< Isaiah 49 >

1 Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin erékùṣù: gbọ́ èyí, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè jíjìnnà réré: kí a tó bí mi Olúwa ti pè mí; láti ìgbà bíbí mi ni ó ti dá orúkọ mi.
Poslouchejte mne ostrovové, a pozorujte národové dalecí: Hospodin hned z života povolal mne, od života matky mé v pamět uvedl jméno mé,
2 Ó ṣe ẹnu mi bí idà tí a pọ́n, ní abẹ́ òjìji ọwọ́ rẹ̀ ni ó ti pa mí mọ́: ó ṣe mí ní ọfà tí a ti dán, ó sì fi mí pamọ́ sínú àpò rẹ̀.
A učinil ústa má podobná meči ostrému. V stínu ruky své skryl mne, a učiniv ze mne střelu vypulerovanou, v toule svém schoval mne.
3 Ó sọ fún mi pé, “Ìránṣẹ́ mi ni ìwọ í ṣe, Israẹli nínú ẹni tí n ó ti fi ògo mi hàn.”
A řekl mi: Služebník můj jsi, v Izraeli skrze tebe oslaven budu.
4 Ṣùgbọ́n èmi sọ pé, “Mo ti ṣe wàhálà lórí asán; mo ti lo gbogbo ipá mi lórí asán àti ìmúlẹ̀mófo. Síbẹ̀síbẹ̀ ohun tí ó tọ́ sí mi ṣì wà lọ́wọ́ Olúwa, èrè mi sì ń bẹ pẹ̀lú Ọlọ́run mi.”
Já pak řekl jsem: Nadarmo jsem pracoval, daremně a marně sílu svou jsem strávil. Ale však soud můj jestiť u Hospodina, a práce má u Boha mého.
5 Nísinsin yìí Olúwa wí pé ẹni tí ó mọ̀ mí láti inú wá láti jẹ́ ìránṣẹ́ rẹ̀ láti mú Jakọbu padà tọ̀ mí wá àti láti kó Israẹli jọ sọ́dọ̀ ara rẹ̀, nítorí pé a bọ̀wọ̀ fún mi ní ojú Olúwa Ọlọ́run mi sì ti jẹ́ agbára mi,
A nyní dí Hospodin, kterýž mne sformoval hned od života za služebníka svého, abych zase přivedl k němu Jákoba; (byť pak i nebyl sebrán Izrael, slávu však mám před očima Hospodinovýma; nebo Bůh můj jest síla má);
6 Òun wí pé: “Ó jẹ́ ohun kékeré fún ọ láti jẹ́ ìránṣẹ́ mi láti mú ẹ̀yà Jakọbu padà bọ̀ sípò àti láti mú àwọn ti Israẹli tí mo ti pamọ́. Èmi yóò sì fi ọ́ ṣe ìmọ́lẹ̀ fún àwọn kèfèrí, kí ìwọ kí ó lè mú ìgbàlà mi wá sí òpin ilẹ̀ ayé.”
I to řekl Hospodin: Máloť by to bylo, abys mi byl služebníkem ku pozdvižení pokolení Jákobových, a k navrácení ostatků Izraelských; protož dal jsem tě za světlo pohanům, abys byl spasení mé až do končin země.
7 Ohun tí Olúwa wí nìyìí, Olùdáǹdè àti Ẹni Mímọ́ Israẹli— sí ẹni náà tí a gàn tí a sì kórìíra lọ́wọ́ àwọn orílẹ̀-èdè, sí ìránṣẹ́ àwọn aláṣẹ: “Àwọn ọba yóò rí ọ wọn yóò sì dìde sókè, àwọn ọmọ ọba yóò rí i wọn yóò sì wólẹ̀, nítorí Olúwa ẹni tí í ṣe olóòtítọ́, Ẹni Mímọ́ Israẹli tí ó ti yàn ọ́.”
Toto praví Hospodin vykupitel Izraelův, Svatý jeho, tomu, jímž pohrdá každý, a jehož sobě oškliví národové, služebníku panujících: Králové, vidouce tě, povstanou, a knížata klaněti se budou pro Hospodina, kterýž věrný jest, Svatého Izraelského, jenž tě vyvolil.
8 Ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Ní àkókò ojúrere mi, èmi yóò dá ọ lóhùn, àti ní ọjọ́ ìgbàlà, èmi yóò ràn ọ́ lọ́wọ́; Èmi yóò pa ọ́ mọ́, n ó sì ṣe ọ́ láti jẹ́ májẹ̀mú fún àwọn ènìyàn, láti mú ilẹ̀ padà bọ̀ sípò àti láti ṣe àtúnpín ogún rẹ̀ tí ó ti dahoro,
Toto praví Hospodin: V čas milosti vyslyším tě, a ve dni spasení spomohu tobě. Nadto ostříhati tě budu, a dám tě v smlouvu lidu, abys utvrdil zemi, a v dědictví uvedl dědictví zpuštěná;
9 láti sọ fún àwọn ìgbèkùn pé, ‘Ẹ jáde wá,’ àti fún àwọn tí ó wà nínú òkùnkùn pé, ‘Ẹ gba òmìnira!’ “Wọn yóò máa jẹ ní ẹ̀bá ọ̀nà àti koríko tútù lórí òkè aláìléwéko.
Abys řekl vězňům: Vyjděte, těm, kteříž jsou ve tmách: Zjevte se. I budou se pásti podlé cest, a na všech místech vysokých bude pastva jejich.
10 Ebi kì yóò pa wọ́n bẹ́ẹ̀ ni òǹgbẹ kì yóò gbẹ wọ́n, tàbí kí ooru inú aṣálẹ̀ tàbí oòrùn kí ó pa wọ́n. Ẹni tí ó ṣàánú fún wọn ni yóò máa tọ́ wọn, tí yóò sì mú wọn lọ sí ibi orísun omi.
Nebudou lačněti ani žízniti, nebude na ně bíti horko ani slunce; nebo slitovník jejich zprovodí je, a podlé pramenů vod povede je.
11 Èmi yóò sọ gbogbo àwọn òkè ńlá mi di ojú ọ̀nà àti gbogbo òpópónà mi ni a ó gbé sókè.
Přes to způsobím na všech horách svých cesty, a silnice mé vyvýšeny budou.
12 Kíyèsi i, wọn yóò wá láti ọ̀nà jíjìn àwọn díẹ̀ láti àríwá àti àwọn díẹ̀ láti ìwọ̀-oòrùn, àwọn díẹ̀ láti ẹkùn Siene.”
Aj, tito zdaleka přijdou, aj, onino od půlnoci a od moře, a jiní z země Sinim.
13 Ẹ hó fún ayọ̀, ẹyin ọ̀run; yọ̀, ìwọ ilẹ̀ ayé; bú sórin, ẹ̀yin òkè ńlá! Nítorí Olúwa tu àwọn ènìyàn rẹ̀ nínú yóò sì ṣàánú fún àwọn ẹni tí a ń pọ́n lójú.
Prozpěvujte nebesa, a plésej země, a zvučně prokřikujte hory; neboť jest potěšil Hospodin lidu svého, a nad chudými svými slitoval se.
14 Ṣùgbọ́n Sioni sọ pé, “Olúwa ti kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa ti gbàgbé è mi.”
Ale řekl Sion: Opustiltě mne Hospodin, a Pán zapomenul se na mne.
15 “Ǹjẹ́ abiyamọ ha le gbàgbé ọmọ ọmú rẹ̀ kí ó má sì ṣàánú fún ọmọ rẹ̀ tí ó ti bí? Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun le gbàgbé, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ!
I zdaliž se může zapomenouti žena nad nemluvňátkem svým, aby se neslitovala nad plodem života svého? A byť se pak ony zapomněly, já však nezapomenu se na tě.
16 Kíyèsi i, mo ti kọ ọ́ sí àtẹ́lẹwọ́ mi ògiri rẹ wà níwájú mi nígbà gbogbo.
Aj, na dlaních vyryl jsem tě, zdi tvé jsou vždycky přede mnou.
17 Àwọn ọmọ rẹ ti kánjú padà, àti àwọn tí ó sọ ọ́ dahoro ti padà lẹ́yìn rẹ.
Pospíšíť k tobě synové tvoji, ti pak, kteříž tě bořili a kazili, odejdou od tebe.
18 Gbójú rẹ sókè kí o sì wò yíká; gbogbo àwọn ọmọkùnrin rẹ kórajọ wọ́n sì wá sọ́dọ̀ rẹ. Níwọ́n ìgbà tí mo bá wà láààyè,” ni Olúwa wí, “Ìwọ yóò wọ gbogbo wọ́n gẹ́gẹ́ bí ohun ọ̀ṣọ́; ìwọ yóò wọ̀ wọ́n gẹ́gẹ́ bí ìyàwó.
Pozdvihni vůkol očí svých, a pohleď, všickni ti shromáždíce se, přijdou k tobě. Živť jsem já, praví Hospodin, že se jimi všemi jako okrasou přioděješ, a otočíš se jimi jako halží nevěsta,
19 “Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a tí run ọ́, a sì sọ ọ́ di ahoro tí gbogbo ilẹ̀ rẹ sì di ìparun, ní ìsinsin yìí, ìwọ yóò kéré jù fún àwọn ènìyàn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni àwọn tí ó jẹ ọ́ run ni yóò wà láti ọ̀nà jíjìn réré.
Proto že pustiny tvé, a pouště tvé, a zbořeniny země tvé že tehdáž těsné budou, příčinou obyvatelů, když vzdáleni budou ti, kteříž tě zžírali;
20 Àwọn ọmọ tí a bí ní àkókò ọ̀fọ̀ rẹ yóò sọ ní etígbọ̀ọ́ rẹ, ‘Ibi yìí ti kéré jù fún wa; ẹ fún wa láyè sí i tí a ó máa gbé.’
Tak že řeknou před tebou synové siroby tvé: Těsné mi jest toto místo, ustup mi, abych bydliti mohl.
21 Nígbà náà ni ìwọ yóò sọ ní ọkàn rẹ pé, ‘Ta ló bí àwọn yìí fún mi? Mo ti ṣọ̀fọ̀ mo sì yàgàn; a sọ mi di àtìpó a sì kọ̀ mí sílẹ̀. Ta ló wo àwọn yìí dàgbà? A fi èmi nìkan sílẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn wọ̀nyí níbo ni wọ́n ti wá?’”
I díš v srdci svém: Kdo mi naplodil těchto? Nebo jsem já byla osiřelá a osamělá, sem i tam přecházející a odcházející. Tyto, pravím, kdo vychoval? Aj, pozůstala jsem byla sama jediná. Kdež tito byli?
22 Ohun tí Olúwa Olódùmarè wí nìyìí, “Kíyèsi i, Èmi yóò ké sí àwọn aláìkọlà, Èmi yóò gbé àsíá mi sókè sí ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ènìyàn; wọn yóò kó àwọn ọmọkùnrin yín wá ní apá wọn wọn yóò sì gbé àwọn ọ̀dọ́mọbìnrin ní èjìká wọn.
Toto praví Panovník Hospodin: Aj, já pozdvihnu k národům ruky své, a k lidem vyzdvihnu korouhev svou, aby přinesli syny tvé na rukou, a dcery tvé aby na plecech neseny byly.
23 Àwọn ọba ni yóò jẹ́ alágbàtọ́ baba fún ọ, àwọn ayaba wọn ni yóò sì jẹ́ ìyá-alágbàtọ́. Wọn yóò foríbalẹ̀ ní iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ojú wọn dídàbolẹ̀; wọn yóò máa lá erùpẹ̀ lẹ́bàá ẹsẹ̀ rẹ. Nígbà náà ni ìwọ yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa; gbogbo àwọn tí wọ́n ní ìrètí nínú mi ni a kì yóò jákulẹ̀.”
I budou králové pěstounové tvoji, a královny jejich chovačky tvé. Tváří k zemi skláněti se budou před tebou, a prach noh tvých lízati budou, a poznáš, že jsem já Hospodin, a že nebývají zahanbeni, kteříž na mne očekávají.
24 Ǹjẹ́ a le gba ìkógun lọ́wọ́ jagunjagun, tàbí kí á gba ìgbèkùn lọ́wọ́ akíkanjú?
Ale díš: Zdaliž odjato bude reku udatnému to, což uchvátil? A zdaž zajatý lid spravedlivého vyproštěn bude?
25 Ṣùgbọ́n ohun tí Olúwa wí nìyìí: “Bẹ́ẹ̀ ni, a ó gba àwọn ìgbèkùn lọ́wọ́ àwọn jagunjagun, àti ìkógun lọ́wọ́ àwọn akíkanjú; ẹni tí ó bá ọ jà ni èmi ó bá jà, àti àwọn ọmọ rẹ ni èmi ó gbàlà.
Anobrž tak praví Hospodin: I zajatý lid reku udatnému odjat bude, a to, což uchvátil násilník, vyproštěno bude; nebo s tím, kterýž se s tebou nesnadní, já se nesnadniti budu, a syny tvé já vysvobodím.
26 Èmi yóò mú kí àwọn aninilára rẹ̀ jẹ ẹran-ara wọn; wọn yóò mu ẹ̀jẹ̀ ara wọn yó bí ẹni mu wáìnì. Nígbà náà ni gbogbo ènìyàn yóò mọ̀ pé, Èmi, Olúwa, èmi ni Olùgbàlà rẹ, Olùdáǹdè rẹ, Alágbára kan ṣoṣo ti Jakọbu.”
A nakrmím ty, kteříž tě utiskují, vlastním masem jejich, a jako mstem krví svou se zpijí. I poznáť všeliké tělo, že já Hospodin jsem spasitel tvůj, a vykupitel tvůj Bůh silný Jákobův.

< Isaiah 49 >