< Jeremiah 24 >

1 Lẹ́yìn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn oníṣọ̀nà àti oníṣẹ́ ọwọ́ ti Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí ilẹ̀ àjèjì Babeli tán. Olúwa fi agbọ̀n èso ọ̀pọ̀tọ́ méjì hàn mí tí a gbé sí iwájú pẹpẹ Olúwa.
L'Eternel me fit voir [une vision], et voici deux paniers de figues, posés devant le Temple de l'Eternel, après que Nébucadnetsar Roi de Babylone eut transporté de Jérusalem Jéchonias fils de Jéhojakim, Roi de Juda, et les principaux de Juda, avec les charpentiers et les serruriers, et les eut emmenés à Babylone.
2 Agbọ̀n kan ni èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó dára bí èyí tí ó tètè pọ́n; èkejì sì ní èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó burú rékọjá tí kò sì le è ṣe é jẹ.
L'un des paniers avait de fort bonnes figues, comme sont d'ordinaire les figues qui sont les premières mûres; et l'autre panier avait de fort mauvaises figues, lesquelles on n'aurait pu manger, tant elles étaient mauvaises.
3 Nígbà náà ni Olúwa bi mí pé, “Kí ni ìwọ rí Jeremiah?” Mo dáhùn pe, “Èso ọ̀pọ̀tọ́.” Mo dáhùn. “Èyí tí ó dáradára púpọ̀, ṣùgbọ́n èyí tí ó burú burú rékọjá tí kò sì ṣe é jẹ.”
Et l'Eternel me dit: que vois-tu, Jérémie? Et je répondis: des figues, de bonnes figues, fort bonnes; et de mauvaises, fort mauvaises, lesquelles on ne saurait manger, tant elles sont mauvaises.
4 Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
Alors la parole de l'Eternel me fut [adressée], en disant:
5 “Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí àwọn èso ọ̀pọ̀tọ́ dáradára yìí ni Èmi yóò ka àwọn tí wọ́n lọ sí ilẹ̀ àjèjì láti Juda sí tí èmi rán jáde kúrò ní ibí yìí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kaldea.
Ainsi a dit l'Eternel, le Dieu d'Israël: comme ces figues sont bonnes, ainsi je me souviendrai, pour leur faire du bien, de ceux qui ont été transportés de Juda, lesquels j'ai envoyés hors de ce lieu au pays des Caldéens.
6 Ojú mi yóò máa ṣọ́ wọn lọ fún rere, Èmi yóò gbé wọn ró, n kò ní já wọn lulẹ̀. Èmi yóò gbìn wọ́n, n kò sì ní fà wọ́n tu.
Et je mettrai mes yeux sur eux pour leur faire du bien, et je les ferai retourner en ce pays, je les y rétablirai, et je ne les ruinerai plus, je les planterai, et je ne les arracherai point.
7 Èmi yóò fún wọn ní ọkàn láti mọ̀ mí pé, “Èmi ni Olúwa.” Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi; Èmi ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn; nítorí pé wọn yóò padà sọ́dọ̀ mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
Et je leur donnerai un cœur pour me connaître, [pour connaître, dis-je], que je suis l'Eternel; et ils seront mon peuple, et je serai leur Dieu: car ils se retourneront à moi de tout leur cœur.
8 “‘Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí èso ọ̀pọ̀tọ́ tí kò dára, tí ó burú tí kò ṣe é jẹ,’ ni Olúwa wí, ‘bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò ṣe pẹ̀lú Sedekiah ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn tí ó yẹ ní Jerusalẹmu, yálà wọ́n wà lórí ilẹ̀ yìí tàbí wọ́n ń gbé Ejibiti.
Et comme ces figues sont si mauvaises qu'on n'en peut manger, tant elles sont mauvaises; ainsi certainement, a dit l'Eternel, je rendrai tel Sédécias le Roi de Juda, et les principaux de sa Cour, et le reste de Jérusalem qui sont demeurés dans ce pays, et ceux qui s'habitueront au pays d'Egypte.
9 Èmi yóò sọ wọ́n di ìwọ̀sí àti ẹni ibi nínú gbogbo ìjọba ayé, láti di ẹni ìfibú àti ẹni òwe, ẹni ẹ̀sín, àti ẹni ẹ̀gàn ní ibi gbogbo tí Èmi ó lé wọn sí.
Et je les livrerai pour être agités pour leur malheur par tous les Royaumes de la terre, et pour être en opprobre, en proverbe, en raillerie, et en malédiction par tous les lieux où je les aurai chassés.
10 Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn sí wọn, títí tí gbogbo wọn yóò parun lórí ilẹ̀ tí a fún wọn àti fún àwọn baba wọn.’”
Et j'enverrai sur eux l'épée, la famine, et la mortalité, jusqu’à ce qu'ils soient consumés de dessus la terre que je leur avais donnée, à eux, et à leurs pères.

< Jeremiah 24 >