< Ezekiel 25 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá wí pé:
Och HERRENS ord kom till mig; han sade:
2 “Ọmọ ènìyàn, kọ ojú rẹ sí àwọn ará Ammoni kí ó sì sọ àsọtẹ́lẹ̀ sí wọn.
Du människobarn, vänd ditt an- sikte mot Ammons barn och profetera mot dem.
3 Sì wí fún àwọn ará Ammoni pé, ‘Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa Olódùmarè tí ó wí pé. Nítorí tí ìwọ wí pé, “Á hà!” Sí ibi mímọ́ mi nígbà tí ó di àìlọ́wọ̀ àti sí orí ilẹ̀ Israẹli nígbà tí ó di ahoro; àti sí ilẹ̀ Juda, nígbà tí wọ́n lọ sí ìgbèkùn,
Och säg till Ammons barn: Hören Herrens, HERRENS ord: Så säger Herren, HERREN: Eftersom du ropar: "Rätt så!" över min helgedom, som har blivit oskärad, och över Israels land, som har blivit ödelagt, och över Juda folk, som har måst vandra bort i fångenskap,
4 kíyèsi i, nítorí náà ni èmi yóò fi fi ọ lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn lọ́wọ́ ni ohun ìní. Wọn yóò sì gbé ààfin wọn kalẹ̀ nínú rẹ, wọn yóò sì gbé ibùgbé wọn nínú rẹ, wọn yóò jẹ èso rẹ, wọn yóò sì mu wàrà rẹ.
se, därför vill jag giva dig till besittning åt österlänningarna, så att de få slå upp sina tältläger i dig och sätta upp sina boningar i dig; de skola få äta din frukt, och de skola dricka din mjölk.
5 Èmi yóò sì sọ Rabba di ibùjẹ, fún àwọn ìbákasẹ àti àwọn ọmọ Ammoni di ibùsùn fún agbo ẹran. Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò mọ̀ pé, Èmi ni Olúwa.
Och jag skall göra Rabba till en betesmark för kameler och Ammons barns land till en lägerplats för får; och I skolen förnimma att Jag är HERREN.
6 Nítorí báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí. Nítorí pé ìwọ pàtẹ́wọ́, ìwọ sì jan ẹsẹ̀ mọ́lẹ̀, tí ìwọ ń yọ̀ pẹ̀lú gbogbo àrankàn rẹ sí ilẹ̀ Israẹli
Ty så säger Herren, HERREN: Eftersom du klappar i händerna och stampar med fötterna och i ditt sinnes hela övermod gläder dig vid Israels lands ofärd,
7 nítorí náà, èmi yóò na ọwọ́ mi lé ọ, èmi yóò sì fi ọ fún àwọn aláìkọlà fún ìkógun. Èmi yóò sì gé ọ kúrò láàrín àwọn ènìyàn, èmi yóò sì jẹ́ kí o parun kúrò ni ilẹ̀ gbogbo. Èmi yóò sì pa ọ́ run, ìwọ yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
se, därför skall jag uträcka min hand mot dig och giva dig till byte åt hedningarna och utrota dig ifrån folken och utplåna dig ur länderna; jag skall förgöra dig, och du skall förnimma att jag är HERREN.
8 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí: ‘Nítorí pé Moabu àti Seiri sọ wí pé, “Wò ó, ilé Juda ti dàbí gbogbo àwọn kèfèrí,”
Så säger Herren, HERREN: Eftersom Moab och Seir säga: "Se, nu är det med Juda hus likasom med alla andra folk",
9 nítorí náà, Èmi yóò ṣí Moabu sílẹ̀ láti àwọn ìlú gbogbo tí ó wà ní ààlà rẹ̀, ògo ilẹ̀ náà, Beti-Jeṣimoti, Baali-Meoni àti Kiriataimu.
se, därför skall jag lägga Moabs bergsluttning öppen och förstöra dess städer, Ja, dess städer så många de äro, vad härligast är i landet, Bet-Hajesimot, Baal-Meon och Kirjatama.
10 Èmi yóò fi Moabu pẹ̀lú àwọn ará Ammoni lé àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn ní ìní, kí a má bà á lè rántí àwọn ará Ammoni láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Åt österlänningarna skall jag giva det till besittning, likasom jag skall göra med Ammons barns land, så att man icke mer tänker på Ammons barn ibland folken.
11 Èmi yóò sì mú ìdájọ́ sẹ sí Moabu lára, wọn yóò sì mọ̀ pé èmi ni Olúwa.’”
Ja, över Moab skall jag hålla dom, och de skola förnimma att jag är HERREN.
12 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí pé Edomu gbẹ̀san lára ilé Juda, ó sì jẹ̀bi gidigidi nípa ṣíṣe bẹ́ẹ̀,
Så säger Herren, HERREN: Eftersom Edom har handlat så hämndgirigt mot Juda hus och ådragit sig svår skuld genom sin hämnd på dem,
13 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé: Èmi yóò na ọwọ́ mi sórí Edomu èmi yóò sì pa àwọn ènìyàn àti àwọn ẹranko rẹ̀. Èmi yóò fi ṣófo láti Temani dé Dedani yóò ti ipa idà ṣubú.
därför säger Herren, HERREN så: Jag skall uträcka min hand mot Edom och utrota därur både människor och djur. Och jag skall göra det till en ödemark ända från Teman, och ända borta i Dedan skola de falla för svärd.
14 Èmi yóò gbẹ̀san lára Edomu láti ọwọ́ àwọn ènìyàn mi Israẹli, wọn sì ṣe sí Edomu gẹ́gẹ́ bí ìbínú àti ìrunú mi, wọn yóò mọ̀ ìgbẹ̀san mi ní Olúwa Olódùmarè wí.’”
Och jag skall utföra min hämnd på Edom genom mitt folk Israel, och dessa skola göra med Edom efter min vrede och förtörnelse; och det skall så få känna min hämnd, säger Herren, HERREN.
15 “Báyìí ni Olúwa Olódùmarè wí pé: ‘Nítorí tí àwọn ará Filistini hùwà ẹ̀san tí wọ́n sì gbẹ̀san pẹ̀lú odì ní ọkàn wọn, àti pẹ̀lú ìkórìíra gbangba àtijọ́ ní wíwá ọ̀nà láti pa Juda run,
Så säger Herren, HERREN: Eftersom filistéerna hava handlat så hämndgirigt, ja, eftersom de i sitt sinnes övermod hava velat utkräva hämnd och i sin eviga fiendskap hava velat bereda fördärv,
16 nítorí náà báyìí ní Olúwa Olódùmarè wí pé, “Èmi ti ṣetán láti na ọwọ́ mi jáde sí àwọn ará Filistini, èmi yóò sì ké àwọn ará Kereti kúrò, èmi yóò sì pa àwọn tí ó kù ní etí kún run.
därför säger Herren, HERREN så: Se, jag vill uträcka min hand mot filistéerna och utrota keretéerna och förgöra vad som är kvar av Kustlandet vid havet.
17 Èmi yóò sì gbẹ̀san ńlá lára wọn nípa ìbáwí gbígbóná; wọn yóò sì mọ̀ wí pé, Èmi ni Olúwa. Nígbà tí èmi yóò gba ẹ̀san lára wọn.”’”
Och jag skall taga stor hämnd på dem och tukta dem i förtörnelse. Och när jag låter min hämnd drabba dem, då skola de förnimma att jag är HERREN.

< Ezekiel 25 >