< Judges 21 >

1 Àwọn ọkùnrin Israẹli ti búra ní Mispa pé, “Kò sí ẹnìkan nínú wa tí yóò fi ọmọ obìnrin rẹ̀ fún ẹ̀yà Benjamini ní ìyàwó.”
Ja Israelin miehet olivat vannoneet Mitspassa ja sanoneet: ei yksikään meistä pidä tytärtänsä antaman BenJaminilaisille emännäksi.
2 Àwọn ènìyàn náà lọ sí Beteli: ilé Ọlọ́run, níbi tí wọ́n jókòó níwájú Ọlọ́run títí di àṣálẹ́, wọ́n gbé ohùn wọn sókè, wọ́n sì sọkún kíkorò.
Ja kansa tuli Jumalan huoneesen ja oli siellä Jumalan edessä ehtoosen asti; ja he korottivat äänensä ja itkivät katkerasti,
3 Wọ́n sọkún wí pé, “Háà! Olúwa Ọlọ́run Israẹli, èéṣe tí nǹkan yìí fi ṣẹlẹ̀ sí Israẹli? Èéṣe tí ẹ̀yà kan yóò fi run nínú Israẹli lónìí?”
Ja sanoivat: O Herra Israelin Jumala, miksi tämä tapahtui Israelissa, että tänäpänä on yksi sukukunta Israelista vähentynyt?
4 Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì àwọn ènìyàn náà mọ pẹpẹ kan wọ́n sì rú ẹbọ sísun àti ọrẹ àlàáfíà.
Ja toisena päivänä nousi kansa varhain ja rakensi siihen alttarin, ja uhrasi polttouhria ja kiitosuhria.
5 Àwọn ọmọ Israẹli sì béèrè wí pé, “Èwo nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti péjọ síwájú Olúwa?” Torí pé wọ́n ti fi ìbúra ńlá búra pé, ẹnikẹ́ni tí ó bá kọ̀ láti péjọ níwájú Olúwa ní Mispa pípa ni àwọn yóò pa á.
Ja Israelin lapset sanoivat: kuka on kaikista Israelin sukukunnista, joka ei tänne ole tullut kansan kanssa Herran eteen? Sillä suuri vala oli tehty, että se joka ei tullut Herran tykö Mitspaan, hänen piti totisesti kuoleman.
6 Àwọn ọmọ Israẹli sì banújẹ́ fún àwọn arákùnrin wọn, àwọn ẹ̀yà Benjamini. Wọ́n wí pé, “A ti ké ẹ̀yà kan kúrò lára Israẹli lónìí.”
Ja Israelin lapset katuivat veljensä BenJaminin tähden ja sanoivat: tänäpänä on yksi sukukunta Israelista hävitetty.
7 Báwo ni a yóò ṣe rí aya fún àwọn tí ó ṣẹ́kù, nítorí àwa ti fi Olúwa búra láti má fi ọ̀kankan nínú àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya.
Ja kuinka me käytämme itsemme heidän kanssansa, että jääneet saisivat emäntiä? sillä me olemme vannoneet Herran kautta, ettemme anna heille emäntiä meidän tyttäristämme.
8 Wọ́n sì béèrè wí pé, “Èwo ni nínú ẹ̀yà Israẹli ni ó kọ̀ láti bá àwọn ènìyàn péjọ níwájú Olúwa ní Mispa?” Wọ́n rí i pé kò sí ẹnikẹ́ni tí ó wa láti Jabesi Gileadi tí ó wá sí ibùdó fún àjọ náà.
Ja he sanoivat: kuka on Israelin sukukunnassa, joka ei ole tänne tullut Herran tykö Mitspaan? ja katso, ei ole yksikään ollut leirissä kansan seassa Jabeksesta Gileadissa.
9 Nítorí pé nígbà tí wọ́n ka àwọn ènìyàn, wọ́n rí i pé kò sí ẹnìkankan láti inú àwọn ará Jabesi Gileadi tí ó wà níbẹ̀.
Ja kansa luettiin: ja katso, ei ollut siellä yhtäkään Jabeksen asuvaa Gileadista.
10 Àwọn ìjọ ènìyàn náà sì rán ẹgbàá mẹ́fà àwọn jagunjagun ọkùnrin, lọ sí Jabesi Gileadi wọ́n fún wọn ní àṣẹ pé, ẹ lọ fi idà kọlu gbogbo àwọn tí ó wà níbẹ̀, pẹ̀lú àwọn obìnrin àti àwọn ọmọ wẹ́wẹ́.
Niin he lähettivät sinne kansasta kaksitoistakymmentä tuhatta sotamiestä ja käskivät heitä, sanoen: menkäät ja lyökäät Jabeksen asuvaiset Gileadissa miekan terällä vaimoinensa ja lapsinensa.
11 Wọ́n ní, “Èyí ni ẹ̀yin yóò ṣe, ẹ pa gbogbo ọkùnrin àti gbogbo obìnrin tí kì í ṣe wúńdíá.”
Mutta näin pitää teidän tekemän: kaiken miehenpuolen ja kaikki vaimot, jotka miesten kanssa ovat maanneet, pitää teidän tappaman.
12 Wọ́n rí àwọn irinwó ọ̀dọ́bìnrin tí kò mọ ọkùnrin rí nínú àwọn olùgbé Jabesi Gileadi, wọ́n sì mú wọn lọ sí ibùdó ní Ṣilo àwọn ará Kenaani.
Ja he löysivät Jabeksen asuvaisista Gileadissa neljäsataa piikaa, jotka neitseet olivat ja ei olleet yhdenkään miehen tykönä maanneet, ne he veivät Silon leiriin, joka on Kanaanin maassa.
13 Gbogbo ìjọ àwọn ènìyàn sì ránṣẹ́ àlàáfíà sí àwọn Benjamini ní ihò àpáta Rimoni.
Niin koko kansa lähetti matkaan ja käski sanoa BenJaminin lapsille, jotka olivat Rimmonin kalliolla, ja kutsuivat heitä ystävällisesti.
14 Àwọn ẹ̀yà Benjamini náà sì padà ní àkókò náà, wọ́n sì fún wọn ní àwọn obìnrin Jabesi Gileadi. Ṣùgbọ́n wọn kò kárí gbogbo wọn.
Ja BenJaminin lapset tulivat silloin jälleen, ja he antoivat heille emäntiä niistä jotka he olivat jättäneet elämään Jabeksen vaimoista Gileadissa; ja ei niinkään heille täytynyt.
15 Àwọn ènìyàn náà sì káàánú nítorí ẹ̀yà Benjamini, nítorí Olúwa fi àlàfo kan sílẹ̀ nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Niin kansa katui BenJaminin tähden, että Herra oli loven tehnyt Israelin sukukunnissa.
16 Àwọn olórí ìjọ àwọn ènìyàn náà wí pé, “Kí ni àwa yóò ṣe láti rí aya fún àwọn ọkùnrin tí ó kù nígbà tí a ti pa gbogbo àwọn obìnrin Benjamini run?”
Ja kansan vanhimmat sanoivat: kuinka me teemme, että jääneet saisivat myös emäntiä? sillä vaimoväki BenJaminissa on hukutettu.
17 Wọ́n sì wí pé, “Àwọn tí ó ṣẹ́kù tí wọ́n là nínú àwọn ẹ̀yà Benjamini ní láti ní ogún àti àrólé, kí ẹ̀yà kan nínú Israẹli má ṣe di píparun kúrò ní orí ilẹ̀.
Ja sanoivat: niiden pitää kuitenkin nautitseman perimisensä, jotka jääneet ovat BenJaminista, ettei yksikään sukukunta Israelista hävitettäisi,
18 Àwa kò le fi àwọn ọmọbìnrin wa fún wọn ní aya, nítorí tí àwa ọmọ Israẹli ti ṣe ìbúra yìí pé, ‘Ègún ni fún ẹnikẹ́ni tí ó fi aya fún ẹnikẹ́ni nínú ẹ̀yà Benjamini.’”
Ja emme taida antaa heille meidän tyttäriämme emänniksi; sillä Israelin lapset ovat vannoneet ja sanoneet: kirottu olkoon se, joka BenJaminilaisille emännän antaa.
19 Wọ́n sì wí pé, “Kíyèsi i ayẹyẹ ọlọ́dọọdún fún Olúwa wà ní Ṣilo ní ìhà àríwá Beteli àti ìhà ìlà-oòrùn òpópó náà tí ó gba Beteli kọjá sí Ṣekemu, àti sí ìhà gúúsù Lebona.”
Ja he sanoivat: katso, Herran jokavuotinen juhlapäivä on Silossa, joka on BetElistä pohjoiseen päin, auringon nousuun päin siitä tiestä, joka menee BetElistä Sikemiin, ja länteen päin Lebonasta.
20 Wọ́n sì fi àṣẹ fún àwọn ará Benjamini pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fi ara pamọ́ nínú àwọn ọgbà àjàrà
Ja he käskivät BenJaminin lapsille ja sanoivat: menkäät ja väijykäät viinamäissä.
21 kí ẹ sì wà ní ìmúrasílẹ̀. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin Ṣilo bá jáde láti lọ darapọ̀ fún ijó, kí ẹ yára jáde láti inú àwọn ọgbà àjàrà wọ̀n-ọn-nì kí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín gbé aya kan nínú àwọn ọmọbìnrin Ṣilo kí ẹ padà sí ilẹ̀ Benjamini.
Ja kuin näette Silon tyttäret käyvän ulos hyppyyn, niin juoskaat kiiruusti viinamäistä, ja ottakaat jokainen teillenne Silon tyttäristä emännän, ja menkäät BenJaminin maalle.
22 Nígbà tí àwọn baba wọn tàbí àwọn arákùnrin wọn bá fi ẹjọ́ sùn wá, àwa yóò wí fún wọn pé, ‘Ẹ ṣe wá ní oore nípa ríràn wọ́n lọ́wọ́, nítorí àwa kò rí aya fún wọn ní àkókò ogun, ẹ̀yin kò sì ní jẹ̀bi, nítorí pé ẹ̀yin kọ́ ni ó fi àwọn ọmọbìnrin yín fún wọn bí aya.’”
Kuin heidän isänsä taikka veljensä tulevat valittamaan meidän eteemme, niin me sanomme heille: olkaat heille armiaat, sillä emme ole ottaneet heille emäntää sodalla; mutta ette tahtoneet heille antaa: tämä on teidän syynne.
23 Èyí sì ni ohun tí àwọn ẹ̀yà Benjamini ṣe. Nígbà tí àwọn ọmọbìnrin náà ń jó lọ́wọ́, ọkùnrin kọ̀ọ̀kan mú ọmọbìnrin kọ̀ọ̀kan, wọ́n sì gbé e lọ láti di aya rẹ̀. Wọ́n sì padà sí ilẹ̀ ìní wọn, wọ́n sì tún àwọn ìlú náà kọ́, wọ́n sì tẹ̀dó sínú wọn.
BenJaminin lapset tekivät niin ja ottivat hypyistä lukunsa jälkeen vaimot ryövyydellä, ja menivät pois ja asuivat perinnössänsä, rakensivat kaupungeita ja asuivat niissä.
24 Ní àkókò náà, àwọn ọmọ Israẹli kúrò ní ibẹ̀, wọ́n lọ sí ilé àti ẹ̀yà rẹ̀ olúkúlùkù sí ilẹ̀ ìní rẹ̀.
Israelin lapset menivät myös sieltä pois silloin, itsekukin sukukuntansa ja lankoutensa tykö, ja menivät sieltä itsekukin perimiseensä.
25 Ní àwọn ọjọ́ wọ̀nyí, kò sí ọba ní ilẹ̀ Israẹli; olúkúlùkù sì ń ṣe bí ó ti tọ́ ní ojú ara rẹ̀.
Silloin ei ollut kuningasta Israelissa, vaan jokainen teki niinkuin hänelle näkyi oikein olevan.

< Judges 21 >