< Isaiah 16 >

1 Fi ọ̀dọ́-àgùntàn ṣe ẹ̀bùn ránṣẹ́ sí aláṣẹ ilẹ̀ náà, láti Sela, kọjá ní aginjù, lọ sí orí òkè ọ̀dọ́mọbìnrin Sioni.
Poślijcie baranki, władcy ziemi, od Sela aż do pustyni, do góry córki Syjonu.
2 Gẹ́gẹ́ bí alárìnkiri ẹyẹ tí a tì jáde kúrò nínú ìtẹ́, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni àwọn obìnrin Moabu ní àwọn ìwọdò Arnoni.
Bo inaczej jak ptak wędrowny i z gniazda wypłoszony będą córki Moabu przy brodach Arnonu.
3 “Fún wa ní ìmọ̀ràn ṣe ìpinnu fún wa. Jẹ́ kí òjìji rẹ dàbí òru, ní ọ̀sán gangan. Fi àwọn ìsáǹsá pamọ́, má ṣe fi àwọn aṣàtìpó han.
Naradź się, rozstrzygnij sprawę; rozłóż swój cień w pełne południe jak w nocy; ukryj wygnańców, nie wydawaj tułacza.
4 Jẹ́ kí àwọn ìsáǹsá Moabu gbé pẹ̀lú rẹ, jẹ́ ààbò fún wọn kúrò lọ́wọ́ ìparun.” Aninilára yóò wá sí òpin, ìparun yóò dáwọ́ dúró; òfinràn yóò pòórá kúrò lórí ilẹ̀.
Niech mieszkają u ciebie moi wygnańcy, Moabie; bądź ich schronieniem przed grabieżcą. Ustanie bowiem gnębiciel, przeminie grabieżca, a ciemięzca zostanie zgładzony z ziemi.
5 Nínú ìfẹ́ a ó fi ìdí ìjọba kan múlẹ̀, ní òdodo ọkùnrin kan yóò jókòó lórí rẹ̀ ẹnìkan láti ilé Dafidi wá. Ẹni yóò ṣe ìdájọ́, yóò sì máa wá ìdájọ́, yóò sì máa yára wá ohun tí í ṣe òdodo.
I tron będzie utwierdzony dzięki miłosierdziu; zasiądzie na nim w prawdzie, w przybytku Dawida, ten, który będzie sądził i dbał o prawo, i niezwłocznie wymierzy sprawiedliwość.
6 Àwa ti gbọ́ nípa ìgbéraga Moabu, ìwọ̀sí ìgbéraga rẹ̀ àti fùlenge fùlenge, gààrù rẹ̀ àti àfojúdi rẹ̀, ṣùgbọ́n ìfọ́nnu rẹ̀ jẹ́ ìmúlẹ̀mófo.
Słyszeliśmy o pysze Moabu, że jest bardzo pyszny, o jego zuchwałości, wyniosłości i gniewie. [Lecz] jego zamiary nie dojdą do skutku.
7 Nítorí náà ni àwọn ará Moabu hu, wọ́n jùmọ̀ hu lórí Moabu. Sọkún kí o sì banújẹ́ fún àkàrà díndín Kiri-Hareseti.
Dlatego Moab będzie zawodzić nad Moabem, wszyscy będą zawodzić. Nad gruntami [miasta] Kir-Chareset będą wzdychać, mówiąc: Już są zniszczone.
8 Gbogbo pápá oko Heṣboni ti gbẹ, bákan náà ni àjàrà Sibma rí. Àwọn aláṣẹ àwọn orílẹ̀-èdè wọ́n tẹ àwọn àyànfẹ́ àjàrà mọ́lẹ̀, èyí tí ó ti fà dé Jaseri ó sì ti tàn dé agbègbè aginjù. Àwọn èhíhù rẹ̀ fọ́n jáde, ó sì lọ títí ó fi dé Òkun.
Spustoszone są bowiem pola Cheszbonu i winorośl Sibmy. Władcy narodów stratowali najwyborniejsze jej latorośle, które sięgały aż do Jazer, a szerzyły się na pustyni; jej latorośle rozłożyły się i przeszły morze.
9 Nítorí náà mo sọkún, gẹ́gẹ́ bí Jaseri ṣe sọkún, fún àwọn àjàrà Sibma. Ìwọ Heṣboni, ìwọ Eleale, mo bomirin ọ́ pẹ̀lú omi ojú! Igbe ayọ̀ lórí àwọn èso pípọ́n rẹ àti lórí ìkórè èyí tí o ti mọ́wọ́ dúró.
Dlatego jak opłakuję Jazer, będę opłakiwał winorośl Sibmy. Zroszę cię swymi łzami, Cheszbonie i Eleale, bo na twój letni owoc i na twoje żniwo padł okrzyk wojenny.
10 Ayọ̀ àti ìdùnnú ni a ti mú kúrò nínú ọgbà-igi eléso rẹ; kò sí ẹnìkan tí ó kọrin tàbí kígbe nínú ọgbà àjàrà: ẹnikẹ́ni kò fún ọtí níbi ìfúntí, nítorí mo ti fi òpin sí gbogbo igbe.
Znikło wesele i znikła radość z urodzajnego pola; w winnicach nie będzie śpiewania ani okrzyku. Nie będzie się tłoczyć wina w tłoczniach; powstrzymałem okrzyki.
11 Ọkàn mi kérora fún Moabu gẹ́gẹ́ bí i dùùrù, àní tọkàntọkàn mi fún ìlú Kiri-Hareseti.
Dlatego moje wnętrze będzie jęczeć nad Moabem jak harfa, a moje serce nad Kir-Chares.
12 Nígbà tí Moabu farahàn ní ibi gíga rẹ̀, ó ṣe ara rẹ̀ ní wàhálà lásán; nígbà tí ó lọ sí ojúbọ rẹ̀ láti gbàdúrà òfo ni ó jásí.
I stanie się, gdy się okaże, że Moab się męczył na wyżynie, że wejdzie [on] do swojej świątyni, aby się modlić, ale nie przemoże.
13 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa ti sọ nípa Moabu.
To jest słowo, które PAN niegdyś powiedział o Moabie.
14 Ṣùgbọ́n ní àkókò yìí Olúwa wí pé, “Láàrín ọdún mẹ́ta gẹ́gẹ́ bí ìwọ̀fà tí ó wà lábẹ́ ìdè ọgbà rẹ̀ ti máa kà á, ògo Moabu àti àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn rẹ̀ ni a ó kẹ́gàn, àwọn tí ó sálà nínú rẹ̀ yóò kéré níye, wọn yóò sì jẹ́ akúrẹtẹ̀.”
Ale teraz PAN powiedział: Po trzech latach, liczonych jak lata najemnika, chwała Moabu zostanie wzgardzona wraz z całym [jego] wielkim tłumem, a [jego] resztka [będzie] bardzo mała i bezsilna.

< Isaiah 16 >