< Lamentations 3 >

1 Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
I am the man who has seen affliction by the rod of his wrath.
2 Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
He has led me and caused me to walk in darkness, and not in light.
3 Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
Surely he turns his hand against me again and again all day long.
4 Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
He has made my flesh and my skin old. He has broken my bones.
5 Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
He has built against me, and surrounded me with bitterness and hardship.
6 Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
He has made me dwell in dark places, as those who have been long dead.
7 Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
He has walled me about, so that I can’t go out. He has made my chain heavy.
8 Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
Yes, when I cry, and call for help, he shuts out my prayer.
9 Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
He has walled up my ways with cut stone. He has made my paths crooked.
10 Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
He is to me as a bear lying in wait, as a lion in hiding.
11 Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
He has turned away my path, and pulled me in pieces. He has made me desolate.
12 Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
He has bent his bow, and set me as a mark for the arrow.
13 Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
He has caused the shafts of his quiver to enter into my kidneys.
14 Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
I have become a derision to all my people, and their song all day long.
15 Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
He has filled me with bitterness. He has stuffed me with wormwood.
16 Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
He has also broken my teeth with gravel. He has covered me with ashes.
17 Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
You have removed my soul far away from peace. I forgot prosperity.
18 Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
I said, “My strength has perished, along with my expectation from the LORD.”
19 Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
Remember my affliction and my misery, the wormwood and the bitterness.
20 Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
My soul still remembers them, and is bowed down within me.
21 Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
This I recall to my mind; therefore I have hope.
22 Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
It is because of the LORD’s loving kindnesses that we are not consumed, because his mercies don’t fail.
23 Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
They are new every morning. Great is your faithfulness.
24 Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
“The LORD is my portion,” says my soul. “Therefore I will hope in him.”
25 Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
The LORD is good to those who wait for him, to the soul who seeks him.
26 Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
It is good that a man should hope and quietly wait for the salvation of the LORD.
27 Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
It is good for a man that he bear the yoke in his youth.
28 Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
Let him sit alone and keep silence, because he has laid it on him.
29 Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
Let him put his mouth in the dust, if it is so that there may be hope.
30 Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
Let him give his cheek to him who strikes him. Let him be filled full of reproach.
31 Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
For the Lord will not cast off forever.
32 Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
For though he causes grief, yet he will have compassion according to the multitude of his loving kindnesses.
33 Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
For he does not afflict willingly, nor grieve the children of men.
34 Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
To crush under foot all the prisoners of the earth,
35 Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
to turn away the right of a man before the face of the Most High,
36 láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
to subvert a man in his cause, the Lord doesn’t approve.
37 Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
Who is he who says, and it comes to pass, when the Lord doesn’t command it?
38 Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
Doesn’t evil and good come out of the mouth of the Most High?
39 Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
Why should a living man complain, a man for the punishment of his sins?
40 Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
Let us search and try our ways, and turn again to the LORD.
41 Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
Let’s lift up our heart with our hands to God in the heavens.
42 “Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
“We have transgressed and have rebelled. You have not pardoned.
43 “Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
“You have covered us with anger and pursued us. You have killed. You have not pitied.
44 Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
You have covered yourself with a cloud, so that no prayer can pass through.
45 Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
You have made us an off-scouring and refuse in the middle of the peoples.
46 “Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
“All our enemies have opened their mouth wide against us.
47 Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
Terror and the pit have come on us, devastation and destruction.”
48 Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
My eye runs down with streams of water, for the destruction of the daughter of my people.
49 Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
My eye pours down and doesn’t cease, without any intermission,
50 títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
until the LORD looks down, and sees from heaven.
51 Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
My eye affects my soul, because of all the daughters of my city.
52 Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
They have chased me relentlessly like a bird, those who are my enemies without cause.
53 Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
They have cut off my life in the dungeon, and have cast a stone on me.
54 Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
Waters flowed over my head. I said, “I am cut off.”
55 Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
I called on your name, LORD, out of the lowest dungeon.
56 Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
You heard my voice: “Don’t hide your ear from my sighing, and my cry.”
57 O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
You came near in the day that I called on you. You said, “Don’t be afraid.”
58 Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
Lord, you have pleaded the causes of my soul. You have redeemed my life.
59 O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
LORD, you have seen my wrong. Judge my cause.
60 Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
You have seen all their vengeance and all their plans against me.
61 Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
You have heard their reproach, LORD, and all their plans against me,
62 ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
the lips of those that rose up against me, and their plots against me all day long.
63 Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
You see their sitting down and their rising up. I am their song.
64 Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
You will pay them back, LORD, according to the work of their hands.
65 Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
You will give them hardness of heart, your curse to them.
66 Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.
You will pursue them in anger, and destroy them from under the heavens of the LORD.

< Lamentations 3 >