< Malachi 1 >

1 Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀: ọ̀rọ̀ Olúwa sí Israẹli láti ẹnu Malaki.
K A WANANA o ka olelo a Iehova i ka Iseraela ma o Malaki la.
2 “Èmí ti fẹ́ ẹ yín,” ni Olúwa wí. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni ìwọ ṣe fẹ́ wa?’ “Esau kì í ha ṣe arákùnrin Jakọbu bí?” ni Olúwa wí. “Síbẹ̀ èmi fẹ́ràn Jakọbu,
Ua aloha aku au ia oukou, wahi a Iehova; Aka, ke ninau mai nei oukou, Ma ke aha la kau i aloha mai ai ia makou? Aole anei o Esau ka hoahanau o Iakoba? wahi a Iehova; Aka, i aloha aku au ia Iakoba,
3 ṣùgbọ́n Esau ni mo kórìíra, mo ti sọ àwọn òkè ńlá rẹ̀ di aṣálẹ̀, mo sì fi ìní rẹ̀ fún àwọn akátá aginjù.”
A hoowahawaha hoi au ia Esau, A hooneoneo aku la au i kona mau mauna, A hoolilo iho la i kona aina i mau wahi noho o ka waonahele.
4 Edomu lè wí pé, “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a run wá, àwa yóò padà wá, a ó sì tún ibùgbé náà kọ́.” Ṣùgbọ́n èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé: “Àwọn lè kọ́, ṣùgbọ́n èmi yóò wó palẹ̀. Wọn yóò sì pè wọ́n ní ilẹ̀ búburú, àwọn ènìyàn tí wọ́n máa ń wà ní ìbínú Olúwa.
No ka mea, ke olelo nei ko Edoma, Ua auhulihia kakou, Aka, e kukulu hou auanei kakou i na wahi neoneo: Penei ka Iehova o na kaua i olelo mai ai, E kukulu lakou, a e wawahi hoi au: E kapaia lakou, Na aina o ka aia, A o na kanaka a Iehova e inaina mau loa ai.
5 Ẹ̀yin yóò sì fi ojú yín rí i, ẹ̀yin yóò sì wí pé, ‘Títóbi ni Olúwa, títóbi rẹ̀ tayọ kọjá agbègbè Israẹli.’
A e ike auanei ko oukou mau maka, a e olelo aku oukou, E hoonuiia auanei o Iehova mai ka palena aku o Iseraela.
6 “Ọmọ a máa bu ọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọ ọ̀dọ̀ a sì máa bu ọlá fún olúwa rẹ̀. Ǹjẹ́ bí èmí bá jẹ́ baba, ọlá tí ó tọ́ sí mi ha dà? Bí èmi bá sì jẹ́ olúwa, ẹ̀rù tí ó tọ́ sí mi dà?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Ẹ̀yin ni, ẹ̀yin àlùfáà, ni ẹ ń gan orúkọ mi. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe gan orúkọ rẹ?’
Ua hoomaikai ke keiki i kona makuakane, A o ke kauwa i kona haku: Ina hoi he makua wau, auhea la kuu hoomaikaiia? Ina hoi he haku wau, auhea la hoi kuu weliweliia? Wahi a Iehova o na kaua ia oukou, e na kahuna hoowahawaha i kuu inoa. Ke ninau mai nei oukou, Ma ke aha ka makou i hoowahawaha ai i kou inoa?
7 “Ẹ̀yin gbé oúnjẹ àìmọ́ sí orí pẹpẹ mi. “Ẹ̀yin sì tún béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe ṣe àìmọ́ sí ọ?’ “Nípa sísọ pé tábìlì Olúwa di ẹ̀gàn.
Ke mohai mai nei oukou i ka berena haumia maluna o ko'u kuahu; Ke ninau mai nei oukou, Ma ke aha la ka makou i hoohaumia aku ai ia oe? Ma ka mea a oukou e olelo nei, He mea wahawaha ka papaaina o Iehova.
8 Nígbà tí ẹ̀yin mú afọ́jú ẹran wá fún ìrúbọ, ṣé èyí kò ha burú bí? Nígbà tí ẹ̀yin fi amúnkùn ún àti aláìsàn ẹran rú ẹbọ, ṣé èyí kò ha burú gidigidi bí? Ẹ dán an wò, ẹ fi wọ́n rú ẹbọ sí àwọn baálẹ̀ yín! Ṣé inú rẹ̀ yóò dùn sí yín? Ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Ina paha e kaumaha oukou i ka mea makapo i mea mohai, aole anei ia he hewa? Ina hoi e mohai oukou i ka mea oopa a me ka mea mai, aole anei he hewa ia? Ke i aku nei au, e haawi aku ia mea na kou alii, E oluolu mai anei ia ia oe? E maliu mai anei kela ia oe? wahi a Iehova o na kaua.
9 “Ní ìsinsin yìí, ẹ bẹ Ọlọ́run kí ó ṣàánú fún wa. Ṣùgbọ́n pẹ̀lú irú àwọn ẹbọ wọ̀nyí láti ọwọ́ yín wá, ṣé yóò gbà yín?” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Nolaila hoi, ke nonoi aku nei oukou i ke Akua, e aloha mai oia ia kakou: No oukou aku ia mea; e maliu mai anei kela ia oukou? Wahi a Iehova o na kaua.
10 “Hó ò! Ẹnìkan ìbá jẹ́ wà láàrín yín ti yóò sé ìlẹ̀kùn tẹmpili, pé kí ẹ má ba à ṣe dá iná asán lórí pẹpẹ mi mọ́! Èmi kò ní inú dídùn sí i yín,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò gba ọrẹ kan lọ́wọ́ yín.
Owai la ka mea o oukou e pani wale i na puka? Aole oukou e kuni make hewa maluna o kuu kuahu. Aole au i oluolu ia oukou, wahi a Iehova o na kaua; Aole hoi e maliu au i ka mohai na ko oukou lima mai.
11 Orúkọ mi yóò tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, láti ìlà-oòrùn títí ó sì fi dé ìwọ̀-oòrùn. Ní ibi gbogbo ni a ó ti mú tùràrí àti ọrẹ mímọ́ wá fún orúkọ mi, nítorí orúkọ mi tóbi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
No ka mea, mai ka hikina o ka la a hiki i ke komohana, E nui auanei kuu inoa iwaena o na lahuikanaka; A ma na wahi a pau loa e kuniia'i ka mea ala no kuu inoa, A me ka mohai maemae: No ka mea, e nui auanei kuu inoa iwaena o na lahuikanaka, Wahi a Iehova o na kaua.
12 “Nítorí ẹ̀yin ti sọ ọ́ di àìmọ́, nínú èyí tí ẹ wí pé, ‘Tábìlì Olúwa di àìmọ́ àti èso rẹ̀,’ àní oúnjẹ rẹ̀ ni ohun ẹ̀gàn.
Aka, ua hoino oukou ia i ka oukou olelo ana, Ua haumia ka papaaina o Iehova, A o ka hua maluna, oia o kana ai, he mea hoowahawaha ia.
13 Ẹ̀yin wí pẹ̀lú pé, ‘Wò ó, irú àjàgà kín ni èyí!’ Ẹ̀yin sì yínmú sí i,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. “Nígbà tí ẹ̀yin sì mú èyí tí ó fi ara pa, arọ àti ọlọkùnrùn ẹran tí ẹ sì fi rú ẹbọ, Èmi o ha gba èyí lọ́wọ́ yín?” ni Olúwa wí.
Ke olelo nei oukou, Ka! kai ka luhi! A na oukou ia i hoopailuaia'i, wahi a Iehova o na kaua; No ka mea, ke mohai iho nei oukou i ka mea i haehaeia, A me ka oopa, a me ka maimai, A pela oukou i lawe mai ai i ka mohai. E oluolu anei au i keia mea na ko oukou lima mai? wahi a Iehova.
14 “Ṣùgbọ́n ègún ni fún ẹlẹ́tàn náà, tí ó ni akọ nínú ọ̀wọ́ ẹran rẹ̀, tí ó sì ṣe ìlérí láti fi lélẹ̀ tí ó sì fi ẹran tó lábùkù rú ẹbọ sí Olúwa; nítorí ọba ńlá ni Èmi,” ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “ẹ̀rù sì ni orúkọ mi láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Aka, auwe ka mea hoopunipuni, Ka mea nana ka hipakane maloko o kana ohana, Aka, ua hoolaa, a ua mohai iho i ka mea haumia: No ka mea, he alii nui hoi wau, wahi a Iehova o na kaua, A he mea weliweli ko'u inoa iwaena o na lahuikanaka.

< Malachi 1 >