< Leviticus 22 >

1 Olúwa sọ fún Mose pé,
I mluvil Hospodin k Mojžíšovi, řka:
2 “Sọ fún Aaroni àti àwọn ọmọ rẹ̀ kí wọ́n fi ọ̀wọ̀ fún ọrẹ mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli yà sọ́tọ̀ fún mi, kí wọ́n má ba à ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́. Èmi ni Olúwa.
Mluv Aronovi a synům jeho, ať se zdržují od věcí těch, kteréž jsou posvěceny od synů Izraelských, a ať nepoškvrňují jména svatého mého v tom, což mi oni posvěcují: Já jsem Hospodin.
3 “Sọ fún wọn pé, ‘Fún àwọn ìran tí ń bọ̀. Bí ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ yín tí kò mọ́ bá wá sí ibi ọrẹ mímọ́ tí àwọn ara Israẹli ti yà sọ́tọ̀ fún Olúwa, kí ẹ yọ ẹni náà kúrò nínú iṣẹ́ àlùfáà ní iwájú mi. Èmi ni Olúwa.
Rci jim: Kdo by koli ze všeho semene vašeho v pronárodech vašich přistoupil ku posvěceným věcem, kterýchž by posvětili synové Izraelští Hospodinu, když nečistota jeho na něm jest, vyhlazena bude duše ta od tváři mé: Já jsem Hospodin.
4 “‘Bí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Aaroni bá ní ààrùn ara tí ń ran ni, tàbí ìtújáde nínú ara. Ó lè má jẹ ọrẹ mímọ́ náà títí di ìgbà tí a ó fi wẹ̀ ẹ́ mọ́. Òun tún lè di aláìmọ́ bí ó bá fọwọ́ kan ohunkóhun tí òkú nǹkan bá sọ di àìmọ́ tàbí bí ó bá farakan ẹnikẹ́ni tí ó ní ìtújáde.
Kdo by koli z semene Aronova byl malomocný, aneb tok semene trpící, nebude jísti z věcí posvěcených, dokavadž by se neočistil. A kdož by se koli dotekl nečistoty těla mrtvého, aneb toho, z něhož by vyšlo símě scházení,
5 Tàbí bí ó bá fọwọ́ kan èyíkéyìí nínú ohun tí ń rákò, tí ó sọ ọ́ di aláìmọ́, tàbí ẹnikẹ́ni tí ó sọ ọ́ di àìmọ́, ohunkóhun yówù kí àìmọ́ náà jẹ́.
Aneb kdo by se dotkl kterého zeměplazu, jímž by se poškvrnil, aneb člověka, pro něhož by byl nečistý vedlé všelijaké nečistoty jeho:
6 Ẹni náà tí ó fọwọ́ kan irú nǹkan bẹ́ẹ̀ yóò di aláìmọ́ títí ìrọ̀lẹ́. Kò gbọdọ̀ jẹ èyíkéyìí nínú ọrẹ mímọ́ àyàfi bí ó bá wẹ ara rẹ̀.
Člověk, kterýž by se čehokoli toho dotekl, nečistý bude až do večera, a nebude jísti z věcí posvěcených, leč by umyl tělo své vodou.
7 Bí oòrùn bá wọ̀, ẹni náà di mímọ́, lẹ́yìn náà ni ó tó le jẹ ọrẹ mímọ́, torí pé wọ́n jẹ́ oúnjẹ rẹ̀.
A po západu slunce čistý bude, a potom bude moci jísti z věcí posvěcených, nebo pokrm jeho jest.
8 Kò gbọdọ̀ jẹ ohunkóhun tí ó bá ti kú sílẹ̀, tàbí tí ẹranko fàya, kí ó sì tipa bẹ́ẹ̀ di aláìmọ́. Èmi ni Olúwa.
Mrchy a udáveného jísti nebude, aby se tím nepoškvrnil: Já jsem, Hospodin.
9 “‘Kí àwọn àlùfáà pa ìlànà mi mọ́, kí wọn má ba à jẹ̀bi, kí wọn sì kú nítorí pé wọ́n ṣe ọrẹ wọ̀nyí pẹ̀lú fífojútẹ́ńbẹ́lú wọn. Èmi ni Olúwa tí ó sọ wọ́n di mímọ́.
Protož ostříhati budou přisluhování mých, aby hříchů na se neuvedli, a nezemřeli v něm, proto že je zprznili: Jáť jsem Hospodin posvětitel jejich.
10 “‘Kò sí ẹnikẹ́ni lẹ́yìn ìdílé àlùfáà tí ó le jẹ ọrẹ mímọ́ náà, bẹ́ẹ̀ ni, àlejò àlùfáà tàbí alágbàṣe rẹ̀ kò le jẹ ẹ́.
Žádný cizí nebude jísti z věcí posvěcených, ani podruh kněžský, ani nájemník nebude jísti věcí posvěcených.
11 Ṣùgbọ́n bí àlùfáà bá ra ẹrú, pẹ̀lú owó, tàbí tí a bí ẹrú kan nínú ìdílé rẹ̀, ẹrú náà lè jẹ oúnjẹ rẹ̀.
Koupil-li by kněz člověka za své peníze, ten jísti bude z věcí těch, též v domě jeho zplozený; ti budou jísti z pokrmu jeho.
12 Bí ọmọbìnrin àlùfáà bá fẹ́ ẹni tí kì í ṣe àlùfáà, kò gbọdọ̀ jẹ nínú èyíkéyìí nínú ohun ọrẹ mímọ́.
Ale dcera knězova, kteráž by se vdala za muže z jiného pokolení, ta z obětí vzhůru pozdvižených, totiž věcí svatých, nebude jísti.
13 Ṣùgbọ́n bí ọmọbìnrin àlùfáà bá jẹ́ opó tàbí tí a ti kọ ọ́ sílẹ̀, ṣùgbọ́n tí kò lọ́mọ tí ó sì padà sínú ilé baba rẹ̀ láti máa gbé bẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìgbà èwe rẹ̀, ó le jẹ oúnjẹ baba rẹ̀. Bí ó ti wù kí ó rí, àlejò tí kò lẹ́tọ̀ọ́ kò gbọdọ̀ jẹ èyíkéyìí nínú oúnjẹ náà.
Kdyby pak dcera knězova ovdověla, aneb zahnána byla od muže, nemající plodu, a navrátila by se do domu otce svého: tak jako v dětinství svém chléb otce svého jísti bude, cizí pak žádný nebude jísti z něho.
14 “‘Bí ẹnikẹ́ni bá ṣèèṣì jẹ ọrẹ mímọ́ kan, ó gbọdọ̀ ṣe àtúnṣe lórí ẹbọ náà fún àlùfáà, kí ó sì fi ìdámárùn-ún ohun tí ọrẹ náà jẹ́ kún un.
Jedl-li by pak kdo z nedopatření věci posvěcené, pátý díl nad to přidá knězi, a nahradí jemu tu věc posvěcenou,
15 Àwọn àlùfáà kò gbọdọ̀ sọ ọrẹ mímọ́ tí àwọn ọmọ Israẹli mú wá síwájú Olúwa di àìmọ́.
Aby nepoškvrňovali věcí svatých, kteréž by synové Izraelští obětovali Hospodinu,
16 Nípa fífi ààyè fún wọn láti jẹ ọrẹ mímọ́ náà, kí wọ́n sì tipa bẹ́ẹ̀ mú ẹ̀bi tí wọn yóò san nǹkan fún wá sórí wọn. Èmi ni Olúwa, tí ó sọ wọ́n di mímọ́.’”
A neuvozovali na ně pokuty za provinění, že jedli věci posvěcené jejich; nebo já jsem Hospodin, kterýž jich posvěcuji.
17 Olúwa sọ fún Mose pé,
Dále mluvil Hospodin Mojžíšovi, řka:
18 “Sọ fún Aaroni, àwọn ọmọ rẹ̀ àti fún gbogbo Israẹli kí o sì wí fún wọn pé, ‘Bí ẹnikẹ́ni nínú yín yálà ọmọ Israẹli ni tàbí àlejò tí ń gbé ní Israẹli bá mú ẹ̀bùn wá fún ọrẹ ẹbọ sísun sí Olúwa, yálà láti san ẹ̀jẹ́ tàbí ọrẹ àtinúwá.
Mluv k Aronovi a k synům jeho i ke všechněm synům Izraelským, a rci jim: Kdož by koli z domu Izraelského aneb z pohostinných, kteříž jsou v Izraeli, obětovali obět svou vedlé všech slibů svých, vedlé všech darů dobrovolných svých, kteréž by obětovali Hospodinu v obět zápalnou:
19 Ẹ gbọdọ̀ mú akọ láìní àbùkù láti ara màlúù, àgùntàn tàbí ewúrẹ́, kí ó ba à lè jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
Z dobré vůle své obětovati budete samce bez poškvrny, z skotů, z ovcí a z koz.
20 Ẹ má ṣe mú ohunkóhun tí ó ní àbùkù wá, torí pé kò ní jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
Což by koli mělo na sobě vadu, nebudete toho obětovati; nebo nebude příjemné od vás.
21 Bí ẹnikẹ́ni bá mú ọrẹ àlàáfíà wá láti inú agbo màlúù tàbí ti àgùntàn, fún Olúwa láti san ẹ̀jẹ́ pàtàkì tàbí fún ọrẹ àtinúwá. Ó gbọdọ̀ jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà láìní àbùkù.
Pakli by kdo obětoval obět pokojnou Hospodinu, vykonávaje slib svůj, aneb dobrovolný dar, buď z skotů, aneb z bravů: ať jest bez vady, aby bylo příjemné; nebudeť žádné poškvrny na něm.
22 Ẹ má ṣe fi ẹranko tí ó fọ́jú, tí ó fi ara pa, tí ó yarọ, tí ó ní kókó, tí ó ní èkúkú, èépá àti egbò kíkẹ̀ rú ẹbọ sí Olúwa. Ẹ kò gbọdọ̀ gbé èyíkéyìí nínú wọn sórí pẹpẹ gẹ́gẹ́ bi ọrẹ tí a fi iná ṣe sí Olúwa.
Slepého aneb polámaného, osekaného aneb uhřivého, prašivého aneb s lišeji, takového neobětujte Hospodinu a nedávejte jich k ohnivé oběti na oltář Hospodinův.
23 Ẹ le mú màlúù tàbí àgùntàn tí ó ní àbùkù tàbí tí ó yọ iké wá fún ọrẹ àtinúwá, ṣùgbọ́n kò jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún ọrẹ ẹ̀jẹ́.
Vola neb dobytče s nedorostlými neb přerostlými oudy, v dobrovolný zajisté dar obětovati je budeš, ale za slib nebude příjemný.
24 Ẹ má ṣe fi ẹranko tí kóró ẹpọ̀n rẹ̀ fọ́ tàbí tí a tẹ̀, tàbí tí a yà tàbí tí a là rú ẹbọ sí Olúwa. Ẹ kò gbọdọ̀ ṣe èyí ní ilẹ̀ yín.
Ztlačeného aneb ztlučeného, odtrženého, vykleštěného nebudete obětovati Hospodinu; neučiníte toho v zemi vaší.
25 Ẹ kò gbọdọ̀ gba irú ẹranko bẹ́ẹ̀ lọ́wọ́ àlejò kankan láti fi rú ẹbọ gẹ́gẹ́ bí oúnjẹ sí Ọlọ́run yín. A kò nígbà wọ́n fún yín nítorí pé wọ́n ní àbùkù, wọ́n sì díbàjẹ́.’”
A z ruky cizozemce nebudete obětovati chleba Bohu svému ze všech těch věcí, nebo porušení jejich jest na nich; vadu mají, nebudou příjemné od vás.
26 Olúwa sọ fún Mose pé,
Mluvil také Hospodin k Mojžíšovi, řka:
27 “Nígbà tí màlúù bá bímọ, tí àgùntàn bímọ, tí ewúrẹ́ sì bímọ, ọmọ náà gbọdọ̀ wà pẹ̀lú ìyá rẹ̀ fún ọjọ́ méje. Láti ọjọ́ kẹjọ ni ó ti di ìtẹ́wọ́gbà fún ọrẹ àfinásun sí Olúwa.
Vůl neb beran, aneb koza, když se urodí, za sedm dní při matce své zanecháno bude, osmého pak dne i potom bude příjemné k oběti ohnivé Hospodinu.
28 Ẹ má ṣe pa màlúù àti ọmọ rẹ̀ tàbí àgùntàn àti ọmọ rẹ̀ ní ọjọ́ kan náà.
Krávy pak a dobytčete s mladým jeho nezabijete jednoho dne.
29 “Nígbà tí ẹ bá rú ẹbọ ọpẹ́ sí Olúwa, ẹ rú u ní ọ̀nà tí yóò fi jẹ́ ìtẹ́wọ́gbà fún yín.
A když byste obětovali obět chvály Hospodinu, dobrovolně ji obětovati budete.
30 Ẹ gbọdọ̀ jẹ ẹ́ ní ọjọ́ náà gan an, ẹ má ṣe ṣẹ́ ọ̀kankan kù di àárọ̀. Èmi ni Olúwa.
V tentýž den snědena bude a nepozůstavíte z ní ničeho až do jitra: Já jsem Hospodin.
31 “Ẹ pa òfin mi mọ́, kí ẹ sì máa ṣe wọ́n. Èmi ni Olúwa.
Protož ostříhejte přikázaní mých a čiňte je: Já jsem Hospodin.
32 Ẹ má ṣe ba orúkọ mímọ́ mi jẹ́. Àwọn ọmọ Israẹli gbọdọ̀ mọ̀ mí ní mímọ́. Èmi ni Olúwa tí ó sọ yín di mímọ́.
A nepoškvrňujte jména svatého mého, i buduť posvěcen u prostřed synů Izraelských: Já jsem Hospodin posvětitel váš,
33 Tí ó sì mú yín jáde láti Ejibiti wá láti jẹ́ Ọlọ́run yín. Èmi ni Olúwa.”
Kterýž jsem vás vyvedl z země Egyptské, abych vám byl za Boha: Já jsem Hospodin.

< Leviticus 22 >