< Job 18 >

1 Ìgbà náà ni Bilidadi, ará Ṣuhi, dáhùn, ó sì wí pé,
Then answered Bildad the Shuhite, and said,
2 “Nígbà wo ni ẹ̀yin yóò tó fi ìdí ọ̀rọ̀ tì; ẹ rò ó, nígbẹ̀yìn rẹ̀ ni àwa ó tó máa sọ.
How long [will it be ere] ye make an end of words? mark, and afterwards we will speak.
3 Nítorí kí ni a ṣe ń kà wá sí bí ẹranko, tí a sì ń kà wá si bí ẹni ẹ̀gàn ní ojú yín?
Wherefore are we counted as beasts, [and] reputed vile in your sight?
4 Ìwọ fa ara rẹ ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ nínú ìbínú rẹ̀; kí a ha kọ ayé sílẹ̀ nítorí rẹ̀ bi? Tàbí kí a sí àpáta kúrò ní ipò rẹ̀?
He teareth himself in his anger: shall the earth be forsaken for thee? and shall the rock be removed out of his place?
5 “Nítòótọ́ ìmọ́lẹ̀ ènìyàn búburú ni a ó pa kúrò, ọ̀wọ́-iná rẹ̀ kì yóò sì tan ìmọ́lẹ̀.
Yea, the light of the wicked shall be put out, and the spark of his fire shall not shine.
6 Ìmọ́lẹ̀ yóò di òkùnkùn nínú àgọ́ rẹ̀, fìtílà ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni a ó sì pa pẹ̀lú.
The light shall be dark in his tabernacle, and his candle shall be put out with him.
7 Ìrìn ẹsẹ̀ agbára rẹ̀ yóò di fífọ; ète òun tìkára rẹ̀ ni yóò bí i ṣubú.
The steps of his strength shall be straitened, and his own counsel shall cast him down.
8 Nípa ẹ̀ṣẹ̀ òun tìkára rẹ̀ ó ti bọ́ sínú àwọ̀n, ó sì rìn lórí okùn dídẹ.
For he is cast into a net by his own feet, and he walketh upon a snare.
9 Tàkúté ni yóò mú un ní gìgísẹ̀, àwọn àwọ̀n tí a dẹ yóò sì ṣẹ́gun rẹ̀.
The gin shall take [him] by the heel, [and] the robber shall prevail against him.
10 A dẹkùn sílẹ̀ fún un lórí ilẹ̀, a sì wà ọ̀fìn fún un lójú ọ̀nà.
The snare [is] laid for him in the ground, and a trap for him in the way.
11 Ẹ̀rù ńlá yóò bà á ní ìhà gbogbo, yóò sì lé e dé ẹsẹ̀ rẹ̀.
Terrors shall make him afraid on every side, and shall drive him to his feet.
12 Àìlera rẹ̀ yóò di púpọ̀ fún ebi, ìparun yóò dìde dúró sí i nígbà tí ó bá ṣubú.
His strength shall be hungerbitten, and destruction [shall be] ready at his side.
13 Yóò jẹ ẹ̀yà ara rẹ̀; ikú àkọ́bí ni yóò jẹ agbára rẹ̀ run.
It shall devour the strength of his skin: [even] the firstborn of death shall devour his strength.
14 A ó fà á tu kúrò nínú àgọ́ tí ó gbẹ́kẹ̀lé, a ó sì mú un tọ ọba ẹ̀rù ńlá nì lọ.
His confidence shall be rooted out of his tabernacle, and it shall bring him to the king of terrors.
15 Yóò sì máa jókòó nínú àgọ́ rẹ̀ èyí tí í ṣe tirẹ̀; sulfuru ti o jóná ni a ó fún káàkiri ibùgbé rẹ̀.
It shall dwell in his tabernacle, because [it is] none of his: brimstone shall be scattered upon his habitation.
16 Gbòǹgbò rẹ̀ yóò gbẹ níṣàlẹ̀, a ó sì ké ẹ̀ka rẹ̀ kúrò lókè.
His roots shall be dried up beneath, and above shall his branch be cut off.
17 Ìrántí rẹ̀ yóò parun kúrò ni ayé, kì yóò sí orúkọ rẹ̀ ní ìgboro ìlú.
His remembrance shall perish from the earth, and he shall have no name in the street.
18 A ó sì lé e láti inú ìmọ́lẹ̀ sí inú òkùnkùn, a ó sì lé e kúrò ní ayé.
He shall be driven from light into darkness, and chased out of the world.
19 Kì yóò ní ọmọ tàbí ọmọ ọmọ nínú àwọn ènìyàn rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò kù nínú agbo ilé rẹ̀.
He shall neither have son nor nephew among his people, nor any remaining in his dwellings.
20 Ẹnu yóò ya àwọn ìran ti ìwọ̀-oòrùn sí ìgbà ọjọ́ rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀rù ìwárìrì ti í bá àwọn ìran ti ìlà-oòrùn.
They that come after [him] shall be astonied at his day, as they that went before were affrighted.
21 Nítòótọ́ irú bẹ́ẹ̀ ni ibùgbé àwọn ènìyàn búburú, èyí sì ni ipò ẹni tí kò mọ̀ Ọlọ́run.”
Surely such [are] the dwellings of the wicked, and this [is] the place [of him that] knoweth not God.

< Job 18 >