< Genesis 33 >

1 Jakọbu sì gbójú sókè, ó sì rí Esau àti irinwó ọkùnrin tí wọ́n ń bọ̀, ó sì pín àwọn ọmọ fún Lea, Rakeli àti àwọn ìránṣẹ́bìnrin méjèèjì.
[Then Jacob joined the rest of his family]. [Later that day] Jacob looked up and saw Esau coming, and there were 400 men with him. [Jacob was worried because of that], so he separated the children. He put Leah’s children with Leah, Rachel’s children with Rachel, and the two female slaves’ children with their mothers.
2 Ó sì ti àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn síwájú, Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ sì jẹ ọ̀wọ́ kejì tí ó tẹ̀lé wọn, Rakeli àti Josẹfu sì wà lẹ́yìn pátápátá.
He put the two female slaves and their children in front. He put Leah and her children next. He put Rachel and Joseph at the rear.
3 Jakọbu fúnra rẹ̀ wa lọ síwájú pátápátá, ó sì tẹríba ní ìgbà méje bí ó ti ń súnmọ́ Esau, arákùnrin rẹ̀.
He himself went ahead of them all, and as he continued to approach his older brother, he prostrated himself with his face on the ground seven times.
4 Ṣùgbọ́n Esau sáré pàdé Jakọbu, ó sì dì mọ́ ọn, ó rọ̀ mọ́ ọn lọ́rùn, ó sì fẹnukò ó lẹ́nu. Àwọn méjèèjì sì sọkún.
But Esau ran to Jacob. He hugged him, put his arms around his neck, and kissed him on the cheek. And they both cried.
5 Nígbà tí Esau sì ṣe àkíyèsí àwọn ìyàwó àti ọmọ Jakọbu, ó béèrè lọ́wọ́ Jakọbu pé, “Ti ta ni àwọn wọ̀nyí?” Jakọbu sì fèsì wí pé, “Èyí ni àwọn ọmọ tí Ọlọ́run nínú àánú rẹ̀ ti fi fún ìránṣẹ́ rẹ.”
Then Esau looked up and saw the women and the children. He asked, “Who are these people who are with you?” Jacob replied, “These are the wives and children that God has graciously/kindly given to me.”
6 Nígbà náà ni àwọn ìránṣẹ́bìnrin àti àwọn ọmọ wọn súnmọ́ tòsí, wọ́n sì tẹríba.
Then the female slaves and their children came near and bowed in front of Esau.
7 Lẹ́yìn náà ni Lea àti àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú dé, wọ́n sì tún tẹríba. Ní ìkẹyìn ni Josẹfu àti Rakeli dé, wọ́n sì tún tẹríba pẹ̀lú.
Then Leah and her children came and bowed down. Finally Joseph and Rachel came near and bowed down.
8 Esau sì béèrè pé, “Kí ni èrò rẹ tí o fi to àwọn ọ̀wọ̀ọ̀wọ́ tí mo pàdé wọ̀nyí?” Jakọbu dáhùn pé, “Kí n ba le rí ojúrere rẹ ni olúwa mi.”
Esau asked, “What is the meaning of all the animals that I saw?” Jacob replied, “I am giving them to you, sir, so that you will feel good toward me.”
9 Ṣùgbọ́n Esau wí pé, “Tèmi ti tó mi, pa èyí tí o ní mọ́ fún ara rẹ.”
But Esau replied, “My [younger] brother, I have enough animals! Keep for yourself the animals that you have!”
10 Jakọbu bẹ̀ ẹ́ wí pé, “Rárá bẹ́ẹ̀ kọ́, bí ó bá ṣe pé, mo rí ojúrere rẹ, jọ̀wọ́ gba ọrẹ lọ́wọ́ mi. Bí mo ṣe rí ojú rẹ̀ yìí, ó dàbí wí pé mo rí ojú Ọlọ́run ni báyìí, tí inú rẹ̀ ti dùn sí mi.
But Jacob said, “No, please, if you feel good toward me, accept these gifts from me. You have greeted me very kindly. Seeing your smiling face assures me [that you have forgiven me]. It is like seeing the face of God!
11 Jọ̀wọ́ gba àwọn ohun tí mo mú wá wọ̀nyí lọ́wọ́ mi. Nítorí Ọlọ́run ti fi oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ hàn sí mi, gbogbo ohun tí mo fẹ́ sì ni mo ní.” Nígbà tí Jakọbu sì rọ̀ ọ́ pé Esau gbọdọ̀ gbà wọ́n, Esau sì gbà á.
Please accept these gifts that I have brought to you, because God has acted kindly toward me, and I still have plenty of animals!” Jacob kept on urging him to accept the animals, and finally he accepted them.
12 Nígbà náà ni Esau wí pé, “Jẹ́ kí a máa lọ, n ó sìn ọ.”
Then Esau said, “Let’s continue traveling together, and I will show the road to you.”
13 Ṣùgbọ́n Jakọbu wí fún un pé, “Ṣe ìwọ náà ṣe àkíyèsí pé ọ̀pọ̀ nínú àwọn ọmọ wọ̀nyí kéré, àwọn màlúù àti àgùntàn pẹ̀lú sì ní àwọn ọmọ kéékèèké. Bí a bá dà wọ́n rìn jìnnà ju bí agbára wọn ṣe mọ lọ, wọ́n lè kú.
Jacob [had no intention to go with Esau], but he said, “You know, sir, that the children are weak, and that I must take care of the female sheep and cows that are (sucking their mother’s milk/nursing their young). If I force them to walk fast for a long distance in just one day, the animals will all die.
14 Èmi bẹ̀ ọ́, máa lọ síwájú ìránṣẹ́ rẹ, àwọn ó sì máa rọra bọ̀, títí èmi àti àwọn ọmọ yóò fi dé ọ̀dọ̀ olúwa mi ní Seiri.”
You go ahead of me. I will lead the animals slowly, but I will walk as fast as the children and animals can walk. I will catch up with you in Seir, [in the land where the descendants of Edom live].”
15 Esau wí pé, “Jẹ́ kí n fi díẹ̀ sílẹ̀ fún ọ nínú àwọn ọkùnrin mi nígbà náà.” Jakọbu wí pé, “Èéṣe, àní kí n sá à rí ojúrere olúwa mi?”
Esau said, “Then allow me to leave with you some of the men who came with me, [to protect you].” But Jacob replied, “(Why do that?/There is no need to do that!) [RHQ] The only thing that I want is for you to act friendly toward me.”
16 Ní ọjọ́ náà gan an ni Esau padà lọ sí Seiri.
So on that day Esau left to return to Seir.
17 Jakọbu sì lọ sí Sukkoti, ó sì kọ́ ilé fún ara rẹ̀, ó sì ṣe ọgbà fún àwọn ẹran. Ìdí èyí ní a fi ń pe ibẹ̀ ní Sukkoti.
But [instead of going to Seir], Jacob and his family went to [a place called] Succoth. There he built a house for himself and his family, and built shelters for his livestock. That is the reason they named the place Succoth, [which means ‘shelters’].
18 Lẹ́yìn ìgbà tí Jakọbu tí Padani-Aramu dé, àlàáfíà ni Jakọbu dé ìlú Ṣekemu ní ilẹ̀ Kenaani, ó sì pàgọ́ sí itòsí ìlú náà.
[Some time later, ] Jacob and his family left Paddan-Aram [in Mesopotamia], and they traveled safely to the Canaan region. There they set up their tents in a field near Shechem city.
19 Ó sì ra ilẹ̀ kan tí ó pàgọ́ sí ni ọgọ́rùn-ún owó fàdákà lọ́wọ́ àwọn ọmọ Hamori tí í ṣe baba Ṣekemu.
One of the leaders of the people in that area was named Hamor. Hamor had several sons. Jacob paid the sons of Hamor 100 pieces of silver for the piece of ground on which they set up their tents.
20 Níbẹ̀ ni ó gbé tẹ́ pẹpẹ kan tí ó pè ní El Elohe Israẹli.
He built a stone altar there, and named it El-Elohe Israel, [which means ‘God, the God of Israel].’

< Genesis 33 >