< Jeremiah 23 >

1 “Ègbé ni fún àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń tú agbo ẹran mi ká tí ó sì ń pa wọ́n run!” ni Olúwa wí.
خداوند می‌گوید: «وای بر شبانانی که گله مرتع مرا هلاک و پراکنده می‌سازند.»۱
2 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli sọ ní ti àwọn olùṣọ́-àgùntàn tí ń darí àwọn ènìyàn mi: “Nítorí tí ẹ̀yin tú agbo ẹran mi ká, tí ẹ lé wọn dànù tí ẹ̀yin kò sì bẹ̀ wọ́n wò. Èmi yóò jẹ yín ní yà nítorí nǹkan búburú tí ẹ ti ṣe,” ni Olúwa wí.
بنابراین، یهوه خدای اسرائیل درباره شبانانی که قوم مرا می‌چرانند چنین می‌گوید: «شما گله مرا پراکنده ساخته و رانده ایدو به آنها توجه ننموده‌اید. پس خداوند می‌گویداینک من عقوبت بدی اعمال شما را بر شماخواهم رسانید.۲
3 “Èmi Olúwa tìkára mi yóò kó ìyókù agbo ẹran mi jọ láti inú gbogbo orílẹ̀-èdè tí mo ti lé wọn, Èmi yóò mú wọn padà sínú pápá oko wọn, níbẹ̀ ni wọn ó ti bí sí i, tí wọn ó sì pọ̀ sí i.
و من بقیه گله خویش را از همه زمینهایی که ایشان را به آنها رانده‌ام جمع خواهم کرد و ایشان را به آغلهای ایشان باز خواهم آوردکه بارور و بسیار خواهند شد.۳
4 Èmi ó wá olùṣọ́-àgùntàn fún wọn, tí yóò darí wọn, wọn kì yóò bẹ̀rù tàbí dààmú, bẹ́ẹ̀ ni ọ̀kan kì yóò sọnù,” ni Olúwa wí.
وبرای ایشان شبانانی که ایشان را بچرانند برپا خواهم نمود که بار دیگر ترسان و مشوش نخواهند شد و مفقودنخواهند گردید.» قول خداوند این است.۴
5 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò gbé ẹ̀ka òdodo dìde fún Dafidi, ọba tí yóò lo ìjọba pẹ̀lú ọgbọ́n tí yóò sì ṣe òdodo àti ohun tí ó yẹ lórí ilẹ̀ náà.
خداوند می‌گوید: «اینک ایامی می‌آید که شاخه‌ای عادل برای داود برپا می‌کنم و پادشاهی سلطنت نموده، به فطانت رفتار خواهد کرد وانصاف و عدالت را در زمین مجرا خواهد داشت.۵
6 Ní ọjọ́ rẹ̀ ni a ó gba Juda là, Israẹli yóò sì máa gbé ní aláìléwu. Èyí ni orúkọ tí a ó fi máa pè é: Olúwa Òdodo wa.
در ایام وی یهودا نجات خواهد یافت و اسرائیل با امنیت ساکن خواهد شد و اسمی که به آن نامیده می‌شود این است: یهوه صدقینو (یهوه عدالت ما).۶
7 Nítorí náà, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí ènìyàn kì yóò tún wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa wà láààyè tí ó mú àwọn ọmọ Israẹli jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti.’
بنابراین خداوند می‌گوید: اینک ایامی می‌آید که دیگر نخواهند گفت قسم به حیات یهوه که بنی‌اسرائیل را از زمین مصر برآورد.۷
8 Ṣùgbọ́n wọn yóò máa wí pé, ‘Dájúdájú Olúwa ń bẹ tí ó mú irú-ọmọ ilé Israẹli wá láti ilẹ̀ àríwá àti láti àwọn ilẹ̀ ibi tí mo tí lé wọn lọ,’ wọn ó sì gbé inú ilẹ̀ wọn.”
بلکه قسم به حیات یهوه که ذریت خاندان اسرائیل را از زمین شمال و از همه زمینهایی که ایشان را به آنها رانده بودم بیرون آورده، رهبری نموده است و در زمین خود ساکن خواهند شد.»۸
9 Nípa ti àwọn wòlíì èké. Ọkàn mi ti bàjẹ́ nínú mi, gbogbo egungun mi ni ó wárìrì. Èmi dàbí ọ̀mùtí ènìyàn, bí ọkùnrin tí ọtí wáìnì ń pa; nítorí Olúwa àti àwọn ọ̀rọ̀ mímọ́ rẹ̀.
به‌سبب انبیا دل من در اندرونم شکسته وهمه استخوانهایم مسترخی شده است، مثل شخص مست و مانند مرد مغلوب شراب ازجهت خداوند و از جهت کلام مقدس اوگردیده‌ام.۹
10 Ilẹ̀ náà kún fún panṣágà ènìyàn; nítorí ègún, ilẹ̀ náà gbẹ, àwọn koríko orí aṣálẹ̀ ilẹ̀ náà rọ. Àwọn wòlíì tẹ̀lé ọ̀nà búburú, wọ́n sì ń lo agbára wọn lọ́nà àìtọ́.
زیرا که زمین پر از زناکاران است و به‌سبب لعنت زمین ماتم می‌کند و مرتع های بیابان خشک شده است زیرا که طریق ایشان بد وتوانایی ایشان باطل است.۱۰
11 “Wòlíì àti àlùfáà kò gbé ìgbé ayé ìwà-bí-Ọlọ́run; kódà nínú tẹmpili mi ni mo rí ìwà búburú wọn,” ni Olúwa wí.
چونکه هم انبیا و هم کاهنان منافق‌اند و خداوند می‌گوید: شرارت ایشان را هم در خانه خود یافته‌ام.۱۱
12 “Nítorí náà, ọ̀nà wọn yóò di yíyọ́, a ó lé wọn jáde sínú òkùnkùn; níbẹ̀ ni wọn yóò ṣubú. Èmi yóò mú ìdààmú wá sórí wọn, ní ọdún tí a jẹ wọ́n ní ìyà,” ni Olúwa wí.
بنابراین طریق ایشان مثل جایهای لغزنده در تاریکی غلیظ برای ایشان خواهد بود که ایشان رانده شده در آن خواهند افتاد. زیرا خداوند می‌گوید که «درسال عقوبت ایشان بلا بر ایشان عارض خواهم گردانید.۱۲
13 “Láàrín àwọn wòlíì Samaria, Èmi rí ohun tí ń lé ni sá. Wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀ lórúkọ Baali wọ́n sì mú Israẹli ènìyàn mi ṣìnà.
و در انبیای سامره حماقتی دیده‌ام که برای بعل نبوت کرده، قوم من اسرائیل را گمراه گردانیده‌اند.۱۳
14 Àti láàrín àwọn wòlíì Jerusalẹmu, èmi ti rí ohun búburú. Wọ́n ṣe panṣágà, wọ́n sì ń ṣèké. Wọ́n fún àwọn olùṣe búburú ní agbára, tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ẹnìkan tí ó yípadà kúrò nínú ìwà búburú rẹ̀. Gbogbo wọn dàbí Sodomu níwájú mi, àti àwọn ènìyàn olùgbé rẹ̀ bí Gomorra.”
و در انبیای اورشلیم نیز چیزهولناک دیدم. مرتکب زنا شده، به دروغ سلوک می‌نمایند و دستهای شریران را تقویت می‌دهندمبادا هر یک از ایشان از شرارت خویش بازگشت نماید. و جمیع ایشان برای من مثل سدوم وساکنان آن مانند عموره گردیده‌اند.»۱۴
15 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí ní ti àwọn wòlíì: “Èmi yóò mú wọn jẹ oúnjẹ kíkorò, wọn yóò mu omi májèlé nítorí láti ọ̀dọ̀ àwọn wòlíì Jerusalẹmu ni àìwà-bí-Ọlọ́run ti tàn ká gbogbo ilẹ̀.”
بنابراین یهوه صبایوت درباره آن انبیا چنین می‌گوید: «اینک من به ایشان افسنتین خواهم خورانید و آب تلخ به ایشان خواهم نوشانید زیراکه از انبیای اورشلیم نفاق در تمامی زمین منتشرشده است.»۱۵
16 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ẹ má ṣe fi etí sí àsọtẹ́lẹ̀ tí àwọn wòlíì èké ń sọ fún un yín. Wọ́n ń kún inú ọkàn yín pẹ̀lú ìrètí asán. Wọ́n ń sọ ìran láti ọkàn ara wọn, kì í ṣe láti ẹnu Olúwa.
یهوه صبایوت چنین می‌گوید: «به سخنان این انبیایی که برای شما نبوت می‌کنندگوش مدهید زیرا شما را به بطالت تعلیم می‌دهندو رویای دل خود را بیان می‌کنند و نه از دهان خداوند.۱۶
17 Wọ́n ń sọ fún àwọn tí ó ń gàn mí pé, ‘Olúwa ti wí pé, ẹ̀yin ó ní àlàáfíà.’ Wọ́n sì wí fún gbogbo àwọn tí ó rìn nípa agídí ọkàn rẹ̀ pé, ‘Kò sí ìpalára kan tí yóò ṣẹlẹ̀ sí yín.’
و به آنانی که مرا حقیر می‌شمارندپیوسته می‌گویند: خداوند می‌فرماید که برای شما سلامتی خواهد بود و به آنانی که به‌سرکشی دل خود سلوک می‌نمایند می‌گویند که بلا به شمانخواهد رسید.۱۷
18 Ṣùgbọ́n èwo nínú wọn ni ó dúró nínú ìgbìmọ̀ Olúwa láti rí i tàbí gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀? Ta ni ó gbọ́ tí ó sì fetí sí ọ̀rọ̀ náà?
زیرا کیست که به مشورت خداوند واقف شده باشد تا ببیند و کلام او رابشنود و کیست که به کلام او گوش فرا داشته، استماع نموده باشد.۱۸
19 Wò ó, afẹ́fẹ́ Olúwa yóò tú jáde pẹ̀lú ìbínú à fẹ́ yíká ìjì yóò fẹ́ sí orí àwọn olùṣe búburú.
اینک باد شدید غضب خداوند صادر شده و گردبادی دور می‌زند و برسر شریران فرود خواهد آمد.۱۹
20 Ìbínú Olúwa kì yóò yẹ̀ títí tí yóò sì fi mú èrò rẹ̀ ṣẹ, ní àìpẹ́ ọjọ́, yóò yé e yín yékéyéké.
غضب خداوندتا مقاصد دل او را بجا نیاورد و به انجام نرساندبرنخواهد گشت. در ایام آخر این را نیکو خواهیدفهمید.۲۰
21 Èmi kò rán àwọn wòlíì wọ̀nyí síbẹ̀ wọ́n lọ pẹ̀lú ọ̀rọ̀ wọn. Èmi kò tilẹ̀ bá wọn sọ̀rọ̀, síbẹ̀ wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀.
من این انبیا را نفرستادم لیکن دویدند. به ایشان سخن نگفتم اما ایشان نبوت نمودند.۲۱
22 Ṣùgbọ́n ì bà ṣe pé wọn dúró nínú ìgbìmọ̀ mi, wọn ìbá ti kéde ọ̀rọ̀ mi fún àwọn ènìyàn mi. Wọn ìbá ti wàásù ọ̀rọ̀ mi fun àwọn ènìyàn wọn ìbá ti yípadà kúrò nínú ọ̀nà àti ìṣe búburú wọn.
امااگر در مشورت من قایم می‌ماندند، کلام مرا به قوم من بیان می‌کردند و ایشان را از راه بد و از اعمال شریر ایشان برمی گردانیدند.۲۲
23 “Ǹjẹ́ Ọlọ́run tòsí nìkan ni Èmi bí?” ni Olúwa wí, “kì í sì í ṣe Ọlọ́run ọ̀nà jíjìn.
یهوه می‌گوید: آیا من خدای نزدیک هستم و خدای دور نی؟۲۳
24 Ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè sá pamọ́ sí ibi kọ́lọ́fín kan, kí èmi má ba a rí?” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ èmi kò ha a kún ọ̀run àti ayé bí?” ni Olúwa wí.
و خداوند می‌گوید: آیا کسی خویشتن را درجای مخفی پنهان تواند نمود که من او را نبینم مگر من آسمان و زمین را مملو نمی سازم؟ کلام خداوند این است.۲۴
25 “Mo ti gbọ́ gbogbo ohun tí àwọn wòlíì èké tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ní orúkọ mi ń sọ. Wọ́n sọ wí pé, ‘Mo lá àlá! Mo lá àlá!’
سخنان انبیا را که به اسم من کاذبانه نبوت کردند شنیدم که گفتند خواب دیدم خواب دیدم.۲۵
26 Títí di ìgbà wo ni èyí yóò fi máa tẹ̀síwájú ni ọkàn àwọn wòlíì èké wọ̀nyí tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ ìtànjẹ ọkàn wọn?
این تا به کی در دل انبیایی که کاذبانه نبوت می‌کنند خواهد بود که انبیای فریب دل خودشان می‌باشند،۲۶
27 Wọ́n rò wí pé àlá tí wọ́n ń sọ fún ara wọn yóò mú kí àwọn ènìyàn mi gbàgbé orúkọ mi, gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe gbàgbé orúkọ mi nípa sí sin òrìṣà Baali.
که به خوابهای خویش که هر کدام از ایشان به همسایه خود باز می‌گویند خیال دارند که اسم مرا از یاد قوم من ببرند، چنانکه پدران ایشان اسم مرا برای بعل فراموش کردند.۲۷
28 Jẹ́ kí wòlíì tí ó bá lá àlá sọ àlá rẹ̀, ṣùgbọ́n jẹ́ kí ẹni tí ó ní ọ̀rọ̀ mí sọ ọ́ ní òtítọ́. Kí ni koríko gbígbẹ ní í ṣe nínú ọkà?” ni Olúwa wí.
آن نبی‌ای که خواب دیده است خواب را بیان کند و آن که کلام مرا دارد کلام مرا براستی بیان نماید. خداوند می‌گوید کاه را با گندم چه‌کاراست؟»۲۸
29 “Ọ̀rọ̀ mi kò ha a dàbí iná?” ni Olúwa wí, “àti bí òòlù irin tí ń fọ́ àpáta túútúú?
و خداوند می‌گوید: «آیا کلام من مثل آتش نیست و مانند چکشی که صخره را خردمی کند؟»۲۹
30 “Nítorí náà, èmi lòdì sí àwọn wòlíì ni,” Olúwa wí, “Tí ń jí ọ̀rọ̀ tí ó yẹ kí ó ti ọ̀dọ̀ mi wá lò lọ́dọ̀ ara wọn.
لهذا خداوند می‌گوید: «اینک من به ضد این انبیایی که کلام مرا از بکدیگر می‌دزدندهستم.»۳۰
31 Bẹ́ẹ̀,” ni Olúwa wí, “Èmi lòdì sí àwọn wòlíì tí wọ́n lo ahọ́n wọn káàkiri, síbẹ̀ tí wọ́n ń sọ wí pé, ‘Olúwa wí.’
و خداوند می‌گوید: «اینک من به ضداین انبیا هستم که زبان خویش را بکار برده، می‌گویند: او گفته است.»۳۱
32 Nítòótọ́, mo lòdì sí àwọn tí ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ nípa àlá èké,” ni Olúwa wí. “Wọ́n ń sọ bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì ń mú àwọn ènìyàn mi ṣìnà nípa onírúurú èké wọn, síbẹ̀ èmi kò rán wọn tàbí yàn wọ́n. Wọn kò sì ran àwọn ènìyàn wọ̀nyí lọ́wọ́ bí ó ti wù kí ó kéré mọ,” ni Olúwa wí.
و خداوند می‌گوید: «اینک من به ضد اینان هستم که به خوابهای دروغ نبوت می‌کنند و آنها را بیان کرده، قوم مرا به دروغها و خیالهای خود گمراه می‌نمایند. و من ایشان را نفرستادم و مامور نکردم پس خداوندمی گوید که به این قوم هیچ نفع نخواهند رسانید.۳۲
33 “Nígbà tí àwọn ènìyàn wọ̀nyí, tàbí wòlíì tàbí àlùfáà bá bi ọ́ léèrè wí pé, ‘Kí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa?’ Sọ fún wọn wí pé, ‘Ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ wo? Èmi yóò pa yín tì ni Olúwa wí.’
و چون این قوم یا نبی یا کاهنی از تو سوال نموده، گویند که وحی خداوند چیست؟ پس به ایشان بگو: کدام وحی؟ قول خداوند این است که شما را ترک خواهم نمود.۳۳
34 Bí wòlíì tàbí àlùfáà tàbí ẹnikẹ́ni bá sì gbà wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’ Èmi yóò fi ìyà jẹ ọkùnrin náà àti gbogbo agbo ilé rẹ̀.
و آن نبی یا کاهن یاقومی که گویند وحی یهوه، همانا بر آن مرد و برخانه‌اش عقوبت خواهم رسانید.۳۴
35 Èyí ni ohun tí ẹnìkọ̀ọ̀kan yín ń sọ fún ọ̀rẹ́ àti ará ilé rẹ̀: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa sọ?’
و هر کدام ازشما به همسایه خویش و هر کدام به برادر خودچنین گویید که خداوند چه جواب داده است وخداوند چه گفته است؟۳۵
36 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò gbọdọ̀ dárúkọ ọ̀rọ̀ ‘ìjìnlẹ̀ Olúwa’ mọ́, nítorí pé ọ̀rọ̀ oníkálùkù ènìyàn di ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ rẹ̀. Nítorí náà, ẹ̀yin ń yí ọ̀rọ̀ Ọlọ́run alààyè, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run wa padà.
لیکن وحی یهوه رادیگر ذکر منمایید زیرا کلام هر کس وحی اوخواهد بود چونکه کلام خدای حی یعنی یهوه صبایوت خدای ما را منحرف ساخته‌اید.۳۶
37 Èyí ni ohun tí ẹ̀yin ń sọ fún wòlíì: ‘Kí ni ìdáhùn Olúwa sí ọ́?’ Tàbí ‘Kí ni ohun tí Olúwa bá ọ sọ?’
و به نبی چنین بگو که خداوند به تو چه جواب داده وخداوند به تو چه گفته است؟۳۷
38 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ẹ̀yin ń sọ wí pé, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ èyí ni ohun tí Olúwa sọ, Ẹ̀yin ń lo ọ̀rọ̀ yìí, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa,’ bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé mo sọ fún un yín láti má ṣe lò ó mọ́, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀-ìjìnlẹ̀ Olúwa.’
و اگر می‌گویید: وحی یهوه، پس یهوه چنین می‌فرماید چونکه این سخن یعنی وحی یهوه را گفتید با آنکه نزد شمافرستاده، فرمودم که وحی یهوه را مگویید،۳۸
39 Nítorí náà, Èmi yóò gbàgbé yín, bẹ́ẹ̀ ni n ó lé e yín kúrò níwájú mi pẹ̀lú àwọn ìlú tí mo fi fún un yín àti àwọn baba yín.
لهذا اینک من شما را بالکل فراموش خواهم کرد و شما را با آن شهری که به شما و به پدران داده بودم از حضور خود دور خواهم‌انداخت.۳۹
40 Èmi yóò sì mú ìtìjú ayérayé wá sí orí yín, ìtìjú tí kò ní ní ìgbàgbé.”
و عار ابدی و رسوایی جاودانی را که فراموش نخواهد شد بر شما عارض خواهم گردانید.»۴۰

< Jeremiah 23 >