< Mark 8 >

1 Ní ọjọ́ kan, bí ọ̀pọ̀ ènìyàn ti péjọ, kò sí oúnjẹ fún wọn mọ́ láti jẹ. Jesu pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
I A mau la no, he ahakanaka nui loa, aole nae a lakou mea e paina'i, kahea mai la Iesu i kana mau haumana, i mai la ia lakou,
2 Ó wí fún wọn pé, “Àánú ọ̀pọ̀ ènìyàn wọ̀nyí ṣe mí nítorí pé ó tó ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti wà níhìn-ín, kò sì sí ohun kan tí ó kù sílẹ̀ fún wọn láti jẹ.
Ke aloha aku nei au i ka ahakanaka, no ka mea, ua noho pu iho nei lakou me au, i na la ekolu, aole hoi a lakou mea e paina'i.
3 Bí mo bá sọ fún wọn láti máa lọ sí ilé wọn bẹ́ẹ̀ pẹ̀lú ebi, wọn yóò dákú lójú ọ̀nà, nítorí pé àwọn mìíràn nínú wọn ti ọ̀nà jíjìn wá.”
Ina e hookuu aku au ia lakou i ko lakou hale me ka pololi, e mauleule no lakou ma ke alanui; no ka mea, mai kahi loihi ka hele ana mai o kekahi poe o lakou.
4 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ béèrè pé, “Níbo ni a ó ti rí àkàrà tí ó tó láti fi bọ́ wọn nínú aṣálẹ̀ yìí?”
I aku la kana poe haumana ia ia, Nohea la e hiki ai i kekahi ke hoomaona'i ia lakou nei iloko o ka waonahele?
5 Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ìṣù àkàrà mélòó lẹ ní lọ́wọ́?” Wọ́n fèsì pé, “Ìṣù àkàrà méje.”
Ninau mai la oia ia lakou, Ehia na popo berena a oukou? I mai la lakou, Ehiku.
6 Nítorí náà, ó pàṣẹ fún àwọn ènìyàn náà láti jókòó lórí ilẹ̀. Ó sì mú odindi àkàrà méje náà, ó dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run, ó sì bù wọ́n sí wẹ́wẹ́, ó pín wọn fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti gbé ka iwájú àwọn ènìyàn, wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀.
Kanoha mai la ia i kanaka e noho ilalo ma ka lepo. Lawe ae la ia i na popo berena ehiku, hoomaikai aku la, wawahi iho la, haawi mai ia i kana poe haumana, e kau aku imua o ka ahakanaka; a kau aku la lakou.
7 Wọ́n rí àwọn ẹja wẹ́wẹ́ díẹ̀ pẹ̀lú. Jesu tún dúpẹ́ lọ́wọ́ Ọlọ́run fún ìpèsè náà, ó sì pàṣẹ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti pín wọn fún àwọn ènìyàn náà.
He mau wahi ia liilii no hoi kekahi a lakou; hoomaikai aku la ia, a kauoha mai la, e kau aku no hoi ia mau mea.
8 Gbogbo ọ̀pọ̀ ènìyàn náà ló jẹ àjẹyó àti àjẹtẹ́rùn. Lẹ́yìn èyí wọ́n kó àjẹkù ti ó kù jọ, agbọ̀n méje sì kún.
Ai iho la lakou a maona, a hoiliili iho la lakou i ke koena ai, ehiku hinai i piha.
9 Àwọn tí ó jẹ ẹ́ tó ìwọ̀n ẹgbàajì ènìyàn, ó sì rán wọn lọ.
A o ka poe i ai, eha tausani lakou; a hookuu aku la oia ia lakou.
10 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, lẹ́yìn èyí, Jesu wọ inú ọkọ̀ ojú omi pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, wọ́n sì gúnlẹ̀ sí agbègbè Dalmanuta.
Alaila, ee pu aku la ia me kana poe haumana iluna o ka moku, a holo ae la i na mokuna o Dalamanuta.
11 Àwọn Farisi tọ Jesu wá, wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí béèrè ìbéèrè lọ́wọ́ rẹ̀. Láti dán an wò, wọ́n béèrè fún àmì láti ọ̀run.
Hele mai la ka poe Parisaio, a hoomaka e ninaninau mai ia ia, me ka imi i hoailona ana, mai ka lani mai, i hoao ai lakou ia ia.
12 Jesu mí kanlẹ̀, nígbà tí ó gbọ́ ìbéèrè wọn. Ó sì dáhùn wí pé, “Èéṣe tí ìran yìí fi ń wá àmì? Lóòótọ́ ni mo sọ fún un yín kò si àmì tí a ó fi fún ìran yín.”
Uwe nui iho la ia iloko o kona naau, i ae la, No ke aha la keia hanauna e imi mai nei i hoailona? Oiaio ke hai aku nei au ia oukou, Aole e haawiia'ku ka hoailona no keia hanauna.
13 Nígbà náà ni ó padà sínú ọkọ̀ ojú omi ó fi àwọn ènìyàn sílẹ̀, ó sì rékọjá sí apá kejì Òkun náà.
Haalele iho la oia ia lakou, ee hou aku la maluna o ka moku, a holo aku la i kela kapa.
14 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ẹ̀yìn ti gbàgbé láti mú àkàrà tí yóò tó wọn ọ́n jẹ lọ́wọ́. Ẹyọ ìṣù àkàrà kan ṣoṣo ni ó wà nínú ọkọ̀ wọn.
Ua poina ia lakou ke lawe pu i ka berena, hookahi wale no popo berena a lakou iloko o ka moku.
15 Bí wọ́n sì ti ń rékọjá, Jesu kìlọ̀ fún wọn pé, “Ẹ máa ṣọ́ra nítorí ìwúkàrà àwọn Farisi àti ìwúkàrà Herodu.”
Kauoha mai la oia ia lakou, i mai la, E ao oukou e makaala, no ka mea hu a ka poe Parisaio, a me ka mea hu o Herode.
16 Wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí ronú èyí láàrín ara wọn wí pé, “Torí pé a kò mú àkàrà lọ́wọ́ ni?”
Ohumu malu iho la lakou ia lakou iho no, i ae la, No ko kakou berena ole paha.
17 Jesu mọ ohun tí wọ́n sọ láàrín ara wọn, ó sì dá wọn lóhùn pé, “Èéṣe ti ẹ̀yin fi ń ṣe àròyé pé ẹ̀yin kò mú àkàrà lọ́wọ́? Ẹ̀yin kò kíyèsi i títí di ìsinsin yìí, ẹ kò sì ti mòye, àbí ọkàn yín le ni.
Ua ike no o Iesu, a i mai la oia ia lakou, No ke aba la oukou i ohumu ai i ko oukou berena ole? Aole anei oukou i noonoo? Aole anei iike? Ua paakiki anei ko oukou naau?
18 Ẹ̀yin ní ojú, ẹ kò fi ríran? Ẹ̀yin ni etí ẹ kò sí gbọ́ran? Ẹ̀yin kò sì rántí?
He mau maka no ko oukou, aole anei oukou i ike? He mau pepeiao no ko oukou, aole anei oukou i lohe? Aole anei oukou i hoomanao?
19 Nígbà ti mo bu ìṣù àkàrà márùn-ún fún ẹgbẹ̀rún márùn-ún ènìyàn, agbọ̀n mélòó ni ó kún fún àjẹkù tí ẹ ṣàjọ?” Wọ́n wí pé, “Méjìlá.”
I kuu wawahi ana i na popo berena elima, na na tausani elima, ehia la na hinai i piha i ke koena ai a oukou i hoiliili ai? Hai aku la lakou ia ia, He umikumamalua.
20 “Bákan náà, nígbà tí mo bọ́ ẹgbàajì pẹ̀lú ìṣù àkàrà méje, agbọ̀n mélòó ló kù sílẹ̀ lẹ́yìn àjẹyó àti àjẹtẹ́rùn wọn?” Wọ́n dáhùn pé, “Ó ku ẹ̀kún agbọ̀n méje.”
A i na hiku na na tausani eha, ehia la na hinai i piha i ke koena ai a oukou i hoiliili ai? Hai aku la lakou ia ia, Ehiku.
21 Ó sì wí fún wọn pé, “Èéha ti ṣe tí kò fi yé yin?”
A olelo mai la ia ia lakou, Pehea la hoi i hoomaopopo ole mai ai oukou?
22 Nígbà tí wọ́n dé Betisaida, àwọn ènìyàn kan mú afọ́jú kan wá sọ́dọ̀ rẹ̀. Wọ́n bẹ̀ ẹ́ kí ó fi ọwọ́ kàn án, kí ó sì wò ó sàn.
Hele mai la ia i Betesaida, alaila, nalihali ae la lakou i kekahi kanaka makapo io na la, nonoi aku la ia ia, e hoopa mai ia ia.
23 Jesu fa ọkùnrin náà lọ́wọ́, ó sì mú un jáde lọ sí ẹ̀yìn ìlú. Ó tu itọ́ sí i lójú. Ó sì gbé ọwọ́ rẹ̀ lé ojú náà. Ó sì bi í léèrè pé, “Ǹjẹ́ ìwọ lè rí ohunkóhun nísinsin yìí?”
Lalau iho la ia i ka lima o ke kanaka makapo, alakai aku la ia ia, mai ke kauhale aku; kuha mai la ia i kona mau maka, hoopa mai la kona lima ia ia, ninau mai la i kona ike ana i kekahi mea.
24 Ọkùnrin náà wo àyíká rẹ̀, ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ ni Olúwa, mo rí àwọn ènìyàn, ṣùgbọ́n n kò rí wọn kedere, wọ́n n rìn kiri bí àgékù igi.”
Nana ae la ia iluna, i aku la, Ke ike nei au i kanaka, me he mau laau la e hele ana.
25 Nígbà náà, Jesu tún gbé ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì lé àwọn ojú ọkùnrin náà, bí ọkùnrin náà sì ti ranjú mọ́ ọn, a dá ìran rẹ̀ padà, ó sì rí gbogbo nǹkan kedere.
Mahope iho, kau hou mai la ia i kona lima ma na maka ona, a hoonana hou aku la ia ia iluna; a ola ae la ia, a ike maopopo iho la i kela kanaka i keia kanaka.
26 Jesu sì rán an sí àwọn ẹbí rẹ̀. Ó kìlọ̀ fún un pé, “Má ṣe lọ sí ìlú, kí o má sì sọ fún ẹnikẹ́ni ní ìlú.”
Hoihoi ae la o Iesu ia ia i kona hale, i ae la, Mai hele aku i ke kauhale, mai hai aku i ko ke kauhale.
27 Nísinsin yìí, Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kúrò ní Galili. Wọ́n sì jáde lọ sí àwọn abúlé ní agbègbè Kesarea-Filipi. Bí wọ́n ti ń lọ lọ́nà, ó béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ta ni àwọn ènìyàn ń fi mí pè?”
Hele aku la Iesu, a me kana poe haumana i na kauhale o Kaisareia Pilipi; ninau ae la ia i kana poe haumana ma ke alaloa, i ka i ana, Owai la wau i ka kanaka olelo?
28 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn náà dáhùn pé, “Àwọn kan rò pé ìwọ ni Johanu Onítẹ̀bọmi, àwọn mìíràn sọ pé, ìwọ ni Elijah tàbí àwọn wòlíì mìíràn ni ó tún padà wá sáyé.”
I aku la lakou, O Ioane Bapetite; a o Elia i ka kekahi; a o kekahi o na kaula i ka kekahi.
29 Ó sì bi wọ́n pé, “Ta ni ẹ̀yin ń fi mí pè?” Peteru dáhùn pé, “Ìwọ ni Kristi náà.”
Ninau mai la oia ia lakou, Owai la hoi au i ka oukou olelo? Hai aku la o Petero, i aku la ia ia, O ka Mesia no oe.
30 Ṣùgbọ́n Jesu kìlọ̀ fún wọn, kí wọn má sọ èyí fún ẹnikẹ́ni.
Papa mai la oia ia lakou, mai hai aku ia ia i kekahi kanaka.
31 Ó sì bẹ̀rẹ̀ sí kọ́ wọn, pé, Ọmọ Ènìyàn kò le ṣàìmá jìyà ohun púpọ̀, a ó sì kọ̀ ọ́ sílẹ̀ láti ọwọ́ àwọn àgbàgbà, àwọn olórí àlùfáà àti àwọn olùkọ́ òfin, a ó sì pa á, lẹ́yìn ọjọ́ mẹ́ta yóò sì jíǹde.
Ilaila kana hoomaka ana e hoike mai ia lakou e hoomainoino nui ia ke Keiki a ke kanaka, a e hooleia e ka poe kahiko, a me ka poe kahuna nui, a me ka poe kakauolelo, a e pepehiia oia, a po akolu ae e ala hou mai.
32 Jesu bá wọn sọ̀rọ̀ yìí, láìfi ohunkóhun pamọ́ fún wọn, ṣùgbọ́n Peteru pe Jesu sẹ́yìn, ó sì bẹ̀rẹ̀ si bá a wí.
Hai maopopo mai la oia ia olelo; alaila. lalau ae la o Petero ia ia, a hoomaka e papa aku la ia ia.
33 Jesu yípadà, ó wo àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀. Ó sì wí fún Peteru pẹ̀lú ìtara pé, “Kúrò lẹ́yìn mi Satani, nítorí ìwọ kò ro ohun tí Ọlọ́run bí kò ṣe ohun tí ènìyàn.”
Haliu ae la Iesu, nana ae la i kana mau haumana, papa ae la ia Petero, i ae la, E hele oe pela mahope o'u, e Satana, no ka mea, aole i like kou manao me ko ke Akua, aka, me ko na kanaka.
34 Nígbà náà ni Jesu pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ àti ọ̀pọ̀ ènìyàn láti bá wọn sọ̀rọ̀, ó wí fún wọn pé, “Bí ẹnikẹ́ni bá fẹ́ tọ̀ mí lẹ́yìn, kí ó sẹ́ ara rẹ̀, kí ó si gbé àgbélébùú rẹ̀, kí ó si máa tọ̀ mi lẹ́yìn.
A kahea mai la ia i kanaka, a i kana poe haumana no hoi, i mai la ia lakou, O ka mea makemake e hahai mai mahope o'u, e hoole oia ia ia iho, a e kaikai i kona kea, a e hahai mai ia'u.
35 Nítorí ẹni tó bá gbìyànjú láti gba ẹ̀mí ara rẹ̀ là, yóò sọ ọ́ nù. Iye àwọn tí ó sọ ẹ̀mí wọn nù nìkan nítorí í tèmi àti nítorí ìyìnrere, òun náà ni yóò gbà á là.
O ka mea manao e malama i kona ola nei, e lilo auanei kona ola, a o ka mea haalele i kona ola no'u nei, a no ka enanelio, e loaa ia ia ke ola.
36 Nítorí èrè kí ni ó jẹ́ fún ẹni tí ó jèrè gbogbo ayé, tí ó sọ ẹ̀mí rẹ̀ nù?
Heaha la uanei ko ke kanaka pomaikai ke loaa ia ia ke ao nei a pau, a lilo aku kona uhane?
37 Tàbí kí ni ènìyàn yóò fi ṣe pàṣípàrọ̀ ẹ̀mí rẹ̀?
Heaha la hoi ko ke kanaka kumu e haawi aku ai, e loaa hou mai ai kona uhane?
38 Nítorí náà, bí ẹnikẹ́ni bá tijú àti gbà mí tàbí ọ̀rọ̀ mi nínú ìran panṣágà àti ẹlẹ́ṣẹ̀ yìí, tí ó kún fún àìgbàgbọ́ àti ẹ̀ṣẹ̀ báyìí, Ọmọ Ènìyàn yóò tijú rẹ̀ nígbà tí ó bá padà dé nínú ògo Baba rẹ̀, pẹ̀lú àwọn angẹli mímọ́.”
O ka mea e hilahila mai ia'u a me ka'u olelo, i keia hanauna kolohe a hana hewa, e hilahila no hoi ke Keiki a ke kanaka ia ia i kona wa e hele mai ai me ka nani o kona Makua, me na anela hemolele.

< Mark 8 >