< Ezra 2 >

1 Lákòókò náà, wọ̀nyí ni àwọn ènìyàn agbègbè Juda tí ó gòkè wá láti ìgbèkùn láàrín àwọn tí a kó lọ, ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli ti fi agbára mú ní ìgbèkùn lọ sí Babeli (wọ́n padà sí Jerusalẹmu àti Juda, olúkúlùkù sí ìlú rẹ̀.
Or ce sont ici ceux de la province qui remontèrent de la captivité, d'entre ceux qui avaient été transportés, que Nébucadnetsar Roi de Babylone avait transportés à Babylone, et qui retournèrent à Jérusalem, et en Judée; chacun en sa ville;
2 Àwọn wọ̀nyí bá Serubbabeli, Jeṣua, Nehemiah, Seraiah, Reelaiah, Mordekai, Bilṣani, Mispari, Bigfai, Rehumu àti Baanah wá). Iye àwọn ọkùnrin àwọn ènìyàn Israẹli.
Qui vinrent avec Zorobabel, Jésuah, Néhémie, Séraja, Réhélaja, Mardochée, Bilsan, Mispar, Bigvaï, Réhun, et Bahana; le nombre, [dis-je], des hommes du peuple d'Israël fut [le suivant];
3 Àwọn ọmọ Paroṣi jẹ́ ẹgbàá ó lé méjìléláàádọ́sàn-án
Les enfants de Parrhos, deux mille cent soixante et douze.
4 Ṣefatia jẹ́ òjìdínnírinwó ó lé méjìlá
Les enfants de Séphatia, trois cent soixante et douze.
5 Arah jẹ́ ẹgbẹ̀rin ó dín mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n
Les enfants d'Arah, sept cent soixante et quinze.
6 Pahati-Moabu (láti ipasẹ̀ àwọn ọmọ Jeṣua àti Joabu) jẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì àti ẹgbẹ̀rin lé méjìlá
Les enfants de Pahath-Moab, des enfants de Jésuah, [et] de Joab, deux mille huit cent et douze.
7 Elamu jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀fà ó lé mẹ́rin
Les enfants de Hélam, mille deux cent cinquante-quatre.
8 Sattu jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rún ó lé márùn-ún
Les enfants de Zattu, neuf cent quarante-cinq.
9 Sakkai jẹ́ òjìdínlẹ́gbẹ̀rin
Les enfants de Zaccaï, sept cent soixante.
10 Bani jẹ́ òjìlélẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì
Les enfants de Bani, six cent quarante-deux.
11 Bebai jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mẹ́tàlélógún
Les enfants de Bébaï, six cent vingt et trois.
12 Asgadi jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé méjìlélógún
Les enfants d'Hazgad, mille deux cent vingt et deux.
13 Adonikami jẹ́ ọ̀tàlélẹ́gbẹ̀ta ó lé mẹ́fà
Les enfants d'Adonikam, six cent soixante-six.
14 Bigfai jẹ́ ẹgbàá ó lé mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
Les enfants de Bigvaï, deux mille cinquante-six.
15 Adini jẹ́ àádọ́ta lé ní irinwó ó lé mẹ́rin
Les enfants de Hadin, quatre cent cinquante-quatre.
16 Ateri (nípasẹ̀ Hesekiah) jẹ́ méjìdínlọ́gọ́run
Les enfants d'Ater, [issu] d'Ezéchias, quatre-vingt-dix-huit.
17 Besai jẹ́ ọrùndínnírinwó ó lé mẹ́ta
Les enfants de Betsaï, trois cent vingt et trois.
18 Jora jẹ́ méjìléláàádọ́fà
Les enfants de Jora, cent et douze.
19 Haṣumu jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
Les enfants de Hasum, deux cent vingt et trois.
20 Gibbari jẹ́ márùndínlọ́gọ́rùn.
Les enfants de Guibhar, quatre-vingt et quinze.
21 Àwọn ọmọ Bẹtilẹhẹmu jẹ́ mẹ́tàlélọ́gọ́fà
Les enfants de Bethléhem, six-vingt et trois.
22 Netofa jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́ta
Les gens de Nétopha, cinquante-six.
23 Anatoti jẹ́ méjìdínláàádóje
Les gens de Hanathoth, cent vingt et huit.
24 Asmafeti jẹ́ méjìlélógójì
Les enfants d'Hazmaveth, quarante-deux.
25 Kiriati-Jearimu, Kefira àti Beeroti jẹ́ ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó lé mẹ́ta
Les enfants de Kiriath-harim, de Képhira, et de Bééroth, sept cent quarante-trois.
26 Rama àti Geba jẹ́ ẹgbẹ̀ta ó lé mọ́kànlélógún
Les enfants de Rama et de Guérah, six cent vingt et un.
27 Mikmasi jẹ́ méjìlélọ́gọ́fà
Les gens de Micmas, cent vingt et deux.
28 Beteli àti Ai jẹ́ igba ó lé mẹ́tàlélógún
Les gens de Béth-el et de Haï, deux cent vingt et trois.
29 Nebo jẹ́ méjìléláàádọ́ta
Les enfants de Nébo, cinquante-deux.
30 Magbiṣi jẹ́ mẹ́rìndínlọ́gọ́jọ
Les enfants de Magbis, cent cinquante-six.
31 Elamu mìíràn jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́rìnléláàádọ́ta
Les enfants d'un autre Hélam, mille deux cent cinquante-quatre.
32 Harimu jẹ́ ọ̀rìndínnírinwó.
Les enfants de Harim, trois cent et vingt.
33 Lodi, Hadidi àti Ono jẹ́ ọ̀rìndínlẹ́gbẹ̀rin ó lé márùn-ún
Les enfants de Lod, de Hadid, et d'Ono, sept cent vingt-cinq.
34 Jeriko jẹ́ ọ̀tàdínnírinwó ó lé márùn-ún
Les enfants de Jérico, trois cent quarante-cinq.
35 Senaa jẹ́ egbèji dín lógún ó lé ọgbọ̀n.
Les enfants de Sénaa, trois mille six cent trente.
36 Àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ Jedaiah (láti ipasẹ̀ ìdílé Jeṣua) jẹ́ ogún dín lẹ́gbẹ̀rin ó dín méje
Des Sacrificateurs. Les enfants de Jédahia, de la maison de Jésuah, neuf cent soixante et treize.
37 Immeri jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀rún ó lé méjì
Les enfants d'Immer, mille cinquante-deux.
38 Paṣuri jẹ́ ẹgbẹ̀fà ó lé mẹ́tàdínláàádọ́ta
Les enfants de Pasur, mille deux cent quarante-sept.
39 Harimu jẹ́ ẹgbẹ̀rún ó lé mẹ́tàdínlógún.
Les enfants de Harim, mille et dix-sept.
40 Àwọn ọmọ Lefi. Àwọn ọmọ Jeṣua àti Kadmieli (ti ìdílé Hodafiah) jẹ́ mẹ́rìnléláàádọ́rin.
Des Lévites. Les enfants de Jésuah, et de Kadmiel, d'entre les enfants de Hodavia, soixante et quatorze.
41 Àwọn akọrin. Àwọn ọmọ Asafu jẹ́ méjìdínláàádóje.
Des chantres. Les enfants d'Asaph, cent vingt-huit.
42 Àwọn aṣọ́bodè. Àwọn ará Ṣallumu, Ateri, Talmoni, Akkubu, Hatita àti Ṣobai jẹ́ mọ́kàndínlógóje.
Des enfants des portiers. Les entants de Sallum, les enfants d'Ater, les enfants de Talmon, les enfants de Hakkub, les enfants de Hatita, les enfants de Sobaï, tous cent trente-neuf.
43 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili. Àwọn ọmọ. Siha, Hasufa, Tabboati,
Des Néthiniens. Les enfants de Tsiha, les enfants de Hasupha, les enfants de Tabbahoth.
44 Kerosi, Siaha, Padoni,
Les enfants de Kéros, les enfants de Sihaha, les enfants de Padon,
45 Lebana, Hagaba, Akkubu,
Les enfants de Lebana, les enfants de Hagaba, les enfants de Hakkub,
46 Hagabu, Ṣalmai, Hanani,
Les enfants de Hagab, les enfants de Samlaï, les enfants de Hanan,
47 Giddeli, Gahari, Reaiah,
Les enfants de Guiddel, les enfants de Gahar, les enfants de Réaja.
48 Resini, Nekoda, Gassamu,
Les enfants de Retsin, les enfants de Nékoda, les enfants de Gazam,
49 Ussa, Pasea, Besai,
Les enfants de Huza, les enfants de Paséah, les enfants de Bésaï,
50 Asna, Mehuni, Nefisimu,
Les enfants d'Asna, les enfants de Méhunim, les enfants de Néphusim,
51 Bakbu, Hakufa, Harhuri.
Les enfants de Bakbuk, les enfants de Hakupha, les enfants de Harhur,
52 Basluti, Mehida, Harṣa,
Les enfants de Batsluth, les enfants de Méhida, les enfants de Harsa,
53 Barkosi, Sisera, Tema,
Les enfants de Barkos, les enfants de Sisra, les enfants de Témah,
54 Nesia àti Hatifa.
Les enfants de Netsiah, les enfants de Hatipha.
55 Àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni. Àwọn ọmọ Sotai, Sofereti, Peruda,
Des enfants des serviteurs de Salomon; les enfants de Sotaï, les enfants de Sophereth, les enfants de Peruda,
56 Jaala, Darkoni, Giddeli,
Les enfants de Jahala, les enfants de Darkon, les enfants de Guiddel,
57 Ṣefatia, àwọn ọmọ Hattili, Pokereti ti Haṣebaimu àti àwọn ọmọ Ami.
Les enfants de Sépharia, les enfants de Hattil, les enfants de Pokéreth-hatsébajim, les enfants d'Ami.
58 Àwọn ìránṣẹ́ tẹmpili àti àwọn ọmọ àwọn ìránṣẹ́ Solomoni jẹ́ irinwó ó dín mẹ́jọ.
Tous les Néthiniens, et les enfants des serviteurs de Salomon, [furent] trois cent quatre-vingt douze.
59 Àwọn wọ̀nyí gòkè wá láti àwọn ìlú ti Teli-Mela, Teli-Harṣa, Kerubu, Addoni àti Immeri, ṣùgbọ́n wọn kò lè sọ pẹ̀lú ìdánilójú pé ìdílé àwọn wá láti ara ìran ẹ̀yà Israẹli.
Or ce sont ici ceux qui montèrent de Telmelah, de Tel-harsa, de Kérub, d'Adan, [et] d'Immer; lesquels ne purent montrer la maison de leurs pères, ni leur race, [et faire voir] s'ils étaient d'Israël.
60 Àwọn ọmọ Delaiah, Tobiah àti Nekoda jẹ́ àádọ́ta lé lẹ́gbẹ̀ta ó lé méjì.
Les enfants de Délaja, les enfants de Tobija, les enfants de Nékoda, six cent cinquante et deux.
61 Àti nínú àwọn ọmọ àwọn àlùfáà. Àwọn ọmọ: Hobaiah, Hakosi àti Barsillai (ọkùnrin tí ó fẹ́ ọmọbìnrin Barsillai ará Gileadi a sì ń fi orúkọ náà pè é).
Des enfants des Sacrificateurs; les enfants de Habaja, les enfants de Kots, les enfants de Barzillaï, qui ayant pris pour femme une des filles de Barzillaï Galaadite, fut appelé de leur nom.
62 Àwọn wọ̀nyí wá ìwé ìrántí ìdílé wọn, ṣùgbọ́n wọn kò rí i, bẹ́ẹ̀ ni a kò kà wọ́n kún ara àlùfáà nítorí, a kà wọ́n sí aláìmọ́.
Ceux-là cherchèrent leur registre, en recherchant leur généalogie, mais ils n'y furent point trouvés; c'est pourquoi ils furent rejetés de la sacrificature.
63 Baálẹ̀ pa á láṣẹ fún wọn pé wọn kò gbọdọ̀ jẹ nínú oúnjẹ mímọ́ jùlọ títí tí àlùfáà kan yóò fi ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ pẹ̀lú Urimu àti Tumimu.
Et Attirsatha leur dit qu'ils ne mangeassent point des choses très-saintes, tandis que le Sacrificateur assisterait avec l'Urim et le Thummim.
64 Gbogbo ìjọ ènìyàn náà jẹ́ ẹgbàá mọ́kànlélógún ó lé òjìdínnírinwó.
Tout le peuple ensemble était de quarante-deux mille trois cent soixante;
65 Yàtọ̀ sí ẹgbẹ̀rin dín lẹ́gbàárin ó dín mẹ́tàlélọ́gọ́ta ìránṣẹ́ ọkùnrin àti ìránṣẹ́bìnrin; wọ́n ní igba akọrin ọkùnrin àti obìnrin.
Sans leurs serviteurs et leurs servantes, qui étaient sept mille trois cent trente-sept; et ils avaient deux cents chantres ou chanteuses.
66 Wọ́n ní ọ̀tàdínlẹ́gbẹ̀rin ó dín mẹ́rin ẹṣin; ìbáaka òjìlélúgba ó lé márùn-ún,
Ils avaient sept cent trente-six chevaux, et deux cent quarante-cinq mulets,
67 ràkunmí jẹ́ irinwó ó lé márùndínlógójì àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rin lé lọ́gbọ̀n ó dín ọgọ́rin.
Quatre cent trente-cinq chameaux, et six mille sept cent vingt ânes.
68 Ní ìgbà tí wọ́n dé ilé Olúwa ní Jerusalẹmu, díẹ̀ nínú àwọn olórí àwọn ìdílé fi ọrẹ àtinúwá sílẹ̀ fún ṣíṣe àtúnkọ́ ilé Ọlọ́run ní ààyè rẹ̀.
Et [quelques-uns] d'entre les Chefs des pères, après qu'ils furent venus pour [rebâtir] la maison de l'Eternel, qui habite à Jérusalem, offrant volontairement pour la maison de Dieu, afin de la remettre en son état,
69 Gẹ́gẹ́ bí agbára wọn, wọ́n fún ilé ìṣúra fún iṣẹ́ yìí ní ọ̀kẹ́ mẹ́ta ó lé lẹ́gbẹ̀rún ìwọ̀n dariki wúrà, ẹgbẹ̀rún márùn-ún fàdákà àti ọgọ́rùn-ún ẹ̀wù àlùfáà.
Donnèrent au trésor de l'ouvrage, selon leur pouvoir, soixante et un mille drachmes d'or, et cinq mille mines d'argent, et cent robes de Sacrificateurs.
70 Àwọn àlùfáà, àwọn ará Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́bodè àti àwọn ìránṣẹ́ ilé Olúwa ṣe àtìpó sínú àwọn ìlú wọn, pẹ̀lú àwọn ènìyàn mìíràn, àti ìyókù àwọn ọmọ Israẹli ṣe àtìpó sínú ìlú u wọn.
Et ainsi les Sacrificateurs, les Lévites, quelques-uns du peuple, les chantres, les portiers, et les Néthiniens, habitèrent dans leurs villes, et tous ceux d'Israël aussi dans leurs villes.

< Ezra 2 >