< Jeremiah 50 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
Słowo, które PAN wypowiedział przeciwko Babilonowi i przeciwko ziemi Chaldejczyków przez proroka Jeremiasza:
2 “Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde, kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé, ‘A kó Babeli, ojú tí Beli, a fọ́ Merodaki túútúú, ojú ti àwọn ère rẹ̀, a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
Opowiadajcie wśród narodów, rozgłaszajcie, podnieście sztandar, głoście i nie zatajajcie. Mówcie: Babilon wzięty, Bel pohańbiony, Merodach rozbity; jego posągi pohańbione, jego bożki pokruszone.
3 Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò sì máa gbóguntì wọ́n. Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò sá kúrò ní ìlú yìí.
Nadciągnie bowiem przeciwko niemu naród z północy, który zamieni jego ziemię w pustkowie, tak że nikt w niej nie zamieszka. Uciekną [i] odejdą zarówno ludzie, jak i zwierzęta.
4 “Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,” ni Olúwa wí, “Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá, àwọn, àti àwọn ọmọ Juda, wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí Olúwa Ọlọ́run wọn.
W tych dniach i w tym czasie, mówi PAN, przyjdą synowie Izraela, a wraz z nimi synowie Judy; będą szli w płaczu i będą szukać PANA, swego Boga.
5 Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé, tí a kì yóò gbàgbé.
Będą pytać o drogę na Syjon i [zwróciwszy] tam swoje twarze, [powiedzą]: Chodźcie i przyłączmy się do PANA wiecznym przymierzem, które nie ulegnie zapomnieniu.
6 “Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà, wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré, wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
Mój lud był trzodą owiec zbłąkanych, ich pasterze wiedli ich na manowce, po górach ich rozegnali. Schodził z góry na pagórek, zapomniał o swoim legowisku.
7 Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
Wszyscy, którzy ich spotykali, pożerali ich, a ich wrogowie mówią: Nie jesteśmy nic winni, bo to oni zgrzeszyli [przeciwko] PANU, przybytkowi sprawiedliwości, [przeciwko] PANU, nadziei ich ojców.
8 “Jáde kúrò ní Babeli, ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
Uchodźcie ze środka Babilonu, wychodźcie z ziemi Chaldejczyków i bądźcie jak kozły przed trzodą.
9 Nítorí pé èmi yóò ru, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀; láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo.
Oto bowiem wzbudzę i sprowadzę na Babilon gromadę wielkich narodów z ziemi północnej. I uszykują się przeciwko niemu, i stamtąd będzie zdobyty. Ich strzały będą jak u wprawnego mocarza, żadna nie wróci bez skutku.
10 A ó dààmú Babeli, gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,” ni Olúwa wí.
Chaldea będzie łupem, [a] wszyscy, którzy ją złupią, zostaną nasyceni, mówi PAN.
11 “Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀, ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù, ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
Ponieważ się cieszyliście, ponieważ się radowaliście, grabieżcy mego dziedzictwa; ponieważ utyliście jak jałówka na trawie i ryczycie jak wół;
12 Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ yóò sì gba ìtìjú. Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
Wasza matka będzie bardzo zawstydzona, spłonie ze wstydu wasza rodzicielka. Oto [stanie się] ostatnią z narodów, pustkowiem, ziemią suchą i pustynną.
13 Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé; ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀. Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
Z powodu gniewu PANA nie będzie zamieszkana, ale cała zostanie spustoszona. Ktokolwiek będzie przechodził obok Babilonu, zdumieje się i będzie świstał nad wszystkimi jego plagami.
14 “Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà. Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
Ustawcie się przeciw Babilonowi w koło. Wszyscy, którzy napinacie łuk, strzelajcie do niego, nie żałujcie strzał, bo zgrzeszył przeciwko PANU.
15 Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà! Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa, gbẹ̀san lára rẹ̀. Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
Wołajcie przeciwko niemu zewsząd. Poddał się, upadły jego fundamenty, jego mury są zburzone. Jest to bowiem zemsta PANA. Pomścijcie się nad nim; jak on czynił [innym, tak] jemu też uczyńcie.
16 Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli, àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè! Nítorí idà àwọn aninilára jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
Wyniszczcie z Babilonu siewcę i tego, który chwyta sierp w czasie żniwa. Przed mieczem niszczycielskim każdy się zwróci do swego ludu i każdy ucieknie do swojej ziemi.
17 “Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri, kìnnìún sì ti lé e lọ. Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ, àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli fa egungun rẹ̀ ya.”
Izrael jest owcą przegnaną, [którą] spłoszyły lwy. Najpierw król Asyrii pożarł go, a na koniec ten Nabuchodonozor, król Babilonu, pokruszył jego kości.
18 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí, “Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
Dlatego tak mówi PAN zastępów, Bóg Izraela: Oto ukarzę króla Babilonu i jego ziemię, jak ukarałem króla Asyrii.
19 Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli padà wá pápá oko tútù rẹ̀ òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani, a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè Efraimu àti ní Gileadi.
I znowu przyprowadzę Izraela do swego mieszkania, i będzie się paść na Karmelu i w Baszanie, i jego dusza nasyci się na górze Efraim i w Gileadzie.
20 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun; àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
W tych dniach i w tym czasie, mówi PAN, będą szukać nieprawości Izraela, ale jej nie będzie, i grzechów Judy, ale nie będą znalezione. Przebaczę bowiem tym, których pozostawię.
21 “Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn tí ó ń gbé ní Pekodi. Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,” ni Olúwa wí, “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
Wyrusz przeciwko ziemi Meratajim, przeciwko niej i mieszkańcom Pekod. Spustosz i zniszcz doszczętnie, goniąc ich, mówi PAN, i uczyń wszystko, jak ci rozkazałem.
22 Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
Wrzawa wojenna w tej ziemi i wielkie spustoszenie.
23 Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó, lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé! Báwo ní Babeli ti di ahoro ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Jakże jest rozbity i złamany młot całej ziemi? Jakże Babilon stał się spustoszeniem wśród narodów?
24 Mo dẹ pàkúté sílẹ̀ fún ọ ìwọ Babeli, kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
Zastawiłem na ciebie sidła i zostałeś schwytany, Babilonie, a nie zauważyłeś tego. Znaleziono cię i pochwycono, ponieważ spierałeś się z PANEM.
25 Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
PAN otworzył swoją zbrojownię i wyniósł oręż swego gniewu. To bowiem jest dzieło Pana BOGA zastępów w ziemi Chaldejczyków.
26 Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo, sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà, kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun, ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
Ruszajcie przeciwko niemu z krańców [ziemi], otwórzcie jego spichlerze. Zbierzcie go w sterty i zniszczcie go doszczętnie, by nic z niego nie pozostało.
27 Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ, jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n! Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé, àkókò ìbẹ̀wò wọn.
Pozabijajcie wszystkie jego cielce, niech idą na rzeź. Biada im, bo nadszedł ich dzień, czas ich nawiedzenia.
28 Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá, sì sọ ní Sioni, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san, ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
[Słychać] głos uciekających i tych, co uchodzą z ziemi Babilonu, aby ogłosić na Syjonie pomstę PANA, naszego Boga, pomstę za jego świątynię.
29 “Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli, ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà. Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe, ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
Zgromadźcie przeciwko Babilonowi wszystkich strzelców, którzy napinają łuk; rozbijcie obóz przeciw niemu dokoła, aby [nikt] nie uszedł. Odpłaćcie mu według jego uczynków, według wszystkiego, co [innym] czynił, uczyńcie mu. Wynosił się bowiem przeciwko PANU, przeciwko Świętemu Izraela.
30 Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn ológun lẹ́nu mọ́,” ní Olúwa wí.
Dlatego jego młodzieńcy polegną na ulicach i wszyscy jego wojownicy zostaną zgładzeni w tym dniu, mówi PAN.
31 “Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “nítorí ọjọ́ rẹ ti dé, àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
Oto jestem przeciwko tobie, zuchwalcze, mówi Pan, BÓG zastępów. Nadszedł bowiem twój dzień [i] czas, gdy cię nawiedzę.
32 Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde. Èmi yóò tan iná ní ìlú náà, èyí tí yóò sì jo run.”
Potknie się zuchwalec i upadnie, i nikt go nie podniesie. Wzniecę ogień w jego miastach, który pochłonie wszystko wokół niego.
33 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú. Gbogbo àwọn tí ó kó wọn nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
Tak mówi PAN zastępów: Synowie Izraela i synowie Judy razem cierpią ucisk. Wszyscy, którzy ich pojmali, trzymają ich i nie chcą ich wypuścić.
34 Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀. Yóò sì gbe ìjà wọn jà, kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà; ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
[Ale] ich Odkupiciel jest potężny, jego imię to PAN zastępów, skutecznie będzie bronił ich sprawy, aby zapewnić pokój tej ziemi i trwożyć mieszkańców Babilonu.
35 “Idà lórí àwọn Babeli!” ni Olúwa wí, “lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli, àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
Miecz [spadnie] na Chaldejczyków, mówi PAN, i na mieszkańców Babilonu, na jego książąt i mędrców;
36 Idà lórí àwọn wòlíì èké wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun, wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
Miecz na kłamców, aby zgłupieli, miecz na jego wojowników, aby byli przerażeni;
37 Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀. Wọn yóò di obìnrin. Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
Miecz na jego konie i rydwany oraz na całą różnorodną ludność, która jest pośród niego, aby była jak kobiety; miecz na jego skarby, aby były zagrabione;
38 Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ. Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère, àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
Susza na jego wody, aby wyschły. Ziemia bowiem jest [pełna] rzeźbionych obrazów, a szaleją przy [swoich] bożkach.
39 “Nítorí náà àwọn ẹranko ijù pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀, abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀, a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
Dlatego zamieszkają tam dzikie zwierzęta pustyni i straszne bestie wysp, zamieszkają w nim też młode sowy. Nie będzie już zaludniony na wieki i nie będą [w nim] mieszkać po wszystkie pokolenia.
40 Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,” ni Olúwa wí, “torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀; ènìyàn ki yóò gbé nínú rè.
Jak Bóg zniszczył Sodomę i Gomorę oraz sąsiednie miasta, mówi PAN, [tak] też nikt tam nie zamieszka ani syn człowieczy nie będzie w nim gościł.
41 “Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá; orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
Oto lud nadciągnie z północy, naród wielki, i liczni królowie zostaną wzbudzeni z krańców ziemi.
42 Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun, wọ́n burú wọn kò sì ní àánú. Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ. Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
Pochwycą łuk i włócznię, są okrutni i bezlitośni; ich głos huczy jak morze i jeżdżą na koniach, każdy uszykowany do walki przeciwko tobie, córko Babilonu!
43 Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wọn sì rọ, ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
Król Babilonu usłyszał o nich wieść i osłabły mu ręce. Ogarnęła go udręka [i] bóle jak rodzącą kobietę.
44 Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
Oto jak lew wystąpi z wezbrania Jordanu przeciwko przybytkowi mocarza. Wypędzę go jednak nagle z tej ziemi, a ustanowię nad nią mojego wybrańca. Któż bowiem jest mi równy? Kto wyznaczy mi termin rozprawy? A kto jest tym pasterzem, który się ostoi przede mną?
45 Nítorí náà, gbọ́ ohun tí Olúwa sọ nípa Babeli, ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli: n ó sì pa agbo ẹran wọn run.
Dlatego słuchajcie postanowienia PANA, które powziął przeciwko Babilonowi i jego zamysłów, które przygotował przeciwko ziemi Chaldejczyków. Zaprawdę, wywloką ich najmniejsi z tej trzody, spustoszą ich i [ich] mieszkania.
46 Ní ohùn igbe ńlá pé; a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì, a sì gbọ́ igbe náà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
Od huku przy zdobyciu Babilonu ziemia się porusza, słychać krzyk wśród narodów.

< Jeremiah 50 >