< Genesis 11 >

1 Lẹ́yìn náà, gbogbo àgbáyé sì ń sọ èdè kan ṣoṣo.
E era toda a terra de uma mesma língua, e de uma mesma fala.
2 Bí àwọn ènìyàn ṣe ń tẹ̀síwájú lọ sí ìhà ìlà-oòrùn, wọ́n rí pẹ̀tẹ́lẹ̀ kan ní ilẹ̀ Ṣinari, wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
E aconteceu que, partindo eles do Oriente, acharam um vale na terra de Shinar; e habitaram ali.
3 Wọ́n sì wí fún ara wọn pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a mọ bíríkì kí a sì sún wọ́n jìnà.” Bíríkì ni wọ́n ń lò ní ipò òkúta, àti ọ̀dà ilẹ̀ tí wọn ń lò láti mú wọn papọ̀ dípò ẹfun (òkúta láìmù tí wọ́n fi ń ṣe símẹ́ńtì àti omi).
E disseram uns aos outros: Eia, façamos tijolos, e queimê-mo-los bem. E foi-lhes o tijolo por pedra, e o betume por cal.
4 Nígbà náà ni wọ́n wí pé, “Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a tẹ ìlú kan dó fún ara wa, kí a sì kọ́ ilé ìṣọ́ kan tí yóò kan ọ̀run, kí a ba à lè ní orúkọ, kí a má sì tú káàkiri sórí gbogbo ilẹ̀ ayé.”
E disseram: Eia, edifiquemos nós uma cidade e uma torre cujo cume toque nos céus, e façamo-nos um nome, para que não sejamos espalhados sobre a face de toda a terra.
5 Ṣùgbọ́n, Olúwa sọ̀kalẹ̀ láti wo ìlú àti ilé ìṣọ́ tí àwọn ènìyàn náà ń kọ́.
Então desceu o Senhor para ver a cidade e a torre que os filhos dos homens edificavam;
6 Olúwa wí pé, “Bí àwọn ènìyàn bá ń jẹ́ ọ̀kan àti èdè kan tí wọ́n sì bẹ̀rẹ̀ sí í ṣe iṣẹ́ yìí, kò sí ohun tí wọ́n gbèrò tí wọn kò ní le ṣe yọrí.
E disse. Eis que o povo é um, e todos tem uma mesma língua; e isto é o que começam a fazer: e agora, não haverá restrição para tudo o que eles intentarem fazer?
7 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a sọ̀kalẹ̀ lọ, kí a da èdè wọn rú kí èdè wọn má ba à yé ara wọn mọ́.”
Eia, desçamos, e confundamos ali a sua língua, para que não entenda um a língua do outro.
8 Olúwa sì tú wọn ká sórí ilẹ̀ gbogbo, wọ́n sì ṣíwọ́ ìlú náà tí wọn ń tẹ̀dó.
Assim o Senhor os espalhou dali sobre a face de toda a terra: e cessaram de edificar a cidade.
9 Ìdí èyí ni a fi pè é ní Babeli nítorí ní ibẹ̀ ni Olúwa ti da èdè gbogbo ayé rú. Olúwa tí sì tú àwọn ènìyàn ká sí gbogbo orí ilẹ̀ ayé.
Por isso se chamou o seu nome Babel, porquanto ali confundiu o Senhor a língua de toda a terra, e dali os espalhou o Senhor sobre a face de toda a terra.
10 Wọ̀nyí ni ìran Ṣemu. Ọdún méjì lẹ́yìn ìkún omi, tí Ṣemu pé ọgọ́rùn-ún ọdún ni ó bí Arfakṣadi.
Estas são as gerações de Sem: Sem era da idade de cem anos, e gerou a Arpachshad, dois anos depois do dilúvio.
11 Lẹ́yìn tí ó bí Arfakṣadi, Ṣemu tún wà láààyè fún ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọdún, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
E viveu Sem, depois que gerou a Arpachshad, quinhentos anos; e gerou filhos e filhas.
12 Nígbà tí Arfakṣadi pé ọdún márùndínlógójì ni ó bí Ṣela.
E viveu Arpachshad trinta e cinco anos, e gerou a Selah.
13 Arfakṣadi sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó lẹ́yìn tí ó bí Ṣela, ó sì bí àwọn ọmọbìnrin àti àwọn ọmọkùnrin mìíràn.
E viveu Arpachshad depois que gerou a Selah, quatrocentos e três anos; e gerou filhos e filhas.
14 Nígbà tí Ṣela pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Eberi.
E viveu Selah, trinta anos, e gerou a Eber:
15 Ṣela sì wà láààyè fún ọdún mẹ́tàlénírinwó lẹ́yìn tí ó bí Eberi tán, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
E viveu Selah, depois que gerou a Eber, quatrocentos e três anos, e gerou filhos e filhas.
16 Eberi sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́rìnlélọ́gbọ̀n, ó sì bí Pelegi.
E viveu Eber trinta e quatro anos e gerou a Peleg:
17 Eberi sì wà láààyè fún irinwó ọdún ó lé ọgbọ̀n lẹ́yìn tí ó bí Pelegi, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
E viveu Eber, depois que gerou a Peleg, quatrocentos e trinta anos, e gerou filhos e filhas.
18 Nígbà tí Pelegi pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Reu.
E viveu Peleg trinta anos, e gerou a Rehu:
19 Pelegi sì tún wà láààyè fún igba ọdún ó lé mẹ́sàn-án lẹ́yìn tí ó bí Reu, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
E viveu Peleg, depois que gerou a Rehu, duzentos e nove anos, e gerou filhos e filhas.
20 Nígbà tí Reu pé ọdún méjìlélọ́gbọ̀n ni ó bí Serugu.
E viveu Rehu, trinta e dois anos, e gerou a Serug:
21 Reu tún wà láààyè lẹ́yìn tí ó bí Serugu fún igba ọdún ó lé méje, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin mìíràn.
E viveu Rehu, depois que gerou a Serug, duzentos e sete anos e gerou filhos e filhas.
22 Nígbà tí Serugu pé ọmọ ọgbọ̀n ọdún ni ó bí Nahori.
E viveu Serug trinta anos, e gerou a Nahor:
23 Serugu sì wà láààyè fún igba ọdún lẹ́yìn tí ó bí Nahori, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
E viveu Serug, depois que gerou a Nahor, duzentos anos, e gerou filhos e filhas.
24 Nígbà tí Nahori pé ọmọ ọdún mọ́kàndínlọ́gbọ̀n, ó bí Tẹra.
E viveu Nahor vinte e nove anos, e gerou a Terah:
25 Nahori sì wà láààyè fún ọdún mọ́kàn dín lọ́gọ́fà lẹ́yìn ìbí Tẹra, ó sì bí àwọn ọmọkùnrin àti àwọn ọmọbìnrin mìíràn.
E viveu Nahor, depois que gerou a Terah, cento e dezenove anos, e gerou filhos e filhas.
26 Lẹ́yìn tí Tẹra pé ọmọ àádọ́rin ọdún ó bí Abramu, Nahori àti Harani.
E viveu Terah, setenta anos, e gerou a Abrão, a Nahor, e a Haran.
27 Wọ̀nyí ni ìran Tẹra. Tẹra ni baba Abramu, Nahori àti Harani. Harani sì bí Lọti.
E estas são as gerações de Terah: Terah gerou a Abrão, a Nahor, e a Haran: e Haran gerou a Lot
28 Harani sì kú ṣáájú Tẹra baba rẹ̀ ní ilẹ̀ ìbí rẹ̀ ní Uri ti ilẹ̀ Kaldea.
E morreu Haran estando seu pai Terah, ainda vivo, na terra do seu nascimento, em Ur dos caldeus.
29 Abramu àti Nahori sì gbéyàwó. Orúkọ aya Abramu ni Sarai, nígbà tí aya Nahori ń jẹ́ Milka, tí ṣe ọmọ Harani. Harani ni ó bí Milka àti Iska.
E tomaram Abrão e Nahor mulheres para si: o nome da mulher de Abrão era Sarai, e o nome da mulher de Nahor era Milcah, filha de Haran, pai de Milcah, e pai de Iscah.
30 Sarai sì yàgàn, kò sì bímọ.
E Sarai foi estéril, e não tinha filhos.
31 Tẹra sì mú ọmọ rẹ̀ Abramu àti Lọti ọmọ Harani, ọmọ ọmọ rẹ̀, ó sì mú Sarai tí i ṣe aya ọmọ rẹ̀. Abramu pẹ̀lú gbogbo wọn sì jáde kúrò ní Uri ti Kaldea láti lọ sí ilẹ̀ Kenaani. Ṣùgbọ́n nígbà tí wọn dé Harani wọ́n tẹ̀dó síbẹ̀.
E tomou Terah a Abrão seu filho, e a Lot filho de Haran, filho de seu filho, e a Sarai sua nora, mulher de seu filho Abrão, e saiu com eles de Ur dos caldeus, para ir à terra de Canaan; e vieram até Haran, e habitaram ali
32 Nígbà tí Tẹra pé ọmọ igba ọdún ó lé márùn-ún ni ó kú ní Harani.
E foram os dias de Terah duzentos e cinco anos: e morreu Terah em Haran.

< Genesis 11 >