< Jeremiah 49 >

1 Nípa Ammoni. Báyìí ni Olúwa wí, “Israẹli kò ha ní ọmọkùnrin? Israẹli kò ha ní àrólé bí? Nítorí kí ni Malkomu ṣe jogún Gadi? Kí ló dé tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ń gbé ìlú rẹ̀?
Against the children of Ammon. Thus saith the Lord: Hath Israel no sons? or hath he no heir? Why then hath Melchom inherited Gad: and his people dwelt in his cities?
2 Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí; “nígbà tí èmi yóò mú kí a gbọ́ ìdágìrì ogun ní Rabba tí Ammoni; yóò sì di òkìtì ahoro, gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná. Nígbà náà ni Israẹli yóò lé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,” ni Olúwa wí.
Therefore behold the days come, saith the Lord, and I will cause the noise of war to be heard in Rabbath of the children of Ammon, and it shall be destroyed into a heap, and her daughters shall be burnt with fire, and Israel shall possess them that have possessed him, saith the Lord.
3 “Hu, ìwọ Heṣboni, nítorí Ai tí rún! Kígbe ẹ̀yin olùgbé Rabba! Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀. Ẹ sáré sókè sódò nínú ọgbà, nítorí Malkomu yóò lọ sí ìgbèkùn, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.
Howl, O Hesebon, for Hai is wasted. Cry, ye daughters of Rabbath, gird yourselves with haircloth: mourn and go about by the hedges: for Melchom shall be carried into captivity, his priests, and his princes together.
4 Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣògo nínú àfonífojì rẹ, ṣògo nínú àfonífojì rẹ fún èso? Ẹ̀yin ọmọbìnrin Ammoni aláìṣòótọ́, ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé, ‘Ta ni yóò kò mí lójú?’
Why gloriest thou in the valleys? thy valley hath flowed away, O delicate daughter, that hast trusted in thy treasures, and hast said: Who shall come to me?
5 Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹ láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,” ni Olúwa, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Behold I will bring a fear upon thee, saith the Lord God of hosts, from all that are round about thee: and you shall be scattered every one out of one another’s sight, neither shall there be any to gather together them that flee.
6 “Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò dá ìkólọ Ammoni padà,” ni Olúwa wí.
And afterwards I will cause the captives of the children of Ammon to return, saith the Lord.
7 Nípa Edomu. Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temani? Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè? Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?
Against Edom. Thus saith the Lord of hosts: Is wisdom no more in Theman? counsel is perished from her children: their wisdom is become unprofitable.
8 Yípadà kí o sálọ, sá pamọ́ sínú ihò, ìwọ tí ó ń gbé ní Dedani, nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí Esau, ní àkókò tí èmi ó bẹ̀ ẹ́ wò.
Flee and turn your backs, go down into the deep hole, ye inhabitants of Dedan: for I have brought the destruction of Esau upon him, the time of his visitation.
9 Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá; ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀? Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò ní kó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?
If grapegatherers had come to thee, would they not have left a bunch? if thieves in the night, they would have taken what was enough for them.
10 Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Esau sí ìhòhò, èmi ti fi ibi ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ hàn, nítorí kí o máa ba à fi ara rẹ pamọ́. Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àti àwọn ará ilé rẹ yóò parun. Wọn kò sì ní sí mọ́.
But I have made Esau bare, I have revealed his secrets, and he cannot be hid: his seed is laid waste, and his brethren, and his neighbours, and he shall not be.
11 Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀ èmi yóò dáàbò bo ẹ̀mí wọn. Àwọn opó rẹ gan an lè gbẹ́kẹ̀lé mi.”
Leave thy fatherless children: I will make them live: and thy widows shall hope in me.
12 Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ago náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mú un.
For thus saith the Lord: Behold they whose judgment was not to drink of the cup, shall certainly drink: and shalt thou come off as innocent? thou shalt not come off as innocent, but drinking thou shalt drink.
13 Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bosra yóò ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ègún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”
For I have sworn by myself, saith the Lord, that Bosra shall become a desolation, and a reproach, and a desert, and a curse: and all her cities shall be everlasting wastes.
14 Ní gbígbọ́, èmi ti gbọ́ ìró kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa, a rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀-èdè pé, ẹ kó ara yín jọ, ẹ wá sórí rẹ̀, ẹ sì dìde láti jagun.
I have heard a rumour from the Lord, and an ambassador is sent to the nations: Gather yourselves together, and come against her, and let us rise up to battle.
15 “Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo; ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ènìyàn.
For behold I have made thee a little one among the nations, despicable among men.
16 Ìpayà tí ìwọ ti fà sínú ìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ; ìwọ tí ń gbé ní pàlàpálá àpáta, tí o jókòó lórí ìtẹ́ gíga síbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì; láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,” ni Olúwa wí.
Thy arrogancy hath deceived thee, and the pride of thy heart: O thou that dwellest in the clefts of the rock, and endeavourest to lay hold on the height of the hill: but though thou shouldst make thy nest as high as an eagle, I will bring thee down from thence, saith the Lord.
17 “Edomu yóò di ahoro gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sì fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ.
And Edom shall be desolate: every one that shall pass by it, shall be astonished, and shall hiss at all its plagues.
18 Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó wà ní àyíká rẹ,” ní Olúwa wí. “Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀; kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.
As Sodom was overthrown and Gomorrha, and the neighbours thereof, saith the Lord: there shall not a man dwell there, and there shall no son of man inhabit it.
19 “Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Edomu kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
Behold one shall come up as a lion from the swelling of the Jordan, against the strong and beautiful: for I will make him run suddenly upon her: and who shall be the chosen one whom I may appoint over her? for who is like to me? and who shall abide me? and who is that shepherd that can withstand my countenance?
20 Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí Olúwa ní fún Edomu, ohun tí ó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Temani. Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde; pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.
Therefore hear ye the counsel of the Lord, which he hath taken concerning Edom: and his thoughts which he hath thought concerning the inhabitants of Theman: surely the little ones of the flock shall cast them down, of a truth they shall destroy them with their habitation.
21 Ilẹ̀ yóò mì tìtì nípa ariwo ìṣubú wọn, a ó gbọ́ igbe wọn ní Òkun pupa.
The earth is moved at the noise of their fall: the cry of their voice is heard in the Red Sea.
22 Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀, yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bosra. Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagun Edomu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ń rọbí.
Behold he shall come up as an eagle, and fly: and he shall spread his wings over Bosra: and in that day the heart of the valiant ones of Edom shall be as the heart of a woman in labour.
23 Nípa Damasku. “Inú Hamati àti Arpadi bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn, wọ́n sì dààmú bí omi Òkun.
Against Damascus. Emath is confounded and Arphad: for they have heard very bad tidings, they are troubled as in the sea: through care they could not rest.
24 Damasku di aláìlera, ó pẹ̀yìndà láti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a; ìbẹ̀rù àti ìrora dìímú, ìrora bí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.
Damascus is undone, she is put to flight, trembling hath seized on her: anguish and sorrows have taken her as a woman in labour.
25 Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀; ìlú tí mo dunnú sí.
How have they forsaken the city of renown, the city of joy!
26 Lóòtítọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ yóò ṣubú lójú pópó, gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ yóò pa ẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
Therefore her young men shall fall in her streets: and all the men of war shall be silent in that day, saith the Lord of hosts.
27 “Èmi yóò fi iná sí odi Damasku, yóò sì jó gbọ̀ngàn Beni-Hadadi run.”
And I will kindle a fire in the wall of Damascus, rind it shall devour the strong holds of Benadad.
28 Nípa ìlú Kedari àti ìjọba Hasori èyí ti Nebukadnessari ọba Babeli dojú ìjà kọ, èyí ni ohun tí Olúwa sọ, “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ ìlú Kedari, kí o sì pa àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn run.
Against Cedar and against the kingdoms of Asor, which Nabuchodonosor king of Babylon destroyed. Thus saith the Lord: Arise, and go ye up to Cedar, and waste the children of the east.
29 Àgọ́ wọn àti agbo àgùntàn wọn ni wọn ó kó lọ; àgọ́ wọn yóò di ìṣínípò padà pẹ̀lú gbogbo ẹrù àti ìbákasẹ wọn. Àwọn ènìyàn yóò ké sórí wọ́n pé, ‘Ẹ̀rù yí káàkiri!’
They shall take their tents, and their flocks: and shall carry off for themselves their curtains, and all their vessels, and their camels: and they shall call fear upon them round about.
30 “Sálọ kíákíá! Fi ara pamọ́ sí ibi jíjìn, ẹ̀yin olùgbé Hasori,” ni Olúwa wí. “Nebukadnessari ọba Babeli ti dojú ìjà kọ ọ́.
Flee ye, get away speedily, sit in deep holes, you that inhabit Asur, saith the Lord: for Nabuchodonosor king of Babylon hath taken counsel against you, and hath conceived designs against you.
31 “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ orílẹ̀-èdè tí ó wà nínú ìrọ̀rùn, èyí tí ó gbé ní àìléwu,” ní Olúwa wí. “Orílẹ̀-èdè tí kò ní odi tàbí irin, àwọn ènìyàn rẹ̀ ń dágbé.
Arise, and so up to a nation that is at ease, and that dwelleth securely, saith the Lord: they have neither gates, nor bars: they dwell alone.
32 Àwọn ìbákasẹ á di ẹrù àti àwọn ẹran ọ̀sìn, wọ́n á di ìkógun. Èmi yóò tú àwọn tí ó wà ní òkèèrè sí inú afẹ́fẹ́. Èmi yóò sì mú ibi wá sí àyíká gbogbo,” báyìí ní Olúwa wí.
And their camels shall be for a spoil, and the multitude of their cattle for a booty, and I will scatter into every wind them that have their hair cut round, and I will bring destruction upon them from I all their confines, saith the Lord.
33 “Hasori yóò di ibi ìdọdẹ àwọn akátá, ibi ìkọ̀sílẹ̀ ayérayé, kò sí ẹni tí yóò gbé ní ibẹ̀.”
And Asor shall be a habitation for dragons, desolate for ever: no man shall abide there, nor son of man inhabit it.
34 Èyí ní ọ̀rọ̀ Olúwa èyí tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa Elamu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekiah ọba Juda.
The word of the Lord that came to Jeremias the prophet against Elam, in the beginning of the reign of Sedecias king of Juda, saying:
35 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “Wò ó, èmi yóò fọ́ ìtẹ̀gùn Elamu, ẹni tí wọ́n sinmi lé nípa agbára.
Thus saith the Lord of hosts: Behold I will break the bow of Elam, and their chief strength.
36 Èmi yóò mú kí afẹ́fẹ́ orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin àgbáyé lòdì sí Elamu. Èmi yóò tú wọn ká sí ìpín afẹ́fẹ́ mẹ́rin àti pé, kò sí orílẹ̀-èdè tí ilẹ̀ àjèjì Elamu kò ní lọ.
And I will bring upon Elam the four winds from the fear quarters of heaven: and I will scatter them into all these winds: and there shall be no nation, to which the fugitives of Elam shall not come.
37 Èmi yóò kẹ́gàn Elamu níwájú àwọn ọ̀tá wọn, àti níwájú àwọn tí wọ́n ń wá ẹ̀mí wọn, Èmi yóò mú ibi wá sí orí wọn, àní, ìbínú gbígbóná mi,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Èmi yóò lé wọn pẹ̀lú idà, di ìgbà tí èmi yóò rẹ́yìn wọn.
And I will cause Elam to be afraid before their enemies, and in the sight of them that seek their life: and I will bring evil upon them, my fierce wrath, saith the Lord: and will send the sword after them, till I consume them.
38 Èmi yóò sì gbé ìtẹ́ mi kalẹ̀ ní Elamu, èmí yóò sì pa ọba wọn àti ìjòyè wọn run,” báyìí ni Olúwa wí.
And I will set my throne in Elam, and destroy kings and princes from thence, saith the Lord.
39 “Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ Elamu padà láìpẹ́ ọjọ́,” báyìí ni Olúwa wí.
But in the latter days I will cause the captives of Elam, to return, saith the Lord.

< Jeremiah 49 >