< Genesis 19 >

1 Ní àṣálẹ́, àwọn angẹli méjì sì wá sí ìlú Sodomu, Lọti sì jókòó ní ẹnu ibodè ìlú. Bí ó sì ti rí wọn, ó sì dìde láti pàdé wọn, ó kí wọn, ó sì foríbalẹ̀ fún wọn.
Un tie divi eņģeļi vakarā nonāca Sodomā, un Lats sēdēja Sodomas vārtos. Un tos ieraudzījis Lats cēlās un gāja tiem pretī un nometās uz savu vaigu pie zemes
2 Ó wí pé, “Ẹ̀yin olúwa mi, èmi bẹ̀ yín, ẹ yà sí ilé ìránṣẹ́ yín kí ẹ sì wẹ ẹsẹ̀ yín, kí n sì gbà yín lálejò, ẹ̀yin ó sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ láti máa bá ìrìnàjò yín lọ.” Wọ́n sì wí pé, “Rárá o, àwa yóò dúró ní ìgboro ní òru òní.”
Un sacīja: redzi, mani kungi, ņemiet lūdzami mājas vietu pie sava kalpa un palieciet šo nakti un mazgājiet savas kājas; tad rītā cēlušies varat iet savu ceļu. Un tie sacīja: nē, bet mēs gribam palikt pa nakti uz ielas.
3 Ṣùgbọ́n Lọti rọ̀ wọ́n gidigidi tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n gbà láti bá a lọ sì ilé. Ó sì ṣe àsè fún wọn, ó sì dín àkàrà aláìwú fún wọ́n, wọ́n sì jẹ.
Bet viņš tos lūgdams lūdza, lai tie pie viņa mājotu; un tie iegāja viņa namā, un viņš tiem taisīja mielastu, cepdams neraudzētas karašas, un tie ēda.
4 Ṣùgbọ́n kí ó tó di pé wọ́n lọ sùn, àwọn ọkùnrin ìlú Sodomu tọmọdé tàgbà yí ilé náà ká.
Pirms ne kā tie apgūlās, Sodomas pilsētas ļaudis apstāja to namu, jauni un veci, viss tas pulks no visām malām,
5 Wọ́n pe Lọti pé, “Àwọn ọkùnrin tí ó wọ̀ sí ilé rẹ lálẹ́ yìí ń kọ́? Mú wọn jáde fún wa, kí a le ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú wọn.”
Un aicināja Latu un sacīja uz to: kur tie vīri, kas šo nakti pie tevis nākuši? Izved tos pie mums ārā, ka tos atzīstam.
6 Lọti sì jáde láti pàdé wọn, ó sì ti ìlẹ̀kùn lẹ́yìn rẹ̀ bí ó ti jáde.
Tad Lats izgāja pie tiem ārā priekš durvīm, un aizslēdza durvis aiz sevis un sacīja:
7 Ó sì wí pé, “Rárá, ẹ̀yin ará mi, ẹ má ṣe ṣe ohun búburú yìí,
Brāļi, nedariet jel tādu grēku.
8 kíyèsi i, mo ní ọmọbìnrin méjì tí kò mọ ọkùnrin rí, ẹ jẹ́ kí n mú wọn tọ̀ yín wá kí ẹ sì ṣe ohun tí ẹ fẹ́ pẹ̀lú wọn. Ṣùgbọ́n ẹ má ṣe ṣe àwọn ọkùnrin wọ̀nyí ní ibi kan nítorí wọ́n wá wọ̀ lábẹ́ ààbò ní ilé mi.”
Redziet, man ir divas meitas, kas nav atzinušas vīra, tās izvedīšu pie jums, un dariet ar tām, kā patīk, - tikai šiem vīriem nedariet nekā, jo tāpēc tie nākuši mana jumta pavēnī.
9 Wọ́n sì wí fún pé, “Bì sẹ́yìn fún wa. Èyí yìí wá ṣe àtìpó láàrín wa, òun sì fẹ́ ṣe onídàájọ́! Aburú tí a ó fi ṣe ọ́ yóò pọ̀ ju tí wọn lọ.” Wọn rọ́ lu Lọti, wọ́n sì súnmọ́ ọn láti fọ́ ìlẹ̀kùn.
Tad tie sacīja: atkāpies nost! Un tie sacīja: šis viens ir atnācis kā svešinieks un grib valdīt? Nu tev vairāk ļauna darīsim nekā viņiem.
10 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà nawọ́ fa Lọti wọlé, wọ́n sì ti ìlẹ̀kùn.
Un mākdamies tie mācās virsū tam vīram, Latam, un nāca durvis uzlauzt. Bet tie vīri izstiepa ārā savu roku un ierāva Latu pie sevis namā un aizslēdza durvis,
11 Wọ́n sì bu ìfọ́jú lu àwọn ọkùnrin tí ó wà ní ẹnu-ọ̀nà ilé náà, àti èwe àti àgbà: wọ́n kò sì rí ẹnu-ọ̀nà mọ́.
Un apstulboja tos ļaudis priekš nama durvīm, mazos un lielos, tā ka tie piekusa pēc durvīm grābstīdamies.
12 Àwọn ọkùnrin náà sì wí fún Lọti pé, “Ǹjẹ́ ó ní ẹlòmíràn ní ìlú yìí bí? Àna rẹ ọkùnrin, àwọn ọmọ rẹ lọ́kùnrin àti lóbìnrin, tàbí ẹnikẹ́ni tí ìwọ ní ní ìlú yìí, kó wọn jáde kúrò ní ibí yìí,
Tad tie vīri sacīja uz Latu: vai tev še vēl kāds znots vai dēli vai meitas vai cits kāds, kas tev pieder šai pilsētā, - izved tos no šās vietas.
13 nítorí a ó pa ìlú yìí run, nítorí igbe iṣẹ́ búburú wọn ń dí púpọ̀ níwájú Olúwa, Olúwa sì rán wa láti pa á run.”
Jo mēs samaitāsim šo vietu, tāpēc ka tā brēkšana par viņu ir liela Tā Kunga priekšā, un Tas Kungs mūs ir sūtījis to samaitāt.
14 Nígbà náà ni Lọti jáde, ó sì wí fún àwọn àna rẹ̀ ọkùnrin tí ó ti bá jẹ́ ẹ̀jẹ́ láti fẹ́ àwọn ọmọ rẹ̀ pé, “Ẹ ṣe kánkán, kí ẹ jáde ní ìlú yìí, nítorí Olúwa fẹ́ pa ìlú yìí run!” Ṣùgbọ́n àwọn ọkọ ọmọ rẹ̀ wọ̀nyí rò pé àwàdà ló ń ṣe.
Un Lats izgāja un runāja uz saviem znotiem, kas viņa meitas gribēja apņemt, un sacīja: ceļaties un ejat ārā no šās vietas, jo Tas Kungs samaitās šo pilsētu. Bet tiem znotiem viņš izlikās tā kā smieklus runājot.
15 Ní àfẹ̀mọ́júmọ́, àwọn angẹli náà rọ Lọti pé, “Ṣe wéré, mú aya rẹ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ méjèèjì tí ó wà níhìn-ín, àìṣe bẹ́ẹ̀, ìwọ yóò parun pẹ̀lú ìlú yìí nígbà tí wọ́n bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.”
Un kad gaisma ausa, tad tie eņģeļi Latu skubināja sacīdami: celies, ņem savu sievu un savas divas meitas, kas tev ir, ka tu neietu bojā šīs pilsētas noziegumā.
16 Nígbà tí ó ń jáfara, àwọn ọkùnrin náà nawọ́ mú un lọ́wọ́, wọ́n sì nawọ́ mú aya rẹ̀ náà lọ́wọ́ àti àwọn ọmọbìnrin rẹ̀ méjèèjì, wọ́n sì mú wọn jáde sẹ́yìn odi ìlú, nítorí Olúwa ṣàánú fún wọn.
Bet viņš kavējās; un tie vīri satvēra viņa roku un viņa sievas roku un viņa divēju meitu roku, tāpēc ka Tas Kungs viņu žēloja, un tie to izveda un to palaida ārpus pilsētas.
17 Ní kété tí wọ́n mú wọn jáde sẹ́yìn odi tán, ọ̀kan nínú wọn wí pé, “Sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ! Má ṣe wo ẹ̀yìn rẹ, bẹ́ẹ̀ ni kí ìwọ kí ó má ṣe dúró ní gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀! Sá àsálà lọ sí orí òkè, kí ìwọ ó má ba ṣègbé!”
Un kad tie tos bija izveduši ārā, tad viņš sacīja: Izglāb jel savu dzīvību, neskaties atpakaļ un nestāvi nekur šinī klajumā; glābies kalnā, ka neej bojā.
18 Ṣùgbọ́n Lọti wí fún wọn pé, “Rárá, ẹ̀yin Olúwa mi, ẹ jọ̀wọ́!
Un Lats sacīja uz tiem: ak nē, Kungs!
19 Nígbà tí ìránṣẹ́ rẹ ti rí ojúrere rẹ, tí o sì ti fi àánú rẹ hàn nípa gbígba ẹ̀mí mi là, èmi kò le è sálọ sórí òkè, kí búburú yìí má ba à lé mi bá, kí n sì kú.
Redzi jel, tavs kalps ir atradis žēlastību tavās acīs, un varen liela ir tava žēlošana, ko tu man esi darījis, izglābdams manu dzīvību; bet es nespēju glābties kalna galā, lai man ļaunums neuznāk un es nemirstu.
20 Wò ó, ìlú kékeré kan nìyí ní tòsí láti sá sí: jẹ́ kí n sálọ síbẹ̀, ìlú kékeré ha kọ́? Ẹ̀mí mi yóò sì yè.”
Redzi jel, šī pilsēta ir tuvu klāt, uz turieni bēgt, un tā ir maza; tur es gribu glābties, - vai tā nav maza? - Ka es palieku dzīvs.
21 Ó sì wí fún un pé, “Ó dára, mo gba ẹ̀bẹ̀ rẹ. Èmi kì yóò run ìlú náà tí ìwọ sọ̀rọ̀ rẹ̀.
Un viņš uz to sacīja: redzi, arī šinī lietā es tevi esmu uzlūkojis, ka es nesamaitāšu to pilsētu, par ko tu esi runājis.
22 Tètè! Sálọ síbẹ̀, nítorí èmi kò le ṣe ohun kan àyàfi tí ó bá dé ibẹ̀.” (ìdí nìyí tí a fi ń pe ìlú náà ní Soari).
Steidzies, glābies turp, jo es nekā nevaru darīt, tiekams tu uz turieni neesi nonācis. Tādēļ tās pilsētas vārdu sauc Coāru (t.i. maza).
23 Nígbà tí Lọti yóò fi dé ìlú Soari, oòrùn ti yọ.
Saule uzlēca pār zemi, kad Lats nonāca Coārā.
24 Nígbà náà ni Olúwa rọ̀jò iná àti sulfuru sórí Sodomu àti Gomorra láti ọ̀run lọ́dọ̀ Olúwa wá.
Un Tas Kungs lika līt sēram un ugunij uz Sodomu un Gomoru no Tā Kunga, no debesīm.
25 Báyìí ni ó run àwọn ìlú náà àti gbogbo ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó wà ní ìlú ńlá ńlá wọ̀n-ọn-nì àti ohun gbogbo tí ó hù jáde nílẹ̀.
Un viņš izpostīja tās pilsētas un visu to apgabalu un visus to pilsētu iedzīvotājus, ir zemes augļus.
26 Ṣùgbọ́n aya Lọti bojú wo ẹ̀yìn, ó sì di ọ̀wọ́n iyọ̀.
Un viņa sieva skatījās atpakaļ un palika par sālsstabu.
27 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Abrahamu sì dìde ó sì padà lọ sí ibi tí ó gbé dúró níwájú Olúwa.
Un Ābraams cēlās it agri uz to vietu, kur viņš bija stāvējis priekš Tā Kunga vaiga,
28 Ó sì wo ìhà Sodomu àti Gomorra àti àwọn ilẹ̀ pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀n-ọn-nì, ó sì rí èéfín tí ń ti ibẹ̀ jáde bí èéfín iná ìléru.
Un skatījās uz Sodomas un Gomoras pusi un uz visu to apgabalu, un redzi, dūmi cēlās no zemes, tā kā kāda cepļa dūmi.
29 Ọlọ́run sì rántí Abrahamu, nígbà tí ó run ìlú pẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ̀n-ọn-nì tan, ó sì mú Lọti jáde kúrò láàrín ìparun náà, tí ó kọlu ìlú tí Lọti ti gbé.
Un notikās, kad Dievs šī apgabala pilsētas samaitāja, tad viņš pieminēja Ābrahāmu un izveda Latu no tā posta, kad viņš tās pilsētas izpostīja, kur Lats mita.
30 Lọti àti àwọn ọmọ rẹ̀ obìnrin méjèèjì sì kúrò ní Soari, wọ́n sì ń lọ gbé ní orí òkè ní inú ihò àpáta, nítorí ó bẹ̀rù láti gbé ní ìlú Soari.
Un Lats gāja no Coāras uz augšu un mita kalnos, un viņa divas meitas līdz ar viņu; jo viņam bija bail Coārā mist; un viņš dzīvoja kādā alā līdz ar savām abām meitām.
31 Ní ọjọ́ kan, èyí ẹ̀gbọ́n sọ fún àbúrò rẹ̀ pé, “Baba wa ti dàgbà, kò sì sí ọkùnrin kankan ní agbègbè yìí tí ìbá bá wa lòpọ̀, bí ìṣe gbogbo ayé.
Un tā pirmdzimušā sacīja uz to jaunāko: mūsu tēvs ir vecs, un vīra nav virs zemes, kas pie mums nāktu pēc visas pasaules ieraduma.
32 Wá, jẹ́ kí a mú baba wa mu ọtí yó, kí ó ba à le bá wa lòpọ̀, kí àwa kí ó lè bí ọmọ, kí ìran wa má ba à parẹ́.”
Nāc, dosim savam tēvam vīnu dzert un gulēsim pie tā un paturēsim dzīvu dzimumu no sava tēva.
33 Ní òru ọjọ́ náà, wọ́n rọ baba wọn ní ọtí yó. Èyí ẹ̀gbọ́n sì wọlé tọ̀ ọ́, ó sì bá a lòpọ̀, baba wọn kò mọ̀ ìgbà tí ó sùn ti òun àti ìgbà tí ó dìde.
Un tās deva savam tēvam vīnu dzert tanī naktī, un tā pirmdzimušā nāca un gulēja pie sava tēva, un viņš to nenomanīja, kad tā apgūlās, nedz kad tā cēlās.
34 Ní ọjọ́ kejì èyí ẹ̀gbọ́n wí fún àbúrò rẹ̀ pé, “Ní àná mo sùn ti baba mi. Jẹ́ kí a tún wọlé tọ̀ ọ́, kí a lè ní irú-ọmọ láti ọ̀dọ̀ baba wa.”
Un no rīta tā pirmdzimušā sacīja uz to jaunāko: redzi, izgājušo nakti es esmu gulējusi pie sava tēva; dosim viņam arī šo nakti vīnu dzert, tad ieej tu un guli pie tā, ka dzimumu gādājam no sava tēva.
35 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n tún fún baba wọn ní ọtí mu yó ni alẹ́ ọjọ́ náà, èyí àbúrò náà sì wọlé tọ̀ ọ́ lọ, ó sì bá a lòpọ̀, kò sì tún mọ ìgbà tí ó wọlé sùn ti òun tàbí ìgbà tí ó dìde.
Un tās arī tanī naktī deva savam tēvam vīnu dzert, un tā jaunākā cēlās un gulēja pie tā, un tas nenomanīja, kad tā apgūlās, nedz kad tā cēlās.
36 Àwọn ọmọbìnrin Lọti méjèèjì sì lóyún fún baba wọn.
Un Lata abas meitas tapa grūtas no sava tēva.
37 Èyí ẹ̀gbọ́n sì bí ọmọkùnrin, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Moabu. Òun ni baba ńlá àwọn ará Moabu lónìí.
Un tā pirmdzimušā dzemdēja dēlu un nosauca viņa vārdu Moabs, šis ir Moabiešu tēvs līdz šai dienai.
38 Èyí àbúrò náà sì bí ọmọkùnrin, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Bene-Ami. Òun ni baba ńlá àwọn ará Ammoni lónìí.
Un tā jaunākā dzemdēja arī dēlu un nosauca viņa vārdu Ben-Ammi: šis ir Amona bērnu tēvs līdz šai dienai.

< Genesis 19 >