< Genesis 28 >

1 Nítorí náà Isaaki pe Jakọbu, ó sì súre fún un, ó sì pàṣẹ fún un pé, “Ìwọ kò gbọdọ̀ fẹ́ aya láàrín àwọn ọmọbìnrin Kenaani.
Wtedy Izaak wezwał Jakuba i błogosławił mu, i rozkazał: Nie bierz sobie żony z córek Kanaanu.
2 Dípò bẹ́ẹ̀ lọ sí Padani-Aramu, sí ilé Betueli, baba ìyá rẹ, kí ìwọ kí ó sì fẹ́ aya fún ara rẹ nínú àwọn ọmọbìnrin Labani arákùnrin ìyá rẹ.
[Ale] wstań i idź do krainy Paddan-Aram, do domu Betuela, ojca twojej matki, i weź sobie stamtąd żonę z córek Labana, brata twojej matki.
3 Kí Ọlọ́run Olódùmarè El-Ṣaddai kí ó bùkún fún ọ, kí ó sì mú ọ bí sí i, kí ó sì mú ọ pọ̀ sí i ní iye títí tí ìwọ yóò di àgbájọ àwọn ènìyàn.
A Bóg Wszechmogący niech ci błogosławi i niech cię uczyni płodnym i rozmnoży, abyś stał się licznym ludem;
4 Kí Ọlọ́run kí ó fún ìwọ àti irú-ọmọ rẹ ní ìre tí ó sú fún Abrahamu, kí ìwọ kí ó le gba ilẹ̀ níbi tí a ti ń ṣe àtìpó yìí, ilẹ̀ tí Ọlọ́run ti fi fún Abrahamu.”
I niech ci da błogosławieństwo Abrahama, tobie i twemu potomstwu z tobą, abyś odziedziczył ziemię, na której jesteś przybyszem, którą Bóg dał Abrahamowi.
5 Bẹ́ẹ̀ ni Isaaki sì rán Jakọbu lọ. Ó sì lọ sí Padani-Aramu, lọ́dọ̀ Labani ọmọ Betueli, ará Aramu, tí í ṣe arákùnrin Rebeka ìyá Jakọbu àti Esau.
I tak Izaak wysłał Jakuba, który udał się do krainy Paddan-Aram, do Labana, syna Betuela, Syryjczyka, brata Rebeki, matki Jakuba i Ezawa.
6 Nígbà tí Esau gbọ́ pé, Isaaki ti súre fún Jakọbu, ó sì ti rán Jakọbu lọ sí Padani-Aramu láti fẹ́ aya níbẹ̀ àti pé nígbà tí ó súre fún un, ó kìlọ̀ fun un pé, kò gbọdọ̀ fẹ́ nínú àwọn ọmọbìnrin Kenaani
A Ezaw widział, że Izaak błogosławił Jakubowi i posłał go do krainy Paddan-Aram, aby stamtąd wziął sobie żonę, [i że] błogosławiąc mu, przykazał: Nie weźmiesz żony z córek Kanaanu;
7 àti pé, Jakọbu ti gbọ́rọ̀ sí ìyá àti baba rẹ̀ lẹ́nu, ó sì ti lọ sí Padani-Aramu.
I że Jakub był posłuszny swemu ojcu oraz swojej matce, i poszedł do krainy Paddan-Aram;
8 Nígbà náà ni Esau mọ bí Isaaki baba rẹ ti kórìíra àwọn ọmọbìnrin Kenaani tó.
Widział też Ezaw, że córki Kanaanu nie podobają się jego ojcu Izaakowi;
9 Nítorí náà Esau tọ Iṣmaeli lọ, ó sì fẹ́ Mahalati, arábìnrin Nebaioti, ọmọbìnrin Iṣmaeli tí í ṣe ọmọ Abrahamu. Ó fẹ́ ẹ, kún àwọn ìyàwó tí ó ti ní tẹ́lẹ̀.
Wtedy Ezaw poszedł do Izmaela i oprócz żon, które już miał, wziął za żonę Machalat, córkę Izmaela, syna Abrahama, siostrę Nebajota.
10 Jakọbu kúrò ní Beerṣeba, ó sì kọrí sí ìlú Harani.
A Jakub wyszedł z Beer-Szeby i udał się do Charanu.
11 Nígbà tí ó dé ibìkan, ó dúró ní òru náà nítorí tí ilẹ̀ ti ń ṣú, ó sì gbé òkúta kan ó fi ṣe ìrọ̀rí, ó sì sùn.
Przyszedł na pewne miejsce i tam nocował, bo słońce już zaszło. Wziął [jeden] z kamieni z tego miejsca, podłożył go sobie pod głowę i zasnął na tym miejscu.
12 Ó sì lá àlá pé, a gbé àkàsọ̀ kan dúró ti ó fi ìdí lélẹ̀, orí rẹ̀ sì kan ọ̀run, àwọn angẹli Ọlọ́run sì ń gòkè, wọ́n sì ń sọ̀kalẹ̀ lórí rẹ̀.
I śniło mu się, że na ziemi stała drabina, a jej szczyt sięgał nieba. A oto aniołowie Boży wstępowali i zstępowali po niej.
13 Olúwa sì dúró lókè rẹ̀, ó sì wí pé, “Èmi ni Olúwa, Ọlọ́run baba rẹ Abrahamu àti Ọlọ́run Isaaki, ìwọ àti ìran rẹ ni èmi yóò fi ilẹ̀ tí ìwọ dùbúlẹ̀ sórí rẹ̀ yìí fún.
A PAN stał nad nią i powiedział: Ja jestem PAN, Bóg twego ojca Abrahama i Bóg Izaaka. Ziemię, na której leżysz, dam tobie i twemu potomstwu.
14 Ìran rẹ yóò pọ̀ bí erùpẹ̀ ilẹ̀, ìwọ yóò sì tànkálẹ̀ dé ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn, àti dé gúúsù àti àríwá. A ó sì bùkún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nípasẹ̀ ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ.
A twoje potomstwo będzie jak proch ziemi i rozprzestrzenisz się na zachód i na wschód, na północ i na południe. A w tobie i w twoim potomstwie będą błogosławione wszystkie narody ziemi.
15 Èmi wà pẹ̀lú rẹ, èmi yóò sì pa ọ mọ́ ní ibikíbi tí ìwọ bá lọ, èmi yóò sì mú ọ padà wá sí ilẹ̀ yìí ní àlàáfíà. Èmi kì yóò fi ọ sílẹ̀ ní ìgbà kan, títí tí èmi yóò fi mú gbogbo ìlérí mi ṣẹ.”
Oto ja [jestem] z tobą i będę cię strzegł, gdziekolwiek pójdziesz, i przyprowadzę cię z powrotem do tej ziemi. Bo nie opuszczę cię, aż spełnię to, co ci obiecałem.
16 Nígbà tí Jakọbu jí lójú oorun rẹ̀, ó rò nínú ara rẹ̀ pé, “Dájúdájú Olúwa ń bẹ ní ìhín yìí, èmi kò sì mọ̀.”
Gdy Jakub zbudził się ze snu, powiedział: Naprawdę PAN jest na tym miejscu, a ja [o tym] nie wiedziałem.
17 Ẹ̀rù sì bà á, ó sì wí pé, “Ìhín yìí ní ẹ̀rù gidigidi; ibí kì í ṣe ibòmíràn bí kò ṣe ilé Ọlọ́run, àní ẹnu ibodè ọ̀run nìyìí.”
I przestraszył się, i powiedział: O, jakie straszne to miejsce! To nie może być nic [innego] jak dom Boży i brama nieba.
18 Jakọbu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀, ó sì gbé òkúta tí ó fi ṣe ìrọ̀rí lélẹ̀ bí ọ̀wọ́n, ó sì da òróró si lórí.
I Jakub wstał wcześnie rano, wziął kamień, który podłożył sobie pod głowę i postawił go na znak, i nalał oliwy na jego wierzch.
19 Ó sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Beteli, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìlú náà ń jẹ́ Lusi tẹ́lẹ̀ rí.
I nadał temu miejscu nazwę Betel, lecz przedtem miasto nazywało się Luz.
20 Jakọbu sì jẹ́ ẹ̀jẹ́ níbẹ̀ pé, “Bí Ọlọ́run yóò bá wà pẹ̀lú mi, tí yóò sì pa mí mọ́ ní ìrìnàjò mi tí mo ń lọ, tí yóò sì fún mi ní oúnjẹ láti jẹ àti aṣọ láti wọ̀,
Wtedy Jakub złożył ślub, mówiąc: Jeśli Bóg będzie ze mną i będzie mnie strzegł na tej drodze, którą idę, [jeśli] da mi chleb do jedzenia i odzież do ubrania;
21 tí mo sì padà sílé baba mi ní àlàáfíà, nígbà náà Olúwa ni yóò jẹ́ Ọlọ́run mi,
I [jeśli] wrócę w pokoju do domu mego ojca, to PAN będzie moim Bogiem.
22 Òkúta yìí tí mo gbé kalẹ̀ bí ọ̀wọ́n yóò jẹ́ ilé Ọlọ́run, nínú gbogbo ohun tí ìwọ ó fi fún mi, èmi yóò sì fi ìdámẹ́wàá rẹ̀ fún ọ.”
A ten kamień, który postawiłem [na] znak, będzie domem Bożym. I ze wszystkiego, co mi dasz, będę ci na pewno oddawał dziesięcinę.

< Genesis 28 >