< Judges 1 >

1 Lẹ́yìn ikú Joṣua, ni orílẹ̀-èdè Israẹli béèrè lọ́wọ́ Olúwa pé, “Èwo nínú ẹ̀yà wa ni yóò kọ́kọ́ gòkè lọ bá àwọn ará Kenaani jagun fún wa?”
MAHOPE iho o ka make ana o Iosua, ninau aku la ka poe mamo a Iseraela ia Iehova, i aku la, Owai ko makou mea e pii mua aku i ke alo o ko Kanaana, e kaua aku ia lakou?
2 Olúwa sì dáhùn pé, “Juda ni yóò lọ; nítorí pé èmi ti fi ilẹ̀ náà lé e lọ́wọ́.”
I mai la o Iehova, E pii ae ka Iuda; aia hoi, ua haawi au i ka aina i kona lima.
3 Nígbà náà ni àwọn olórí ẹ̀yà Juda béèrè ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Simeoni arákùnrin wọn pé, “Ẹ wá bá wa gòkè lọ sí ilẹ̀ tí a ti fi fún wa, láti bá àwọn ará Kenaani jà kí a sì lé wọn kúrò, àwa pẹ̀lú yóò sì bá a yín lọ sí ilẹ̀ tiyín bákan náà láti ràn yín lọ́wọ́.” Àwọn ọmọ-ogun Simeoni sì bá àwọn ọmọ-ogun Juda lọ.
I ae la ka Iuda i ka Simeona, i kona kaikuaana, E hele pu oe me au, ma ko'u hele ana, i kaua aku kakou i ko Kanaana, a e hele pu no hoi au me oe, ma kou hele ana. A hele pu aku la ka Simeona me ia.
4 Nígbà tí àwọn ọmọ-ogun Juda sì kọlu wọ́n, Olúwa sì fi àwọn ará Kenaani àti àwọn ará Peresi lé wọn lọ́wọ́, wọ́n sì pa ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọkùnrin ní Beseki.
Pii aku la ka Iuda, a haawi mai la o Iehova i ko Kanaana, a me ka Pereza, i ko lakou lima. A luku aku la lakou i kela poe ma Bezeka, he umi tausani kanaka.
5 Ní Beseki ni wọ́n ti rí Adoni-Beseki, wọ́n sì bá a jagun, wọ́n sì ṣẹ́gun àwọn ará Kenaani àti Peresi.
A ma Bezeka, loaa ia lakou o Adonibezeka; a kaua aku la lakou ia ia, a luku aku la lakou i ko Kanaana, a me ka Pereza.
6 Ọba Adoni-Beseki sá àsálà, ṣùgbọ́n ogun Israẹli lépa rẹ̀ wọ́n sì bá a, wọ́n sì gé àwọn àtàǹpàkò ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀.
Holo aku la o Adonibezeka, a hahai aku la lakou ia ia, a loaa oia, alaila ooki ae la lakou i na manamana nui o kona mau lima, a me na manamana nui o kona mau wawae.
7 Nígbà náà ni Adoni-Beseki wí pé, “Àádọ́rin ọba ni èmi ti gé àtàǹpàkò wọn tí wọ́n sì ń ṣa èérún oúnjẹ jẹ lábẹ́ tábìlì mi. Báyìí Ọlọ́run ti san án fún mi gẹ́gẹ́ bí ohun tí mo ṣe sí wọn.” Wọ́n sì mú un wá sí Jerusalẹmu, ó sì kú síbẹ̀.
I ae la o Adonibezeka, He kanahiku alii, ua okiia na manamana nui o ko lakou lima, a me ko lakou wawae, hoiliili lakou malalo iho o ko'u papaaina. E like me ka'u i hana aku ai, pela i hoopai mai ai ke Akua ia'u. Lawe ae la lakou ia ia i Ierusalema, a malaila ia i make ai
8 Àwọn ológun Juda sì ṣẹ́gun Jerusalẹmu, wọ́n sì kó o, wọ́n sì fi ojú idà kọlù ú, wọ́n sì dáná sun ìlú náà.
Ua kaua aku ka poe mamo a Iuda, a ua hoopio, a ua luku aku ia Ierusalema, i ka maka o ka pahikaua, a ua puhi aku ia kulanakauhale i ke ahi.
9 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni àwọn ogun Juda sọ̀kalẹ̀ lọ láti bá àwọn ará Kenaani tí ń gbé ní àwọn ìlú orí òkè ní gúúsù àti ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ òkè lápá ìwọ̀-oòrùn Juda jagun.
A mahope iho hele ae la na mamo a Iuda e kaua aku i ko Kanaana, i ka poe i noho ma ka mauna, a ma ka aoao hema, a ma ka papu.
10 Ogun Juda sì tún ṣígun tọ ará Kenaani tí ń gbé Hebroni (tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Kiriati-Arba) ó sì ṣẹ́gun Ṣeṣai, Ahimani àti Talmai.
Hele ka e aku la ka Iuda i ko Kanaana, i ka poe i noho ma Heberona; o Kiriatareba ka inoa kahiko o Heberona; a pepehi aku la lakou ia Sesai, a me Ahimana, a me Talemai.
11 Láti ibẹ̀, wọ́n sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
A malaila aku lakou i hele ai e ku e ia Debira; o Kiriatesepera ka inoa kahiko o Debira.
12 Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
I iho la o Kaleba, O ka mea nana e pepehi ia Kiriatesepera, a e hoopio iho, e haawi aku au ia Akesa, i ka'u kaikamahine, i wahine nana.
13 Otnieli ọmọ Kenasi, àbúrò Kalebu sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
Na Oteniela, ke keiki a Kenaza, ke kaikaina o Kaleba i hoopio aku ia wahi; a haawi iho la oia ia Akesa, i kana kaikamahine, i wahine nana.
14 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
Eia hoi kekahi, a hiki mai ka wahine io na la, koi ae la oia ia ia e noi aku i kona makuakane i aina. A iho iho la ia mai luna mai o ka hoki. Ninau ae la o Kaleba i ke kaikamahine, Heaha kau?
15 Aksa sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
I mai la kela, E haawi mai oe ia'u i mea e pomaikai ai. No ka mea, ua haawi mai oe ia'u i aina ma ke kukuluhema; e haawi mai no hoi oe i na kumuwai. A haawi mai la o Kaleba i na kumuwai luna a me na kumuwai lalo.
16 Àwọn ìran Keni tí wọ́n jẹ́ àna Mose bá àwọn ọmọ Juda gòkè láti ìlú ọ̀pẹ lọ sí aginjù Juda ní gúúsù Aradi; wọ́n sì lọ, orílẹ̀-èdè méjèèjì sì jùmọ̀ ń gbé pọ̀ láti ìgbà náà.
Pii aku la na mamo a ka mea no Keni, a ka makuahonowai kane o Mose, mai ke kulanakauhale o na laau pama aku, me na mamo a Iuda, a i ka waonahele o ka Iuda, aia no ia ma ka aoao hema o Arada; a hele ae la lakou a noho pu iho la me kanaka.
17 Ó sì ṣe, àwọn ológun Juda tẹ̀lé àwọn ológun Simeoni arákùnrin wọn, wọ́n sì lọ bá àwọn ará Kenaani tí ń gbé Sefati jagun, wọ́n sì run ìlú náà pátápátá, ní báyìí àwa yóò pe ìlú náà ní Horma (Horma èyí tí ń jẹ́ ìparun).
Hele pu aku la ka Iuda, me ka Simeona, kona kaikuaana, a luku aku la lakou i ko Kanaana, ka poe i noho ma Zepata, a hooki loa iho la ia wahi. Ua kapaia ka inoa o ia kulanakauhale, o Horema.
18 Àwọn ogun Juda sì ṣẹ́gun Gasa àti àwọn agbègbè rẹ̀, Aṣkeloni àti Ekroni pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó yí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ká.
Hoopio iho la ka Iuda ia Gaza a me ko laila mau mokuna, a ia Asekelona kekahi me ko laila mau mokuna, a ia Ekerona hoi me ko laila mau mokuna.
19 Olúwa sì wà pẹ̀lú ẹ̀yà Juda, wọ́n gba ilẹ̀ òkè, ṣùgbọ́n wọn kò le lé àwọn ènìyàn tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, nítorí wọ́n ní kẹ̀kẹ́ ogun onírin.
O Iehova pu no kekahi me ka Iuda, a loaa ia lakou ka mauna; aole hiki ia lakou ke kipaku aku i ka poe i noho ma na aina haahaa, no ka mea, he hao ko lakou kaakaua.
20 Gẹ́gẹ́ bí Mose ti ṣèlérí, wọ́n fún Kalebu ní Hebroni, ó sì lé àwọn tí ń gbé ibẹ̀ kúrò; àwọn náà ni ìran àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta.
A haawi ae la lakou ia Heberona no Kaleba, e like me ka Mose i olelo mai ai. A kipaku aku la ia, malaila aku, i na keiki ekolu a Anaka.
21 Àwọn ẹ̀yà Benjamini ni wọn kò le lé àwọn Jebusi tí wọ́n ń gbé Jerusalẹmu, nítorí náà wọ́n ń gbé àárín àwọn Israẹli títí di òní.
Aole i kipaku na mamo a Beniamina i ka Iebusi, i noho ma Ierusalema; aka, noho pu no ka Iebusi me na mamo a Beniamina ma Ierusalema, a hiki loa mai i keia la.
22 Àwọn ẹ̀yà Josẹfu sì bá Beteli jagun, Olúwa síwájú pẹ̀lú wọn.
O ka ohana a Iosepa kekahi i pii, e kaua aku ia Betela; a o Iehova pu no me lakou.
23 Nígbà tí ẹ̀yà Josẹfu rán àwọn ènìyàn láti lọ yọ́ Beteli wò (orúkọ ìlú náà tẹ́lẹ̀ rí ni Lusi).
Kiu aku ka ohana a Iosepa ia Betela. o Luza ka inoa kahiko o ia kulanakauhale.
24 Àwọn ayọ́lẹ̀wò náà rí ọkùnrin kan tí ń jáde láti inú ìlú náà wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Fi ọ̀nà àtiwọ ìlú yìí hàn wá, àwa ó sì dá ẹ̀mí rẹ sí, a ó sì ṣe àánú fún ọ.”
Ike aku la na kiu i kekahi kanaka, mai ke kulanakauhale ia i hele mai ai. I aku la lakou ia ia, E kuhikuhi mai oe ia makou, i kahi e komo aku ai iloko o ke kulanakauhale, a e hana lokomaikai aku makou ia oe.
25 Ó sì fi ọ̀nà ìlú náà hàn wọ́n, wọ́n sì fi ojú idà kọlu ìlú náà, ṣùgbọ́n wọ́n dá ọkùnrin náà àti gbogbo ìdílé rẹ̀ si.
Kuhikuhi mai la oia ia lakou i kahi o komo aku ai iloko o ke kulanakauhale, a luku aku la lakou ia kulanakauhale i ka maka o ka pahi kaua; a kuu aku la lakou i ua kanaka la, a me kona poe a pau.
26 Ọkùnrin náà sí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Hiti, ó sì tẹ ìlú kan dó, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Lusi, èyí sì ni orúkọ rẹ̀ títí di òní.
A hele aku la ua kanaka nei i ka aina o ka Heta, a kukulu iho la i kulanakauhale, a kapa aku la i ka inoa, o Luza, oia hoi kona inoa a hiki mai i neia la.
27 Ṣùgbọ́n Manase kò lé àwọn ará Beti-Ṣeani àti ìlú rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì jáde, tàbí àwọn ará Taanaki àti àwọn ìgbèríko rẹ̀, tàbí àwọn ará Dori àti àwọn ìgbèríko rẹ̀, tàbí àwọn ará Ibleamu àti àwọn ìgbèríko rẹ̀, tàbí àwọn ará Megido àti àwọn ìgbèríko tí ó yí i ká, torí pé àwọn ará Kenaani ti pinnu láti máa gbé ìlú náà.
Aole i kipaku ka Manase i ko Beteseana, a me ko laila mau wahi; aole hoi i ko Taanaka, a me ko laila mau wahi, aole i ka poe i noho ma Dora, a me ko laila mau wahi; aole i ka poe i noho ma Ibeleama, a me ko laila mau wahi, aole i ka poe i noho ma Megido, a me ko laila mau wahi; aka, hoopaa no ko Kanaana i ko lakou noho ana ma ia aina.
28 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli di alágbára, wọ́n mú àwọn ará Kenaani sìn bí i ẹrú, ṣùgbọ́n wọn kò fi agbára lé wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ náà.
A hiki i ka manawa i ikaika ai ka Iseraela, auhau aku la lakou i ko Kanaana, aole i kipaku loa ia lakou.
29 Efraimu náà kò lé àwọn ará Kenaani tí ó ń gbé Geseri jáde, ṣùgbọ́n àwọn ará Kenaani sì ń gbé láàrín àwọn ẹ̀yà Efraimu.
Aole hoi i kipaku ka Eperaima i ko Kanaana i noho ma Gezera. Noho pu no ko Kanaana me lakou ma Gezera.
30 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Sebuluni kò lé àwọn ará Kenaani tí ń gbé Kitironi jáde tàbí àwọn ará Nahalali, ṣùgbọ́n wọ́n sọ wọ́n di ẹrú. Wọ́n sì ń sin àwọn ará Sebuluni.
Aole hoi i kipaku aku ka Zebuluna i ka poe i noho ma Kiterona, aole i ka poe i noho ma Nahalola. Noho pu no ko Kanaana mo lakou, a lilo lakou i poe i hookupu mai.
31 Bẹ́ẹ̀ ni Aṣeri kò lé àwọn tí ń gbé ní Akko tàbí ní Sidoni tàbí ní Ahlabu tàbí ní Aksibu tàbí ní Helba tàbí ní Afiki tàbí ní Rehobu.
Aole hoi i kipaku aku o Asera i ka poe i noho ma Ako, aole i ka poe i noho ma Zidona, aole i ko Ahelaba, aole i ko Akeziba, aole i ko Helaba, aole i ko Apika, aole i ko Rehoba.
32 Ṣùgbọ́n nítorí àwọn ará Aṣeri ń gbé láàrín àwọn ará Kenaani tí wọ́n ni ilẹ̀ náà.
Noho pu no ka Asera me ko Kanaana, na kanaka o ka aina, no ka mea, aole lakou i kipaku aku ia poe.
33 Àwọn ẹ̀yà Naftali pẹ̀lú kò lé àwọn ará Beti-Ṣemeṣi àti Beti-Anati jáde; ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Naftali náà ń gbé àárín àwọn ará Kenaani tí ó ti ní ilẹ̀ náà rí, ṣùgbọ́n àwọn tí ń gbé Beti-Ṣemeṣi àti Beti-Anati ń sìn ìsìn tipátipá.
Aole hoi i kipaku aku ka Napetali i ka poe i noho ma Betesemesa, aole hoi i ka poe i noho ma Beteanata; noho pu no lakou me ko Kanaana, na kanaka o ka aina; aka, lilo na kanaka o Betesemesa, a me Beteanata, i poe hookupu mai na lakou.
34 Àwọn ará Amori fi agbára dá àwọn ẹ̀yà Dani dúró sí àwọn ìlú orí òkè, wọn kò sì jẹ́ kí wọn sọ̀kalẹ̀ wá sí pẹ̀tẹ́lẹ̀.
Hooke aku la ka Amora i na mamo a Dana, a hiki iluna o ka puu. Aole lakou i ae aku ke iho mai ia poe i na aina papu.
35 Àwọn ará Amori ti pinnu láti dúró lórí òkè Heresi àti òkè Aijaloni àti ti Ṣaalbimu, ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yà Josẹfu di alágbára wọ́n borí Amori wọ́n sì mú wọn sìn.
Hoopaa no ka Amora i ko lakou noho ana ma ka mauna o Heresa, a ma Aialona, a ma Saalebima: aka, ua kaumaha aku no ka lima o ko Iosepa poe, a lilo kela i poe hookupu mai.
36 Ààlà àwọn ará Amori sì bẹ̀rẹ̀ láti ìgòkè Akrabbimu kọjá lọ sí Sela àti síwájú sí i.
O na mokuna o ka Amora, mai ka puu o Akerabima aku ia, a mai I Sela aku no.

< Judges 1 >