< John 3 >

1 Ọkùnrin kan sì wà nínú àwọn Farisi, tí a ń pè ní Nikodemu, ìjòyè kan láàrín àwọn Júù.
O KEKAHI kanaka o ka poe Parisaio, o Nikodemo kona inoa, he alii o na Iudaio:
2 Òun náà ní ó tọ Jesu wá ní òru, ó sì wí fún un pé, Rabbi, àwa mọ̀ pé olùkọ́ni láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá ni ìwọ ń ṣe, nítorí pé kò sí ẹni tí ó lè ṣe iṣẹ́ àmì wọ̀nyí tí ìwọ ń ṣe, bí kò ṣe pé Ọlọ́run wà pẹ̀lú rẹ̀.
Hele aku la ia io Iesu la i ka po, i aku la ia ia, E Rabi, ua ike makou he kumu oe i hele mai nei mai ke Akua mai: no ka mea, aole e hiki i kekahi kanaka ke hana i keia mau hana mana au e hana nei, ke ole ke Akua me ia.
3 Jesu dáhùn ó sì wí fún un pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, bí kò ṣe pé a tún ènìyàn bí, òun kò lè rí ìjọba Ọlọ́run.”
Olelo mai la o Iesu ia ia, i mai la, Oiaio, he oiaio ka'u e olelo aku nei ia oe, Ina e hanau hou ole ia ke kanaka, aole e hiki ia ia ke ike aku i ke aupuni o ke Akua.
4 Nikodemu wí fún un pé, a ó ti ṣe lè tún ènìyàn bí nígbà tí ó di àgbàlagbà tan? Ó ha lè wọ inú ìyá rẹ̀ lọ nígbà kejì, kí a sì bí i?
Ninau aka la o Nikodemo ia ia, Pehea la e hiki ai i ke kanaka ke hanauia i kona wa kahiko? e hiki anei ia ia ke komo hoa iloko o ka opu o kona makuwahine, a e hanauia mai?
5 Jesu dáhùn wí pé, “Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, bí kò ṣe pé a fi omi àti Ẹ̀mí bí ènìyàn, òun kò lè wọ ìjọba Ọlọ́run.
Olelo mai la o Iesu, Oiaio, he oiaio ka'u e olelo aku nei ia oe, Ina e hanau ole ia ke kanaka i ka wai, a me ka Uhane, aole e hiki ia ia ke komo iloko o ke aupuni o ke Akua.
6 Èyí tí a bí nípa ti ara, ti ara ni; èyí tí a sì bí nípa ti Ẹ̀mí, ti Ẹ̀mí ni.
O ka mea i hanauia na ke kino, he kino no ia; a o ka mea i hanauia na ka Uhane, he uhane ia.
7 Kí ẹnu kí ó má ṣe yà ọ́, nítorí mo wí fún ọ pé, ‘A kò lè ṣe aláìtún yín bí.’
Mai kahaha kou naau i ka'u i olelo aku ai ia oe, E pau oukou i ka hanau hou e pono ai.
8 Afẹ́fẹ́ ń fẹ́ sí ibi tí ó gbé wù ú, ìwọ sì ń gbọ́ ìró rẹ̀, ṣùgbọ́n ìwọ kò mọ ibi tí ó gbé ti wá, àti ibi tí ó gbé ń lọ, gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí a bí nípa ti Ẹ̀mí.”
Ke pa nei ka makani i kana wahi i makemake ai, a lohe no oe i kona halulu, aole nae oe i ike i kana wahi i hele mai ai, aole hoi i kana wahi e hele aku ai: pela hoi na mea a pau i hanauia e ka Uhane.
9 Nikodemu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Nǹkan wọ̀nyí yóò ti ṣe lè rí bẹ́ẹ̀?”
Olelo aku la o Nikodemo, i aku la, Pehea la e hiki ai keia mau mea.
10 Jesu dáhùn, ó sì wí fún un pé, “Ṣé olùkọ́ni ní Israẹli ni ìwọ ń ṣe, o kò sì mọ nǹkan wọ̀nyí?
Olelo mai la o Iesu, i mai la ia ia. He kumu oe na ka Iseraela, aole anei oe i ike ia mau mea?
11 Lóòótọ́ lóòótọ́ ni mo wí fún ọ, Àwa ń sọ èyí tí àwa mọ̀, a sì ń jẹ́rìí èyí tí àwa ti rí; ẹ̀yin kò sì gba ẹ̀rí wa.
Oiaio, he oiaio ka'u olelo aku nei ia oe, O ka makou mea i ike ai, o ka makou ia e olelo nei, a o ka makou mea i nana'i, oia ka makou e hoike nei; aole hoi oukou i hoomaopopo i ka mea a makou e hoike nei.
12 Bí mo bá sọ ohun ti ayé yìí fún yín, tí ẹ̀yin kò sì gbàgbọ́, ẹ̀yin ó ti ṣe gbàgbọ́ bí mo bá sọ ohun ti ọ̀run fún yín?
Ina ua oleie wau i na mea o keia ao, a manaoio ole oukou, pehea la oukou e manaoio ai, ke olelo wau ia oukou i na mea iloko o ka lani?
13 Kò sì ṣí ẹni tí ó gòkè re ọ̀run bí kò ṣe ẹni tí ó ti ọ̀run sọ̀kalẹ̀ wá, Ọmọ Ènìyàn tí ń bẹ ní ọ̀run.
Aohe kanaka i pii iluna i ka lani, o ka mea wale no i iho mai, mai ka lani mai, o ke Keiki a ke kanaka, o ka mea iloko o ka lani.
14 Bí Mose sì ti gbé ejò sókè ní aginjù, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni a kò le ṣe aláìgbé Ọmọ Ènìyàn sókè pẹ̀lú.
A e like me ka Mose kau ana i ka nahesa iluna ma ka waonahele, pela e pono ai ke Keiki a ke kanaka e kaulia'i;
15 Kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, kí ó má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó le ní ìyè àìnípẹ̀kun.” (aiōnios g166)
I ole e make ka mea manaoio ia ia, aka, e loaa ia ia ke ola mau loa. (aiōnios g166)
16 “Nítorí Ọlọ́run fẹ́ aráyé tó bẹ́ẹ̀ gẹ́ẹ́, tí ó fi ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo fún ni, kí ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà á gbọ́, má bà á ṣègbé, ṣùgbọ́n kí ó lè ní ìyè àìnípẹ̀kun. (aiōnios g166)
No ka mea, na aloha nui mai ke Akua i ko ke ao nei, nolaila, ua haawi mai oia i kana Keiki hiwahiwa, i ole e make ka mea manaoio ia ia, aka, e loaa ia ia ke ola mau loa. (aiōnios g166)
17 Nítorí Ọlọ́run kò rán ọmọ rẹ̀ sí ayé láti dá aráyé lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n kí a le ti ipasẹ̀ rẹ̀ gba aráyé là.
Aole no hoi i hoouna mai ke Akua i kana Keiki i ke ao nei, i hoohewa'i oia i ko ke ao nei; aka, i ola'i ko ke ao nei ma o na la.
18 Ẹni tí ó bá gbà á gbọ́, a kò ní dá a lẹ́jọ́; ṣùgbọ́n a ti dá ẹni tí kò gbà á gbọ́ lẹ́jọ́ ná, nítorí tí kò gba orúkọ ọmọ kan ṣoṣo ti Ọlọ́run gbọ́.
O ka mea manaoio ia ia, aole ia e hoahewaia; aka o ka mea manaoio ole, ua hoahewaia oia ano, i kona manaoio ole i ka inoa o ke Keiki hiwahiwa a ke Akua.
19 Èyí ni ìdájọ́ náà pé, ìmọ́lẹ̀ wá sí ayé, àwọn ènìyàn sì fẹ́ òkùnkùn ju ìmọ́lẹ̀ lọ, nítorí tí iṣẹ́ wọn burú.
Eia ka mea i hoahewaia'i; ua hiki mai ka malamalama i ke ao nei, aka, ua makemake na kanaka i ka pouli, aole i ka malamalama, no ka mea, ua hewa na hana ana a lakou.
20 Nítorí olúkúlùkù ẹni tí ó bá hùwà búburú ní ìkórìíra ìmọ́lẹ̀, kì í sì í wá sí ìmọ́lẹ̀, kí a má ṣe bá iṣẹ́ rẹ̀ wí.
O ka mea e hana ana i na mea ino, oia ke hoowahawaha i ka malamalama, aole hoi ia e hele mai i ka malamalama, o ikea auanei kana hana ana.
21 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá ń sọ òtítọ́ ní í wá sí ìmọ́lẹ̀, kí iṣẹ́ rẹ̀ kí ó lè fi ara hàn pé a ṣe wọ́n nípa ti Ọlọ́run.”
Aka, o ka mea o hana ana ma ka oiaio, oia ke hele mai i ka malamalama, i akaka ai kana hana ana, ua hanaia ma ka ke Akua.
22 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, Jesu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wá sí ilẹ̀ Judea; ó sì dúró pẹ̀lú wọn níbẹ̀ ó sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi fún ni.
A mahope iho o keia mau mea, hele aku la o Iesu me kana poe haumana i ka aina o Iudea; a noho iho la ia ilaila me lakou, a bapetizo iho la.
23 Johanu pẹ̀lú sì ń ṣe ìtẹ̀bọmi ní Aenoni, ní agbègbè Salimu, nítorí tí omi púpọ̀ wà níbẹ̀, wọ́n sì ń wá, a sì ń tẹ̀ ẹ́ wọn bọ omi.
A e bapetizo ana no hoi o Ioane ma Ainona e kokoke ana i Salima, no ka mea, ua nui ka wai malaila; a hele mai lakouu; a bapetizoia iho la.
24 (Nítorí tí a kò tí ì sọ Johanu sínú túbú).
No ka mea, aole i hahaoia o Ioane iloko a ka halepaahao ia ma nawa.
25 Nígbà náà ni iyàn kan wà láàrín àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu àti Júù kan nípa ti ìwẹ̀nù.
Ia wa hoopaapaa ae la na haumana a Ioane me na Iudaio no ka hoomaemae ana.
26 Wọ́n sì tọ Johanu wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Rabbi, ẹni tí ó ti wà pẹ̀lú rẹ lókè odò Jordani, tí ìwọ ti jẹ́rìí rẹ̀, wò ó, òun tẹ àwọn ènìyàn bọ omi, gbogbo ènìyàn sì ń tọ̀ ọ́ wá.”
A hele aku la lakou io Ioane la, i aku la ia ia, E Rabi, o ka mea me oe ma kela kapa o Ioredane, nona au i hoike ai, aia hoi, ke bapetizo la oia, a ke hele nei na kanaka a pau io na la.
27 Johanu dáhùn ó sì wí pé, “Ènìyàn kò le rí nǹkan kan gbà, bí kò ṣe pé a bá ti fi fún ún láti ọ̀run wá.
Olelo mai la o Ioane, i mai la, Aole e hiki i ke kanaka ko lawe wale i kekahi mea, ke haawi ole ia mai ia nana mai ka lani moi.
28 Ẹ̀yin fúnra yín jẹ́rìí mi pé mo wí pé, ‘Èmi kì í ṣe Kristi náà, ṣùgbọ́n pé a rán mi síwájú rẹ̀.’
O oukou no ko'u poe hoike i ka'u i olelo ai, Aole wau ka Mesia, aka, ua hoounaia mai au mamua ona.
29 Ẹni tí ó bá ni ìyàwó ni ọkọ ìyàwó; ṣùgbọ́n ọ̀rẹ́ ọkọ ìyàwó tí ó dúró tí ó sì ń gbóhùn rẹ̀, ó ń yọ̀ gidigidi nítorí ohùn ọkọ ìyàwó; nítorí náà ayọ̀ mi yí di kíkún.
O ka mea nana ka wahine mare, o ke kane mare ia: aka, o ka hoaaloha o ke kane mare o ku ana, a e hoolohe ana ia ia, oia ke olioli nui i ka leo o ke kane mare. Ua loaa hoi ia'u keia olioli.
30 Òun kò lè ṣàì máa pọ̀ sí i, ṣùgbọ́n èmi kò lè ṣàìmá rẹlẹ̀.
E mahuahua ana no oia, aka, e emi iho auanei hoi au.
31 “Ẹni tí ó ti òkè wá ju gbogbo ènìyàn lọ; ẹni tí ó ti ayé wá ti ayé ni, a sì máa sọ ohun ti ayé. Ẹni tí ó ti ọ̀run wá ju gbogbo ènìyàn lọ.
O ka mea noluna mai maluna ia o na mea a pau: o ka mea no ka honua, no ka honua ia, a no ka honua hoi kana olelo: o ka mea no ka lani mai, maluna ia o na mea a pau.
32 Ohun tí ó ti rí tí ó sì ti gbọ́ èyí náà sì ni òun ń jẹ́rìí rẹ̀; kò sì sí ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀.
O ka mea ana i ike ai, a i lohe ai hoi, oia kana e hoike ai; aole nae kekahi mea i malama i kana mea i hoike ai.
33 Ẹni tí ó gba ẹ̀rí rẹ̀ fi èdìdì dì í pé, olóòtítọ́ ni Ọlọ́run.
O ka mea o malama i kana mea i hoike mai ai, oia ke ae mai, he oiaio ka ke Akua.
34 Nítorí ẹni tí Ọlọ́run ti rán ń sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run: nítorí tí Ọlọ́run fi Ẹ̀mí fún un láìsí gbèdéke.
No ka mea, o ka ke Akua mea i hoouna mai ai, o ka ke Akua olelo kana e olelo ai: no ka mea, aole ke Akua e haawi liilii mai i ka Uhane ia ia.
35 Baba fẹ́ Ọmọ, ó sì ti fi ohun gbogbo lé e lọ́wọ́.
Ke aloha nei ka Makua i ke Keiki, a na haawi hoi ia i na mea a pau iloko o kona lima.
36 Ẹni tí ó bá gba Ọmọ gbọ́, ó ní ìyè àìnípẹ̀kun, ẹni tí kò bá sì gba Ọmọ gbọ́, kì yóò rí ìyè, nítorí ìbínú Ọlọ́run ń bẹ lórí rẹ̀.” (aiōnios g166)
O ka mea manaoio i ke Keiki, he ola mau loa kona: aka, o ka mea manaoio ole i ke Keiki, aole ia e ike i ke oia; e kau mai ana ka inaina o ke Akua maluna iho ona. (aiōnios g166)

< John 3 >