< Genesis 20 >

1 Abrahamu sì kó kúrò níbẹ̀ lọ sí ìhà gúúsù ó sì ń gbé ní agbede-méjì Kadeṣi àti Ṣuri; ó sì gbé ní ìlú Gerari fún ìgbà díẹ̀.
Och Abraham bröt upp därifrån och drog till Sydlandet; där uppehöll han sig mellan Kades och Sur, och någon tid bodde han i Gerar.
2 Abrahamu sì sọ ní ti Sara aya rẹ̀ níbẹ̀ pé, “Arábìnrin mi ni.” Abimeleki ọba Gerari sì ránṣẹ́ mú Sara wá sí ààfin rẹ̀.
Och Abraham sade om sin hustru Sara att hon var hans syster. Då sände Abimelek, konungen i Gerar, och lät hämta Sara till sig.
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tọ Abimeleki wá ní ojú àlá lọ́jọ́ kan, ó sì wí fún un pé, “Kíyèsi, kò sí ohun tí o fi sàn ju òkú lọ, nítorí obìnrin tí ìwọ mú sọ́dọ̀ n nì, aya ẹni kan ní íṣe.”
Men Gud kom till Abimelek i en dröm om natten och sade till honom: "Se, du måste dö för den kvinnas skull som du har tagit till dig, fast hon är en annan mans äkta hustru."
4 Ṣùgbọ́n Abimeleki kò tí ìbá obìnrin náà lòpọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀-èdè aláìlẹ́bi bí?
Men Abimelek hade icke kommit vid henne. Och han svarade: "Herre, vill du då dräpa också rättfärdiga människor?
5 Ǹjẹ́ òun kò sọ fún mi pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ obìnrin náà pẹ̀lú sì sọ pé, ‘Arákùnrin mí ni’? Ní òtítọ́ pẹ̀lú ọkàn mímọ́ àti ọwọ́ mímọ́, ni mo ṣe èyí.”
Sade han icke själv till mig: 'Hon är min syster'? Och likaså sade hon: 'Han är min broder.' I mitt hjärtas oskuld och med rena händer har jag gjort detta."
6 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un nínú àlá náà pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ pé pẹ̀lú òtítọ́ inú ni ìwọ ṣe èyí, èyí ni mo fi pa ọ́ mọ́ tí ń kò jẹ́ kí o ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyí tí n kò fi jẹ́ kí o ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin náà.
Då sade Gud till honom i drömmen: "Ja, jag vet att du har gjort detta i ditt hjärtas oskuld, och jag har själv hindrat dig från att synda mot mig; därför har jag icke tillstatt dig att komma vid henne.
7 Nísinsin yìí, dá aya ọkùnrin náà padà, nítorí pé wòlíì ni, yóò sì gbàdúrà fún ọ, ìwọ yóò sì yè. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá dá a padà, mọ̀ dájú pé ìwọ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tìrẹ yóò kú.”
Men giv nu mannen hans hustru tillbaka; ty han är en profet. Och han må bedja för dig, så att du får leva. Men om du icke giver henne tillbaka, så vet att du skall döden dö, du själv och alla som tillhöra dig.
8 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, Abimeleki pe gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀. Nígbà tí ó sì sọ gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún wọn, ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.
Då stod Abimelek upp bittida om morgonen och kallade till sig alla sina tjänare och berättade allt detta för dem; och männen blevo mycket förskräckta.
9 Nígbà náà ni Abimeleki pe Abrahamu ó sì wí fún un pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ́ tí ìwọ fi mú ìdálẹ́bi ńlá wá sí orí èmi àti ìjọba mi? Kò yẹ kí ìwọ hu irú ìwà yìí sí mi.”
Sedan kallade Abimelek Abraham till sig och sade till honom: "Vad har du gjort mot oss! Vari har jag försyndat mig mot dig, eftersom du har velat komma mig och mitt rike att begå en så stor synd? På otillbörligt sätt har du handlat mot mig."
10 Abimeleki sì bi Abrahamu pé, “Kín ló dé tí ìwọ fi ṣe èyí?”
Och Abimelek sade ytterligare till Abraham: "Vad var din mening, när du gjorde detta?"
11 Abrahamu sì dáhùn pé, “Mo ṣe èyí nítorí mo rò nínú ara mi pé, ẹ̀yin tí ẹ wà níhìn-ín, ẹ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, pé, ẹ sì le pa mí nítorí aya mi.
Abraham svarade: "Jag tänkte: 'På denna ort fruktar man nog icke Gud; de skola dräpa mig för min hustrus skull.'
12 Yàtọ̀ fún ìyẹn, òtítọ́ ni pé arábìnrin mi ni. Ọmọ baba kan ni wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, a kì í ṣe ọmọ ìyá kan. Mo sì fẹ́ ẹ ní aya.
Hon är också verkligen min syster, min faders dotter, fastän icke min moders dotter; och så blev hon min hustru.
13 Nígbà tí Ọlọ́run sì mú mi rìn kiri kúrò ní ilé baba mi, mo wí fún un pé, ‘Èyí ni ọ̀nà tí ó lè gbà fihàn pé ó fẹ́ràn mi. Gbogbo ibi tí a bá dé máa sọ pé, “Arákùnrin rẹ ni mí.”’”
Men när Gud sände mig ut på vandring bort ifrån min faders hus, sade jag till henne: 'Bevisa mig din kärlek därmed att du säger om mig, varthelst vi komma, att jag är din broder.'"
14 Nígbà náà ni Abimeleki mú àgùntàn àti màlúù wá, àti ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ó sì kó wọn fún Abrahamu, ó sì dá Sara aya rẹ̀ padà fún un.
Då tog Abimelek får och fäkreatur, tjänare och tjänarinnor och gav dem åt Abraham. Han gav honom ock hans hustru Sara tillbaka.
15 Abimeleki sì tún wí fún un pé, “Gbogbo ilẹ̀ mí nìyí níwájú rẹ, máa gbé ní ibikíbi tí o fẹ́ níbẹ̀.”
Och Abimelek sade: "Se, mitt land ligger öppet för dig; du må bo var du finner för gott."
16 Abimeleki sì wí fún Sara pé, “Mo fi ẹgbẹ̀rún owó ẹyọ fàdákà fún arákùnrin rẹ. Èyí ni owó ìtánràn ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ níwájú gbogbo ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ àti pé, a dá ọ láre pátápátá.”
Och till Sara sade han: "Se, jag giver åt din broder tusen siklar silver; det skall för dig vara en försoningsgåva inför allt ditt folk. Så har du inför alla fått upprättelse."
17 Nígbà náà, Abrahamu gbàdúrà sí Ọlọ́run, Ọlọ́run sì wo Abimeleki àti aya rẹ̀ àti àwọn ẹrúbìnrin rẹ̀ sàn. Wọ́n sì tún ń bímọ,
Och Abraham bad till Gud, och Gud botade Abimelek och hans hustru och hans tjänstekvinnor, så att de åter kunde föda barn.
18 nítorí Olúwa ti sé gbogbo ará ilé Abimeleki nínú nítorí Sara aya Abrahamu.
HERREN hade nämligen gjort alla kvinnor i Abimeleks hus ofruktsamma, för Saras, Abrahams hustrus, skull.

< Genesis 20 >