< Genesis 27 >

1 Nígbà ti Isaaki di arúgbó, ojú rẹ̀ sì ti di bàìbàì tó bẹ́ẹ̀ tí kò le ríran. Ó pe Esau àkọ́bí rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Ọmọ mi.” Esau sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
I KO Isaaka manawa i elemakule ai, a powehiwehi ai kona mau maka, a hiki ole ia ia ke ike aku; hea aku la oia ia Esau i kana keiki mua, i aku la ia ia, E kuu keiki: i mai la kela, Eia wau.
2 Isaaki sì wí pé, “Nísinsin yìí mo di arúgbó, èmi kò sì mọ ọjọ́ tí èmi yóò kú.
I aku la oia, Eia hoi, ua elemakule au, aole hoi au i ike i kuu la e make ai:
3 Nítorí náà, mú ohun èlò ọdẹ rẹ, apó àti ọrún, nísinsin yìí kí o sì lọ pa ẹran wá fún mi nínú igbó.
Ano hoi, e lawe oe i kau mau mea pana, i kau aapua a me kau kakaka, e hele aku oe i ka nahelehele e imi i kahi io na'u;
4 Kí o sì ṣe ẹran àdídùn fún mi, irú èyí tí mo fẹ́ràn, kí o gbe wá fún mi kí n jẹ, kí n sì súre fún ọ kí n tó kú.”
A e hana oe i mea ono na'u i ka mea hoi a'u i ono ai, a e lawe mai oe i o'u nei, i paina au, a i hoomaikai aku kuu uhane ia oe mamua o kuu make ana.
5 Ṣùgbọ́n Rebeka ń fetí léko gbọ́ nígbà tí Isaaki ń bá Esau ọmọ rẹ̀ sọ̀rọ̀. Nítorí náà, nígbà ti Esau ti ṣe ọdẹ lọ sínú igbó,
Lohe ae la o Rebeka i ka wa a Isaaka i olelo aku ai ia Esau i kana keiki A hele aku o Esau i ka nahelehele e imi aku a e lawe mai i ka io o ka holoholona hihiu.
6 Rebeka sọ fún Jakọbu ọmọ rẹ̀ pé, “Wò ó, mo gbọ́ tí baba rẹ ń wí fún Esau ẹ̀gbọ́n rẹ pé,
Olelo aku la o Rebeka ia Iakoba i kana keiki, i aku la, Aia hoi, ua lohe iho nei au i kou makuakane e olelo ana i kou kaikuaana ia Esau, i ka i ana ae,
7 ‘Pa ẹran fún mi wá, kí o sì ṣe oúnjẹ àdídùn fún mi láti jẹ, kí n ba à le súre fún ọ níwájú Olúwa kí èmi tó kú.’
E lawe mai oe io'u nei i io holoholona hihiu, a e hana i ka mea ono na'u, i paina au, a i hoomaikai hoi au ia oe imua o Iehova mamua o kuu make ana.
8 Nísinsin yìí ọmọ mi, gbọ́ tèmi, kí o sì ṣe ohun tí èmi yóò wí fún ọ.
Ano hoi, e kuu keiki, e hoolohe mai oe i ko'u leo, ma ka mea a'u e kauoha aku nei ia oe.
9 Lọ sínú agbo ẹran, kí o sì mú ọmọ ewúrẹ́ méjì, kí ó lè ṣe oúnjẹ àdídùn fún baba rẹ, irú èyí tí ó fẹ́ràn dáradára.
E hele koke aku oe i ka poe holoholona, a e lawe mai i na keiki kao maikai i elua; a na'u no e hana i ka mea ono na kou makuakane, i kana mea i ono ai:
10 Ìwọ yóò sì gbé e tọ baba rẹ lọ, kí òun ba à lè jẹ ẹ́, kí ó sì súre fún ọ, kí ó tó kú.”
A e halihali aku oe ia mea i kou makuakane, i ai iho ia, a i hoomaikai mai oia ia oe mamua o kona make ana.
11 Jakọbu sì wí fún Rebeka ìyá rẹ̀ pé, “Ṣùgbọ́n Esau ẹ̀gbọ́n mi jẹ́ ènìyàn onírun lára, bẹ́ẹ̀ alára ọ̀bọ̀rọ́ sì ni èmi,
Olelo mai la o Iakoba ia Rebeka i kona makuwahine, Aia hoi, he kanaka huluhulu o Esau kuu kai kuaana, a he kanaka pahee no wau:
12 bí baba mi bá fọwọ́ kàn mi ń kọ́? Èmi yóò jọ ẹlẹ́tàn lójú rẹ̀, dípò kí ó súre fún mi, èmi yóò sì mú ègún wá sórí ara mi.”
A e hana mai paha kuu makuakane ia'u, a e ikea auanei au e ia he mea hoopunipuni; a e hooili mai au i ka hoinoia maluna iho o'u, aole ka hoomaikaiia,
13 Ìyá rẹ̀ wá wí fun un pé, “Ọmọ mi jẹ́ kí ègún náà wá sórí mi, sá à ṣe ohun tí mo wí, kí o sì mú wọn wá fún mi.”
I aku la kona makuwahine ia ia, Maluna iho o'u kou hoinoia, e kuu keiki; e hoolohe wale mai oe i ko'u leo, e kii aku, a e lawe mai io'u nei.
14 Jakọbu sì ṣe ohun gbogbo tí ìyá rẹ̀ wí fun un, Rebeka sì ṣe oúnjẹ àdídùn náà, irú èyí tí Isaaki fẹ́ràn.
Kii aku la ia, a lawe mai la ia mau mea i kona makuwahine: a na kona makuwahine i hana i ka mea ono, a kona makuakane i ono ai.
15 Nígbà náà ni Rebeka mú èyí tí ó dára jù nínú aṣọ Esau ọmọ rẹ̀ àgbà tí ó wà nínú ilé Rebeka, ó sì fi wọ Jakọbu ọmọ rẹ̀ àbúrò.
Lawe ae la o Rebeka i ka aahu maikai o kana keiki mua o Esau, i ka mea e waiho ana iloko o ka hale me ia, a hoaahu iho la ia Iakoba i kana keiki muli iho ia mea.
16 Ó sì fi awọ ewúrẹ́ wọ̀n-ọn-nì bo ọwọ́ àti ibi tí ọ̀bọ̀rọ́ ọrùn.
A hoopili aku la o Rebeka i na ili o na keiki kao maluna o kona mau lima, a me ka pahee o kona a-i.
17 Nígbà náà ni ó gbé ẹran dídùn náà àti oúnjẹ tí ó ti sè lé Jakọbu ọmọ rẹ̀ lọ́wọ́.
Haawi aku la ia i ka mea ono, a me ka berena ana i hoomakaukau ai, iloko o ka lima o Iakoba o kana keiki.
18 Jakọbu wọlé lọ sí ọ̀dọ̀ baba rẹ̀ ó sì wí pé, “Baba mi.” Baba rẹ sì dáhùn pé, “Èmi nìyí, ìwọ ta ni, ọmọ mi?”
A hele aku la ia i kona makuakane, i aku la, E kuu makuakane: i mai la kela, Eia no wau; owai la oe, e kuu keiki?
19 Jakọbu sì fèsì pé, “Èmi ni Esau àkọ́bí rẹ, èmi ti ṣe gẹ́gẹ́ bí ìwọ ti sọ fún mi, jọ̀wọ́ dìde jókòó, kí o sì jẹ nínú ẹran igbó mi tí mo ti sè, kí o ba à le súre fún mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn rẹ.”
I aku la o Iakoba i kona makuakane, Owau no o Esau, o kau makahiapo; ua hana iho nei au i kau mea i kauoha mai ai; ke noi aku nei au, e ala mai oe, e noho a e ai iho i ka'u io o ka mea hihiu, i hoomaikai mai kou uhane ia'u.
20 Isaaki tún béèrè pé, “Ọmọ mi, báwo ni ó ṣe tètè yá ọ bẹ́ẹ̀?” Jakọbu sì tún dáhùn pé, “Olúwa Ọlọ́run rẹ ló fún mi pa.”
I mai la o Isaaka i kana keiki, Pehea ka emoole o ka loaa ana o ia mea ia oe, e kuu keiki? I aku la kela, No ka mea, na Iehova na kou Akua i hoohalawai ia mea me au.
21 Nígbà náà ni Isaaki wí fún Jakọbu pé, “Súnmọ́ mi, kí n le è fọwọ́ kàn ọ́, kí n lè mọ̀ bóyá Esau ọmọ mi ni nítòótọ́ tàbí òun kọ́.”
I mai la o Isaaka ia Iakoba, Ke noi aku nei au ia oe, e neenee mai a kokoke, i hana aku au ia oe, e kuu keiki, i ike au o ka'u keiki o Esau paha oe, aole paha.
22 Jakọbu sì súnmọ́ Isaaki baba rẹ̀. Isaaki sì fọwọ́ kàn án, ó sì wí pé, “Ohùn ni ohùn Jakọbu; ṣùgbọ́n ọwọ́ ni ọwọ́ Esau.”
Neenee aku la o Iakoba io Isaaka la i kona makuakane: a hana mai la oia ia ia, i mai la, O ka leo, ka leo no o Iakoba, aka, o na lima, na lima no o Esau.
23 Kò sì dá Jakọbu mọ̀ nítorí ọwọ́ rẹ̀ ní irun bí i ti Esau arákùnrin rẹ, nítorí náà, ó súre fún un
Aole no i ikea oia, no ka mea, ua huluhulu kona mau lima, e like me na lima o kona kaikuaana, o Esau: a hoomaikai mai oia ia ia.
24 ó sì bi í léèrè pé, “Ǹjẹ́ ìwọ ni Esau ọmọ mi ni tòótọ́?” Jakọbu sì dáhùn pé, “Èmi ni.”
Ninau mai la oia ia ia, O oe io no anei o ka'u keiki o Esau? I aku la kela, Owau no.
25 Nígbà náà ni Isaaki wí pé, “Gbé ẹran igbó náà súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi, kí èmi kí ó jẹ ẹ́, kí èmi sì súre fún ọ láti inú ọkàn mi wá.” Jakọbu sì gbé e wá ó sì jẹ ẹ́, ó sì tún fún un ní wáìnì, ó sì mú un pẹ̀lú.
I mai la oia, E lawe mai ia mea a kokoke ia'u, a e ai iho no wau i ka io mea hihiu a kuu keiki, i hoomaikai aku kuu uhane ia oe, Lawe aku la o Iakoba a kokoke, a ai iho la kela: lawe aku la hoi oia i ka waina, a inu iho la kela.
26 Nígbà náà ni Isaaki baba rẹ̀ wí fun un pé, “Súnmọ́ mi, ọmọ mi, kí o sì fẹnukò mí ní ẹnu.”
Olelo mai la kona makuakane o Isaaka ia ia, E hele mai oe a honi ia'u, e kuu keiki.
27 Ó sì súnmọ́ ọn, ó sì fẹnukò ó ní ẹnu. Nígbà tí Isaaki gbọ́ òórùn aṣọ rẹ̀, ó súre fún un ó wí pé, “Wò ó òórùn ọmọ mi dàbí òórùn oko tí Olúwa ti bùkún.
Hele aku la o Iakoba, a honi ae la ia ia: honi iho la o Isaaka i ke ala o kona aahu, hoomaikai mai la ia ia, i mai la, Aia, o ke ala o kuu keiki, ua like me ke ala o ka mahinaai a Iehova i hoomaikai ai:
28 Kí Ọlọ́run kí ó fún ọ nínú ìrì ọ̀run àti nínú ọ̀rá ilẹ̀ àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọkà àti wáìnì tuntun.
E haawi mai ke Akua ia oe i ka hau no ka lani mai, me ka momona o ka honua, a me ka palaoa a me ka waina he nui:
29 Kí àwọn orílẹ̀-èdè kí ó máa sìn ọ́, kí àwọn ènìyàn sì máa tẹríba fún ọ, máa ṣe olórí àwọn arákùnrin rẹ, kí àwọn iyèkan rẹ sì máa wólẹ̀ fún ọ Fífibú ni àwọn ẹni tó fi ọ́ bú, ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ó súre fún ọ.”
E hookauwa mai na kanaka nau, a e moe iho na lahuikanaka imua ou, o lilo oe i haku maluna o kou poe hoahanau, a e moe iho na keiki o kou makuwahine imua ou: e hoinoia'ku na mea a pau e hoino mai ia oe, a e hoopomaikaiia'ku ka mea hoomaikai ia oe.
30 Bí Isaaki ti súre tán tí Jakọbu ṣẹ̀ṣẹ̀ jáde kúrò ní ọ̀dọ̀ baba rẹ̀ ni Esau ti oko ọdẹ dé.
A oki ae la ka hoomaikai ana mai a Isaaka ia Iakoba, aneane hoi ole mai o Iakoba mai ke alo mai o Isaaka o kona makuakane, puka mai la hoi o Esau o kona kaikuaana mai kona imi mea hihiu ana.
31 Òun pẹ̀lú ṣe ẹran dídùn, ó sì gbé e tọ baba rẹ̀ wá, ó sì wí fún un pé, “Baba mi, dìde jókòó, kí o sì jẹ nínú ẹran igbó tí mo ti ṣè, kí o sì súre fún mi.”
Hana no hoi oia i ka mea ono, a lawe mai hoi ia mea i kona makuakane, i aku la ia i kona makuakane, E ala mai oe, e kuu makuakane, a e ai iho i ka io mea hihia a kana keiki, i hoomaikai mai kou uhane ia'u.
32 Isaaki baba rẹ̀ sì bi í wí pé, “Ìwọ ta ni?” Ó sì dáhùn pé, “Èmi Esau, àkọ́bí rẹ ni.”
Ninau mai la o Isaaka o kona makuakane ia ia, Owai oe? I aku la kela, Owau no o kau keiki, o kau makahiapo, o Esau.
33 Nígbà náà ni Isaaki wárìrì gidigidi, ó sì wí pé, “Ta ni ẹni náà, tí ó ti pa ẹran igbó tí ó sì ti gbe wá fún mi, tí mo sì ti jẹ ẹ́ kí ó tó dé? Mo sì ti súre fún un, sì wò ó dájúdájú a ó sì bùkún un!”
Haalulu nui loa iho la o Isaaka, i mai la, Owai? auhea hoi ka mea i kii i ka io mea hihiu, a i lawe mai hoi io'u nei, a ua ai iho nei au a pau, mamua o kou hiki ana mai, a ua hoomaikai au ia ia? Oiaio, oia ke hoomaikaiia.
34 Nígbà tí Esau gbọ́ ọ̀rọ̀ baba rẹ̀, ó ké, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní sọkún kíkorò, ó sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Baba mi súre fún èmi náà, àní fún èmi náà pẹ̀lú.”
A lohe ae la o Esau i ka olelo a kona makuakane, uwe iho la ia me ka uwe nui loa, i aku la ia i kona makuakane, E hoomaikai mai ia'u, ia'u hoi, e kuu makuakane,
35 Ṣùgbọ́n Isaaki wí pé, “Àbúrò rẹ ti fi ẹ̀tàn wá, ó sì ti gba ìbùkún rẹ lọ.”
I mai la kela, Ua hele mai nei kou kaikaina me ka maalea, a ua lawe aku i kou hoomaikaiia,
36 Esau sì wí pé, “Lásán ni a pe orúkọ rẹ̀ ní Jakọbu bí? Ní ìgbà méjì yìí ni ó ti tàn mí jẹ: ní àkọ́kọ́, ó gba ogún ìbí mi, nísinsin yìí, ó tún gba ìbùkún mi!” O sì béèrè pé, “Ṣe o kò wá fi ìre kankan sílẹ̀ fun mi ni?”
I aku la oia, Aole anei i pono ke kapa ana ia ia o Iakoba? no ka mea, eia ka lua o kona kaili ana i ko'u pono: kaili aku la oia i ko ka hanaumua pono o'u; eia hoi, ano, ua kaili ae la oia i ko'u hoomaikaiia. I aku la hoi o Esau, Aole anei oe i malama no'u kekahi hoomaikai ana?
37 Isaaki sì dá Esau lóhùn pé, “Mo ti fi ṣe olórí rẹ àti àwọn ìbátan rẹ ni mo fi ṣe ìránṣẹ́ fún un, àti ọkà àti wáìnì ni mo ti fi lé e lọ́wọ́ lọ́pọ̀lọ́pọ̀, kí ni ó tún kù tí ǹ bá tún fún ọ báyìí ọmọ mi?”
Olelo mai la o Isaaka ia Esau, Aia hoi, ua hoolilo aku au ia ia i haku nou, a ua haawi aku no wau i kona poe hoahanau a pau i poe kauwa nana; ua malama aku hoi au ia ia i ka palaoa a me ka waina: a heaha ka'u e hana aku ai nau, e kuu keiki?
38 Esau sì wí fún baba rẹ̀ pé, “Ṣe ìre kan ṣoṣo ni ìwọ ní lẹ́nu ni baba mi? Súre fún èmi náà, baba mi.” Esau sì sọkún kíkankíkan.
I aku la o Esau i kona makuakane, Hookahi wale no anei au hoomaikai ana, e kuu makuakane? e hoomaikai mai oe ia'u hoi, e kuu makuakane. Hookiekie ae la o Esau i kona leo, a uwe iho la.
39 Isaaki baba rẹ̀ sì dá a lóhùn pé, “Ibùjókòó rẹ yóò jìnnà sí ọ̀rá ilẹ̀, àti sí ibi ìrì ọ̀run láti òkè wá.
Olelo mai la o Isaaka, kona makuakane, i mai la ia ia, Aia hoi, ma ka aina momona kou noho ana, a ma kahi o ka hau o ka lani mai luna iho.
40 Nípa idà rẹ ni ìwọ yóò máa gbé, ìwọ yóò sì máa sin àbúrò rẹ, ṣùgbọ́n ní ìkẹyìn, nígbà tí ìwọ bá di alágbára ìwọ yóò já àjàgà rẹ̀ kúrò lọ́rùn rẹ.”
I kau pahikaua e ola auanei oe, a e hookauwa aku oe na kou kaikaina: a i ka manawa e loaa'i ia oe ke alii ana, alaila e haihai iho oe i kana anamo ma kou a-i.
41 Esau sì kórìíra Jakọbu nítorí ìre tí baba rẹ̀ sú fún un, ó sì wí fún ara rẹ̀ pé, “Baba mi sá à ti fẹ́rẹ kú, nígbà náà ni èmi ó pa Jakọbu, arákùnrin mi.”
Inaina aku la o Esau ia Iakoba, no ka hoomaikai ana a kona makuakane i hoomaikai aku ai ia ia: i iho la o Esau iloko o kona naau, Ua kokoke mai na la e kanikau ai i kuu makuakane; alaila au e pepehi ai i kuu kaikaina ia Iakoba.
42 Nígbà tí Rebeka sì gbọ́ ohun tí Esau àkọ́bí rẹ̀ wí, ó sì ránṣẹ́ sí Jakọbu, ó sì wí fun un pé, “Esau ẹ̀gbọ́n rẹ ń tu ara rẹ̀ nínú pẹ̀lú èrò à ti pa ọ́.
Ua haiia'ku keia olelo ana a Esau ia Rebeka: hoouna aku la ia e hea ia Iakoba i kana keiki muli iho, i aku la ia ia, Aia hoi, o kou kaikuaana o Esau, e hooluolu ana oia ia ia iho nou, e pepehi iho ia oe.
43 Nítorí náà ọmọ mi, ṣe ohun tí èmi yóò sọ fún ọ, sálọ sọ́dọ̀ Labani ẹ̀gbọ́n mi ní Harani.
Ano hoi, e kuu keiki, e hoolohe mai oe i kuu lee; e ku ae oe, e holo aku io Labana la, i kuu kaikunane ma Harana:
44 Jókòó sí ibẹ̀ títí di ìgbà tí ìbínú ẹ̀gbọ́n rẹ yóò fi rọ̀.
E noho me ia i kekahi mau la, a huli ae ka inaina o kou kaikuaana mai ou aku la;
45 Nígbà tí ẹ̀gbọ́n rẹ kò bá bínú sí ọ mọ́, tí ó sì ti gbàgbé ohun tí ìwọ ṣe sí i, èmí ó ránṣẹ́ sí ọ láti padà wá. Èéṣe tí èmi ó fi pàdánù ẹ̀yin méjèèjì ní ọjọ́ kan náà?”
A huli ae ka inaina o kou kaikuaana mai ou aku la, a poina ia ia kau mea i hana aku ai ia ia: alaila e hoouna aku no wau e hoihoi mai ia oe: no ke aha la e hooneleia mai au ia olua a elua i ka la hookahi?
46 Nígbà náà ni Rebeka wí fún Isaaki pé, “Ayé sì sú mi nítorí àwọn ọmọbìnrin Hiti wọ̀nyí. Bí Jakọbu bá fẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọmọbìnrin Hiti wọ̀nyí, ó kúkú sàn kí n má wà láààyè.”
Olelo aku la o Rebeka ia Isaaka, Ua pauaho no wau i kuu ola ana, no na kaikamahine a ka Heta: ina e lawe o Iakoba i kekahi kaikamahine a ka Heta i wahine nana, e like me na kaikamahine o ka aina, pehea la wau e pono ai i kuu ola aua?

< Genesis 27 >