< Jeremiah 49 >

1 Nípa Ammoni. Báyìí ni Olúwa wí, “Israẹli kò ha ní ọmọkùnrin? Israẹli kò ha ní àrólé bí? Nítorí kí ni Malkomu ṣe jogún Gadi? Kí ló dé tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ń gbé ìlú rẹ̀?
`Go ye to the sones of Amon. The Lord seith these thingis. Whether no sones ben of Israel, ether an eir is not to it? whi therfor weldide Melchon the eritage of Gad, and the puple therof dwellide in the citees of Gad?
2 Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí; “nígbà tí èmi yóò mú kí a gbọ́ ìdágìrì ogun ní Rabba tí Ammoni; yóò sì di òkìtì ahoro, gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná. Nígbà náà ni Israẹli yóò lé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,” ni Olúwa wí.
Lo! daies comen, seith the Lord, and Y schal make the gnaisting of batel herd on Rabath of the sones of Amon; and it schal be distried in to noise, and the vilagis therof schulen be brent with fier, and Israel schal welde hise welderis, seith the Lord.
3 “Hu, ìwọ Heṣboni, nítorí Ai tí rún! Kígbe ẹ̀yin olùgbé Rabba! Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀. Ẹ sáré sókè sódò nínú ọgbà, nítorí Malkomu yóò lọ sí ìgbèkùn, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.
Yelle ye, Esebon, for Hay is distried; crie, ye douytris of Rabath, girde you with heiris, weile ye, and cumpasse bi heggis; for whi Melchon schal be lad in to passyng ouer, the prestis therof and princes therof togidere.
4 Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣògo nínú àfonífojì rẹ, ṣògo nínú àfonífojì rẹ fún èso? Ẹ̀yin ọmọbìnrin Ammoni aláìṣòótọ́, ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé, ‘Ta ni yóò kò mí lójú?’
What hast thou glorie in valeis? Thi valeis fleet awei, thou delicat douyter, that haddist trist in thi tresours, and seidist, Who schal come to me?
5 Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹ láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,” ni Olúwa, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Lo! Y schal bringe in drede on thee, seith the Lord God of oostis, God of Israel, of alle men that ben in thi cumpasse; and ye schulen be scaterid, ech bi hym silf, fro youre siyt, and noon schal be, that gadere hem that fleen.
6 “Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò dá ìkólọ Ammoni padà,” ni Olúwa wí.
And after these thingis Y schal make the fleeris and prisoneris of the sones of Amon to turne ayen, seith the Lord.
7 Nípa Edomu. Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temani? Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè? Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?
To Ydumee the Lord God of oostis seith these thingis. Whether wisdom is no more in Theman? Councel perischide fro sones, the wisdom of hem is maad vnprofitable.
8 Yípadà kí o sálọ, sá pamọ́ sínú ihò, ìwọ tí ó ń gbé ní Dedani, nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí Esau, ní àkókò tí èmi ó bẹ̀ ẹ́ wò.
Fle ye, and turne ye backis; go doun in to a swolowe, ye dwelleris of Dedan, for Y haue brouyt the perdicioun of Esau on hym, the tyme of his visitacioun.
9 Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá; ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀? Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò ní kó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?
If gadereris of grapis hadden come on thee, thei schulden haue left a clustre; if theues in the niyt, thei schulden haue rauyschid that that suffiside to hem.
10 Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Esau sí ìhòhò, èmi ti fi ibi ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ hàn, nítorí kí o máa ba à fi ara rẹ pamọ́. Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àti àwọn ará ilé rẹ yóò parun. Wọn kò sì ní sí mọ́.
Forsothe Y haue vnhilid Esau, and Y haue schewid the hid thingis of hym, and he mai not mow be hid; his seed is distried, and hise britheren, and hise neiyboris, and it schal not be.
11 Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀ èmi yóò dáàbò bo ẹ̀mí wọn. Àwọn opó rẹ gan an lè gbẹ́kẹ̀lé mi.”
Forsake thi fadirles children, and Y schal make hem to lyue, and thi widewis schulen hope in me.
12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ago náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mú un.
For the Lord seith these thingis, Lo! thei drynkynge schulen drynke, to whiche was no doom, that thei schulden drynke the cuppe. And `schalt thou be left as innocent? thou schalt not be innocent, but thou drynkynge schalt drynke.
13 Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bosra yóò ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ègún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”
For Y swoor bi my silf, seith the Lord, that Bosra schal be in to wildirnesse, and in to schenschipe, and in to forsakyng, and in to cursyng; and alle the citees therof schulen be in to euerlastynge wildirnessis.
14 Ní gbígbọ́, èmi ti gbọ́ ìró kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa, a rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀-èdè pé, ẹ kó ara yín jọ, ẹ wá sórí rẹ̀, ẹ sì dìde láti jagun.
I herde an heryng of the Lord, and Y am sent a messanger to hethene men; be ye gaderid togidere, and come ye ayens it, and rise we togidere in to batel.
15 “Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo; ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ènìyàn.
For lo! Y haue youe thee a litil oon among hethene men, despisable among men.
16 Ìpayà tí ìwọ ti fà sínú ìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ; ìwọ tí ń gbé ní pàlàpálá àpáta, tí o jókòó lórí ìtẹ́ gíga síbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì; láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,” ni Olúwa wí.
Thi boost, and the pride of thin herte, hath disseyued thee, that dwellist in the caues of stoon, and enforsist to take the hiynesse of a litil hil; whanne thou as an egle hast reisid thi nest, fro thennus Y schal drawe thee doun, seith the Lord.
17 “Edomu yóò di ahoro gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sì fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ.
And Ydumee schal be forsakun; ech man that schal passe bi it, schal wondre, and schal hisse on alle the woundis therof;
18 Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó wà ní àyíká rẹ,” ní Olúwa wí. “Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀; kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.
as Sodom and Gommor is distried, and the niy citees therof, seith the Lord. A man schal not dwelle there, and the sone of man schal not enhabite it.
19 “Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Edomu kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
Lo! as a lioun he schal stie, fro the pride of Jordan to the strong fairnesse; for Y schal make hym renne sudenli to it; and who schal be the chosun man, whom Y schal sette bifore hym? For who is lijk to me, and who schal suffre me? and who is this scheepherde, that schal ayenstonde my cheer?
20 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí Olúwa ní fún Edomu, ohun tí ó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Temani. Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde; pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.
Therfor here ye the councel of the Lord, which he took of Edom, and his thouytis, whiche he thouyte of the dwelleris of Theman. If the litle of the floc caste not hem doun, if thei distrien not with hem the dwellyng of hem, ellis no man yyue credence to me.
21 Ilẹ̀ yóò mì tìtì nípa ariwo ìṣubú wọn, a ó gbọ́ igbe wọn ní Òkun pupa.
The erthe was mouyd of the vois of fallyng of hem; the cry of vois therof was herd in the reed see.
22 Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀, yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bosra. Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagun Edomu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ń rọbí.
Lo! as an egle he schal stie, and fle out, and he schal sprede abrood hise wynges on Bosra; and the herte of the strong men of Idumee schal be in that dai, as the herte of a womman trauelynge of child.
23 Nípa Damasku. “Inú Hamati àti Arpadi bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn, wọ́n sì dààmú bí omi Òkun.
To Damask. Emath is schent, and Arphath, for thei herden a ful wickid heryng; thei weren disturblid in the see, for angwisch thei miyten not haue reste.
24 Damasku di aláìlera, ó pẹ̀yìndà láti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a; ìbẹ̀rù àti ìrora dìímú, ìrora bí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.
Damask was discoumfortid, it was turned in to fliyt; tremblyng took it, angwischis and sorewis helden it, as a womman trauelynge of child.
25 Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀; ìlú tí mo dunnú sí.
How forsoken thei a preisable citee, the citee of gladnesse?
26 Lóòtítọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ yóò ṣubú lójú pópó, gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ yóò pa ẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Therfor the yonge men therof schulen falle in the stretis therof, and alle men of batel schulen be stille in that dai, seith the Lord of oostis.
27 “Èmi yóò fi iná sí odi Damasku, yóò sì jó gbọ̀ngàn Beni-Hadadi run.”
And Y schal kyndle fier in the wal of Damask, and it schal deuoure the bildyngis of Benadab.
28 Nípa ìlú Kedari àti ìjọba Hasori èyí ti Nebukadnessari ọba Babeli dojú ìjà kọ, èyí ni ohun tí Olúwa sọ, “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ ìlú Kedari, kí o sì pa àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn run.
To Cedar, and to the rewme of Azor, which Nabugodonosor, kyng of Babiloyne, smoot, the Lord seith these thingis. Rise ye, and stie to Cedar, and distrie ye the sones of the eest.
29 Àgọ́ wọn àti agbo àgùntàn wọn ni wọn ó kó lọ; àgọ́ wọn yóò di ìṣínípò padà pẹ̀lú gbogbo ẹrù àti ìbákasẹ wọn. Àwọn ènìyàn yóò ké sórí wọ́n pé, ‘Ẹ̀rù yí káàkiri!’
Thei schulen take the tabernaclis of hem, and the flockis of hem; thei schulen take to hem the skynnes of hem, and alle the vessels of hem, and the camels of hem; and thei schulen clepe on hem inward drede in cumpas.
30 “Sálọ kíákíá! Fi ara pamọ́ sí ibi jíjìn, ẹ̀yin olùgbé Hasori,” ni Olúwa wí. “Nebukadnessari ọba Babeli ti dojú ìjà kọ ọ́.
Fle ye, go ye awei greetli, ye that dwellen in Asor, sitte in swolewis, seith the Lord. For whi Nabugodonosor, kyng of Babiloyne, hath take councel ayens you, and he thouyte thouytis ayens you.
31 “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ orílẹ̀-èdè tí ó wà nínú ìrọ̀rùn, èyí tí ó gbé ní àìléwu,” ní Olúwa wí. “Orílẹ̀-èdè tí kò ní odi tàbí irin, àwọn ènìyàn rẹ̀ ń dágbé.
Rise ye togidere, and stie ye to a pesible folk, and dwellinge tristili, seith the Lord; not doris nether barris ben to it, thei dwellen aloone.
32 Àwọn ìbákasẹ á di ẹrù àti àwọn ẹran ọ̀sìn, wọ́n á di ìkógun. Èmi yóò tú àwọn tí ó wà ní òkèèrè sí inú afẹ́fẹ́. Èmi yóò sì mú ibi wá sí àyíká gbogbo,” báyìí ní Olúwa wí.
And the camels of hem schulen be in to rauyschyng, and the multitude of her beestis in to prey; and Y schal schatere hem in to ech wynd, that ben biclippid on the long heer, and bi ech coost of hem Y schal brynge perischyng on hem, seith the Lord.
33 “Hasori yóò di ibi ìdọdẹ àwọn akátá, ibi ìkọ̀sílẹ̀ ayérayé, kò sí ẹni tí yóò gbé ní ibẹ̀.”
And Asor schal be in to a dwellyng place of dragouns; it schal be forsakun `til in to withouten ende; a man schal not dwelle there, nether the sone of man schal enhabite it.
34 Èyí ní ọ̀rọ̀ Olúwa èyí tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa Elamu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekiah ọba Juda.
The word of the Lord that was maad to Jeremye, the profete, ayens Elam, in the bigynnyng of the rewme of Sedechie,
35 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “Wò ó, èmi yóò fọ́ ìtẹ̀gùn Elamu, ẹni tí wọ́n sinmi lé nípa agbára.
kyng of Juda, and seide, The Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, Lo! Y schal breke the bowe of Elam, and Y schal take the strengthe of hem.
36 Èmi yóò mú kí afẹ́fẹ́ orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin àgbáyé lòdì sí Elamu. Èmi yóò tú wọn ká sí ìpín afẹ́fẹ́ mẹ́rin àti pé, kò sí orílẹ̀-èdè tí ilẹ̀ àjèjì Elamu kò ní lọ.
And I schal bringe on Elam foure wyndis; fro foure coostis of heuene, and Y schal wyndewe hem in to alle these wyndis, and no folc schal be, to which the fleeris of Elam schulen not come.
37 Èmi yóò kẹ́gàn Elamu níwájú àwọn ọ̀tá wọn, àti níwájú àwọn tí wọ́n ń wá ẹ̀mí wọn, Èmi yóò mú ibi wá sí orí wọn, àní, ìbínú gbígbóná mi,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Èmi yóò lé wọn pẹ̀lú idà, di ìgbà tí èmi yóò rẹ́yìn wọn.
And Y schal make Elam for to drede bifore her enemyes, and in the siyt of men sekynge the lijf of hem; and Y schal brynge on hem yuel, the wraththe of my strong veniaunce, seith the Lord; and Y schal sende after hem a swerd, til Y waste hem.
38 Èmi yóò sì gbé ìtẹ́ mi kalẹ̀ ní Elamu, èmí yóò sì pa ọba wọn àti ìjòyè wọn run,” báyìí ni Olúwa wí.
And Y schal sette my kyngis seete in Elam, and Y schal leese therof kyngis, and princes, seith the Lord.
39 “Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ Elamu padà láìpẹ́ ọjọ́,” báyìí ni Olúwa wí.
But in the laste daies Y schal make the prisoneris of Elam to turne ayen, seith the Lord.

< Jeremiah 49 >