< Ezekiel 5 >

1 “Báyìí, ọmọ ènìyàn, mú ìdá tí ó mú kí o sì fi ṣe abẹ ìfárí onígbàjámọ̀, kí o fi fá irun orí àti irùngbọ̀n rẹ. Fi irun yìí sórí ìwọ̀n kí o sì pín in.
»Ti pa, človeški sin, si vzemi oster nož, vzemi si brivčevo britev in ji povzroči, da gre čez tvojo glavo in po tvoji bradi. Potem si vzemi tehtnico, da stehtaš in razdeliš lase.
2 Nígbà tí ọjọ́ ìgbóguntì bá parí, sun ìdákan nínú ìdámẹ́ta irun yìí níná láàrín ìlú. Mú ìdákan nínú mẹ́ta kí o fi idà bù ú káàkiri ìlú. Kí o sì tú ìdákan yòókù ká sínú afẹ́fẹ́. Nítorí pé pẹ̀lú idà ni èmi yóò máa lé wọn ká.
Z ognjem boš sežgal tretjino v sredi mesta, ko se dopolnijo dnevi obleganja. Vzel boš tretjino in okoli nje udarjal z nožem. Tretjino boš raztrosil v vetru, jaz pa bom za njimi izvlekel meč.
3 Ṣùgbọ́n mú díẹ̀ nínú irun yìí kí o sì ta á mọ́ etí aṣọ rẹ.
Od teh boš vzel malo po številu in jih povezal v krajce svojega oblačila.
4 Tún ju díẹ̀ nínú irun yìí sínú iná, kí o sun ún níná. Torí pé láti ibẹ̀ ni iná yóò ti jáde lọ sí gbogbo ilé Israẹli.
Potem ponovno vzemi od teh in jih vrzi v sredo ognja in jih sežgi v ognju, kajti od teh bo prišel ogenj v vso Izraelovo hišo.«
5 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èyí ní Jerusalẹmu, tí mo gbé kalẹ̀ sí àárín àwọn Orílẹ̀-èdè, pẹ̀lú àwọn ìlú gbogbo tí o yí i ká.
Tako govori Gospod Bog: »To je [prestolnica] Jeruzalem. Postavil sem jo v sredo narodov in dežel, ki so naokoli nje.
6 Síbẹ̀ nínú ìwà búburú rẹ ó ti ṣọ̀tẹ̀ si òfin àti ìlànà mi ju àwọn orílẹ̀-èdè àti àwọn ilẹ̀ tó yí i ká lọ. Ó ti kọ òfin mi sílẹ̀, o kò sì pa ìlànà mi mọ́.
Moje sodbe je spremenila v zlobnost bolj kakor narodi in moje zakone bolj kakor dežele, ki so okoli nje, kajti zavrnili so moje sodbe in moje zakone; niso hodili v njih.«
7 “Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Nítorí pé ẹ̀yin ti ṣe àìgbọ́ràn ju àwọn orílẹ̀-èdè tó yí yín ká lọ, tí ẹ kò sì tẹ̀lé ìlànà mi tàbí kí o pa òfin mi mọ́. O kò tilẹ̀ túnṣe dáradára tó àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
Zato tako govori Gospod Bog: »Ker ste se pomnožili bolj kakor narodi, ki so okoli vas in niste hodili po mojih zakonih niti se niste držali mojih sodb niti niste delali glede na sodbe narodov, ki so naokoli vas, «
8 “Nítorí náà báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: Èmi gan an lòdì sí ọ, Jerusalẹmu, èmi yóò sì jẹ ọ́ ní yà lójú àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká.
zato tako govori Gospod Bog: »Glej jaz, celo jaz, sem zoper tebe in v tvoji sredi bom izvršil sodbe pred očmi narodov.
9 Nítorí gbogbo ohun ìríra rẹ, èmi yóò ṣe ohun tí n kò tí ì ṣe rí láàrín rẹ àti èyí tí n kò ní í ṣe irú rẹ̀ mọ́.
V tebi bom storil to, česar nisem storil in ne bom več storil temu podobnega, zaradi vseh tvojih ogabnosti.
10 Nítorí náà láàrín rẹ àwọn baba yóò máa jẹ ọmọ wọn, àwọn ọmọ náà yóò máa jẹ baba wọn. Èmi yóò jẹ ọ́ ní yà, èmi yóò sì tú àwọn tó bá ṣẹ́kù ká sínú ẹ̀fúùfù.
Zato bodo v tvoji sredi očetje jedli sinove in sinovi bodo jedli svoje očete. Izvršil bom sodbe v tebi in tvoj celotni preostanek bom razkropil na vse vetrove.
11 Nítorí náà, Olúwa Olódùmarè wí pé, bí mo ṣe wà láààyè, nítorí pé ìwọ ti sọ ibi mímọ́ mi di àìmọ́ pẹ̀lú àwọn àwòrán ẹ̀gbin àti àwọn ohun ìríra rẹ, èmi yóò mú ojúrere mi kúrò lára rẹ, èmi kò ní í da ọ sí, bẹ́ẹ̀ ni èmi kì yóò wò ọ́ pẹ̀lú àánú mọ́.
Zato, kakor jaz živim, « govori Gospod Bog, »zagotovo, ker si moje svetišče omadeževala z vsemi svojimi ostudnimi stvarmi in z vsemi svojimi ogabnostmi, zato bom tudi jaz tebe zmanjšal; niti moje oko ne bo prizaneslo, niti ne bom imel nobenega usmiljenja.
12 Ìdámẹ́ta nínú àwọn ènìyàn rẹ yóò kú nípa àjàkálẹ̀-ààrùn tàbí kí ìyàn run wọ́n: ìdámẹ́ta yóò ṣubú nípa idà lẹ́yìn odi rẹ, èmi yóò sì tú ìdámẹ́ta yòókù ká sínú ẹ̀fúùfù, èmi yóò sì máa fi idà lé wọn.
Tvoja tretjina bo umrla s kužno boleznijo in z lakoto bodo použiti v tvoji sredi. Tretjina bo padla pod mečem naokoli tebe, tretjino pa bom razkropil na vse vetrove in za njimi bom izvlekel meč.
13 “Ìbínú mi yóò sì dúró, bẹ́ẹ̀ ni ìbínú gbígbóná mi yóò sì rọlẹ̀, èmi yóò sì ti gba ẹ̀san mi. Nígbà tí mo bá sì parí ìbínú mi lórí wọn, wọn ó mọ̀ pé, Èmi Olúwa ti sọ̀rọ̀ nínú ìtara mi.
Tako bo moja jeza dovršena in svoji razjarjenosti bom povzročil, da počiva nad njimi, jaz pa bom potolažen. Oni pa bodo vedeli, da sem jaz, Gospod, to govoril v svoji gorečnosti, ko sem svojo razjarjenost dovršil v njih.
14 “Èmi yóò fi ọ́ ṣòfò, èmi yóò sì sọ ọ́ di ẹ̀gàn fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, àti lójú àwọn tó ń kọjá.
Poleg tega te bom naredil opustošenje in grajo med narodi, ki so naokoli tebe, pred očmi vseh, ki hodijo mimo.
15 O ó wá di ẹ̀gàn, ẹ̀sín àti ẹ̀kọ̀ àti ohun ẹ̀rù àti ìyanu fún àwọn orílẹ̀-èdè tó yí ọ ká, nígbà tí mo bá fìyà jẹ ọ́ nínú ìbínú àti nínú ìbínú gbígbóná mi. Èmi Olúwa ni ó sọ bẹ́ẹ̀.
Tako bo to graja in zbadljivka, poučevanje in osuplost narodom, ki so naokoli tebe, ko bom v tebi izvršil sodbe v jezi, v razjarjenosti in v besnih ukorih. Jaz, Gospod, sem to govoril.
16 Nígbà tí èmi ó rán ọfà búburú ìyàn sí wọn, èyí tí yóò jẹ́ fún ìparun wọn. Èmí tí èmi yóò rán run yín. Èmí yóò sì sọ ìyàn di púpọ̀ fún yín. Èmí yóò sì ṣẹ́ ọ̀pá oúnjẹ yín.
Ko bom nanje poslal zle puščice lakote, ki bodo za njihovo uničenje in ki jih bom poslal, da vas uničijo; in jaz bom razširil lakoto nad vami in zlomil vašo oporo kruha.
17 Èmi yóò rán ìyàn àti ẹranko búburú sí i yín, wọn yóò fi yín sílẹ̀ ni àìlọ́mọ. Àjàkálẹ̀-ààrùn àti ìtàjẹ̀ sílẹ̀ yóò kọjá láàrín yín. Èmi yóò si mú idà wá sórí rẹ. Èmi Olúwa ló sọ bẹ́ẹ̀.”
Tako bom nad vas poslal lakoto in zle živali in te te bodo oropale in kužna bolezen in kri bosta šla skozte in nadte bom privedel meč. Jaz, Gospod, sem to govoril.«

< Ezekiel 5 >