< Matthew 25 >

1 “Nígbà náà ni ó fi ìjọba ọ̀run wé àwọn wúńdíá mẹ́wàá. Ti wọ́n gbé fìtílà wọn láti lọ pàdé ọkọ ìyàwó.
«Alors le Royaume des cieux sera semblable à dix vierges qui, allèrent, leurs lampes à la main, à la rencontre de l'époux.
2 Márùn-ún nínú wọn jẹ́ ọlọ́gbọ́n, márùn-ún nínú wọn ni wọ́n jẹ́ aláìgbọ́n.
Cinq d'entre elles étaient folles, cinq étaient sages.
3 Àwọn tí wọ́n jẹ́ aláìgbọ́n gbé fìtílà wọn ṣùgbọ́n wọn kò mú epo kankan lọ́wọ́.
Folles, car, en prenant leurs lampes, elles n'avaient pas emporté d'huile avec elles;
4 Àwọn ọlọ́gbọ́n mú epo sínú kólòbó lọ́wọ́ pẹ̀lú fìtílà wọn.
mais les sages avaient pris, avec leurs lampes, de l'huile dans des vases.
5 Nígbà tí ọkọ ìyàwó pẹ́, gbogbo wọn tòògbé wọn sì sùn.
L'époux tardant à venir, elles s'assoupirent toutes et s'endormirent.
6 “Nígbà tí ó di ọ̀gànjọ́, igbe ta sókè, ‘Wò ó, ọkọ ìyàwó ń bọ̀, ẹ jáde sóde láti pàdé rẹ̀.’
Au milieu de la nuit un cri retentit: «Voici l'époux! sortez au-devant de lui!»
7 “Nígbà náà ni àwọn wúńdíá sì tají, wọ́n tún fìtílà wọn ṣe.
Alors toutes ces vierges se levèrent et apprêtèrent leurs lampes,
8 Àwọn aláìgbọ́n márùn-ún tí kò ní epo rárá bẹ àwọn ọlọ́gbọ́n pé kí wọn fún àwọn nínú èyí tí wọ́n ní nítorí fìtílà wọn ń kú lọ.
et les folles dirent aux sages: «Nos lampes s'éteignent; donnez-nous de votre huile.»
9 “Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n márùn-ún dáhùn pé, bẹ́ẹ̀ kọ́; kí ó má ba à ṣe aláìtó fún àwa àti ẹ̀yin, ẹ kúkú tọ àwọn tí ń tà á lọ, kí ẹ sì rà fún ara yín.
Les sages répondirent: «Il n'y en aurait peut-être pas assez pour nous et pour vous; allez plutôt à ceux qui en vendent et vous en achetez.»
10 “Ní àsìkò tí wọ́n lọ ra epo tiwọn, ni ọkọ ìyàwó dé. Àwọn wúńdíá tí ó múra tán bá a wọlé sí ibi àsè ìgbéyàwó, lẹ́yìn náà, a sì ti ìlẹ̀kùn.
«Or, pendant qu'elles allaient en acheter, l'époux vint, et celles qui étaient prêtes entrèrent avec lui au festin de noces; et la porte fut fermée.
11 “Ní ìkẹyìn ni àwọn wúńdíá márùn-ún ìyókù dé, wọ́n ń wí pé, ‘Olúwa, Olúwa, ṣílẹ̀kùn fún wa.’
«Enfin arrivent aussi les autres vierges, en disant: «Seigneur! Seigneur! ouvre-nous!»
12 “Ṣùgbọ́n ọkọ ìyàwó dáhùn pé, ‘Lóòótọ́ ni mo wí fún yín èmi kò mọ̀ yín rí.’
mais il leur répondit: «En vérité, je vous le dis, je ne vous connais pas.»
13 “Nítorí náà, ẹ máa ṣọ́nà. Nítorí pé ẹ̀yin kò mọ ọjọ́ tàbí wákàtí tí Ọmọ Ènìyàn yóò dé.
Donc, veillez, parce que vous ne savez ni le jour ni l'heure.»
14 “A sì tún fi ìjọba ọ̀run wé ọkùnrin kan tí ó ń lọ sí ìrìnàjò. Ó pe àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì kó ohun ìní rẹ̀ fún wọn.
«Tel encore le Royaume des cieux, tel un homme qui, partant pour un voyage, appela ses serviteurs et leur confia ses biens.
15 Ó fún ọ̀kan ni tálẹ́ǹtì márùn-ún, ó fún èkejì ni tálẹ́ǹtì méjì, ó sì fún ẹ̀kẹta ni tálẹ́ǹtì kan, ó fún olúkúlùkù gẹ́gẹ́ bí agbára rẹ̀ ti mọ, ó sì lọ ìrìnàjò tirẹ̀.
A celui-ci, il donna cinq talents; à celui-là, deux; à ce troisième, un seul; à chacun suivant sa capacité personnelle. Aussitôt après, il partit.
16 Ọkùnrin tí ó gba tálẹ́ǹtì márùn-ún bẹ̀rẹ̀ lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ láti fi owó náà ṣòwò. Láìpẹ́, ó sì jèrè márùn-ún mìíràn.
Celui qui avait reçu les cinq talents alla les faire valoir et en gagna cinq autres.
17 Ọkùnrin tí ó gba tálẹ́ǹtì méjì náà fi tirẹ̀ ṣòwò. Láìpẹ́, ó sì jèrè tálẹ́ǹtì méjì mìíràn.
De même celui qui en avait deux en gagna deux autres.
18 Ṣùgbọ́n ọkùnrin tí ò gba tálẹ́ǹtì kan, ó wa ihò ní ilẹ̀, ó sì bo owó ọ̀gá mọ́ ibẹ̀.
Mais celui qui n'en avait reçu qu'un, alla faire un trou dans la terre et il y enfouit l'argent de son maître.
19 “Lẹ́yìn ọjọ́ pípẹ́, olúwa àwọn ọmọ ọ̀dọ̀ dé láti àjò rẹ̀. Ó pè wọ́n jọ láti bá wọn ṣírò owó rẹ̀.
Après un long temps écoulé, le maître revint et il fit rendre compte à ses serviteurs.
20 Ọkùnrin tí ó gba tálẹ́ǹtì márùn-ún, mú márùn-ún mìíràn padà wá, ó wí pé, ‘Olúwa, ìwọ ti fi tálẹ́ǹtì márùn-ún fún mi, mo sì ti jèrè márùn-ún mìíràn pẹ̀lú rẹ̀.’
Celui qui avait reçu les cinq talents se présenta, en apportant cinq autres. «Seigneur, dit-il, tu m'as confié cinq talents; en voici cinq autres que j'ai gagnés.»
21 “Olúwa rẹ̀ wí fún un pé, ‘O ṣeun ìwọ ọmọ ọ̀dọ̀ rere àti olóòtítọ́: ìwọ ṣe olóòtítọ́ nínú ohun díẹ̀, èmi yóò fi ọ́ ṣe olórí ohun púpọ̀, bọ́ sínú ayọ̀ olúwa rẹ.’
Le maître lui dit: «Bien, serviteur bon et fidèle; c'est dans peu de chose que tu t'es montré fidèle, c'est sur beaucoup que je t'établirai. Entre dans la joie de ton seigneur.»
22 “Èyí tí ó gba tálẹ́ǹtì méjì wí pé ‘Olúwa, ìwọ fún mi ní tálẹ́ǹtì méjì láti lò, èmi sì ti jèrè tálẹ́ǹtì méjì mìíràn.’
S'approchant aussi, celui qui avait reçu les deux talents, dit: «Seigneur, tu m'as confié deux talents; en voici deux autres que j'ai gagnés.»
23 “Olúwa rẹ̀ sì wí fún un pé, ‘O ṣeun, ìwọ ọmọ ọ̀dọ̀ rere àti olóòtítọ́. Ìwọ ti jẹ́ olóòtítọ́ nínú ohun díẹ̀, èmi yóò fi ọ ṣe olórí ohun púpọ̀. Ìwọ bọ́ sínú ayọ̀ olúwa rẹ.’
Son maître lui dit: «Bien, serviteur bon et fidèle; c'est dans peu de chose que tu t'es montré fidèle, c'est sur beaucoup que je t'établirai. Entre dans la joie de ton seigneur.»
24 “Níkẹyìn, ọkùnrin tí a fún ní tálẹ́ǹtì kan wá, ó wí pé, ‘Olúwa, mo mọ̀ pé òǹrorò ènìyàn ni ìwọ ń ṣe ìwọ ń kórè níbi tí ìwọ kò gbìn sí, ìwọ ń kójọ níbi tí ìwọ kò ó ká sí.
Mais celui qui avait reçu un seul talent vint à son tour et dit: Seigneur, je savais que tu es un homme dur, tu moissonnes là où tu n'as pas semé, tu ramasses sur l'aire où tu n'as pas étendu de gerbes;
25 Èmi bẹ̀rù, mo sì lọ pa tálẹ́ǹtì rẹ mọ́ sínú ilẹ̀. Wò ó, nǹkan rẹ nìyìí.’
et, plein de crainte, je suis allé enfouir en terre ton talent. Le voilà; tu es en possession de ce qui t'appartient.»
26 “Ṣùgbọ́n olúwa rẹ̀ dáhùn pé, ‘Ìwọ ọmọ ọ̀dọ̀ búburú, ìwọ mọ̀ pé èmi ń kórè níbi tí èmi kò fúnrúgbìn sì, èmi sì ń kójọ níbi tí èmi kò fọ́nká ká sí.
Mais son maître lui répondit par ces paroles: «Mauvais serviteur! paresseux! tu savais que je moissonne là où je n'ai pas semé et que je ramasse sur l'aire où je n'ai pas étendu de gerbes.
27 Nígbà náà ìwọ ìbá kúkú fi owó mi sí ilé ìfowópamọ́ tí èmi bá dé èmi ìbá le gba owó mi pẹ̀lú èrè.
Il te fallait en conséquence placer ton argent chez les banquiers, et, à mon retour, j'aurais retiré ce qui est à moi avec un intérêt.
28 “‘Ó sì pàṣẹ kí a gba tálẹ́ǹtì náà lọ́wọ́ rẹ̀, kí a sì fún ọkùnrin tí ó ní tálẹ́ǹtì mẹ́wàá.
Donc, ôtez lui le talent et donnez-le à celui qui a les dix.
29 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá ní a ó fún sí i, yóò sí tún ní sí lọ́pọ̀lọ́pọ̀. Ṣùgbọ́n láti ọwọ́ ẹni tí kò ní ni a ó ti gbà èyí tí ó ní.
Car à tout homme qui a il sera donné, et il sera dans l'abondance; mais à celui qui n'a pas, même ce qu'il a lui sera ôté.
30 Nítorí ìdí èyí, gbé aláìlérè ọmọ ọ̀dọ̀, jù ú sínú òkùnkùn lóde, ibẹ̀ ni ẹ̀kún òun ìpayínkeke yóò gbé wà.’
Quant au serviteur inutile, jetez-le dehors, dans les ténèbres, — là seront les pleurs et le grincement des dents.
31 “Ṣùgbọ́n nígbà ti Ọmọ Ènìyàn yóò wá nínú ògo rẹ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn angẹli rẹ̀ nígbà náà ni yóò jókòó lórí ìtẹ́ ògo ní ọ̀run.
Lorsque le Fils de l'homme viendra dans sa gloire, et, avec lui, tous les anges, il s'assiéra sur son trône de gloire.
32 Gbogbo orílẹ̀-èdè ni a ó kójọ níwájú rẹ̀, òun yóò sì ya àwọn ènìyàn ayé sí ọ̀tọ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn ṣe é ya àgùntàn kúrò lára àwọn ewúrẹ́.
Devant lui seront rassemblées toutes les nations; et il séparera les uns d'avec les autres, comme le berger sépare les brebis d'avec les boucs;
33 Òun yóò sì fi àgùntàn sí ọwọ́ ọ̀tún àti ewúrẹ́ sí ọwọ́ òsì.
il placera les brebis à sa droite, les boucs à sa gauche.
34 “Nígbà náà ni ọba yóò wí fún àwọn tí ó wà lọ́wọ́ ọ̀tún pé, ‘Ẹ wá, ẹ̀yin tí Baba mi ti bùkún fún, ẹ jogún ìjọba tí a ti pèsè fún yín láti ìpilẹ̀ṣẹ̀ ayé.
Après quoi, le Roi dira à ceux qui seront à sa droite: «Venez, les bénis de mon Père! entrez en possession du Royaume qui vous a été préparé depuis la création du monde;
35 Nítorí ebi pa mi, ẹ̀yin sì fún mi ní oúnjẹ, òǹgbẹ gbẹ mí, ẹ̀yin sì fún mi ní omi. Mo jẹ́ àlejò, ẹ̀yin sì pè mí sínú ilé yín.
car j'ai eu faim, et vous m'avez donné à manger; j'ai eu soif, et vous m'avez donné à boire; j'étais étranger, et vous m'avez recueilli;
36 Mo wà ní ìhòhò, ẹ̀yin sì daṣọ bò mí. Nígbà tí mo ṣe àìsàn ẹ ṣe ìtójú mi, àti ìgbà tí mo wà ní ọgbà ẹ̀wọ̀n ẹ̀yin bẹ̀ mí wò.’
nu, et vous m'avez vêtu; malade, et vous m'avez visité; en prison, et vous êtes venus près de moi.»
37 “Nígbà náà ni àwọn olódodo yóò fèsì pé, ‘Olúwa, nígbà wo ni àwa rí ọ tí ebi ń pa ọ́, tí a sì fún ọ ní oúnjẹ? Tàbí tí òǹgbẹ ń gbẹ ọ́ tí a sì fún ọ ní ohun mímu?
Les justes alors lui répondront par ces paroles: «Seigneur, quand est-ce que nous t'avons vu avoir faim et que nous t'avons nourri? Avoir soif et que nous t'avons donné à boire?
38 Tàbí tí o jẹ́ àlejò tí a gbà ó sínú ilé wa? Tàbí tí o wà ní ìhòhò, tí a sì daṣọ bò ọ́?
Quand est-ce que, te voyant étranger, nous t'avons recueilli; que, te voyant dans la nudité, nous t'avons vêtu?
39 Nígbà wo ni a tilẹ̀ rí i tí o ṣe àìsàn, tàbí tí o wà ní ọgbà ẹ̀wọ̀n, tí a bẹ̀ ọ́ wò?’
Quand est-ce que nous t'avons vu malade ou en prison et que nous sommes venus près de toi?»
40 “Ọba náà yóò sì dáhùn yóò sì wí fún wọn pé, ‘Lóòótọ́ ni mo wí fún yín pé níwọ̀n ìgbà tí ẹ̀yin ṣe nǹkan wọ̀nyí fún àwọn arákùnrin mi yìí tí o kéré jú lọ, ẹ̀ ń ṣe wọn fún mi ni.’
Et le Roi leur fera cette réponse: «En vérité, je vous le dis, toutes les fois que vous avez fait cela à un seul des plus petits parmi mes frères que voici, c'est à moi que vous l'avez fait.»
41 “Nígbà náà ni yóò sọ fún àwọn tí ọwọ́ òsì pé, ‘Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin ẹni ègún, sínú iná àìnípẹ̀kun tí a ti tọ́jú fún èṣù àti àwọn angẹli rẹ̀. (aiōnios g166)
Puis il dira à ceux qui seront à sa gauche: «Allez loin de moi, maudits, dans le feu éternel préparé pour le diable et ses anges. (aiōnios g166)
42 Nítorí tí ebi pa mi, ẹ̀yin kò tilẹ̀ bọ́ mi, òrùngbẹ gbẹ mi, ẹ kò tilẹ̀ fún mi ní omi láti mu.
Car j'ai eu faim et vous ne m'avez pas donné à manger; j’ai eu soif et vous ne m'avez pas donné à boire;
43 Mo jẹ́ àlejò, ẹ̀yin kò tilẹ̀ gbà mi sílé. Mo wà ní ìhòhò, ẹ̀yin kò fi aṣọ bò mi. Mo ṣàìsàn, mo sì wà lọ́gbà ẹ̀wọ̀n, ẹ̀yin kò bẹ̀ mí wò.’
j'étais étranger et vous ne m'avez pas recueilli; nu et vous ne m'avez pas vêtu; malade et en prison et vous ne m'avez pas visité.»
44 “Nígbà náà àwọn pẹ̀lú yóò dáhùn pé, ‘Olúwa, nígbà wo ni àwa rí ọ, tí ebi ń pa ọ́ tàbí tí òǹgbẹ ń gbẹ ọ́, tàbí tí o ṣàìsàn, tàbí tí o wà lọ́gbà ẹ̀wọ̀n, tí a kò sí ràn ọ́ lọ́wọ́?’
Alors ils répondront, eux aussi, par ces paroles: «Seigneur, quand est-ce que nous t'avons vu avoir faim, avoir soif, être étranger ou nu, ou malade, ou en prison, et que nous ne t'avons pas assisté?»
45 “Nígbà náà àwọn yóò dáhùn pé, ‘Lóòótọ́ ni mo wí fún pé, nígbà tí ẹ̀yin ti kọ̀ láti ran ọ̀kan nínú àwọn tí ó kéré jù lọ́wọ́ nínú arákùnrin mi, ẹ̀yin tí kọ̀ láti ṣe ìrànlọ́wọ́ fún mi ni.’
Mais il leur fera cette réponse: «En vérité, je vous le dis, toutes les fois que vous n'avez pas fait cela à un seul de ces plus petits, que voici, c'est à moi que vous ne l'avez pas fait.
46 “Nígbà náà wọn yóò sì kọjá lọ sínú ìyà àìnípẹ̀kun, ṣùgbọ́n àwọn olódodo yóò lọ sí ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōnios g166)
Et ceux-là s'en iront à un châtiment éternel et les justes à une vie éternelle.» (aiōnios g166)

< Matthew 25 >