< Genesis 48 >

1 Lẹ́yìn ìgbà díẹ̀ si, a wí fún Josẹfu pé, “Baba rẹ ń ṣàìsàn,” nítorí náà, ó mú àwọn ọmọ rẹ̀ méjèèjì, Manase àti Efraimu lọ́wọ́ lọ pẹ̀lú rẹ̀.
Gdy to się stało, dano znać Józefowi: Oto twój ojciec zachorował. Wziął więc ze sobą swoich dwóch synów, Manassesa i Efraima.
2 Nígbà tí a sọ fún Jakọbu pé, “Josẹfu ọmọ rẹ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ,” Israẹli rọ́jú dìde jókòó lórí ibùsùn rẹ̀.
I powiedziano Jakubowi: Oto twój syn Józef idzie do ciebie. A Izrael zebrał siłę i usiadł na łożu.
3 Jakọbu wí fún Josẹfu pé, “El-Ṣaddai, fi ara hàn mí ní Lusi ní ilẹ̀ Kenaani, níbẹ̀ ni ó sì ti súre fún mi.
Wtedy Jakub powiedział do Józefa: Bóg Wszechmogący ukazał mi się w Luz, w ziemi Kanaan, i błogosławił mi.
4 Ó sì wí fún mi pé, ‘Èmi yóò mú kí o bí sí i, ìwọ yóò sì pọ̀ sí i, èmi yóò sì sọ ọ́ di orílẹ̀-èdè ńlá, èmi yóò sì fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ lẹ́yìn rẹ ní ilẹ̀ yìí gẹ́gẹ́ bí ohun ìní ayérayé.’
I powiedział do mnie: Oto ja uczynię cię płodnym i rozmnożę cię, i wywiodę z ciebie wielki lud. I dam tę ziemię twemu potomstwu po tobie w wieczne dziedzictwo.
5 “Nítorí náà báyìí, àwọn ọmọ rẹ méjèèjì tí a bí fún ọ ní ilẹ̀ Ejibiti, kí èmi kí ó tó tọ̀ ọ́ wá ní ìhín, ni mo sọ di ọmọ mi fúnra mi. Manase àti Efraimu yóò jẹ́ tèmi gẹ́gẹ́ bí Reubeni àti Simeoni ti jẹ́ tèmi.
Dlatego teraz twoi dwaj synowie, Efraim i Manasses, którzy urodzili ci się w ziemi Egiptu, zanim przyszedłem tu do ciebie do Egiptu, są moimi. Będą moi jak Ruben i Symeon.
6 Àwọn ọmọ mìíràn tí ìwọ bá bí lẹ́yìn wọn yóò jẹ́ ọmọ rẹ. Ní ilẹ̀ tí wọn yóò jogún, orúkọ arákùnrin wọn ni a ó máa fi pè wọ́n.
Ale twoje dzieci, które spłodzisz po nich, będą twoje; będą zwane w swych posiadłościach imieniem swoich braci.
7 Bí mo ti ń padà láti Padani, Rakeli kú ní ọ̀nà nígbà tí ó ṣì wà ní ilẹ̀ Kenaani, èyí tó mú ìbànújẹ́ bá mi, níbi tí kò jìnnà sí Efrata. Nítorí náà èmí sì sin ín sí ẹ̀bá ọ̀nà tí ó lọ sí Efrata” (tí ṣe Bẹtilẹhẹmu).
A gdy wracałem z Paddan, umarła mi Rachela w ziemi Kanaan, w drodze, gdy byłem jeszcze w niewielkiej odległości od Efraty, i pogrzebałem ją tam przy drodze do Efraty, czyli Betlejem.
8 Nígbà tí Israẹli rí àwọn ọmọ Josẹfu, ó béèrè wí pé, “Àwọn wo nìyí?”
A gdy Izrael zobaczył synów Józefa, zapytał: Czyi oni są?
9 Josẹfu fún baba rẹ̀ lésì pé, “Wọ̀nyí ni àwọn ọmọkùnrin tí Ọlọ́run ti fi fún mi ní ìhín.” Nígbà náà ni Israẹli wí pé, “Kó wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi kí èmi kí ó ba à le súre fún wọn.”
Józef odpowiedział swemu ojcu: To są moi synowie, których Bóg dał mi tutaj. A [on] powiedział: Proszę, przyprowadź ich do mnie, abym im błogosławił.
10 Báyìí, ojú Israẹli ti ń di bàìbàì nítorí ogbó, agbára káká sì ni ó fi ń ríran. Josẹfu sì kó àwọn ọmọ rẹ̀ súnmọ́ ọ̀dọ̀ rẹ̀, baba rẹ̀ fẹnukò wọ́n ni ẹnu, ó sì dì mọ́ wọn.
A oczy Izraela były tak słabe ze starości, że nie mógł widzieć. I przyprowadził ich do niego, a [Jakub] ich pocałował i uścisnął.
11 Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Èmi kò lérò rárá pé, mo tún le rí ojú rẹ mọ́ láéláé, ṣùgbọ́n Ọlọ́run tún fún mi ní àǹfààní, mo sì tún rí àwọn ọmọ rẹ pẹ̀lú.”
Potem Izrael powiedział do Józefa: Nie spodziewałem się, że będę jeszcze oglądał twoją twarz, a oto Bóg dał mi widzieć nawet twoje potomstwo.
12 Nígbà náà ni Josẹfu kó àwọn ọmọ náà kúrò ní orí eékún baba rẹ̀, ó wólẹ̀, ó sì tẹríba.
Wtedy Józef odsunął ich od jego kolan i pokłonił się twarzą aż do ziemi.
13 Josẹfu sì mú àwọn méjèèjì, Efraimu ni o fi sí ọwọ́ ọ̀tún òun tìkára rẹ̀, èyí tí í ṣe ọwọ́ òsì fún Israẹli, ó sì fi Manase sí ọwọ́ òsì ara rẹ̀, èyí tí ó bọ́ sí ọwọ́ ọ̀tún Israẹli.
Potem Józef wziął obydwu i [postawił] Efraima po swojej prawej ręce, czyli po lewej stronie Izraela; a Manassesa po swojej lewej ręce, czyli po prawej stronie Izraela, i przyprowadził ich do niego.
14 Israẹli sì na ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ jáde, ó sì gbe lé Efraimu lórí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé òun ni àbúrò, ó sì fi ọwọ́ rẹ̀ tàsé ara wọn, ó sì na ọwọ́ òsì lé Manase lórí, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé Manase ni àkọ́bí.
Izrael wyciągnął swoją prawą rękę, położył ją na głowę Efraima, który był młodszy, a swoją lewą rękę na głowę Manassesa, umyślnie pokładając swoje ręce, choć pierworodny był Manasses.
15 Nígbà náà ni ó súre fún Josẹfu wí pé, “Ǹjẹ́ kí Ọlọ́run, ẹni tí baba mi Abrahamu àti Isaaki rìn níwájú rẹ̀, Ọlọ́run tí ó ti jẹ́ olùtọ́jú àti aláàbò mi ní gbogbo ọjọ́ ayé mi títí di òní,
I błogosławił Józefowi, mówiąc: Bóg, przed którego obliczem chodzili moi ojcowie, Abraham i Izaak, Bóg, który mnie żywił od mej młodości aż do dziś;
16 Angẹli tí ó dá mi ní ìdè kúrò lọ́wọ́ gbogbo ewu, kí ó súre fún àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí. Kí a máa fi orúkọ mi pè wọ́n àti orúkọ àwọn baba mi Abrahamu àti Isaaki, kí wọn kí ó sì pọ̀ sí i lọ́pọ̀lọ́pọ̀ lórí ilẹ̀ ayé.”
Anioł, który wybawił mnie ze wszelkiego zła, niech błogosławi tym chłopcom i niech będą nazywani [od] mego imienia i od imienia moich ojców, Abrahama i Izaaka, i niech się rozmnożą na ziemi.
17 Nígbà tí Josẹfu rí i pé baba òun gbé ọwọ́ ọ̀tún lé Efraimu lórí, inú rẹ̀ bàjẹ́, ó sì gbá ọwọ́ baba rẹ̀ mú láti gbé ọwọ́ rẹ̀ kúrò lórí Efraimu lọ sí orí Manase.
A gdy Józef zobaczył, że jego ojciec położył swoją prawą rękę na głowę Efraima, nie podobało mu się to. Wziął więc rękę swego ojca, aby ją przenieść z głowy Efraima na głowę Manassesa.
18 Josẹfu wí fun pé, “Rárá, baba mi, èyí ni àkọ́bí, orí rẹ̀ ni kí ìwọ kí o gbé ọwọ́ ọ̀tún rẹ lé.”
I Józef powiedział do swego ojca: Nie tak, mój ojcze. Ten bowiem [jest] pierworodny, połóż swoją prawą rękę na jego głowę.
19 Ṣùgbọ́n baba rẹ̀ kò gbà, ó wí pé, “Mo mọ̀, ọmọ mi, mo mọ̀. Òun náà yóò di orílẹ̀-èdè, òun náà yóò sì di ńlá. Ṣùgbọ́n àbúrò rẹ̀ yóò di ẹni ńlá jù ú lọ, irú-ọmọ rẹ yóò sì di ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè.”
Ale jego ojciec wzbraniał się i powiedział: Wiem, mój synu, wiem. Ten też stanie się ludem i on też urośnie, ale jego młodszy brat go przewyższy, a z jego potomstwa wyjdzie mnóstwo narodów.
20 Ó súre fún wọn lọ́jọ́ náà pé, “Ní orúkọ yín ni Israẹli yóò máa súre yìí pé, ‘Kí Ọlọ́run ṣe ọ́ bí i ti Efraimu àti Manase.’” Ó sì gbé Efraimu gẹ́gẹ́ bí ẹ̀gbọ́n sí Manase.
Błogosławił im więc tego dnia, mówiąc: Przez ciebie Izrael będzie błogosławił, mówiąc: Niech Bóg cię uczyni jak Efraim i jak Manasses. Tak wyróżnił Efraima przed Manassesem.
21 Nígbà náà ni Israẹli wí fún Josẹfu pé, “Ọjọ́ ikú mi súnmọ́ etílé, ṣùgbọ́n Ọlọ́run yóò wà pẹ̀lú yín, yóò sì mú un yín padà sí ilẹ̀ àwọn baba yín.
Potem Izrael powiedział do Józefa: Oto ja umieram, ale Bóg będzie z wami i przywróci was do ziemi waszych ojców.
22 Pẹ̀lúpẹ̀lú èmi yóò fún ọ ní ìpín kan ju ti àwọn arákùnrin rẹ lọ. Ilẹ̀ tí mo fi idà àti ọ̀kọ̀ mi gbà lọ́wọ́ àwọn ará Amori.”
Oto daję ci jedną część więcej niż twoim braciom, którą nabyłem moim mieczem i moim łukiem z ręki Amorytów.

< Genesis 48 >