< Matthew 20 >

1 “Nítorí ìjọba ọ̀run dàbí ọkùnrin tí ó jẹ́ baálé kan, tí ó jíjáde lọ ní kùtùkùtù òwúrọ̀, tí ó gba àwọn alágbàṣe sínú ọgbà àjàrà rẹ̀.
སྭརྒརཱཛྱམ྄ ཨེཏཱདྲྀཤཱ ཀེནཙིད྄ གྲྀཧསྱེན སམཾ, ཡོ྅ཏིཔྲབྷཱཏེ ནིཛདྲཱཀྵཱཀྵེཏྲེ ཀྲྀཥཀཱན྄ ནིཡོཀྟུཾ གཏཝཱན྄།
2 Òun pinnu láti san dínárì kan fún iṣẹ́ òòjọ́ kan. Lẹ́yìn èyí ó sì rán wọn lọ sínú ọgbà àjàrà rẹ̀.
པཤྩཱཏ྄ ཏཻཿ སཱཀཾ དིནཻཀབྷྲྀཏིཾ མུདྲཱཙཏུརྠཱཾཤཾ ནིརཱུཔྱ ཏཱན྄ དྲཱཀྵཱཀྵེཏྲཾ པྲེརཡཱམཱས།
3 “Ní wákàtí kẹta ọjọ́ bí ó ti ń kọjá níwájú ilé ìgbanisíṣẹ́, ó rí díẹ̀ nínú àwọn aláìríṣẹ́ tí wọ́n dúró ní ọjà.
ཨནནྟརཾ པྲཧརཻཀཝེལཱཡཱཾ གཏྭཱ ཧཊྚེ ཀཏིཔཡཱན྄ ནིཥྐརྨྨཀཱན྄ ཝིལོཀྱ ཏཱནཝདཏ྄,
4 Ó wí fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin pàápàá, ẹ lọ ṣiṣẹ́ nínú ọgbà àjàrà mi, bí ó bá sì di òpin ọjọ́, èmi yóò san iye ti ó bá yẹ fún yín.’
ཡཱུཡམཔི མམ དྲཱཀྵཱཀྵེཏྲཾ ཡཱཏ, ཡུཥྨབྷྱམཧཾ ཡོགྱབྷྲྀཏིཾ དཱསྱཱམི, ཏཏསྟེ ཝཝྲཛུཿ།
5 Wọ́n sì lọ. “Ó tún jáde lọ́sàn án ní nǹkan bí wákàtí kẹfà àti wákàtí kẹsànán, ó túnṣe bákan náà.
པུནཤྩ ས དྭིཏཱིཡཏྲྀཏཱིཡཡོཿ པྲཧརཡོ རྦཧི རྒཏྭཱ ཏཐཻཝ ཀྲྀཏཝཱན྄།
6 Lọ́jọ́ kan náà ní wákàtí kọkànlá ọjọ́, ó tún jáde sí àárín ìlú, ó sì rí àwọn aláìríṣẹ́ mìíràn tí wọ́n dúró. Ó bi wọ́n pé, ‘Èéṣe tí ẹ̀yin kì í ṣiṣẹ́ ní gbogbo ọjọ́?’
ཏཏོ དཎྜདྭཡཱཝཤིཥྚཱཡཱཾ ཝེལཱཡཱཾ བཧི རྒཏྭཱཔརཱན྄ ཀཏིཔཡཛནཱན྄ ནིཥྐརྨྨཀཱན྄ ཝིལོཀྱ པྲྀཥྚཝཱན྄, ཡཱུཡཾ ཀིམརྠམ྄ ཨཏྲ སཪྻྭཾ དིནཾ ནིཥྐརྨྨཱཎསྟིཥྛཐ?
7 “Wọ́n sì dáhùn pé, ‘Nítorí pé kò sí ẹni tí yóò fún wa ní iṣẹ́ ṣe.’ “Ó tún sọ fún wọn pé, ‘Ẹ̀yin náà ẹ jáde lọ ṣiṣẹ́ pẹ̀lú nínú ọgbà àjàrà mi.’
ཏེ པྲཏྱཝདན྄, ཨསྨཱན྄ ན ཀོཔི ཀརྨམཎི ནིཡུཾཀྟེ། ཏདཱནཱིཾ ས ཀཐིཏཝཱན྄, ཡཱུཡམཔི མམ དྲཱཀྵཱཀྵེཏྲཾ ཡཱཏ, ཏེན ཡོགྱཱཾ བྷྲྀཏིཾ ལཔྶྱཐ།
8 “Nígbà tí ó di àṣálẹ́, ẹni tó ni ọgbà àjàrà sọ fún aṣojú rẹ̀ pé, ‘Pe àwọn òṣìṣẹ́ náà, kí ó san owó iṣẹ́ wọn fún wọn, bẹ̀rẹ̀ láti ẹni ìkẹyìn lọ sí ti ìṣáájú.’
ཏདནནྟརཾ སནྡྷྱཱཡཱཾ སཏྱཱཾ སཨེཝ དྲཱཀྵཱཀྵེཏྲཔཏིརདྷྱཀྵཾ གདིཝཱན྄, ཀྲྀཥཀཱན྄ ཨཱཧཱུཡ ཤེཥཛནམཱརབྷྱ པྲཐམཾ ཡཱཝཏ྄ ཏེབྷྱོ བྷྲྀཏིཾ དེཧི།
9 “Nígbà tí àwọn ti a pè ní wákàtí kọkànlá ọjọ́ dé, ẹnìkọ̀ọ̀kan gba owó dínárì kan.
ཏེན ཡེ དཎྜདྭཡཱཝསྠིཏེ སམཱཡཱཏཱསྟེཥཱམ྄ ཨེཀཻཀོ ཛནོ མུདྲཱཙཏུརྠཱཾཤཾ པྲཱཔྣོཏ྄།
10 Nígbà tí àwọn tí a gbà ṣiṣẹ́ lákọ̀ọ́kọ́ fẹ́ gba owó tiwọn, èrò wọn ni pé àwọn yóò gba jù bẹ́ẹ̀ lọ, ṣùgbọ́n ẹnìkọ̀ọ̀kan wọn gba owó dínárì kan.
ཏདཱནཱིཾ པྲཐམནིཡུཀྟཱ ཛནཱ ཨཱགཏྱཱནུམིཏཝནྟོ ཝཡམདྷིཀཾ པྲཔྶྱཱམཿ, ཀིནྟུ ཏཻརཔི མུདྲཱཙཏུརྠཱཾཤོ྅ལཱབྷི།
11 Bí wọ́n ti ń gbà á, wọ́n ń kùn sí onílẹ̀ náà,
ཏཏསྟེ ཏཾ གྲྀཧཱིཏྭཱ ཏེན ཀྵེཏྲཔཏིནཱ སཱཀཾ ཝཱགྱུདྡྷཾ ཀུཪྻྭནྟཿ ཀཐཡཱམཱསུཿ,
12 pé, ‘Wákàtí kan péré ni àwọn tí a gbà kẹ́yìn fi ṣiṣẹ́, ìwọ sì san iye kan náà fún wọn àti àwa náà ti a fi gbogbo ọjọ́ ṣiṣẹ́ nínú oòrùn gangan.’
ཝཡཾ ཀྲྀཏྶྣཾ དིནཾ ཏཱཔཀླེཤཽ སོཌྷཝནྟཿ, ཀིནྟུ པཤྩཱཏཱཡཱ སེ ཛནཱ དཎྜདྭཡམཱཏྲཾ པརིཤྲཱནྟཝནྟསྟེ྅སྨཱབྷིཿ སམཱནཱཾཤཱཿ ཀྲྀཏཱཿ།
13 “Ṣùgbọ́n ó dá ọ̀kan nínú wọn lóhùn pé, ‘Ọ̀rẹ́, kò sí aburú nínú nǹkan tí èmi ṣe sí yín. Kì í ha ṣe pé ẹ̀yin gbà láti ṣiṣẹ́ fún owó dínárì kan.
ཏཏཿ ས ཏེཥཱམེཀཾ པྲཏྱུཝཱཙ, ཧེ ཝཏྶ, མཡཱ ཏྭཱཾ པྲཏི ཀོཔྱནྱཱཡོ ན ཀྲྀཏཿ ཀིཾ ཏྭཡཱ མཏྶམཀྵཾ མུདྲཱཙཏུརྠཱཾཤོ ནཱངྒཱིཀྲྀཏཿ?
14 Ó ní, gba èyí tí í ṣé tìrẹ, ki ó sì máa lọ. Èmi fẹ́ láti fún ẹni ìkẹyìn gẹ́gẹ́ bí mo ti fi fún ọ.
ཏསྨཱཏ྄ ཏཝ ཡཏ྄ པྲཱཔྱཾ ཏདཱདཱཡ ཡཱཧི, ཏུབྷྱཾ ཡཏི, པཤྩཱཏཱིཡནིཡུཀྟལོཀཱཡཱཔི ཏཏི དཱཏུམིཙྪཱམི།
15 Àbí ó lòdì sí òfin pé kí èmi fún ẹnikẹ́ni ní owó mi bí mo bá yàn láti ṣe bẹ́ẹ̀? Kí ni ìdí tí ìwọ ní láti bínú nítorí èmi ṣe ohun rere?’
སྭེཙྪཡཱ ནིཛདྲཝྱཝྱཝཧརཎཾ ཀིཾ མཡཱ ན ཀརྟྟཝྱཾ? མམ དཱཏྲྀཏྭཱཏ྄ ཏྭཡཱ ཀིམ྄ ཨཱིརྵྱཱདྲྀཥྚིཿ ཀྲིཡཏེ?
16 “Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ẹni ìkẹyìn yóò di ẹni ìṣáájú, ẹni ìṣáájú yóò sì di ẹni ìkẹyìn.”
ཨིཏྠམ྄ ཨགྲཱིཡལོཀཱཿ པཤྩཏཱིཡཱ བྷཝིཥྱནྟི, པཤྩཱཏཱིཡཛནཱཤྩགྲཱིཡཱ བྷཝིཥྱནྟི, ཨཧཱུཏཱ བཧཝཿ ཀིནྟྭལྤེ མནོབྷིལཥིཏཱཿ།
17 Bí Jesu ti ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu, ó pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ méjìlá sí apá kan ó sì wí pé,
ཏདནནྟརཾ ཡཱིཤུ ཪྻིརཱུཤཱལམྣགརཾ གཙྪན྄ མཱརྒམདྷྱེ ཤིཥྱཱན྄ ཨེཀཱནྟེ ཝབྷཱཥེ,
18 “Wò ó, àwa ń gòkè lọ sí Jerusalẹmu. Ó sọ fún wọn pé, a ó fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́ òfin lọ́wọ́, wọn yóò sì dá mi lẹ́bi ikú.
པཤྱ ཝཡཾ ཡིརཱུཤཱལམྣགརཾ ཡཱམཿ, ཏཏྲ པྲདྷཱནཡཱཛཀཱདྷྱཱཔཀཱནཱཾ ཀརེཥུ མནུཥྱཔུཏྲཿ སམརྤིཥྱཏེ;
19 Wọn yóò sì fà á lé àwọn kèfèrí lọ́wọ́ láti fi ṣe ẹlẹ́yà àti láti náà án, àti láti kàn mi mọ́ àgbélébùú, ní ọjọ́ kẹta, yóò jí dìde.”
ཏེ ཙ ཏཾ ཧནྟུམཱཛྙཱཔྱ ཏིརསྐྲྀཏྱ ཝེཏྲེཎ པྲཧརྟྟུཾ ཀྲུཤེ དྷཱཏཡིཏུཉྩཱནྱདེཤཱིཡཱནཱཾ ཀརེཥུ སམརྤཡིཥྱནྟི, ཀིནྟུ ས ཏྲྀཏཱིཡདིཝསེ ཤྨཤཱནཱད྄ ཨུཏྠཱཔིཥྱཏེ།
20 Nígbà náà ni ìyá àwọn ọmọ Sebede bá àwọn ọmọ rẹ̀ wá sọ́dọ̀ Jesu, ó wólẹ̀ lórí eékún rẹ̀, o béèrè fún ojúrere rẹ̀.
ཏདཱནཱིཾ སིཝདཱིཡསྱ ནཱརཱི སྭཔུཏྲཱཝཱདཱཡ ཡཱིཤོཿ སམཱིཔམ྄ ཨེཏྱ པྲཎམྱ ཀཉྩནཱནུགྲཧཾ ཏཾ ཡཡཱཙེ།
21 Jesu béèrè pé, “Kí ni ìwọ ń fẹ́?” Ó sì dáhùn pé, “Jẹ́ kí àwọn ọmọ mi méjèèjì jókòó ní apá ọ̀tún àti apá òsì lórí ìtẹ́ ìjọba rẹ?”
ཏདཱ ཡཱིཤུསྟཱཾ པྲོཀྟཝཱན྄, ཏྭཾ ཀིཾ ཡཱཙསེ? ཏཏཿ སཱ བབྷཱཥེ, བྷཝཏོ རཱཛཏྭེ མམཱནཡོཿ སུཏཡོརེཀཾ བྷཝདྡཀྵིཎཔཱརྴྭེ དྭིཏཱིཡཾ ཝཱམཔཱརྴྭ ཨུཔཝེཥྚུམ྄ ཨཱཛྙཱཔཡཏུ།
22 Ṣùgbọ́n Jesu dáhùn ó sì wí pé, “Ẹ̀yin kò mọ ohun tí ẹ̀yin ń béèrè, ẹ̀yin ha le mu nínú ago tí èmi ó mu?” Wọ́n dáhùn pé, “Àwa lè mu ún.”
ཡཱིཤུཿ པྲཏྱུཝཱཙ, ཡུཝཱབྷྱཱཾ ཡད྄ ཡཱཙྱཏེ, ཏནྣ བུདྷྱཏེ, ཨཧཾ ཡེན ཀཾསེན པཱསྱཱམི ཡུཝཱབྷྱཱཾ ཀིཾ ཏེན པཱཏུཾ ཤཀྱཏེ? ཨཧཉྩ ཡེན མཛྫེནེན མཛྫིཥྱེ, ཡུཝཱབྷྱཱཾ ཀིཾ ཏེན མཛྫཡིཏུཾ ཤཀྱཏེ? ཏེ ཛགདུཿ ཤཀྱཏེ།
23 Jesu sì wí fún wọn pé, “Dájúdájú, ẹ̀yin yóò mu nínú ago mi, ṣùgbọ́n èmi kò ní àṣẹ láti sọ irú ènìyàn tí yóò jókòó ní apá ọ̀tún tàbí apá òsì. Baba mi ti pèsè ààyè wọ̀n-ọn-nì sílẹ̀ fún kìkì àwọn tí ó yàn.”
ཏདཱ ས ཨུཀྟཝཱན྄, ཡུཝཱཾ མམ ཀཾསེནཱཝཤྱཾ པཱསྱཐཿ, མམ མཛྫནེན ཙ ཡུཝཱམཔི མཛྫིཥྱེཐེ, ཀིནྟུ ཡེཥཱཾ ཀྲྀཏེ མཏྟཱཏེན ནིརཱུཔིཏམ྄ ཨིདཾ ཏཱན྄ ཝིཧཱཡཱནྱཾ ཀམཔི མདྡཀྵིཎཔཱརྴྭེ ཝཱམཔཱརྴྭེ ཙ སམུཔཝེཤཡིཏུཾ མམཱདྷིཀཱརོ ནཱསྟི།
24 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn mẹ́wàá ìyókù sì gbọ́ èyí, wọ́n bínú sí àwọn arákùnrin méjì yìí.
ཨེཏཱཾ ཀཐཱཾ ཤྲུཏྭཱནྱེ དཤཤིཥྱཱསྟཽ བྷྲཱཏརཽ པྲཏི ཙུཀུཔུཿ།
25 Ṣùgbọ́n Jesu pé wọ́n papọ̀, ó wí pé, “Dájúdájú, ẹ̀yin mọ̀ pé àwọn ọba aláìkọlà a máa lo agbára lórí wọn, àwọn ẹni ńlá láàrín wọn a sì máa fi ọlá tẹrí àwọn tí ó wà lábẹ́ wọn ba.
ཀིནྟུ ཡཱིཤུཿ སྭསམཱིཔཾ ཏཱནཱཧཱུཡ ཛགཱད, ཨནྱདེཤཱིཡལོཀཱནཱཾ ནརཔཏཡསྟཱན྄ ཨདྷིཀུཪྻྭནྟི, ཡེ ཏུ མཧཱནྟསྟེ ཏཱན྄ ཤཱསཏི, ཨིཏི ཡཱུཡཾ ཛཱནཱིཐ།
26 Ṣùgbọ́n èyí yàtọ̀ láàrín yín. Dípò bẹ́ẹ̀, ẹni tí ó bá ń fẹ́ ṣe olórí láàrín yín, ní láti ṣe bí ìránṣẹ́ fún yín ni,
ཀིནྟུ ཡུཥྨཱཀཾ མདྷྱེ ན ཏཐཱ བྷཝེཏ྄, ཡུཥྨཱཀཾ ཡཿ ཀཤྩིཏ྄ མཧཱན྄ བུབྷཱུཥཏི, ས ཡུཥྨཱན྄ སེཝེཏ;
27 àti ẹni tí ó bá fẹ́ ṣe olórí nínú yín, ẹ jẹ́ kí ó máa ṣe ọmọ ọ̀dọ̀ yin.
ཡཤྩ ཡུཥྨཱཀཾ མདྷྱེ མུཁྱོ བུབྷཱུཥཏི, ས ཡུཥྨཱཀཾ དཱསོ བྷཝེཏ྄།
28 Gẹ́gẹ́ bí Ọmọ Ènìyàn kò ṣe wá sí ayé, kí ẹ lè ṣe ìránṣẹ́ fún un, ṣùgbọ́n láti ṣe ìránṣẹ́ fún yín, àti láti fi ẹ̀mí rẹ ṣe ìràpadà ọ̀pọ̀ ènìyàn.”
ཨིཏྠཾ མནུཛཔུཏྲཿ སེཝྱོ བྷཝིཏུཾ ནཧི, ཀིནྟུ སེཝིཏུཾ བཧཱུནཱཾ པརིཏྲཱཎམཱུལྱཱརྠཾ སྭཔྲཱཎཱན྄ དཱཏུཉྩཱགཏཿ།
29 Bí Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ti ń fi ìlú Jeriko sílẹ̀, ọ̀pọ̀ ènìyàn sì wọ́ tẹ̀lé e lẹ́yìn.
ཨནནྟརཾ ཡིརཱིཧོནགརཱཏ྄ ཏེཥཱཾ བཧིརྒམནསམཡེ ཏསྱ པཤྩཱད྄ བཧཝོ ལོཀཱ ཝཝྲཛུཿ།
30 Àwọn ọkùnrin afọ́jú méjì sì jókòó lẹ́bàá ọ̀nà, nígbà tí wọ́n sí gbọ́ pé Jesu ń kọjá lọ, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í kígbe pé, “Olúwa, Ọmọ Dafidi, ṣàánú fún wa!”
ཨཔརཾ ཝརྟྨཔཱརྴྭ ཨུཔཝིཤནྟཽ དྭཱཝནྡྷཽ ཏེན མཱརྒེཎ ཡཱིཤོ རྒམནཾ ནིཤམྱ པྲོཙྩཻཿ ཀཐཡཱམཱསཏུཿ, ཧེ པྲབྷོ དཱཡཱུདཿ སནྟཱན, ཨཱཝཡོ རྡཡཱཾ ཝིདྷེཧི།
31 Àwọn ènìyàn sí bá wọn wí pé kí wọn dákẹ́, ṣùgbọ́n wọ́n kígbe sókè sí i. “Olúwa, ọmọ Dafidi, ṣàánú fún wa!”
ཏཏོ ལོཀཱཿ སཪྻྭེ ཏུཥྞཱིམྦྷཝཏམིཏྱུཀྟྭཱ ཏཽ ཏརྫཡཱམཱསུཿ; ཏཐཱཔི ཏཽ པུནརུཙྩཻཿ ཀཐཡཱམཱསཏུཿ ཧེ པྲབྷོ དཱཡཱུདཿ སནྟཱན, ཨཱཝཱཾ དཡསྭ།
32 Jesu dúró lójú ọ̀nà, ó sì pè wọ́n, Ó béèrè pé, “Kí ni ẹ̀yin fẹ́ kí èmi ṣe fún yín?”
ཏདཱནཱིཾ ཡཱིཤུཿ སྠགིཏཿ སན྄ ཏཱཝཱཧཱུཡ བྷཱཥིཏཝཱན྄, ཡུཝཡོཿ ཀྲྀཏེ མཡཱ ཀིཾ ཀརྟྟཪྻྱཾ? ཡུཝཱཾ ཀིཾ ཀཱམཡེཐེ?
33 Wọ́n dáhùn pé, “Olúwa, àwa fẹ́ kí a ríran.”
ཏདཱ ཏཱཝུཀྟཝནྟཽ, པྲབྷོ ནེཏྲཱཎི ནཽ པྲསནྣཱནི བྷཝེཡུཿ།
34 Àánú wọn sì ṣe Jesu, ó fi ọwọ́ kan ojú wọn. Lójúkan náà, wọ́n sì ríran, wọ́n sì ń tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
ཏདཱནཱིཾ ཡཱིཤུསྟཽ པྲཏི པྲམནྣཿ སན྄ ཏཡོ རྣེཏྲཱཎི པསྤརྴ, ཏེནཻཝ ཏཽ སུཝཱིཀྵཱཉྩཀྲཱཏེ ཏཏྤཤྩཱཏ྄ ཛགྨུཏུཤྩ།

< Matthew 20 >