wọn là. Ìwọ kì yóò sì lè máa rìn ní ìgbéraga mọ́, nítorí yóò jẹ́ àkókò ibi.
Eh bien! dit l’Eternel, voici je médite, moi, contre cette engeance une calamité où vous enfoncerez jusqu’au cou: vous ne marcherez plus la tête haute, car ce sera un temps de malheur.
4 Ní ọjọ́ náà ni ẹnìkan yóò pa òwe kan sí yín; wọn yóò sì pohùnréré ẹkún kíkorò pé: ‘Ní kíkó a ti kó wọn tán; Olúwa ti pín ohun ìní àwọn ènìyàn mi; Ó ti mú un kúrò lọ́dọ̀ mi! Ó fi oko wa lé àwọn ọlọ̀tẹ̀ lọ́wọ́.’”
En ce jour, on chantera à votre propos une satire, on soupirera une complainte; on dira: "Nous sommes totalement ruinés! L’Héritage de mon peuple passe à d’autres mains. Hélas! Comme on m’en expulse pour le répartir entre les ravisseurs de notre champ!"
5 Nítorí náà, ìwọ kò ní ní ẹnìkankan tí yóò ta okùn nínú ìjọ Olúwa, tí yóò pín ilẹ̀ nípa ìbò.
En vérité il n’y aura personne pour toi qui puisse jeter le cordeau sur un lot de terre dans la Communauté du Seigneur.
6 “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀,” ni àwọn wòlíì wọn wí. “Ẹ má ṣe sọtẹ́lẹ̀ nípa nǹkan wọ̀nyí; kí ìtìjú má ṣe le bá wa.”
"Ne pérorez pas, ainsi pérorent-ils; on ne débite pas de pareils discours; les avanies n’ont pas de fin!"
7 Ṣé kí á sọ ọ́, ìwọ ilé Jakọbu: “Ǹjẹ́ ẹ̀mí Olúwa ha ń bínú bí? Ǹjẹ́ iṣẹ́ rẹ ha nìwọ̀nyí?” “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ mi kò ha ń ṣe rere fún ẹni tí ń rìn déédé bí?
Est-il permis de parler ainsi, maison de Jacob? L’Eternel manque-t-il de patience? Sont-ce là ses œuvres? Mes paroles ne sont-elles pas bienveillantes pour celui qui marche droit?
8 Láìpẹ́ àwọn ènìyàn mi dìde bí ọ̀tá sí mi. Ìwọ bọ́ aṣọ ọlọ́rọ̀ kúrò lára àwọn tí ń kọjá lọ ní àìléwu, bí àwọn ẹni tí ó padà bọ̀ láti ojú ogun.
Mais depuis longtemps mon peuple s’érige en ennemi; ceux qui passent en sécurité, comme s’ils revenaient du combat, vous les dépouillez du manteau qui couvre leur vêtement.
9 Ẹ̀yin sì lé obìnrin àwọn ènìyàn mi kúrò nínú ilé ayọ̀ wọn, ẹ̀yin sì ti gba ògo mi, kúrò lọ́wọ́ àwọn ọmọ wọn láéláé.
Les femmes de mon peuple, vous les chassez de leurs maisons de plaisance; à leurs enfants vous enlevez pour toujours le lustre qu’ils me doivent.
10 Ẹ dìde, kí ẹ sì máa lọ! Nítorí èyí kì í ṣe ibi ìsinmi yín, nítorí tí a ti sọ ọ́ di àìmọ́ yóò pa yín run, àní ìparun kíkorò.
Debout et en route! car ce n’est plus ici une terre de repos: parce qu’elle a été souillée, elle sera une cause de souffrances, de cruelles souffrances.
11 Tí òpùrọ́ àti ẹlẹ́tàn bá wà tí wọ́n sì wí pé, ‘Èmi yóò sọtẹ́lẹ̀ fún ọ nípa ọ̀pọ̀lọpọ̀ wáìnì àti ọtí líle,’ òun ni yóò tilẹ̀ ṣe wòlíì àwọn ènìyàn wọ̀nyí!
Qu’un homme se présente, se nourrissant de vent, inventant des mensonges, et qu’il dise: "Je vais te tenir des discours sur le vin et les boissons fortes," voilà un prédicateur pour ce peuple!
12 “Èmi yóò kó gbogbo yín jọ, ìwọ Jakọbu; Èmi yóò gbá ìyókù Israẹli jọ. Èmi yóò kó wọn jọ pọ̀ gẹ́gẹ́ bí àgùntàn nínú agbo ẹran, gẹ́gẹ́ bí ọ̀wọ́ ẹran nínú agbo wọn, ibẹ̀ yóò sì pariwo nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn.
J’Aurai soin de te rassembler tout entier, ô Jacob, de te réunir, ô reste d’Israël! Comme les brebis dans un parc, comme un troupeau dans le pâturage, je les mettrai ensemble: ce sera une multitude bruyante d’hommes.
13 Ẹni tí ó ń fọ ọ̀nà yóò lọ sókè níwájú wọn; wọn yóò fọ láti ẹnu ibodè, wọn yóò sì jáde lọ. Àwọn ọba wọn yóò sì kọjá lọ níwájú wọn, Olúwa ni yóò sì ṣe olórí wọn.”
Devant eux marche celui qui brise la clôture; ils la renversent, se précipitent par l’ouverture et sortent: leur roi les précède et l’Eternel est à leur tête.

< Micah 2 >