< Matthew 24 >

1 Bí Jesu ti ń kúrò ni tẹmpili, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n fẹ́ fi ẹwà tẹmpili náà hàn án.
Ла еширя дин Темплу, пе кынд мерӂя Исус, ученичий Луй с-ау апропият де Ел ка сэ-Й арате клэдириле Темплулуй.
2 Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin kò ha rí gbogbo nǹkan wọ̀nyí? Lóòótọ́ ni mo wí fún yín gbogbo ilé yìí ni a yóò wó lulẹ̀, kò ní sí òkúta kan tí a ó fi sílẹ̀ lórí òmíràn, tí a kì yóò wó lulẹ̀.”
Дар Исус ле-а зис: „Ведець вой тоате ачесте лукрурь? Адевэрат вэ спун кэ нува рэмыне аич пятрэ пе пятрэ каре сэ ну фие дэрыматэ.”
3 Bí ó ti jókòó ní orí òkè Olifi, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn tọ̀ ọ́ wá ní ìkọ̀kọ̀, wọ́n wí pé, “Sọ fún wa nígbà wo ni èyí yóò ṣẹlẹ̀? Kí ni yóò jẹ́ àmì ìpadà wá rẹ, àti ti òpin ayé?” (aiōn g165)
Ел а шезут жос, пе Мунтеле Мэслинилор. Ши ученичий Луй ау венит ла Ел, ла о парте, ши Й-ау зис: „Спуне-не, кынд се вор ынтымпла ачесте лукрурь? Ши каре ва фи семнул венирий Тале ши ал сфыршитулуй вякулуй ачестуя?” (aiōn g165)
4 Jesu dá wọn lóhùn pé, “Ẹ má ṣe jẹ́ kí ẹnikẹ́ni tàn yín jẹ.
Дрепт рэспунс, Исус ле-а зис: „Бэгаць де сямэсэ ну вэ ыншеле чинева.
5 Nítorí ọ̀pọ̀ yóò wá ní orúkọ mi tí wọn yóò máa pe ara wọn ní Kristi náà. Wọn yóò ṣi ọ̀pọ̀lọpọ̀ lọ́nà.
Фииндкэвор вени мулць ын Нумеле Меу ши вор зиче: ‘Еу сунт Христосул!’ Шивор ыншела пе мулць.
6 Ẹ ó máa gbọ́ ìró ogun àti ìdágìrì ogun, kí ẹ̀yin má ṣe jáyà nítorí nǹkan wọ̀nyí kò lè ṣe kí ó ma ṣẹlẹ̀, ṣùgbọ́n òpin kì í ṣe àkókò náà.
Вець аузи де рэзбоае ши вешть де рэзбоае: ведець сэ ну вэ ынспэймынтаць, кэч тоате ачесте лукрурь требуе сэ се ынтымпле. Дар сфыршитул тот ну ва фи атунч.
7 Orílẹ̀-èdè yóò dìde sí orílẹ̀-èdè, àti ìjọba sí ìjọba. Ìyàn àti ilẹ̀ mímì yóò wà ní ibi púpọ̀.
Унням се ва скула ымпотрива алтуй ням, ши о ымпэрэцие, ымпотрива алтей ымпэрэций ши, пе алокурь, вор фи кутремуре де пэмынт, фоамете ши чумь.
8 Ṣùgbọ́n gbogbo nǹkan wọ̀nyí sì jẹ́ ìbẹ̀rẹ̀ ìpọ́njú tí ó ń bọ̀.
Дар тоате ачесте лукрурь ну вор фи декыт ынчепутул дурерилор.
9 “Nígbà náà ni a ó sì dá a yín lóró. A ó pa yín, a ó sì kórìíra yín ni gbogbo orílẹ̀-èdè, nítorí pé ẹ̀yin jẹ́ tèmi.
Атунчвэ вор да сэ фиць кинуиць ши вэ вор оморы; ши вець фи урыць де тоате нямуриле пентру Нумеле Меу.
10 Àti pé, ọ̀pọ̀ nínú yín yóò kọsẹ̀, ẹ̀yin yóò ṣòfófó ara yín, ẹ̀yin yóò kórìíra ara yín pẹ̀lú,
Атунч, мулць воркэдя, се вор винде уний пе алций ши се вор уры уний пе алций.
11 ọ̀pọ̀ àwọn èké wòlíì yóò farahàn, wọn yóò tan ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn jẹ.
Се вор скула мулцьпророчь минчиношь ши ворыншела пе мулць.
12 Ẹ̀ṣẹ̀ yóò wà níbi gbogbo, yóò sì sọ ìfẹ́ ọ̀pọ̀ di tútù,
Ши, дин причина ынмулцирий фэрэделеӂий, драгостя челор май мулць се ва рэчи.
13 ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá forítì í dópin ni a ó gbàlà.
Дарчине ва рэбда пынэ ла сфыршит ва фи мынтуит.
14 A ó sì wàásù ìyìnrere nípa ìjọba náà yìí ní gbogbo ayé ká, láti ṣe ẹ̀rí fún gbogbo orílẹ̀-èdè, nígbà náà ni òpin yóò dé.
Евангелияачаста а Ымпэрэцией вафи проповэдуитэ ын тоатэ лумя, ка сэ служяскэ де мэртурие тутурор нямурилор. Атунч ва вени сфыршитул.
15 “Nítorí náà, nígbà tí ẹ̀yin bá rí ìríra ‘ìsọdahoro, tí a ti ẹnu wòlíì Daniẹli sọ,’ tí ó bá dúró ní ibi mímọ́ (ẹnikẹ́ni tí ó bá kà á kí ó yé e),
Де ачея, кынд вець ведя урычуня пустиирий, деспре каре а ворбит пророкул Даниел, ашезатэ ын Локул Сфынт – чине читеште сэ ынцелягэ! –
16 nígbà náà ni kí àwọn tí ń bẹ ni Judea sálọ sí orí òkè.
атунч, чей че вор фи ын Иудея сэ фугэ ла мунць;
17 Kí ẹni tí ó wà lórí ilé rẹ̀ má ṣe sọ̀kalẹ̀ wá mú ohunkóhun jáde nínú ilé rẹ̀.
чине ва фи пе акоперишул касей сэ ну се кобоаре сэ-шь я лукруриле дин касэ;
18 Kí àwọn tí ó sì wà lóko má ṣe darí wá sí ilé láti mú àwọn aṣọ wọn.
ши чине ва фи ла кымп сэ ну се ынтоаркэ сэ-шь я хайна.
19 Ṣùgbọ́n àánú ṣe mí fún àwọn obìnrin ti ó lóyún, àti fún àwọn tí ó ń fún ọmọ loyan ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì!
Вайде фемеиле каре вор фи ынсэрчинате ши де челе че вор да цыцэ ын зилеле ачеля!
20 Ẹ sì máa gbàdúrà kí sísá yín má ṣe jẹ́ ìgbà òtútù, tàbí ọjọ́ ìsinmi.
Ругаци-вэ ка фуга воастрэ сэ ну фие ярна, нич ынтр-о зи де Сабат.
21 Nítorí ìpọ́njú ńlá yóò wà, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ láti ìgbà ìbẹ̀rẹ̀ ọjọ́ ayé wá títí di ìsinsin yìí irú rẹ̀ kì yóò sì ṣí.
Пентру кэатунч ва фи ун неказ аша де маре, кум н-а фост ничодатэ де ла ынчепутул лумий пынэ акум ши нич ну ва май фи.
22 “Lóòótọ́, àfi bí a ké ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì kúrú, gbogbo ẹ̀dá alààyè yóò ṣègbé. Ṣùgbọ́n nítorí ti àwọn àyànfẹ́ ni a ó fi ké ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì kúrú.
Ши дакэ зилеле ачеля н-ар фи фост скуртате, нимень н-ар скэпа; дар, дин причина челор алешь, зилеле ачеля вор фи скуртате.
23 Nígbà náà, bí ẹnikẹ́ni bá sọ fún yín pé, ‘Wo Kristi náà,’ tàbí pé ó ti farahàn níhìn-ín tàbí lọ́hùn ún, ẹ má ṣe gbà á gbọ́.
Атунч, дакэ вэ ва спуне чинева: ‘Ятэ, Христосул есте аич сау аколо!’, сэ ну-л кредець.
24 Nítorí àwọn èké Kristi àti àwọn èké wòlíì yóò dìde. Wọn yóò sì ṣe ọ̀pọ̀ iṣẹ́ àmì àti ìyanu. Bí ó bá lè ṣe é ṣe wọn yóò tan àwọn àyànfẹ́ Ọlọ́run pàápàá jẹ.
Кэч севор скула христошь минчиношь ши пророчь минчиношь, вор фаче семне марь ши минунь, пынэ аколо ынкыт сэ ыншеле, дакэ ва фи ку путинцэ, кяр ши пе чей алешь.
25 Wò ó, mo ti kìlọ̀ fún yín tẹ́lẹ̀.
Ятэ кэ в-ам спус май динаинте.
26 “Nítorí náà, bí ẹnìkan bá sọ fún yín pé, ‘Olùgbàlà ti dé,’ àti pé, ‘Ó wà ní aginjù,’ ẹ má ṣe wàhálà láti lọ wò ó, tàbí tí wọ́n bá ní, ó ń fi ara pamọ́ sí iyàrá,” ẹ má ṣe gbà wọn gbọ́.
Деч, дакэ вэ вор зиче: ‘Ятэ-Л ын пустиу’, сэ ну вэ дучець аколо! ‘Ятэ-Л ын одэице аскунсе’, сэ ну кредець.
27 Nítorí bí mọ̀nàmọ́ná ti ń tàn láti ìlà-oòrùn títí dé ìwọ̀-oòrùn, bẹ́ẹ̀ ni wíwá Ọmọ Ènìyàn yóò jẹ́.
Кэч, кум есе фулӂерул де ла рэсэрит ши се веде пынэ ла апус, аша ва фи ши вениря Фиулуй омулуй.
28 Nítorí ibikíbi tí òkú bá gbé wà, ibẹ̀ ni àwọn ẹyẹ igún ń kójọpọ̀ sí.
Орьундева фи стырвул, аколо се вор адуна вултурий.
29 “Lójúkan náà, lẹ́yìn ìpọ́njú ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì, “‘ni oòrùn yóò ṣókùnkùn, òṣùpá kì yóò sì fi ìmọ́lẹ̀ rẹ hàn; àwọn ìràwọ̀ ojú ọ̀run yóò já sílẹ̀, agbára ojú ọ̀run ni a ó mì tìtì.’
Ындатэдупэ ачеле зиле де неказ, соареле сева ынтунека, луна ну-шь ва май да лумина ей, стелеле вор кэдя дин чер ши путериле черурилор вор фи клэтинате.
30 “Nígbà náà ni àmì Ọmọ Ènìyàn yóò sì fi ara hàn ní ọ̀run, nígbà náà ni gbogbo ẹ̀yà ayé yóò káàánú, wọn yóò sì rí Ọmọ Ènìyàn tí yóò máa ti ojú ọ̀run bọ̀ ti òun ti ògo àti agbára ńlá.
Атунчсе ва арэта ын чер семнул Фиулуй омулуй, тоатесеминцииле пэмынтулуй се вор бочи шивор ведя пе Фиул омулуй венинд пе норий черулуй ку путере ши ку о маре славэ.
31 Yóò sì rán àwọn angẹli rẹ̀ jáde pẹ̀lú ohùn ìpè ńlá, wọn yóò sì kó gbogbo àwọn àyànfẹ́ rẹ̀ láti orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin ayé àti ọ̀run jọ.
Елва тримите пе ынӂерий Сэй ку трымбица рэсунэтоаре ши вор адуна пе алеший Луй дин челе патру вынтурь, де ла о марӂине а черурилор пынэ ла чялалтэ.
32 “Nísinsin yìí, ẹ kọ́ òwe lára igi ọ̀pọ̀tọ́. Nígbà tí ẹ̀ka rẹ̀ bá ti ń yọ tuntun tí ó bá sì ń ru ewé, ẹ̀yin mọ̀ pé ìgbà ẹ̀ẹ̀rùn súnmọ́ tòsí.
Де ла смокин ынвэцаць пилдалуй: Кынд ый фрэӂезеште ши ынфрунзеште млэдица, штиць кэвара есте апроапе.
33 Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́, nígbà tí ẹ̀yin bá sì rí i tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí bá ń ṣẹlẹ̀, kí ẹ mọ̀ pé ìpadàbọ̀ mi dé tán lẹ́yìn ìlẹ̀kùn.
Тот аша, ши вой, кынд вець ведя тоате ачесте лукрурь, сэ штиць кэ Фиул омулуй есте апроапе, есте кяр ла ушь.
34 Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, ìran yìí kì yóò kọjá títí tí gbogbo nǹkan wọ̀nyí yóò fi ṣẹ.
Адевэрат вэ спун кэ нува трече нямул ачеста пынэ се вор ынтымпла тоате ачесте лукрурь.
35 Ọ̀run àti ayé yóò rékọjá, ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ mi kì yóò rékọjá.
Черулши пэмынтул вор трече, дар кувинтеле Меле ну вор трече.
36 “Ṣùgbọ́n kò sí ẹnìkan ti ó mọ ọjọ́ àti wákàtí tí òpin náà yóò dé, àwọn angẹli ọ̀run pàápàá kò mọ̀ ọ́n. Àní, ọmọ kò mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe Baba mi nìkan ṣoṣo ló mọ̀ ọ́n.
Деспре зиуа ачея ши деспре часул ачела, ну штие нимень: нич ынӂерий дин черурь, нич Фиул, чи нумайТатэл.
37 Bí ó ṣe rí ní ìgbà ayé Noa, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni wíwá Ọmọ Ènìyàn yóò sì rí.
Кум с-а ынтымплат ын зилеле луй Ное, аидома се ва ынтымпла ши ла вениря Фиулуй омулуй.
38 Nítorí bí àwọn ọjọ́ náà ti wà ṣáájú ìkún omi, tí wọ́n ń jẹ́ tí wọ́n ń mu, tí wọ́n ń gbéyàwó, tí wọ́n sì ń fa ìyàwó fún ni, títí tí ó fi di ọjọ́ tí Noa fi bọ́ sínú ọkọ̀.
Ын адевэр, кумера ын зилеле динаинте де потоп, кынд мынкау ши бяу, се ынсурау ши се мэритау пынэ ын зиуа кынд а интрат Ное ын корабие
39 Ènìyàn kò gbàgbọ́ nípa ohun tí o ṣẹlẹ̀ títí tí ìkún omi fi dé nítòótọ́, tí ó sì kó wọn lọ. Bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni wíwá Ọmọ Ènìyàn.
ши н-ау штиут нимик, пынэ кынд а венит потопул ши й-а луат пе тоць, тот аша ва фи ши ла вениря Фиулуй омулуй.
40 Àwọn ọkùnrin méjì yóò máa ṣiṣẹ́ nínú oko, a o mú ẹnìkan, a ó sì fi ẹni kejì sílẹ̀.
Атунч, дин дой бэрбаць каре вор фи ла кымп, унул ва фи луат ши алтул ва фи лэсат.
41 Àwọn obìnrin méjì yóò jùmọ̀ máa lọ ọlọ pọ̀, a yóò mú ọ̀kan, a ó fi ẹni kejì sílẹ̀.
Дин доуэ фемей каре вор мэчина ла моарэ, уна ва фи луатэ ши алта ва фи лэсатэ.
42 “Nítorí náà, ẹ múra sílẹ̀, nítorí ẹ kò mọ ọjọ́ tí Olúwa yín yóò dé.
Вегяць дар, пентру кэ ну штиць ын че зи ва вени Домнул востру.
43 Ṣùgbọ́n, kí ẹ mọ èyí pé, baálé ilé ìbá mọ wákàtí náà tí olè yóò wá, ìbá máa ṣọ́nà, òun kì bá ti jẹ́ kí a já wọ ilé rẹ̀.
Сэ штицькэ, дакэ ар шти стэпынул касей ла че стражэ дин ноапте ва вени хоцул, ар вегя ши н-ар лэса сэ-й спаргэ каса.
44 Nítorí náà, ẹ gbọdọ̀ wà ní ìmúrasílẹ̀, nítorí ní wákàtí àìròtẹ́lẹ̀ ni dídé Ọmọ Ènìyàn yóò jẹ́.
Де ачея, ши вой фиць гата; кэч Фиул омулуй ва вени ын часул ын каре ну вэ гындиць.
45 “Ǹjẹ́ olóòtítọ́ àti ọlọ́gbọ́n ọmọ ọ̀dọ̀ wo ni olúwa rẹ̀ lè fi ṣe olùbojútó ilé rẹ̀ láti bọ́ àwọn ọmọ rẹ̀ lójoojúmọ́?
Каре есте дечробул крединчос ши ынцелепт, пе каре л-а пус стэпынул сэу песте чата слуӂилор сале, ка сэ ле дя храна ла время хотэрытэ?
46 Alábùkún fún ni ọmọ ọ̀dọ̀ ti olúwa rẹ̀ dé tí ó sì bá a lórí iṣẹ́ ṣíṣe.
Феричеде робул ачела пе каре стэпынул сэу, ла вениря луй, ыл ва гэси фэкынд аша!
47 Lóòótọ́ ni mo wí fún yín, èmi yóò sì fi irú ẹni bẹ́ẹ̀ ṣe alákòóso gbogbo ohun tí mo ní.
Адевэрат вэ спун кэыл ва пуне песте тоате авериле сале.
48 Ṣùgbọ́n bí ọmọ ọ̀dọ̀ náà bá jẹ́ ènìyàn búburú náà bá wí ní ọkàn rẹ̀ pé, ‘Olúwa mi kì yóò tètè dé.’
Дар, дакэ есте ун роб рэу, каре зиче ын инима луй: ‘Стэпынул меу зэбовеште сэ винэ!’
49 Tí ó sì bẹ̀rẹ̀ si í fi ìyà jẹ́ àwọn ìránṣẹ́ ẹlẹgbẹ́ rẹ̀, tí ó ń jẹ, tí ó sì ń mu àmupara.
Дакэ ва ынчепе сэ батэ пе товарэший луй де службэ ши сэ мэнынче ши сэ бя ку бецивий,
50 Nígbà náà ni olúwa ọmọ ọ̀dọ̀ yóò wá ní ọjọ́ àti wákàtí tí kò retí.
стэпынул робулуй ачелуя ва вени ын зиуа ын каре ел ну се аштяптэ ши ын часул пе каре ну-л штие,
51 Yóò sì jẹ ẹ́ ní ìyà gidigidi, yóò sì rán an sí ibùgbé àwọn àgàbàgebè, níbẹ̀ ni ẹkún àti ìpayínkeke yóò wà.
ыл ва тэя ын доуэ, ши соарта луй ва фи соарта фэцарничилор; аколовор фи плынсул ши скрышниря динцилор.

< Matthew 24 >

The World is Destroyed by Water
The World is Destroyed by Water