< Genesis 27 >

1 Nígbà ti Isaaki di arúgbó, ojú rẹ̀ sì ti di bàìbàì tó bẹ́ẹ̀ tí kò le ríran. Ó pe Esau àkọ́bí rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Ọmọ mi.” Esau sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
A gdy Izaak się zestarzał i jego oczy osłabły, tak że nie mógł widzieć, wezwał swego starszego syna Ezawa i powiedział do niego: Synu mój! A on odpowiedział: Oto jestem.
2 Isaaki sì wí pé, “Nísinsin yìí mo di arúgbó, èmi kò sì mọ ọjọ́ tí èmi yóò kú.
[Izaak] powiedział: Oto zestarzałem się już i nie znam dnia swojej śmierci.
3 Nítorí náà, mú ohun èlò ọdẹ rẹ, apó àti ọrún, nísinsin yìí kí o sì lọ pa ẹran wá fún mi nínú igbó.
Teraz więc weź, proszę, swoją broń, kołczan i łuk, wyjdź na pole i upoluj mi zwierzynę.
4 Kí o sì ṣe ẹran àdídùn fún mi, irú èyí tí mo fẹ́ràn, kí o gbe wá fún mi kí n jẹ, kí n sì súre fún ọ kí n tó kú.”
I przygotuj mi smaczną potrawę, jaką lubię, i przynieś mi ją, a będę jadł, aby moja dusza błogosławiła ci, zanim umrę.
5 Ṣùgbọ́n Rebeka ń fetí léko gbọ́ nígbà tí Isaaki ń bá Esau ọmọ rẹ̀ sọ̀rọ̀. Nítorí náà, nígbà ti Esau ti ṣe ọdẹ lọ sínú igbó,
A Rebeka słyszała, gdy Izaak mówił do swego syna Ezawa. I Ezaw wyszedł na pole, aby upolować zwierzynę i [ją] przynieść.
6 Rebeka sọ fún Jakọbu ọmọ rẹ̀ pé, “Wò ó, mo gbọ́ tí baba rẹ ń wí fún Esau ẹ̀gbọ́n rẹ pé,
I Rebeka powiedziała do swego syna Jakuba: Słyszałam, jak twój ojciec mówił do twego brata Ezawa:
7 ‘Pa ẹran fún mi wá, kí o sì ṣe oúnjẹ àdídùn fún mi láti jẹ, kí n ba à le súre fún ọ níwájú Olúwa kí èmi tó kú.’
Przynieś mi zwierzynę i przygotuj mi smaczną potrawę, abym jadł i błogosławił ci przed PANEM, zanim umrę.
8 Nísinsin yìí ọmọ mi, gbọ́ tèmi, kí o sì ṣe ohun tí èmi yóò wí fún ọ.
Teraz więc, mój synu, posłuchaj mego głosu w tym, co ci każę.
9 Lọ sínú agbo ẹran, kí o sì mú ọmọ ewúrẹ́ méjì, kí ó lè ṣe oúnjẹ àdídùn fún baba rẹ, irú èyí tí ó fẹ́ràn dáradára.
Idź do trzody i przynieś mi stamtąd dwoje dobrych koźląt, a przygotuję z nich dla twego ojca smaczną potrawę, jaką lubi.
10 Ìwọ yóò sì gbé e tọ baba rẹ lọ, kí òun ba à lè jẹ ẹ́, kí ó sì súre fún ọ, kí ó tó kú.”
I zaniesiesz twemu ojcu, i będzie jadł, aby ci błogosławił, zanim umrze.
11 Jakọbu sì wí fún Rebeka ìyá rẹ̀ pé, “Ṣùgbọ́n Esau ẹ̀gbọ́n mi jẹ́ ènìyàn onírun lára, bẹ́ẹ̀ alára ọ̀bọ̀rọ́ sì ni èmi,
Wtedy Jakub powiedział do swej matki Rebeki: Przecież mój brat Ezaw jest człowiekiem owłosionym, a ja jestem człowiekiem gładkim;
12 bí baba mi bá fọwọ́ kàn mi ń kọ́? Èmi yóò jọ ẹlẹ́tàn lójú rẹ̀, dípò kí ó súre fún mi, èmi yóò sì mú ègún wá sórí ara mi.”
Jeśli mój ojciec mnie dotknie, okażę się w jego oczach oszustem, ściągnę na siebie przekleństwo, a nie błogosławieństwo.
13 Ìyá rẹ̀ wá wí fun un pé, “Ọmọ mi jẹ́ kí ègún náà wá sórí mi, sá à ṣe ohun tí mo wí, kí o sì mú wọn wá fún mi.”
Jego matka odpowiedziała mu: Mój synu, [niech] na mnie [spadnie] twoje przekleństwo. Tylko posłuchaj mego głosu, idź i przynieś mi [je].
14 Jakọbu sì ṣe ohun gbogbo tí ìyá rẹ̀ wí fun un, Rebeka sì ṣe oúnjẹ àdídùn náà, irú èyí tí Isaaki fẹ́ràn.
Poszedł więc, wziął i przyniósł [je] swej matce, a ona przygotowała smaczną potrawę, jaką lubił jego ojciec.
15 Nígbà náà ni Rebeka mú èyí tí ó dára jù nínú aṣọ Esau ọmọ rẹ̀ àgbà tí ó wà nínú ilé Rebeka, ó sì fi wọ Jakọbu ọmọ rẹ̀ àbúrò.
Potem Rebeka wzięła szaty swego starszego syna Ezawa, najcenniejsze, jakie [miała] u siebie w domu, i ubrała w nie swego młodszego syna Jakuba.
16 Ó sì fi awọ ewúrẹ́ wọ̀n-ọn-nì bo ọwọ́ àti ibi tí ọ̀bọ̀rọ́ ọrùn.
A skórkami koźląt owinęła mu ręce i gładką szyję.
17 Nígbà náà ni ó gbé ẹran dídùn náà àti oúnjẹ tí ó ti sè lé Jakọbu ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́.
I dała chleb i smaczną potrawę, którą przygotowała, w ręce swego syna Jakuba.
18 Jakọbu wọlé lọ sí ọ̀dọ̀ baba rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi.” Baba rẹ sì dáhùn pé, “Èmi nìyí, ìwọ ta ni, ọmọ mi?”
A [on] poszedł do swego ojca i powiedział: Mój ojcze! A on odpowiedział: Oto jestem. Kto ty [jesteś], mój synu?
19 Jakọbu sì fèsì pé, “Èmi ni Esau àkọ́bí rẹ, èmi ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ fún mi, jọ̀wọ́ dìde jókòó, kí o sì jẹ nínú ẹran igbó mi tí mo ti sè, kí o ba à le súre fún mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.”
Jakub odpowiedział swemu ojcu: Ja [jestem] Ezaw, twój pierworodny. Zrobiłem, jak mi kazałeś. Podnieś się, proszę, siądź i jedz z mojej zwierzyny, aby mi błogosławiła twoja dusza.
20 Isaaki tún béèrè pé, “Ọmọ mi, báwo ni ó ṣe tètè yá ọ bẹ́ẹ̀?” Jakọbu sì tún dáhùn pé, “Olúwa Ọlọ́run rẹ ló fún mi pa.”
Izaak zapytał swego syna: Jakże tak szybko to znalazłeś, mój synu? A on odpowiedział: To PAN, twój Bóg, sprawił, że mi się udało.
21 Nígbà náà ni Isaaki wí fún Jakọbu pé, “Súnmọ́ mi, kí n le è fọwọ́ kàn ọ́, kí n lè mọ̀ bóyá Esau ọmọ mi ni nítòótọ́ tàbí òun kọ́.”
Potem Izaak powiedział do Jakuba: Zbliż się, proszę, abym cię dotknął, mój synu, czy ty jesteś moim synem Ezawem, czy nie.
22 Jakọbu sì súnmọ́ Isaaki baba rẹ̀. Isaaki sì fọwọ́ kàn án, ó sì wí pé, “Ohùn ni ohùn Jakọbu; ṣùgbọ́n ọwọ́ ni ọwọ́ Esau.”
Jakub podszedł więc do swego ojca Izaaka, który dotknął go i powiedział: Głos jest głosem Jakuba, ale ręce są rękami Ezawa.
23 Kò sì dá Jakọbu mọ̀ nítorí ọwọ́ rẹ̀ ní irun bí i ti Esau arákùnrin rẹ, nítorí náà, ó súre fún un
I nie rozpoznał go, bo jego ręce były owłosione jak ręce jego brata Ezawa. I błogosławił mu.
24 ó sì bi í léèrè pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni Esau ọmọ mi ni tòótọ́?” Jakọbu sì dáhùn pé, “Èmi ni.”
I zapytał: Czy ty jesteś moim synem Ezawem? A [on] odpowiedział: Jestem.
25 Nígbà náà ni Isaaki wí pé, “Gbé ẹran igbó náà súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi, kí èmi kí ó jẹ ẹ́, kí èmi sì súre fún ọ láti inú ọkàn mi wá.” Jakọbu sì gbé e wá ó sì jẹ ẹ́, ó sì tún fún un ní wáìnì, ó sì mú un pẹ̀lú.
Potem powiedział: Podaj mi, żebym jadł ze zwierzyny mego syna, aby błogosławiła ci moja dusza. Wtedy podał mu i jadł. Przyniósł mu też wina, a on pił.
26 Nígbà náà ni Isaaki baba rẹ̀ wí fun un pé, “Súnmọ́ mi, ọmọ mi, kí o sì fẹnukò mí ní ẹnu.”
Jego ojciec Izaak powiedział mu: Podejdź teraz i pocałuj mnie, mój synu.
27 Ó sì súnmọ́ ọn, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu. Nígbà tí Isaaki gbọ́ òórùn aṣọ rẹ̀, ó súre fún un ó wí pé, “Wò ó òórùn ọmọ mi dàbí òórùn oko tí Olúwa ti bùkún.
Podszedł więc i pocałował go. [Gdy] poczuł zapach jego szat, błogosławił mu, mówiąc: Oto zapach mego syna jak zapach pola, które PAN błogosławił.
28 Kí Ọlọ́run kí ó fún ọ nínú ìrì ọ̀run àti nínú ọ̀rá ilẹ̀ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkà àti wáìnì tuntun.
Niech Bóg da ci z rosy nieba i żyzność ziemi oraz obfitość zboża i wina.
29 Kí àwọn orílẹ̀-èdè kí ó máa sìn ọ́, kí àwọn ènìyàn sì máa tẹríba fún ọ, máa ṣe olórí àwọn arákùnrin rẹ, kí àwọn iyèkan rẹ sì máa wólẹ̀ fún ọ Fífibú ni àwọn ẹni tó fi ọ́ bú, ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ó súre fún ọ.”
Niech ludzie ci służą i niech ci się kłaniają narody. Bądź panem twoich braci i niech ci się kłaniają synowie twojej matki. Niech będzie przeklęty, kto cię przeklina, a niech będzie błogosławiony, kto cię błogosławi.
30 Bí Isaaki ti súre tán tí Jakọbu ṣẹ̀ṣẹ̀ jáde kúrò ní ọ̀dọ̀ baba rẹ̀ ni Esau ti oko ọdẹ dé.
Gdy Izaak skończył błogosławić Jakuba i ledwie Jakub odszedł sprzed oblicza swego ojca Izaaka, jego brat Ezaw wszedł z łowów.
31 Òun pẹ̀lú ṣe ẹran dídùn, ó sì gbé e tọ baba rẹ̀ wá, ó sì wí fún un pé, “Baba mi, dìde jókòó, kí o sì jẹ nínú ẹran igbó tí mo ti ṣè, kí o sì súre fún mi.”
On także przygotował smaczną potrawę, przyniósł ją swemu ojcu i powiedział mu: Podnieś się, mój ojcze, i jedz ze zwierzyny twego syna, aby błogosławiła mi twoja dusza.
32 Isaaki baba rẹ̀ sì bi í wí pé, “Ìwọ ta ni?” Ó sì dáhùn pé, “Èmi Esau, àkọ́bí rẹ ni.”
Jego ojciec Izaak zapytał go: Kim jesteś? A on odpowiedział: [Jestem] twoim synem, twoim pierworodnym, Ezawem.
33 Nígbà náà ni Isaaki wárìrì gidigidi, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni náà, tí ó ti pa ẹran igbó tí ó sì ti gbe wá fún mi, tí mo sì ti jẹ ẹ́ kí ó tó dé? Mo sì ti súre fún un, sì wò ó dájúdájú a ó sì bùkún un!”
Wtedy Izaak bardzo się przeraził i zapytał: Któż [to]? A gdzie jest ten, co ułowił zwierzynę i przyniósł mi, a ja jadłem ze wszystkiego, zanim ty przyszedłeś, i błogosławiłem mu? Będzie więc błogosławionym.
34 Nígbà tí Esau gbọ́ ọ̀rọ̀ baba rẹ̀, ó ké, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún kíkorò, ó sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Baba mi súre fún èmi náà, àní fún èmi náà pẹ̀lú.”
A gdy Ezaw usłyszał słowa swego ojca, podniósł donośny krzyk pełen goryczy i powiedział swemu ojcu: Błogosław też [i] mi, mój ojcze.
35 Ṣùgbọ́n Isaaki wí pé, “Àbúrò rẹ ti fi ẹ̀tàn wá, ó sì ti gba ìbùkún rẹ lọ.”
A on mu powiedział: Twój brat podstępnie przyszedł i wziął twoje błogosławieństwo.
36 Esau sì wí pé, “Lásán ni a pe orúkọ rẹ̀ ní Jakọbu bí? Ní ìgbà méjì yìí ni ó ti tàn mí jẹ: ní àkọ́kọ́, ó gba ogún ìbí mi, nísinsin yìí, ó tún gba ìbùkún mi!” O sì béèrè pé, “Ṣe o kò wá fi ìre kankan sílẹ̀ fun mi ni?”
Ezaw powiedział: Czy nie słusznie nadano mu imię Jakub? Podszedł mnie bowiem już dwukrotnie: wziął moje pierworództwo, a teraz zabrał moje błogosławieństwo. I zapytał: Czy nie zachowałeś dla mnie błogosławieństwa?
37 Isaaki sì dá Esau lóhùn pé, “Mo ti fi ṣe olórí rẹ àti àwọn ìbátan rẹ ni mo fi ṣe ìránṣẹ́ fún un, àti ọkà àti wáìnì ni mo ti fi lé e lọ́wọ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀, kí ni ó tún kù tí ǹ bá tún fún ọ báyìí ọmọ mi?”
Izaak odpowiedział Ezawowi: Ustanowiłem go panem nad tobą i wszystkich jego braci dałem mu za sługi, i zapewniłem mu zboże i wino. Cóż więc mogę dla ciebie zrobić, mój synu?
38 Esau sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Ṣe ìre kan ṣoṣo ni ìwọ ní lẹ́nu ni baba mi? Súre fún èmi náà, baba mi.” Esau sì sọkún kíkankíkan.
I Ezaw powiedział do swego ojca: Czy masz [tylko] jedno błogosławieństwo, mój ojcze? Błogosław także [i] mnie, mój ojcze. I Ezaw podniósł głos i zapłakał.
39 Isaaki baba rẹ̀ sì dá a lóhùn pé, “Ibùjókòó rẹ yóò jìnnà sí ọ̀rá ilẹ̀, àti sí ibi ìrì ọ̀run láti òkè wá.
I jego ojciec Izaak odpowiedział mu: Twoje mieszkanie będzie z żyznej ziemi i z rosy nieba z góry.
40 Nípa idà rẹ ni ìwọ yóò máa gbé, ìwọ yóò sì máa sin àbúrò rẹ, ṣùgbọ́n ní ìkẹyìn, nígbà tí ìwọ bá di alágbára ìwọ yóò já àjàgà rẹ̀ kúrò lọ́rùn rẹ.”
A będziesz żył z twego miecza i będziesz służył twemu bratu. Ale gdy stanie się, że będziesz panował, zrzucisz jego jarzmo z twojej szyi.
41 Esau sì kórìíra Jakọbu nítorí ìre tí baba rẹ̀ sú fún un, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, “Baba mi sá à ti fẹ́rẹ kú, nígbà náà ni èmi ó pa Jakọbu, arákùnrin mi.”
Dlatego Ezaw nienawidził Jakuba z powodu błogosławieństwa, którym mu błogosławił jego ojciec. I Ezaw mówił w swym sercu: Zbliżają się dni żałoby po moim ojcu, wtedy zabiję mego brata Jakuba.
42 Nígbà tí Rebeka sì gbọ́ ohun tí Esau àkọ́bí rẹ̀ wí, ó sì ránṣẹ́ sí Jakọbu, ó sì wí fun un pé, “Esau ẹ̀gbọ́n rẹ ń tu ara rẹ̀ nínú pẹ̀lú èrò à ti pa ọ́.
I doniesiono Rebece o słowach jej starszego syna Ezawa. Kazała więc przywołać swego młodszego syna Jakuba i powiedziała do niego: Oto twój brat Ezaw pociesza się tym, że cię zabije.
43 Nítorí náà ọmọ mi, ṣe ohun tí èmi yóò sọ fún ọ, sálọ sọ́dọ̀ Labani ẹ̀gbọ́n mi ní Harani.
Teraz więc, mój synu, posłuchaj mego głosu, wstań i uciekaj do mego brata Labana, do Charanu;
44 Jókòó sí ibẹ̀ títí di ìgbà tí ìbínú ẹ̀gbọ́n rẹ yóò fi rọ̀.
Pozostań u niego przez pewien czas, aż ucichnie gniew twego brata;
45 Nígbà tí ẹ̀gbọ́n rẹ kò bá bínú sí ọ mọ́, tí ó sì ti gbàgbé ohun tí ìwọ ṣe sí i, èmí ó ránṣẹ́ sí ọ láti padà wá. Èéṣe tí èmi ó fi pàdánù ẹ̀yin méjèèjì ní ọjọ́ kan náà?”
Aż ustąpi zapalczywość twego brata na ciebie i zapomni o tym, co mu zrobiłeś. Wtedy każę cię stamtąd sprowadzić. Czemu mam być pozbawiona was obu w jednym dniu?
46 Nígbà náà ni Rebeka wí fún Isaaki pé, “Ayé sì sú mi nítorí àwọn ọmọbìnrin Hiti wọ̀nyí. Bí Jakọbu bá fẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin Hiti wọ̀nyí, ó kúkú sàn kí n má wà láààyè.”
I Rebeka powiedziała do Izaaka: Obrzydło mi życie z powodu córek Cheta. Jeśli Jakub [też] weźmie sobie żonę z córek Cheta, jakie są na tej ziemi, po co mi życie?

< Genesis 27 >