< Job 25 >

1 Nígbà náà ní Bilidadi, ará Ṣuhi, dáhùn wí pé,
Then Baldad the Suhite answered, and I said:
2 “Ìjọba àti ẹ̀rù ń bẹ lọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀, òun ní i ṣe ìlàjà ní ibi gíga gíga ọ̀run.
Power and terror are with him, who maketh peace in his high places.
3 Àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ ha ní ìyè bí, tàbí ara ta ni ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ kò tàn sí?
Is there any numbering of his soldiers? and upon whom shall not his light arise?
4 Èéha ti ṣe tí a ó fi dá ènìyàn láre lọ́dọ̀ Ọlọ́run? Tàbí ẹni tí a bí láti inú obìnrin wá yóò ha ṣe mọ́?
Can man be justified compared with God, or he that is born of a woman appear clean?
5 Kíyèsi i, òṣùpá kò sì lè tàn ìmọ́lẹ̀, àní àwọn ìràwọ̀ kò mọ́lẹ̀ ní ojú rẹ̀,
Behold even the moon doth not shine, and the stars are not pure in his sight.
6 kí a má sọ ènìyàn tí i ṣe ìdin, àti ọmọ ènìyàn tí í ṣe kòkòrò!”
How much less man that is rottenness and the son of man who is a worm?

< Job 25 >