< Isaiah 29 >

1 Ègbé ni fún ọ, Arieli, Arieli, ìlú níbi tí Dafidi tẹ̀dó sí! Fi ọdún kún ọdún sì jẹ́ kí àwọn àkọlùkọgbà àjọ̀dún un rẹ tẹ̀síwájú.
Ak vai, Ariel, Ariel, pilsēta, kur Dāvids mitis, lai vēl gads ar gadu mijās, lai vēl svētki savā rindā pāriet.
2 Síbẹ̀síbẹ̀ èmi yóò dó ti Arieli òun yóò ṣọ̀fọ̀ yóò sì sọkún, òun yóò sì dàbí pẹpẹ ọkàn sí mi.
Tad Es Arieli gribu apbēdināt, un tur būs vaidi un skumjas, un Man tomēr būs kā Ariels (Dieva lauva).
3 Èmi yóò sì wà ní bùba yí ọ ká níbi gbogbo, Èmi yóò sì fi ilé ìṣọ́ yí ọ ká, Èmi yóò sì fi iṣẹ́ ìdó ti ni mi dojúkọ ọ́.
Jo Es gan apmetīšos visapkārt pret tevi un tevi spaidīšu ar karaspēku un uzcelšu pret tevi vaļņus.
4 Ní ìrẹ̀sílẹ̀, ìwọ ó sì máa sọ̀rọ̀ láti ilẹ̀ wá; ọ̀rọ̀ rẹ yóò sì máa kùn jáde láti inú erùpẹ̀. Ohun rẹ yóò máa jáde bí i ti ẹnìkan tó ní ẹ̀mí àfọ̀ṣẹ láti ilẹ̀ jáde wá, láti inú erùpẹ̀ ni ohùn rẹ yóò máa wá wúyẹ́wúyẹ́.
Tad tu tapsi pazemota, tu runāsi no zemes, un tava valoda skanēs klusiņām no pīšļiem, un tava balss būs kā burvja balss no zemes, un tava valoda čukstēs no pīšļiem.
5 Ṣùgbọ́n àwọn ọ̀tá rẹ, yóò dàbí yanrìn kíkúnná, agbo àwọn aláìláàánú bí ìyàngbò tí a fẹ́ dànù. Lójijì, ní ìṣẹ́jú kan,
Un tavu ienaidnieku pulks būs tāpat kā smalki putekļi, un tas varas darītāju pulks kā vieglas pelavas, un tas notiks vienā acumirklī piepeši.
6 Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò wá pẹ̀lú àrá àti ilẹ̀-rírì àti ariwo ńlá, àti ẹ̀fúùfù líle àti iná ajónirun.
Tu tapsi piemeklēta no Tā Kunga Cebaot ar pērkoni un ar zemes trīcēšanu un ar lielu rūkšanu, ar viesuli un ar aukām un ar rijošu uguns liesmu.
7 Lẹ́yìn náà, ọ̀gọ̀ọ̀rọ̀ ènìyàn tí gbogbo orílẹ̀-èdè tí ó bá Arieli jà, tí ó dojú ìjà kọ òun àti ilé olódi rẹ̀ tí ó sì dó tì í, yóò dàbí ẹni pé nínú àlá, bí ìran ní òru
Bet kā sapņa parādīšana naktī, tā būs visu pagānu pulks, kas karos pret Arieli, un visi, kas karos pret viņu un pret viņa pilīm un to spaidīs.
8 àti bí ìgbà tí ẹni tí ebi ń pa ń lá àlá pé òun ń jẹun, ṣùgbọ́n ó jí, ebi rẹ̀ sì wà pẹ̀lú rẹ̀; tàbí bí ìgbà tí ẹni tí òǹgbẹ ń gbẹ lá àlá pé òun ń mu omi, ṣùgbọ́n nígbà tí ó jí, sì wò ó, ó dákú, òǹgbẹ sì ń gbẹ ọkàn rẹ̀. Bẹ́ẹ̀ ni yóò sì rí fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè tí ń bá òkè Sioni jà.
Tas būs tā, kā kad izsalcis sapnī redz, ka tas ēd, bet kad uzmostas, tad viņa sirds tukša, vai kā kad izslāpis sapnī redz, ka tas dzer, bet kad uzmostas, tad vēl ir izslāpis, un viņa sirds tvīkst. Tā būs ar visu pagānu pulku, kas karo pret Ciānas kalnu.
9 Ẹ bẹ̀rù kí ẹnu kí ó yà yín, ẹ fọ́ ara yín lójú kí ẹ má sì ríran; ẹ mutí yó kì í ṣe ọtí wáìnì, ẹ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n, ṣùgbọ́n kì í ṣe ti ọtí líle.
Iztrūcinājāties un brīnāties, paliekat stulbi un akli! Tie ir piedzērušies, bet ne no vīna, tie streipuļo, bet ne no stipra dzēriena.
10 Olúwa ti mú oorun ìjìká wá sórí i yín: ó ti dì yín lójú ẹ̀yin wòlíì; ó ti bo orí yín ẹ̀yin aríran.
Jo Tas Kungs pār jums izlējis grūta miega garu, un jūsu acis, tos praviešus, Viņš ir aizdarījis, un jūsu galvas, tos redzētājus, apstulbojis.
11 Fún un yín gbogbo ìran yìí kò yàtọ̀ sí àwọn ọ̀rọ̀ tí a fi èdìdì dì sínú ìwé kíká. Bí ẹ bá sì fún ẹni tí ó lè ka ìwé kíká náà, tí ẹ sì sọ fún un pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò lè kà á; a ti dì í ní èdìdì.”
Tādēļ jums visa parādīšana palikusi kā aizzieģelētas grāmatas vārdi, ko vienam dod, kas māk lasīt, un saka: lasi jel šo! Un viņš saka: es nevaru, ja tā ir aizzieģelēta.
12 Tàbí bí ẹ bá fún ẹni tí kò lè ka ìwé kíká náà tí ẹ sì sọ pé, “Jọ̀wọ́ ka èyí,” òun yóò dáhùn pé, “Èmi kò mọ̀ ọ́n kà.”
Un to grāmatu dod vienam, kas nemāk lasīt, un saka: lasi jel šo! Un viņš saka: es nemāku lasīt.
13 Olúwa wí pé: “Àwọn ènìyàn yìí súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹnu wọn, wọ́n sì bọ̀wọ̀ fún mi pẹ̀lú ètè wọn, ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnnà sí mi. Ìsìn wọn si mi ni a gbé ka orí òfin tí àwọn ọkùnrin kọ́ ni.
Jo Tas Kungs ir sacījis: tādēļ ka šie ļaudis pie Manis nāk ar savu muti un Mani godā ar savām lūpām, bet viņu sirds ir tālu no Manis nost, un ka tie Mani bīstas pēc cilvēku baušļiem, kas tiem top mācīti,
14 Nítorí náà lẹ́ẹ̀kan sí i èmi yóò ya àwọn ènìyàn yìí lẹ́nu pẹ̀lú ìyanu lórí ìyanu; ọgbọ́n àwọn ọlọ́gbọ́n ni yóò ṣègbé, ìmọ̀ àwọn onímọ̀ ni yóò pòórá.”
Tādēļ, redzi, Es joprojām ar šiem ļaudīm darīšu brīnišķi, brīnišķi un apbrīnojami, ka viņu gudro gudrība zudīs, un viņu prātīgo prāts apslēpsies.
15 Ègbé ni fún àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun láti fi ètò wọn pamọ́ kúrò lójú Olúwa, tí wọ́n ń ṣe iṣẹ́ ẹ wọn nínú òkùnkùn tí wọ́n sì rò pé, “Ta ló rí wa? Ta ni yóò mọ̀?”
Ak vai, tiem, kas savu padomu dziļi grib apslēpt no Tā Kunga, un kuru darbi notiek tumsībā, un kas saka: kas mūs redz un kas mūs pazīst?
16 Ẹ̀yin dojú nǹkan délẹ̀, bí ẹni pé wọ́n rò pé amọ̀kòkò dàbí amọ̀! Ǹjẹ́ ohun tí a ṣe le sọ fún olùṣe pé, “Òun kọ́ ló ṣe mí”? Ǹjẹ́ ìkòkò lè sọ nípa amọ̀kòkò pé, “Kò mọ nǹkan”?
Ak tavu bezprātību! Vai māls turams podniekam līdzi, ka darbs sacītu par savu darītāju: viņš mani nav darījis, un tēls par savu tēlotāju: viņš neprot?
17 Ní àìpẹ́ jọjọ, ǹjẹ́ a kò ní sọ Lebanoni di pápá ẹlẹ́tù lójú àti pápá ẹlẹ́tù lójú yóò dàbí aginjù?
Vai nav tikai mazs brīdis vēl, ka Lībanus taps darīts par auglīgu tīrumu, un auglīgais tīrums taps turēts par mežu?
18 Ní ọjọ́ náà adití yóò gbọ́ ọ̀rọ̀ ìwé kíká náà, láti inú fìrífìrí àti òkùnkùn ni àwọn ojú afọ́jú yóò ríran.
Un tai dienā kurlie dzirdēs grāmatas vārdus, un aklo acis redzēs no krēslas un tumsas.
19 Lẹ́ẹ̀kan sí i àwọn onírẹ̀lẹ̀ yóò yọ̀ nínú Olúwa: àwọn aláìní yóò yọ̀ nínú Ẹni Mímọ́ ti Israẹli.
Un bēdīgiem būs atkal prieks iekš Tā Kunga, un nabagi starp cilvēkiem līksmosies iekš Israēla Svētā,
20 Aláìláàánú yóò pòórá, àwọn tí ń ṣẹlẹ́yà yóò di àwátì, gbogbo àwọn tí ó ní ojú ibi ni a ó ké lulẹ̀—
Ka varas darītājam gals klāt, un mēdītājs beigts, un visi izdeldēti, kas uz blēņām domā,
21 àwọn tí wọ́n fi ọ̀rọ̀ kan mú ẹnìkan di ẹlẹ́bi, ẹni tí ń dẹkùn mú olùgbèjà ní ilé ẹjọ́ tí ẹ fi ẹ̀rí èké dun aláìṣẹ̀ ní ìdájọ́.
Kas viena vārda dēļ cilvēku notiesā un liek valgus tam, kas vārtos pārmāca, un taisno nospiež ar viltu.
22 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa, ẹni tí ó ra Abrahamu padà sọ sí ilé Jakọbu: “Ojú kì yóò ti Jakọbu mọ́; ojú wọn kì yóò sì rẹ̀wẹ̀sì mọ́.
Tādēļ Tas Kungs, kas Ābrahāmu atpestījis, saka uz Jēkaba namu: Jēkabs vairs netaps kaunā, un viņa vaigs vairs nenobālēs.
23 Nígbà tí wọ́n bá rí i láàrín àwọn ọmọ wọn, àwọn iṣẹ́ ọwọ́ mi, wọn yóò ya orúkọ mi sí mímọ́, wọn yóò tẹ́wọ́gbà mímọ́ Ẹni Mímọ́ Jakọbu wọn yóò dìde dúró ní ìbọ̀wọ̀ fún Ọlọ́run Israẹli.
Jo kad viņš, kad viņa bērni redzēs Manu roku darbu savā vidū, tad tie svētīs Manu Vārdu un svētīs to Svēto iekš Jēkaba un bīsies Israēla Dievu.
24 Gbogbo àwọn tí ń rìn ségesège ní yóò jèrè ìmọ̀; gbogbo àwọn tí ń ṣe àròyé yóò gba ìtọ́sọ́nà.”
Un tie, kam gars alojās, nāks pie saprašanas, un kurnētāji pieņems mācību.

< Isaiah 29 >